< Genesis 23 >

1 Sara sì pé ọmọ ọdún mẹ́tàdínláàádóje.
Sarah kah a hingnah khaw kum ya kum kul kum rhih lo. Sarah kah a hingnah kum tah amah he coeng ni.
2 Ó sì kú ní Kiriati-Arba (ìyẹn ní Hebroni) ní ilẹ̀ Kenaani, Abrahamu lọ láti ṣọ̀fọ̀ àti láti sọkún nítorí Sara.
Sarah te Kanaan kho Hebron kah Kiriatharba ah duek. Te dongah Sarah rhaengsae ham Abraham cet tih a rhah thil.
3 Abrahamu sì dìde lẹ́gbẹ̀ẹ́ òkú aya rẹ̀, ó sì sọ fún àwọn ará Hiti wí pé,
Te phoeiah Abraham te duek kung lamkah thoo tih Kheth ca rhoek te a voek tih,
4 “Èmi jẹ́ àtìpó àti àlejò láàrín yín, ẹ ta ilẹ̀ ìsìnkú fún mi kí èmi le sin òkú tí ó kú fún mi sí.”
“Kai tah nangmih taengah yinlai neh lampah ni, nangmih kah khohut phuel te kai taengah m'pae mai, ka mikhmuh lamkah ka hlang duek ka up thai ham khaw,” a ti nah.
5 Àwọn ọmọ Hiti dá Abrahamu lóhùn pé,
Tedae Kheth ca rhoek loh Abraham a doo uh tih amah taengah,
6 “Olúwa mi, gbọ́ tiwa, ó jẹ́ alágbára ọmọ-aládé láàrín wa, sin òkú rẹ sí ibojì tí ó dára jù nínú àwọn ibojì wa, kò sí ẹni tí yóò fi ibojì rẹ dù ọ́ láti sin òkú rẹ sí.”
“Ka boeipa kaimih ol he hnatun lah. Kaimih khui ah namah ni Pathen khoboei. Kaimih kah phuel saelh khuiah na rhok te up ngawn. Na duek vaengah up ham tah kaimih kah hlang loh a phuel te nang taengah hloh mahpawh,” a ti nauh.
7 Nígbà náà ni Abrahamu dìde, ó sì tẹríba níwájú àwọn ará ilẹ̀ náà, àwọn ará Hiti.
Te dongah Abraham te thoo tih tolrhum kah pilnam hmai neh Kheth ca rhoek hmaiah bakop.
8 Ó sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá ṣe pé, lóòótọ́ ni ẹ fẹ́ kí n sin òkú mi kúrò nílẹ̀, ẹ gbọ́ tèmi, ẹ bá mi bẹ Efroni ọmọ Sohari,
Amih te koep a voek tih, “Ka mikhmuh kah aka duek he up ham nangmih hinglu ah ni a om atah kai ol hnatang uh lamtah kai yueng la Zohar capa Ephron te hloep uh.
9 kí ó ta ihò àpáta Makpela tí ó jẹ́ tirẹ̀ fún mi, èyí tí ó wà ni orí oko rẹ̀, kí ó tà á fún mi ni iye owó tí à ń ta irú rẹ̀ fún ilẹ̀ ìsìnkú láàrín yín.”
Anih kah lohma bawt ah aka om amah hut Makpelah kah lungko te kai taengah m'pae mai saeh. Tangka a ting yet la m'pae saeh lamtah nang lakli ah kamah kah phuel khohut la om saeh,” a ti nah.
10 Efroni ará Hiti sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú, ó sì dá Abrahamu lóhùn lójú gbogbo àwọn ará ìlú tí ó wà níbẹ̀, lẹ́nu ibodè ìlú,
Te vaengah Kheth ca rhoek lakli ah Ephron ngol. Te dongah Khitti hoel Ephron loh khopuei vongka la aka lo Kheth ca rhoek boeih kah a hna ah Abraham te a doo tih,
11 pé, “Rárá, olúwa mi. Gbọ́ tèmi; mo fún ọ ní ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà níbẹ̀. Mo fún ọ níwájú gbogbo àwọn ènìyàn mi. Sin òkú rẹ síbẹ̀.”
