< Genesis 23 >
1 Sara sì pé ọmọ ọdún mẹ́tàdínláàádóje.
And they were [the] life of Sarah one hundred year[s] and twenty year[s] and seven years [the] years of [the] life of Sarah.
2 Ó sì kú ní Kiriati-Arba (ìyẹn ní Hebroni) ní ilẹ̀ Kenaani, Abrahamu lọ láti ṣọ̀fọ̀ àti láti sọkún nítorí Sara.
And she died Sarah at Kiriath Arba that [is] Hebron in [the] land of Canaan and he went Abraham to mourn for Sarah and to weep for her.
3 Abrahamu sì dìde lẹ́gbẹ̀ẹ́ òkú aya rẹ̀, ó sì sọ fún àwọn ará Hiti wí pé,
And he arose Abraham from on [the] face of dead his and he spoke to [the] people of Heth saying.
4 “Èmi jẹ́ àtìpó àti àlejò láàrín yín, ẹ ta ilẹ̀ ìsìnkú fún mi kí èmi le sin òkú tí ó kú fún mi sí.”
[am] a sojourner And a resident alien I with you give to me a possession of a burial site with you so let me bury dead my from to before me.
5 Àwọn ọmọ Hiti dá Abrahamu lóhùn pé,
And they answered [the] people of Heth Abraham saying to him.
6 “Olúwa mi, gbọ́ tiwa, ó jẹ́ alágbára ọmọ-aládé láàrín wa, sin òkú rẹ sí ibojì tí ó dára jù nínú àwọn ibojì wa, kò sí ẹni tí yóò fi ibojì rẹ dù ọ́ láti sin òkú rẹ sí.”
Listen to us - O lord my [are] a prince of God you in midst of us in [the] choicest of burial sites our bury dead your anyone of us burial site his not he will withhold from you from burying dead your.
7 Nígbà náà ni Abrahamu dìde, ó sì tẹríba níwájú àwọn ará ilẹ̀ náà, àwọn ará Hiti.
And he arose Abraham and he bowed down to [the] people of the land to [the] people of Heth.
8 Ó sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá ṣe pé, lóòótọ́ ni ẹ fẹ́ kí n sin òkú mi kúrò nílẹ̀, ẹ gbọ́ tèmi, ẹ bá mi bẹ Efroni ọmọ Sohari,
And he spoke with them saying if there with desire your to bury dead my from to before me listen to me and entreat for me Ephron [the] son of Zohar.
9 kí ó ta ihò àpáta Makpela tí ó jẹ́ tirẹ̀ fún mi, èyí tí ó wà ni orí oko rẹ̀, kí ó tà á fún mi ni iye owó tí à ń ta irú rẹ̀ fún ilẹ̀ ìsìnkú láàrín yín.”
So may he give to me [the] cave of Machpelah which [belongs] to him which [is] at [the] end of field his for silver full let him give it to me in midst of you to a possession of a burial site.
10 Efroni ará Hiti sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú, ó sì dá Abrahamu lóhùn lójú gbogbo àwọn ará ìlú tí ó wà níbẹ̀, lẹ́nu ibodè ìlú,
And Ephron [was] sitting in among [the] people of Heth and he answered Ephron the Hethite Abraham in [the] ears of [the] people of Heth to all [those who were] entering [the] gate of city his saying.
11 pé, “Rárá, olúwa mi. Gbọ́ tèmi; mo fún ọ ní ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà níbẹ̀. Mo fún ọ níwájú gbogbo àwọn ènìyàn mi. Sin òkú rẹ síbẹ̀.”
No O lord my listen to me the field I give to you and the cave which [is] in it to you I give it to [the] eyes of [the] sons of people my I give it to you bury dead your.
12 Abrahamu sì tún tẹríba níwájú àwọn ènìyàn ìlú náà,
And he bowed down Abraham before [the] people of the land.
13 ó sì wí fún Efroni lójú gbogbo wọn pé, “Bí ìwọ bá fẹ́, gbọ́ tèmi, èmi yóò san owó ilẹ̀ náà, gbà á lọ́wọ́ mi kí n lè sin òkú mi síbẹ̀.”
And he spoke to Ephron in [the] ears of [the] people of the land saying nevertheless if you if listen to me I give [the] money of the field take [it] from me so let me bury dead my there.
14 Efroni sì dá Abrahamu lóhùn pé,
And he answered Ephron Abraham saying to him.
15 “Gbọ́ tèmi Olúwa mi, irinwó òsùwọ̀n owó fàdákà ni ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n kín ni ìyẹn já mọ láàrín àwa méjèèjì? Sá à sin òkú rẹ.”
O lord my listen to me land of four hundred shekel[s] of silver between me and between you what? [is] it and dead your bury.
16 Abrahamu sì gbọ́ tí Efroni wí, Abrahamu sì wọn iye fàdákà náà fún Efroni, tí ó sọ ní etí àwọn ọmọ Hiti, irinwó òsùwọ̀n ṣékélì fàdákà, tí ó kọjá lọ́dọ̀ àwọn oníṣòwò.
And he listened Abraham to Ephron and he weighed out Abraham for Ephron the money which he had spoken in [the] ears of [the] people of Heth four hundred shekel[s] of silver passing along to the trader.
17 Báyìí ni ilẹ̀ Efroni tí ó wà ni Makpela nítòsí Mamre, ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ àti gbogbo igi tí ó wà nínú ilẹ̀ náà ni a ṣe ètò rẹ̀ dájú,
And it was confirmed - [the] field of Ephron which [was] in Machpelah which [was] before Mamre the field and the cave which [was] in it and every tree which [was] in the field which [was] in all border its round about.
18 bí ohun ìní fún Abrahamu níwájú gbogbo ará Hiti tí ó wá sí ẹnu ibodè ìlú náà.
To Abraham to a possession to [the] eyes of [the] people of Heth for all [those who were] entering [the] gate of city his.
19 Lẹ́yìn náà ni Abrahamu sin aya rẹ̀ Sara sínú ihò àpáta ní ilẹ̀ Makpela nítòsí Mamre (tí í ṣe Hebroni) ní ilẹ̀ Kenaani.
And after thus he buried Abraham Sarah wife his into [the] cave of [the] field of Machpelah on [the] face of Mamre that [is] Hebron in [the] land of Canaan.
20 Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni àwọn ará Hiti fi fún Abrahamu gẹ́gẹ́ bí ohun ìní títí láé, bí ilẹ̀ ìsìnkú fún àwọn òkú tí ó bá kú fun un.
And it was confirmed the field and the cave which [was] in it to Abraham to a possession of a burial site from with [the] people of Heth.