< Genesis 23 >
1 Sara sì pé ọmọ ọdún mẹ́tàdínláàádóje.
Sarah a vécu cent vingt-sept ans. Telle fut la durée de la vie de Sara.
2 Ó sì kú ní Kiriati-Arba (ìyẹn ní Hebroni) ní ilẹ̀ Kenaani, Abrahamu lọ láti ṣọ̀fọ̀ àti láti sọkún nítorí Sara.
Sara mourut à Kiriath Arba (appelée aussi Hébron), dans le pays de Canaan. Abraham vint pour porter le deuil de Sara et pour la pleurer.
3 Abrahamu sì dìde lẹ́gbẹ̀ẹ́ òkú aya rẹ̀, ó sì sọ fún àwọn ará Hiti wí pé,
Abraham se leva de devant sa mort et parla aux fils de Heth, en disant:
4 “Èmi jẹ́ àtìpó àti àlejò láàrín yín, ẹ ta ilẹ̀ ìsìnkú fún mi kí èmi le sin òkú tí ó kú fún mi sí.”
« Je suis un étranger et une étrangère qui vit avec vous. Donnez-moi la possession d'un lieu de sépulture chez vous, afin que j'enterre mes morts hors de ma vue. »
5 Àwọn ọmọ Hiti dá Abrahamu lóhùn pé,
Les fils de Heth prirent la parole et dirent à Abraham:
6 “Olúwa mi, gbọ́ tiwa, ó jẹ́ alágbára ọmọ-aládé láàrín wa, sin òkú rẹ sí ibojì tí ó dára jù nínú àwọn ibojì wa, kò sí ẹni tí yóò fi ibojì rẹ dù ọ́ láti sin òkú rẹ sí.”
« Écoute-nous, mon seigneur. Tu es un prince de Dieu parmi nous. Enterre tes morts dans le meilleur de nos tombeaux. Aucun de nous ne te refusera son tombeau. Enterre tes morts. »
7 Nígbà náà ni Abrahamu dìde, ó sì tẹríba níwájú àwọn ará ilẹ̀ náà, àwọn ará Hiti.
Abraham se leva, et se prosterna devant le peuple du pays, devant les fils de Heth.
8 Ó sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá ṣe pé, lóòótọ́ ni ẹ fẹ́ kí n sin òkú mi kúrò nílẹ̀, ẹ gbọ́ tèmi, ẹ bá mi bẹ Efroni ọmọ Sohari,
Il leur parla ainsi: « Si vous êtes d'accord pour que j'enterre mes morts hors de ma vue, écoutez-moi, et plaidez pour moi auprès d'Ephron, fils de Zohar,
9 kí ó ta ihò àpáta Makpela tí ó jẹ́ tirẹ̀ fún mi, èyí tí ó wà ni orí oko rẹ̀, kí ó tà á fún mi ni iye owó tí à ń ta irú rẹ̀ fún ilẹ̀ ìsìnkú láàrín yín.”
afin qu'il me vende la grotte de Macpéla qu'il possède, qui est au bout de son champ. Pour le plein prix, qu'il me la vende au milieu de vous comme une possession pour une sépulture. »
10 Efroni ará Hiti sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú, ó sì dá Abrahamu lóhùn lójú gbogbo àwọn ará ìlú tí ó wà níbẹ̀, lẹ́nu ibodè ìlú,
Or Éphron était assis au milieu des fils de Heth. Ephron, le Hittite, répondit à Abraham en présence des fils de Heth, de tous ceux qui entraient à la porte de sa ville, et dit:
11 pé, “Rárá, olúwa mi. Gbọ́ tèmi; mo fún ọ ní ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà níbẹ̀. Mo fún ọ níwájú gbogbo àwọn ènìyàn mi. Sin òkú rẹ síbẹ̀.”
« Non, mon seigneur, écoute-moi. Je te donne le champ, et je te donne la grotte qui s'y trouve. En présence des enfants de mon peuple, je te la donne. Enterre tes morts. »
12 Abrahamu sì tún tẹríba níwájú àwọn ènìyàn ìlú náà,
Abraham se prosterna devant le peuple du pays.
13 ó sì wí fún Efroni lójú gbogbo wọn pé, “Bí ìwọ bá fẹ́, gbọ́ tèmi, èmi yóò san owó ilẹ̀ náà, gbà á lọ́wọ́ mi kí n lè sin òkú mi síbẹ̀.”
Il s'adressa à Ephron, en présence du peuple du pays, et dit: « Mais si tu le veux, écoute-moi. Je vais donner le prix du champ. Prends-le de ma part, et j'y enterrerai mes morts. »
14 Efroni sì dá Abrahamu lóhùn pé,
Ephron prit la parole et dit à Abraham:
15 “Gbọ́ tèmi Olúwa mi, irinwó òsùwọ̀n owó fàdákà ni ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n kín ni ìyẹn já mọ láàrín àwa méjèèjì? Sá à sin òkú rẹ.”
« Mon seigneur, écoute-moi. Qu'est-ce qu'un morceau de terre valant quatre cents sicles d'argent entre moi et toi? Enterre donc tes morts. »
16 Abrahamu sì gbọ́ tí Efroni wí, Abrahamu sì wọn iye fàdákà náà fún Efroni, tí ó sọ ní etí àwọn ọmọ Hiti, irinwó òsùwọ̀n ṣékélì fàdákà, tí ó kọjá lọ́dọ̀ àwọn oníṣòwò.
Abraham écouta Ephron. Abraham pesa à Ephron l'argent qu'il avait nommé à l'audition des fils de Heth, quatre cents sicles d'argent, selon l'usage courant des marchands.
17 Báyìí ni ilẹ̀ Efroni tí ó wà ni Makpela nítòsí Mamre, ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ àti gbogbo igi tí ó wà nínú ilẹ̀ náà ni a ṣe ètò rẹ̀ dájú,
Le champ d'Ephron, qui était à Macpéla, en face de Mamré, le champ, la caverne qui s'y trouvait, et tous les arbres qui étaient dans le champ, dans toute son étendue, furent donnés
18 bí ohun ìní fún Abrahamu níwájú gbogbo ará Hiti tí ó wá sí ẹnu ibodè ìlú náà.
à Abraham comme possession en présence des fils de Heth, devant tous ceux qui entraient à la porte de sa ville.
19 Lẹ́yìn náà ni Abrahamu sin aya rẹ̀ Sara sínú ihò àpáta ní ilẹ̀ Makpela nítòsí Mamre (tí í ṣe Hebroni) ní ilẹ̀ Kenaani.
Après cela, Abraham enterra Sara, sa femme, dans la caverne du champ de Macpéla, devant Mamré, c'est-à-dire Hébron, au pays de Canaan.
20 Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni àwọn ará Hiti fi fún Abrahamu gẹ́gẹ́ bí ohun ìní títí láé, bí ilẹ̀ ìsìnkú fún àwọn òkú tí ó bá kú fun un.
Le champ et la grotte qui s'y trouve ont été cédés à Abraham par les fils de Heth comme une possession pour une sépulture.