< Genesis 22 >

1 Nígbà tí ó ṣe, Ọlọ́run dán Abrahamu wò, ó pè é, ó sì wí pé, “Abrahamu.” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Şi s-a întâmplat după aceste lucruri, că Dumnezeu l-a încercat pe Avraam şi i-a spus: Avraam; iar el a spus: Iată-mă.
2 Ọlọ́run sì wí pé, “Mú ọmọ rẹ, àní Isaaki ọmọ rẹ kan ṣoṣo nì, tí ìwọ fẹ́ràn, lọ sí ilẹ̀ Moria, kí o sì fi rú ẹbọ sísun níbẹ̀ lórí ọ̀kan nínú àwọn òkè tí èmi yóò sọ fún ọ.”
Iar el a spus: Ia acum pe fiul tău, pe singurul tău fiu, Isaac, pe care îl iubeşti, şi du-te în ţinutul Moria; şi adu-l acolo ca o ofrandă arsă pe unul din munţii pe care ţi-l voi spune.
3 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì mú méjì nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì ṣẹ́ igi fún ẹbọ sísun, ó sì gbéra lọ sí ibi tí Ọlọ́run ti sọ fún un.
Şi Avraam s-a sculat devreme dimineaţa şi a înşeuat măgarul său şi a luat doi dintre tinerii săi cu el şi pe Isaac, fiul său, şi a despicat lemnele pentru ofranda arsă şi s-a ridicat şi a mers la locul despre care Dumnezeu îi spusese.
4 Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹta, Abrahamu gbé ojú sókè, ó sì rí ibi tí ó ń lọ ní òkèrè,
Apoi în a treia zi Avraam şi-a ridicat ochii şi a văzut locul de departe.
5 Abrahamu sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin, ẹ dúró níhìn-ín pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, èmi àti ọmọ yìí yóò lọ sí ohunkóhun láti sin Ọlọ́run, a ó sì tún padà wá bá a yín.”
Şi Avraam a spus tinerilor săi: Staţi aici cu măgarul; şi eu şi băiatul vom merge acolo şi ne vom închina şi ne vom întoarce la voi.
6 Abrahamu sì gbé igi ẹbọ sísun náà ru Isaaki, òun fúnra rẹ̀ sì mú iná àti ọ̀bẹ. Bí àwọn méjèèjì ti ń lọ,
Şi Avraam a luat lemnele ofrandei arse şi l-a pus pe Isaac, fiul său; şi a luat focul în mâna sa şi un cuţit; şi au mers amândoi împreună.
7 Isaaki sì sọ fún Abrahamu baba rẹ̀ wí pé, “Baba mi.” Abrahamu sì dalóhùn pé, “Èmi nìyí ọmọ mi.” Isaaki sì tún wí pé, “Wò ó iná àti igi nìyí, ṣùgbọ́n níbo ni ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà wà?”
Şi Isaac i-a vorbit tatălui său, Avraam, şi a zis: Tată; iar el a spus: Iată-mă, fiul meu. Iar el a spus: Iată, focul şi lemnele, dar unde este mielul pentru ofranda arsă?
8 Abrahamu sì dáhùn pé, “Ọmọ mi, Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni yóò pèsè ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì jùmọ̀ ń lọ.
Şi Avraam a spus: Fiul meu, Dumnezeu însuşi se va îngriji de mielul pentru ofranda arsă; astfel au mers amândoi împreună.
9 Nígbà tí wọn sì dé ibi tí Ọlọ́run sọ fún Abrahamu, ó mọ pẹpẹ kan, ó sì to igi lé e lórí, ó sì di Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì da dùbúlẹ̀ lórí pẹpẹ náà.
Şi au ajuns la locul despre care Dumnezeu îi spusese; şi Avraam a zidit un altar acolo şi a pus lemnele în ordine şi a legat pe Isaac, fiul său, şi l-a pus pe altar deasupra lemnelor.
10 Abrahamu sì nawọ́ mú ọ̀bẹ, láti dúńbú ọmọ rẹ̀.
Şi Avraam şi-a întins mâna şi a luat cuţitul să înjunghie pe fiul său.
11 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa ké sí i láti ọ̀run wá wí pé “Abrahamu! Abrahamu!” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Şi îngerul DOMNULUI a strigat către el din cer şi a spus: Avraame, Avraame; iar el a spus: Iată-mă.
