< Genesis 23 >

1 Sara sì pé ọmọ ọdún mẹ́tàdínláàádóje.
A żyła Sara sto lat, i dwadzieścia lat, i siedem lat; te są lata żywota Sary.
2 Ó sì kú ní Kiriati-Arba (ìyẹn ní Hebroni) ní ilẹ̀ Kenaani, Abrahamu lọ láti ṣọ̀fọ̀ àti láti sọkún nítorí Sara.
I umarła Sara w mieście Arba, które zowią Hebron, w ziemi Chananejskiej: i przyszedł Abraham, aby żałował Sary, i płakał jej.
3 Abrahamu sì dìde lẹ́gbẹ̀ẹ́ òkú aya rẹ̀, ó sì sọ fún àwọn ará Hiti wí pé,
Potem wstał Abraham od umarłego swego, i rzekł do synów Hetowych, mówiąc:
4 “Èmi jẹ́ àtìpó àti àlejò láàrín yín, ẹ ta ilẹ̀ ìsìnkú fún mi kí èmi le sin òkú tí ó kú fún mi sí.”
Gościem i przychodniem jestem u was; dajcież mi osiadłość grobu między wami, abym pogrzebał umarłego mego od twarzy mojej.
5 Àwọn ọmọ Hiti dá Abrahamu lóhùn pé,
Tedy opowiedzieli synowie Hetowi Abrahamowi, mówiąc mu:
6 “Olúwa mi, gbọ́ tiwa, ó jẹ́ alágbára ọmọ-aládé láàrín wa, sin òkú rẹ sí ibojì tí ó dára jù nínú àwọn ibojì wa, kò sí ẹni tí yóò fi ibojì rẹ dù ọ́ láti sin òkú rẹ sí.”
Słuchaj nas, panie mój: Książęciem Bożym jesteś ty w pośrodku nas: w najprzedniejszych grobach naszych pogrzeb umarłego twego; żaden z nas nie będzie bronił grobu swego tobie, abyś nie miał pogrzebać umarłego twego.
7 Nígbà náà ni Abrahamu dìde, ó sì tẹríba níwájú àwọn ará ilẹ̀ náà, àwọn ará Hiti.
Tedy wstawszy Abraham, pokłonił się ludowi onej ziemi, to jest synom Hetowym, i rzekł do nich, mówiąc:
8 Ó sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá ṣe pé, lóòótọ́ ni ẹ fẹ́ kí n sin òkú mi kúrò nílẹ̀, ẹ gbọ́ tèmi, ẹ bá mi bẹ Efroni ọmọ Sohari,
Jeźli się wam podoba, abym pogrzebał umarłego mego od twarzy mojej, słuchajcież mię, a przyczyńcie się za mną, do Efrona, syna Socharowego,
9 kí ó ta ihò àpáta Makpela tí ó jẹ́ tirẹ̀ fún mi, èyí tí ó wà ni orí oko rẹ̀, kí ó tà á fún mi ni iye owó tí à ń ta irú rẹ̀ fún ilẹ̀ ìsìnkú láàrín yín.”
Aby mi ustąpił jaskini swojej Machpela, którą ma na końcu pola swego, za słuszne pieniądze; niech mi ją spuści przed wami w osiadłość grobu.
10 Efroni ará Hiti sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú, ó sì dá Abrahamu lóhùn lójú gbogbo àwọn ará ìlú tí ó wà níbẹ̀, lẹ́nu ibodè ìlú,
( A Efron siedział w pośrodku synów Hetowych. ) Tedy odpowiedział Efron Hetejczyk Abrahamowi, w przytomności synów Hetowych, przed wszystkimi, którzy chodzili w bramę miasta jego, mówiąc:
11 pé, “Rárá, olúwa mi. Gbọ́ tèmi; mo fún ọ ní ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà níbẹ̀. Mo fún ọ níwájú gbogbo àwọn ènìyàn mi. Sin òkú rẹ síbẹ̀.”
Nie tak, panie mój, ale słuchaj mię: Pole to dam tobie i jaskinią, która jest w niem, dawam ją tobie; przed oczyma synów ludu mego, dawam ją tobie, pogrzebże umarłego twego.
12 Abrahamu sì tún tẹríba níwájú àwọn ènìyàn ìlú náà,
Tedy się pokłonił Abraham przed ludem onej ziemi;
13 ó sì wí fún Efroni lójú gbogbo wọn pé, “Bí ìwọ bá fẹ́, gbọ́ tèmi, èmi yóò san owó ilẹ̀ náà, gbà á lọ́wọ́ mi kí n lè sin òkú mi síbẹ̀.”
I rzekł do Efrona, w przytomności ludu onej ziemi, mówiąc: Raczej, jeźlić się zda, proszę, słuchaj mię: dam ci pieniądze za pole, weźmijże je ode mnie, a pogrzebię tam umarłego mego.
14 Efroni sì dá Abrahamu lóhùn pé,
I odpowiedział Efron Abrahamowi mówiąc mu:
15 “Gbọ́ tèmi Olúwa mi, irinwó òsùwọ̀n owó fàdákà ni ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n kín ni ìyẹn já mọ láàrín àwa méjèèjì? Sá à sin òkú rẹ.”
Panie mój, słuchaj mię. Ziemia ta stoi za cztery sta syklów srebra; ale cóż to jest między mną i między tobą? pogrzeb umarłego twego.
16 Abrahamu sì gbọ́ tí Efroni wí, Abrahamu sì wọn iye fàdákà náà fún Efroni, tí ó sọ ní etí àwọn ọmọ Hiti, irinwó òsùwọ̀n ṣékélì fàdákà, tí ó kọjá lọ́dọ̀ àwọn oníṣòwò.
I usłuchał Abraham Efrona; i odważył Abraham Efronowi srebro, jako był rzekł w przytomności synów Hetowych, cztery sta syklów srebra, tak jako szły między kupcami.
17 Báyìí ni ilẹ̀ Efroni tí ó wà ni Makpela nítòsí Mamre, ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ àti gbogbo igi tí ó wà nínú ilẹ̀ náà ni a ṣe ètò rẹ̀ dájú,
I dostało się pole Efronowe ( które jest w Machpelu przeciwko Mamre, pole i jaskinia, która jest na niem, i wszystkie drzewa, które były na polu, które były na wszystkich granicach jego w około ).
18 bí ohun ìní fún Abrahamu níwájú gbogbo ará Hiti tí ó wá sí ẹnu ibodè ìlú náà.
Abrahamowi w osiadłość przed oczyma synów Hetowych, i wszystkich, którzy wchodzili w bramę miasta onego.
19 Lẹ́yìn náà ni Abrahamu sin aya rẹ̀ Sara sínú ihò àpáta ní ilẹ̀ Makpela nítòsí Mamre (tí í ṣe Hebroni) ní ilẹ̀ Kenaani.
A tak pogrzebał Abraham Sarę, żonę swoję, w jaskini pola w Machpelu przeciwko Mamre, to jest Hebron, w ziemi Chananejskiej.
20 Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni àwọn ará Hiti fi fún Abrahamu gẹ́gẹ́ bí ohun ìní títí láé, bí ilẹ̀ ìsìnkú fún àwọn òkú tí ó bá kú fun un.
I oddane jest pole i jaskinia, która była na niem, Abrahamowi w osiadłość grobu, od synów Hetowych.

< Genesis 23 >