< Genesis 22 >
1 Nígbà tí ó ṣe, Ọlọ́run dán Abrahamu wò, ó pè é, ó sì wí pé, “Abrahamu.” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
És lőn ezeknek utána, az Isten megkisérté Ábrahámot, és monda néki: Ábrahám! S az felele: Ímhol vagyok.
2 Ọlọ́run sì wí pé, “Mú ọmọ rẹ, àní Isaaki ọmọ rẹ kan ṣoṣo nì, tí ìwọ fẹ́ràn, lọ sí ilẹ̀ Moria, kí o sì fi rú ẹbọ sísun níbẹ̀ lórí ọ̀kan nínú àwọn òkè tí èmi yóò sọ fún ọ.”
És monda: Vedd a te fiadat, ama te egyetlenegyedet, a kit szeretsz, Izsákot, és menj el Mórijának földére, és áldozd meg ott égő áldozatul a hegyek közűl egyen, a melyet mondándok néked.
3 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì mú méjì nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì ṣẹ́ igi fún ẹbọ sísun, ó sì gbéra lọ sí ibi tí Ọlọ́run ti sọ fún un.
Felkele azért Ábrahám jó reggel, és megnyergelé az ő szamarát, és maga mellé vevé két szolgáját, és az ő fiát Izsákot, és fát hasogatott az égő áldozathoz. Akkor felkele és elindula a helyre, melyet néki az Isten mondott vala.
4 Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹta, Abrahamu gbé ojú sókè, ó sì rí ibi tí ó ń lọ ní òkèrè,
Harmadnapon felemelé az ő szemeit Ábrahám, és látá a helyet messziről.
5 Abrahamu sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin, ẹ dúró níhìn-ín pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, èmi àti ọmọ yìí yóò lọ sí ohunkóhun láti sin Ọlọ́run, a ó sì tún padà wá bá a yín.”
És monda Ábrahám az ő szolgáinak: Maradjatok itt a szamárral, én pedig és ez a gyermek elmegyünk amoda és imádkozunk, azután visszatérünk hozzátok.
6 Abrahamu sì gbé igi ẹbọ sísun náà ru Isaaki, òun fúnra rẹ̀ sì mú iná àti ọ̀bẹ. Bí àwọn méjèèjì ti ń lọ,
Vevé azért Ábrahám az égő áldozathoz való fákat, és feltevé az ő fiára Izsákra, ő maga pedig kezébe vevé a tüzet, és a kést, és mennek vala ketten együtt.
7 Isaaki sì sọ fún Abrahamu baba rẹ̀ wí pé, “Baba mi.” Abrahamu sì dalóhùn pé, “Èmi nìyí ọmọ mi.” Isaaki sì tún wí pé, “Wò ó iná àti igi nìyí, ṣùgbọ́n níbo ni ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà wà?”
És szóla Izsák Ábrahámhoz az ő atyjához, és monda: Atyám! Az pedig monda: Ímhol vagyok, fiam. És monda Izsák: Ímhol van a tűz és a fa; de hol van az égő áldozatra való bárány?
8 Abrahamu sì dáhùn pé, “Ọmọ mi, Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni yóò pèsè ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì jùmọ̀ ń lọ.
És monda Ábrahám: Az Isten majd gondoskodik az égő áldozatra való bárányról, fiam; és mennek vala ketten együtt.
9 Nígbà tí wọn sì dé ibi tí Ọlọ́run sọ fún Abrahamu, ó mọ pẹpẹ kan, ó sì to igi lé e lórí, ó sì di Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì da dùbúlẹ̀ lórí pẹpẹ náà.
Hogy pedig eljutának arra a helyre, melyet Isten néki mondott vala, megépíté ott Ábrahám az oltárt, és reá raká a fát, és megkötözé Izsákot az ő fiát, és feltevé az oltárra, a fa-rakás tetejére.
10 Abrahamu sì nawọ́ mú ọ̀bẹ, láti dúńbú ọmọ rẹ̀.
És kinyújtá Ábrahám az ő kezét és vevé a kést, hogy levágja az ő fiát.
11 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa ké sí i láti ọ̀run wá wí pé “Abrahamu! Abrahamu!” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Akkor kiálta néki az Úrnak Angyala az égből, és monda: Ábrahám! Ábrahám! Ő pedig felele: Ímhol vagyok.
