< Genesis 23 >

1 Sara sì pé ọmọ ọdún mẹ́tàdínláàádóje.
Sarah viveu cento e vinte e sete anos. Esta foi a duração da vida de Sarah.
2 Ó sì kú ní Kiriati-Arba (ìyẹn ní Hebroni) ní ilẹ̀ Kenaani, Abrahamu lọ láti ṣọ̀fọ̀ àti láti sọkún nítorí Sara.
Sarah morreu em Kiriath Arba (também chamada Hebron), na terra de Canaã. Abraão veio para chorar por Sara, e chorar por ela.
3 Abrahamu sì dìde lẹ́gbẹ̀ẹ́ òkú aya rẹ̀, ó sì sọ fún àwọn ará Hiti wí pé,
Abraão levantou-se de antes de sua morte e falou aos filhos de Heth, dizendo:
4 “Èmi jẹ́ àtìpó àti àlejò láàrín yín, ẹ ta ilẹ̀ ìsìnkú fún mi kí èmi le sin òkú tí ó kú fún mi sí.”
“Sou um estranho e um estrangeiro vivendo com você. Dê-me a posse de um lugar de sepultamento com você, para que eu possa enterrar meus mortos fora de minha vista”.
5 Àwọn ọmọ Hiti dá Abrahamu lóhùn pé,
Os filhos de Heth responderam a Abraão, dizendo-lhe:
6 “Olúwa mi, gbọ́ tiwa, ó jẹ́ alágbára ọmọ-aládé láàrín wa, sin òkú rẹ sí ibojì tí ó dára jù nínú àwọn ibojì wa, kò sí ẹni tí yóò fi ibojì rẹ dù ọ́ láti sin òkú rẹ sí.”
“Ouça-nos, meu senhor”. Vós sois um príncipe de Deus entre nós”. Enterrai vossos mortos no melhor de nossos túmulos”. Nenhum de nós lhe ocultará seu túmulo. Enterrai vossos mortos”.
7 Nígbà náà ni Abrahamu dìde, ó sì tẹríba níwájú àwọn ará ilẹ̀ náà, àwọn ará Hiti.
Abraão se levantou e se curvou diante do povo da terra, diante dos filhos de Heth.
8 Ó sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá ṣe pé, lóòótọ́ ni ẹ fẹ́ kí n sin òkú mi kúrò nílẹ̀, ẹ gbọ́ tèmi, ẹ bá mi bẹ Efroni ọmọ Sohari,
Ele falou com eles, dizendo: “Se você concorda que eu deveria enterrar meus mortos fora de minha vista, ouça-me e rogue por mim a Efrom, filho de Zohar,
9 kí ó ta ihò àpáta Makpela tí ó jẹ́ tirẹ̀ fún mi, èyí tí ó wà ni orí oko rẹ̀, kí ó tà á fún mi ni iye owó tí à ń ta irú rẹ̀ fún ilẹ̀ ìsìnkú láàrín yín.”
para que ele me venda a caverna de Machpelah, que ele tem, que está no fim de seu campo. Pelo preço total, deixai-o vender-ma entre vós como posse para um lugar de sepultamento”.
10 Efroni ará Hiti sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú, ó sì dá Abrahamu lóhùn lójú gbogbo àwọn ará ìlú tí ó wà níbẹ̀, lẹ́nu ibodè ìlú,
Agora Ephron estava sentado no meio das crianças de Heth. Efrom, o hitita, respondeu a Abraão na audiência dos filhos de Heth, mesmo de todos que entraram pelo portão de sua cidade, dizendo:
11 pé, “Rárá, olúwa mi. Gbọ́ tèmi; mo fún ọ ní ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà níbẹ̀. Mo fún ọ níwájú gbogbo àwọn ènìyàn mi. Sin òkú rẹ síbẹ̀.”
“Não, meu senhor, ouça-me. Eu lhe dou o campo, e lhe dou a caverna que está nele. Na presença dos filhos de meu povo, eu o dou a vós. Enterrai vossos mortos”.
12 Abrahamu sì tún tẹríba níwájú àwọn ènìyàn ìlú náà,
Abraão se curvou diante do povo da terra.
13 ó sì wí fún Efroni lójú gbogbo wọn pé, “Bí ìwọ bá fẹ́, gbọ́ tèmi, èmi yóò san owó ilẹ̀ náà, gbà á lọ́wọ́ mi kí n lè sin òkú mi síbẹ̀.”
Ele falou a Efron na audiência do povo da terra, dizendo: “Mas se você quiser, por favor, me ouça”. Eu darei o preço do campo”. Tirem-no de mim e eu enterrarei meus mortos lá”.
14 Efroni sì dá Abrahamu lóhùn pé,
Ephron respondeu a Abraão, dizendo-lhe:
15 “Gbọ́ tèmi Olúwa mi, irinwó òsùwọ̀n owó fàdákà ni ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n kín ni ìyẹn já mọ láàrín àwa méjèèjì? Sá à sin òkú rẹ.”
“Meu senhor, escute-me. O que é um pedaço de terra que vale quatrocentos siclos de prata entre mim e você? Enterrai, pois, vossos mortos”.
16 Abrahamu sì gbọ́ tí Efroni wí, Abrahamu sì wọn iye fàdákà náà fún Efroni, tí ó sọ ní etí àwọn ọmọ Hiti, irinwó òsùwọ̀n ṣékélì fàdákà, tí ó kọjá lọ́dọ̀ àwọn oníṣòwò.
Abraham ouviu Ephron. Abraão pesou para Ephron a prata que ele havia nomeado na audiência dos filhos de Heth, quatrocentos siclos de prata, de acordo com o padrão atual dos comerciantes.
17 Báyìí ni ilẹ̀ Efroni tí ó wà ni Makpela nítòsí Mamre, ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ àti gbogbo igi tí ó wà nínú ilẹ̀ náà ni a ṣe ètò rẹ̀ dájú,
Assim, o campo de Efron, que estava em Machpelah, que estava antes de Mamre, o campo, a caverna que estava nele, e todas as árvores que estavam no campo, que estavam em todas as suas fronteiras, foram escrituradas
18 bí ohun ìní fún Abrahamu níwájú gbogbo ará Hiti tí ó wá sí ẹnu ibodè ìlú náà.
a Abraão por posse na presença dos filhos de Heth, antes de todos os que entraram pelo portão de sua cidade.
19 Lẹ́yìn náà ni Abrahamu sin aya rẹ̀ Sara sínú ihò àpáta ní ilẹ̀ Makpela nítòsí Mamre (tí í ṣe Hebroni) ní ilẹ̀ Kenaani.
Depois disto, Abraão enterrou Sara sua esposa na caverna do campo de Machpelah antes de Mamre (isto é, Hebron), na terra de Canaã.
20 Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni àwọn ará Hiti fi fún Abrahamu gẹ́gẹ́ bí ohun ìní títí láé, bí ilẹ̀ ìsìnkú fún àwọn òkú tí ó bá kú fun un.
O campo, e a caverna que nele se encontra, foram escrituras de Abraão pelos filhos de Heth como possessão para um lugar de sepultamento.

< Genesis 23 >