< Genesis 22 >

1 Nígbà tí ó ṣe, Ọlọ́run dán Abrahamu wò, ó pè é, ó sì wí pé, “Abrahamu.” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
In kutu pacl tok, God El srikal Abraham. El pangnol, “Abraham!” Ac Abraham el topuk, “Nga inge.”
2 Ọlọ́run sì wí pé, “Mú ọmọ rẹ, àní Isaaki ọmọ rẹ kan ṣoṣo nì, tí ìwọ fẹ́ràn, lọ sí ilẹ̀ Moria, kí o sì fi rú ẹbọ sísun níbẹ̀ lórí ọ̀kan nínú àwọn òkè tí èmi yóò sọ fún ọ.”
God El fahk, “Eisal Isaac, wen sefanna nutum su kom arulana kuloi, ac som nwe in facl Moriah. Ke kom ac sun acn we, na kom fah kisakunulma in mwe kisa firir nu sik fin soko eol su nga ac akkalemye nu sum.”
3 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì mú méjì nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì ṣẹ́ igi fún ẹbọ sísun, ó sì gbéra lọ sí ibi tí Ọlọ́run ti sọ fún un.
Toangna in lotu tok ah, Abraham el telak etong mwe orek kisa, ac sang nu fin donkey natul ah. Na el eisal Isaac ac mwet kulansap luo welul, ac elos som nu yen se ma God El fahk mu elan som nu we ah.
4 Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹta, Abrahamu gbé ojú sókè, ó sì rí ibi tí ó ń lọ ní òkèrè,
Ke len se aktolu ah, Abraham el liyauk acn sac, ohkokme emeeto.
5 Abrahamu sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin, ẹ dúró níhìn-ín pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, èmi àti ọmọ yìí yóò lọ sí ohunkóhun láti sin Ọlọ́run, a ó sì tún padà wá bá a yín.”
Na el fahk nu sin mwet kulansap luo ah, “Muta inse wi donkey uh. Nga, ac tulik se nutik inge, ac som nu meet ah in alu, ac kut ac fah foloko.”
6 Abrahamu sì gbé igi ẹbọ sísun náà ru Isaaki, òun fúnra rẹ̀ sì mú iná àti ọ̀bẹ. Bí àwọn méjèèjì ti ń lọ,
Abraham el sang Isaac elan us etong nu ke kisa uh, ac el us mitmit se ac mulut firir mwe tanak e uh. Ac ke eltal tukeni fahsr,
7 Isaaki sì sọ fún Abrahamu baba rẹ̀ wí pé, “Baba mi.” Abrahamu sì dalóhùn pé, “Èmi nìyí ọmọ mi.” Isaaki sì tún wí pé, “Wò ó iná àti igi nìyí, ṣùgbọ́n níbo ni ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà wà?”
Isaac el kasla ac fahk, “Papa!” Ac el topuk, “Mea?” Isaac el siyuk, “Efu ku oasr etong ac mulut kut us, a pia sheep fusr mwe kisa an?”
8 Abrahamu sì dáhùn pé, “Ọmọ mi, Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni yóò pèsè ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì jùmọ̀ ń lọ.
Ac Abraham el fahk, “God El ac fah ase.” Na eltal tukenina fahsr.
9 Nígbà tí wọn sì dé ibi tí Ọlọ́run sọ fún Abrahamu, ó mọ pẹpẹ kan, ó sì to igi lé e lórí, ó sì di Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì da dùbúlẹ̀ lórí pẹpẹ náà.
Ke eltal tuku nu ke acn se ma God El fahk nu sel kac, Abraham el etoak loang se ac takunla etong ah fac. El kapriya wen se natul ah, ac likilya fin etong ma oan fin loang ah.
10 Abrahamu sì nawọ́ mú ọ̀bẹ, láti dúńbú ọmọ rẹ̀.
Na el srukak mitmit sac in unilya.
11 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa ké sí i láti ọ̀run wá wí pé “Abrahamu! Abrahamu!” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Tusruktu lipufan lun LEUM GOD el pang nu sel inkusrao me, “Abraham, Abraham!” Ac el topuk, “Nga pa inge.”