12 Angẹli Olúwa sì wí pé, “Má ṣe fọwọ́ kan ọmọ náà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣe é ni ohun kan. Nísinsin yìí ni mo mọ̀ pé o bẹ̀rù Ọlọ́run, nítorí pé ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí.”
És monda: Ne nyujtsd ki a te kezedet a gyermekre, és ne bántsd őt: mert most már tudom, hogy istenfélő vagy, és nem kedvezél a te fiadnak, a te egyetlenegyednek én érettem.
13 Abrahamu sì gbójú sókè, ó sì rí àgbò kan tí ó fi ìwo há pàǹtírí, ó sì lọ mú un, ó sì fi rú ẹbọ sísun dípò ọmọ rẹ̀.
És felemelé Ábrahám az ő szemeit, és látá hogy ímé háta megett egy kos akadt meg szarvánál fogva a szövevényben. Oda méne tehát Ábrahám, és elhozá a kost, és azt áldozá meg égő áldozatul az ő fia helyett.
14 Abrahamu sì pe orúkọ ibẹ̀ ni, Jehofah Jire. Bẹ́ẹ̀ ni a sì ń wí títí di òní olónìí pé, “Ní orí òkè Olúwa, ni a ó ti pèsè.”
És nevezé Ábrahám annak a helynek nevét Jehova-jire-nek. Azért mondják ma is: Az Úr hegyén a gondviselés.
15 Angẹli Olúwa sì tún pe Abrahamu láti ọ̀run wá lẹ́ẹ̀kejì.
És kiálta az Úrnak Angyala Ábrahámnak másodszor is az égből.
16 Ó sì wí pé, Olúwa wí pé, “Mo fi ara mi búra, níwọ̀n bí ìwọ ti ṣe èyí, tí ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí,
És monda: Én magamra esküszöm azt mondja az Úr: mivelhogy e dolgot cselekedéd, és nem kedvezél a te fiadnak, a te egyetlenegyednek:
17 nítòótọ́, ní bíbùkún èmi ó bùkún fún ọ, àti ní bíbísí èmi ó sì mú ọ bí sí i bí i ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti bí iyanrìn etí Òkun. Irú-ọmọ rẹ yóò sì gba ẹnu ibodè àwọn ọ̀tá wọn,
Hogy megáldván megáldalak tégedet, és bőségesen megsokasítom a te magodat mint az ég csillagait, és mint a fövényt, mely a tenger partján van, és a te magod örökség szerint fogja bírni az ő ellenségeinek kapuját.
18 àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó ti bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nítorí tí ìwọ gbọ́rọ̀ sí mi lẹ́nu.”
És megáldatnak a te magodban a földnek minden nemzetségei, mivelhogy engedtél az én beszédemnek.
19 Nígbà náà ni Abrahamu padà tọ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ. Gbogbo wọn sì padà lọ sí Beerṣeba. Abrahamu sì jókòó ní Beerṣeba.
Megtére azért Ábrahám az ő szolgáihoz, és felkelének és együtt elmenének Beérsebába, mert lakozék Ábrahám Beérsebában.
20 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni a wí fún Abrahamu pé, “Milka aya Nahori bí àwọn ọmọkùnrin fún un.
És lőn ezeknek utánna, hírt hozának Ábrahámnak mondván: Ímé Milkha is szűlt fiakat Nákhornak, a te atyádfiának:
21 Usi àkọ́bí rẹ̀, Busi arákùnrin rẹ̀, Kemueli (baba Aramu).
Úzt az ő elsőszülöttét, és Búzt annak testvérét, és Kemuélt Arámnak atyját.
22 Kesedi, Haso, Pildasi, Jidlafi, àti Betueli.”
És Keszedet, Házót, Pildást, Jidláfot és Bethuélt.
23 Betueli sì ni baba Rebeka. Milka sì bí àwọn ọmọ mẹ́jọ wọ̀nyí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
Bethuél pedig nemzé Rebekát. Ezt a nyolczat szűlé Milkha Nákhornak az Ábrahám atyjafiának.
24 Àlè rẹ̀ tí ń jẹ́ Reuma náà bí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí fun un: Teba, Gahamu, Tahasi àti Maaka.
Az ő ágyasa is, kinek neve Reuma vala, szűlé néki Tebáhot, Gakhámot, Thakhást és Mahákhát.