“Pawh, ka boeipa, kai ol hnatun lah, khohmuen te nang kan paek coeng dongah a khuikah lungko khaw ka pilnam koca rhoek kah mikhmuh ah nang kan paek vanbangla nang kan paek phuel ah na rhok khaw up,” a ti nah.
12 Abrahamu sì tún tẹríba níwájú àwọn ènìyàn ìlú náà,
Te dongah Abraham te tolrhum pilnam hmai ah bakop tih,
13 ó sì wí fún Efroni lójú gbogbo wọn pé, “Bí ìwọ bá fẹ́, gbọ́ tèmi, èmi yóò san owó ilẹ̀ náà, gbà á lọ́wọ́ mi kí n lè sin òkú mi síbẹ̀.”
tolrhum pilnam kah hna yaak ah Ephron te, “Nang khaw kai ol he hnatun mai. Kai lamkah khohmuen phu tangka kan paek vetih na doe koinih ka rhok khaw pahoi ka up sue,” a ti nah.
14 Efroni sì dá Abrahamu lóhùn pé,
Tedae Ephron loh Abraham te a doo tih amah taengah,
15 “Gbọ́ tèmi Olúwa mi, irinwó òsùwọ̀n owó fàdákà ni ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n kín ni ìyẹn já mọ láàrín àwa méjèèjì? Sá à sin òkú rẹ.”
“Ka boeipa, kai ol hnatun lah. Khohmuen phu tangka shekel ya li te kai neh nang laklo ah bahamnim ca? Tahae ah khaw na rhok te up ngawn,” a ti nah.
16 Abrahamu sì gbọ́ tí Efroni wí, Abrahamu sì wọn iye fàdákà náà fún Efroni, tí ó sọ ní etí àwọn ọmọ Hiti, irinwó òsùwọ̀n ṣékélì fàdákà, tí ó kọjá lọ́dọ̀ àwọn oníṣòwò.
Abraham loh Ephron te a rhoi. Te dongah thimpom taengkah vanbangla tangka shekel ya li te Kheth ca rhoek kah hna yaak ah a tae tih Abraham loh Ephron ham tangka a thuek pah.
17 Báyìí ni ilẹ̀ Efroni tí ó wà ni Makpela nítòsí Mamre, ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ àti gbogbo igi tí ó wà nínú ilẹ̀ náà ni a ṣe ètò rẹ̀ dájú,
Te dongah Mamre khohmuen kaep, Makpelah kah Ephron lo neh a khuikah lungko te khaw, lohma li neh a kaepvai rhi boeih kah thing boeih khaw,
18 bí ohun ìní fún Abrahamu níwájú gbogbo ará Hiti tí ó wá sí ẹnu ibodè ìlú náà.
khopuei vongka la aka lo boeih hmai neh Kheth ca rhoek kah mikhmuh ah Abraham kah kho lai la a saii.
19 Lẹ́yìn náà ni Abrahamu sin aya rẹ̀ Sara sínú ihò àpáta ní ilẹ̀ Makpela nítòsí Mamre (tí í ṣe Hebroni) ní ilẹ̀ Kenaani.
Te phoei daengah Kanaan kho Hebron Mamre kaep, Makpelah lo kah lungko ah a yuu Sarah te Abraham loh a up.
20 Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni àwọn ará Hiti fi fún Abrahamu gẹ́gẹ́ bí ohun ìní títí láé, bí ilẹ̀ ìsìnkú fún àwọn òkú tí ó bá kú fun un.
Te dongah lohma neh a khuikah lungko te Kheth ca rhoek taeng lamkah Abraham phuel khohut la a hlaih.

< Genesis 23 >