12 Angẹli Olúwa sì wí pé, “Má ṣe fọwọ́ kan ọmọ náà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣe é ni ohun kan. Nísinsin yìí ni mo mọ̀ pé o bẹ̀rù Ọlọ́run, nítorí pé ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí.”
Na lipufan sac fahk, “Nimet kom kahlya tulik sacn ku oru kutena ma nu sel. Inge nga etu lah kom akfulatye God ac akos ma El sapkin, mweyen kom tia sruokya wen sefanna nutum an lukel.”
13 Abrahamu sì gbójú sókè, ó sì rí àgbò kan tí ó fi ìwo há pàǹtírí, ó sì lọ mú un, ó sì fi rú ẹbọ sísun dípò ọmọ rẹ̀.
Abraham el ngetnget nwe liyauk sheep mukul soko, sremla koacl ke sripin sak se. El som sruokya ac kisakin tuh in sie mwe kisa firir in aolla wen natul.
14 Abrahamu sì pe orúkọ ibẹ̀ ni, Jehofah Jire. Bẹ́ẹ̀ ni a sì ń wí títí di òní olónìí pé, “Ní orí òkè Olúwa, ni a ó ti pèsè.”
Abraham el sang inen acn sac, “LEUM GOD El Ase.” Fahsru nwe misenge, mwet uh srakna fahk ouinge, “Fineol sin LEUM GOD, El fah ase.”
15 Angẹli Olúwa sì tún pe Abrahamu láti ọ̀run wá lẹ́ẹ̀kejì.
Lipufan lun LEUM GOD el pang nu sel Abraham inkusrao me pacl se akluo
16 Ó sì wí pé, Olúwa wí pé, “Mo fi ara mi búra, níwọ̀n bí ìwọ ti ṣe èyí, tí ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí,
ac fahk, “LEUM GOD El fahk ouinge: ‘Nga orala sie wuleang ke Inek sifacna lah nga fah arulana akinsewowoye kom. Ke sripen kom tuh oru ma se inge, ac tia seko wen sefanna nutum,
17 nítòótọ́, ní bíbùkún èmi ó bùkún fún ọ, àti ní bíbísí èmi ó sì mú ọ bí sí i bí i ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti bí iyanrìn etí Òkun. Irú-ọmọ rẹ yóò sì gba ẹnu ibodè àwọn ọ̀tá wọn,
nga wuleot nu sum lah nga ac fah akpusye fita nutum in pukanten oana itu inkusrao ku puk wekof uh. Fwilin tulik nutum ac fah kutangla mwet lokoalok lalos.
18 àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó ti bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nítorí tí ìwọ gbọ́rọ̀ sí mi lẹ́nu.”
Mutanfahl nukewa ac fah siyuk sik in akinsewowoyalos oana ke nga akinsewowoye fita lom. Ma inge nukewa ma na ke sripen kom tuh akos ma nga sapkin.’”
19 Nígbà náà ni Abrahamu padà tọ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ. Gbogbo wọn sì padà lọ sí Beerṣeba. Abrahamu sì jókòó ní Beerṣeba.
Abraham el folokla nu yurin mwet kulansap lal, ac elos tukeni som nu Beersheba, yen Abraham el muta we.
20 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni a wí fún Abrahamu pé, “Milka aya Nahori bí àwọn ọmọkùnrin fún un.
In kutu pacl tok, Abraham el lohngak lah Milcah el oswela tulik oalkosr nu sel Nahor, tamulel lal Abraham:
21 Usi àkọ́bí rẹ̀, Busi arákùnrin rẹ̀, Kemueli (baba Aramu).
Uz wounse, Buz tamulel lal, Kemuel papa tumal Aram,
22 Kesedi, Haso, Pildasi, Jidlafi, àti Betueli.”
Chesed, Hazo, Pildash, Jidlaph, ac Bethuel
23 Betueli sì ni baba Rebeka. Milka sì bí àwọn ọmọ mẹ́jọ wọ̀nyí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
papa tumal Rebecca. Milcah el oswela wen oalkosr inge nu sel Nahor, tamulel lal Abraham.
24 Àlè rẹ̀ tí ń jẹ́ Reuma náà bí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí fun un: Teba, Gahamu, Tahasi àti Maaka.
Reumah, mutan kulansap kial Nahor, el oswella Tebah, Gaham, Tahash, ac Maacah.

< Genesis 22 >