12 Angẹli Olúwa sì wí pé, “Má ṣe fọwọ́ kan ọmọ náà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣe é ni ohun kan. Nísinsin yìí ni mo mọ̀ pé o bẹ̀rù Ọlọ́run, nítorí pé ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí.”
Şi a spus: Nu pune mâna pe băiat, nici nu îi face nimic, pentru că acum ştiu că te temi de Dumnezeu, văzând că nu ai cruţat pe fiul tău, singurul tău fiu, pentru mine.
13 Abrahamu sì gbójú sókè, ó sì rí àgbò kan tí ó fi ìwo há pàǹtírí, ó sì lọ mú un, ó sì fi rú ẹbọ sísun dípò ọmọ rẹ̀.
Şi Avraam şi-a ridicat ochii şi a privit şi, iată, în spatele lui un berbec prins cu coarnele într-un desiş; şi Avraam a mers şi a luat berbecul şi l-a adus ca o ofrandă arsă în locul fiului său.
14 Abrahamu sì pe orúkọ ibẹ̀ ni, Jehofah Jire. Bẹ́ẹ̀ ni a sì ń wí títí di òní olónìí pé, “Ní orí òkè Olúwa, ni a ó ti pèsè.”
Şi Avraam a pus numele acelui loc, Iehova-Iire, aşa cum este spus până în ziua de azi: În muntele DOMNULUI îngrijirea se va vedea.
15 Angẹli Olúwa sì tún pe Abrahamu láti ọ̀run wá lẹ́ẹ̀kejì.
Şi îngerul DOMNULUI a strigat din cer către Avraam a doua oară,
16 Ó sì wí pé, Olúwa wí pé, “Mo fi ara mi búra, níwọ̀n bí ìwọ ti ṣe èyí, tí ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí,
Şi a spus: Pe mine însumi am jurat, spune DOMNUL, pentru că ai făcut acest lucru şi nu ai cruţat pe fiul tău, pe singurul tău fiu;
17 nítòótọ́, ní bíbùkún èmi ó bùkún fún ọ, àti ní bíbísí èmi ó sì mú ọ bí sí i bí i ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti bí iyanrìn etí Òkun. Irú-ọmọ rẹ yóò sì gba ẹnu ibodè àwọn ọ̀tá wọn,
De aceea binecuvântând te voi binecuvânta şi înmulţind voi înmulţi sămânţa ta ca stelele cerului şi ca nisipul de pe ţărmul mării; şi sămânţa ta va stăpâni poarta duşmanilor săi.
18 àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó ti bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nítorí tí ìwọ gbọ́rọ̀ sí mi lẹ́nu.”
Şi în sămânţa ta toate naţiunile pământului vor fi binecuvântate, pentru că ai ascultat de vocea mea.
19 Nígbà náà ni Abrahamu padà tọ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ. Gbogbo wọn sì padà lọ sí Beerṣeba. Abrahamu sì jókòó ní Beerṣeba.
Aşa că Avraam s-a întors la tinerii săi şi s-au sculat şi au mers împreună la Beer-Şeba; şi Avraam a locuit la Beer-Şeba.
20 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni a wí fún Abrahamu pé, “Milka aya Nahori bí àwọn ọmọkùnrin fún un.
Şi s-a întâmplat, după aceste lucruri, că i s-a spus lui Avraam, zicând: Iată, Milca a născut şi ea copii fratelui tău, Nahor;
21 Usi àkọ́bí rẹ̀, Busi arákùnrin rẹ̀, Kemueli (baba Aramu).
Uţ, primul său născut, şi Buz, fratele său, şi Chemuel, tatăl lui Aram,
22 Kesedi, Haso, Pildasi, Jidlafi, àti Betueli.”
Şi Chesed şi Hazo şi Pildaş şi Iidlaf şi Betuel.
23 Betueli sì ni baba Rebeka. Milka sì bí àwọn ọmọ mẹ́jọ wọ̀nyí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
Şi Betuel a născut pe Rebeca; pe aceştia opt Milca i-a născut lui Nahor, fratele lui Avraam.
24 Àlè rẹ̀ tí ń jẹ́ Reuma náà bí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí fun un: Teba, Gahamu, Tahasi àti Maaka.
Şi concubina sa, al cărei nume era Reuma, a născut de asemenea pe Tebah şi pe Gaham şi pe Tahaş şi pe Maaca.

< Genesis 22 >