< Genesis 23 >

1 Sara sì pé ọmọ ọdún mẹ́tàdínláàádóje.
And the life of Sarah came to be, a hundred and twenty-seven years, —the years of the life of Sarah.
2 Ó sì kú ní Kiriati-Arba (ìyẹn ní Hebroni) ní ilẹ̀ Kenaani, Abrahamu lọ láti ṣọ̀fọ̀ àti láti sọkún nítorí Sara.
And Sarah died in Kiriath-arba, the same, is Hebron in the land of Canaan, —and Abraham went in to wail for Sarah and to weep for her.
3 Abrahamu sì dìde lẹ́gbẹ̀ẹ́ òkú aya rẹ̀, ó sì sọ fún àwọn ará Hiti wí pé,
And Abraham rose up from over the face of his dead, —and spake unto the sons of Heth, saying;
4 “Èmi jẹ́ àtìpó àti àlejò láàrín yín, ẹ ta ilẹ̀ ìsìnkú fún mi kí èmi le sin òkú tí ó kú fún mi sí.”
A sojourner and settler, am I with you, —Give me a possession of a buryingplace with you, That I may bury my dead, from before me.
5 Àwọn ọmọ Hiti dá Abrahamu lóhùn pé,
And the sons of Heth answered Abraham, saying to him:
6 “Olúwa mi, gbọ́ tiwa, ó jẹ́ alágbára ọmọ-aládé láàrín wa, sin òkú rẹ sí ibojì tí ó dára jù nínú àwọn ibojì wa, kò sí ẹni tí yóò fi ibojì rẹ dù ọ́ láti sin òkú rẹ sí.”
Hear us, my lord! A prince of God, art thou in our midst, In the choice of our buryingplaces, bury thy dead, —Not, a man from among us his, burying-place, will withhold from thee, from burying thy dead.
7 Nígbà náà ni Abrahamu dìde, ó sì tẹríba níwájú àwọn ará ilẹ̀ náà, àwọn ará Hiti.
And Abraham rose up, and bowed himself down to the people of the land, to the sons of Heth;
8 Ó sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá ṣe pé, lóòótọ́ ni ẹ fẹ́ kí n sin òkú mi kúrò nílẹ̀, ẹ gbọ́ tèmi, ẹ bá mi bẹ Efroni ọmọ Sohari,
and spake with them, saying, —If it is with the consent of your minds that I should bury my dead from before me, hear me, and intercede for me, with Ephron son of Zohar:
9 kí ó ta ihò àpáta Makpela tí ó jẹ́ tirẹ̀ fún mi, èyí tí ó wà ni orí oko rẹ̀, kí ó tà á fún mi ni iye owó tí à ń ta irú rẹ̀ fún ilẹ̀ ìsìnkú láàrín yín.”
That he would give me, the cave of Machpelah, which pertaineth unto him, which is within the bounds of his field, —For full silver, let him give it me in your midst, For a possession of a buryingplace.
10 Efroni ará Hiti sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú, ó sì dá Abrahamu lóhùn lójú gbogbo àwọn ará ìlú tí ó wà níbẹ̀, lẹ́nu ibodè ìlú,
Now, Ephron, was sitting in the midst of the sons of Heth, —so Ephron the Hittite responded to Abraham, in the ears of the sons of Heth, even all that were entering the gate of his city, saying:
11 pé, “Rárá, olúwa mi. Gbọ́ tèmi; mo fún ọ ní ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà níbẹ̀. Mo fún ọ níwájú gbogbo àwọn ènìyàn mi. Sin òkú rẹ síbẹ̀.”
Nay, my lord, hear me, The field, have I given to thee And, the cave that is therein, to thee, have I given it, —In the eyes of the sons of my people, have I given it thee Bury thy dead.
12 Abrahamu sì tún tẹríba níwájú àwọn ènìyàn ìlú náà,
So Abraham boweth himself down, before the people of the land:
13 ó sì wí fún Efroni lójú gbogbo wọn pé, “Bí ìwọ bá fẹ́, gbọ́ tèmi, èmi yóò san owó ilẹ̀ náà, gbà á lọ́wọ́ mi kí n lè sin òkú mi síbẹ̀.”
and spake unto Ephron in the ears of the people of the land saying, Only if, thou, wouldst, hear me, —I have given the silver of the field Take it of me, That I may bury my dead here.
14 Efroni sì dá Abrahamu lóhùn pé,
And Ephron responded to Abraham, saying to him,
15 “Gbọ́ tèmi Olúwa mi, irinwó òsùwọ̀n owó fàdákà ni ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n kín ni ìyẹn já mọ láàrín àwa méjèèjì? Sá à sin òkú rẹ.”
My lord, hear me, —Land worth four hundred shekels of silver—betwixt me and thee, what is that? And thy dead., bury thou.
16 Abrahamu sì gbọ́ tí Efroni wí, Abrahamu sì wọn iye fàdákà náà fún Efroni, tí ó sọ ní etí àwọn ọmọ Hiti, irinwó òsùwọ̀n ṣékélì fàdákà, tí ó kọjá lọ́dọ̀ àwọn oníṣòwò.
And Abraham hearkened unto Ephron, and Abraham weighed out to Ephron the silver of which he had spoken in the ears of the sons of Heth, —four hundred shekels of silver, current with the merchant,
17 Báyìí ni ilẹ̀ Efroni tí ó wà ni Makpela nítòsí Mamre, ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ àti gbogbo igi tí ó wà nínú ilẹ̀ náà ni a ṣe ètò rẹ̀ dájú,
So was confirmed the field of Ephron, which is in Machpelah, which is before Mamre, —the field and the cave which is therein, and all the timber which was in the field, which was in all the boundary thereof round about,
18 bí ohun ìní fún Abrahamu níwájú gbogbo ará Hiti tí ó wá sí ẹnu ibodè ìlú náà.
to Abraham as a purchase in the eyes of the sons of Heth, —with all who were entering the gate of his city.
19 Lẹ́yìn náà ni Abrahamu sin aya rẹ̀ Sara sínú ihò àpáta ní ilẹ̀ Makpela nítòsí Mamre (tí í ṣe Hebroni) ní ilẹ̀ Kenaani.
And after this, did Abraham bury Sarah his wife, within the cave of the field of Machpelah, over against Mamre, the same, is Hebron, —in the land of Canaan.
20 Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni àwọn ará Hiti fi fún Abrahamu gẹ́gẹ́ bí ohun ìní títí láé, bí ilẹ̀ ìsìnkú fún àwọn òkú tí ó bá kú fun un.
So was confirmed the field with the cave which was therein to Abraham, for a possession of a buryingplace, —from the sons of Heth.

< Genesis 23 >