< Genesis 22 >
1 Nígbà tí ó ṣe, Ọlọ́run dán Abrahamu wò, ó pè é, ó sì wí pé, “Abrahamu.” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Thuutha wa maũndũ macio-rĩ, Ngai nĩageririe Iburahĩmu. Ngai akĩmwĩta atĩrĩ, “Iburahĩmu!” Nake agĩcookia atĩrĩ, “Niĩ ũyũ haha.”
2 Ọlọ́run sì wí pé, “Mú ọmọ rẹ, àní Isaaki ọmọ rẹ kan ṣoṣo nì, tí ìwọ fẹ́ràn, lọ sí ilẹ̀ Moria, kí o sì fi rú ẹbọ sísun níbẹ̀ lórí ọ̀kan nínú àwọn òkè tí èmi yóò sọ fún ọ.”
Nake Ngai akĩmwĩra atĩrĩ, “Oya mũriũ waku, o we ũrĩa wa mũmwe Isaaka, ũrĩa wendete, ũthiĩ rũgongo rwa Moria, na ũmũrute ta igongona rĩa njino kuo kĩrĩma-inĩ kĩmwe kĩa iria ngaakuonia.”
3 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì mú méjì nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì ṣẹ́ igi fún ẹbọ sísun, ó sì gbéra lọ sí ibi tí Ọlọ́run ti sọ fún un.
Nĩ ũndũ ũcio mũthenya ũyũ ũngĩ rũciinĩ tene, Iburahĩmu agĩũkĩra, agĩtandĩka ndigiri yake. Akĩoya ndungata ciake igĩrĩ na mũriũ wake Isaaka. Aarĩkia gwatũra ngũ cia kũigana igongona rĩa njino-rĩ, akiumagara erekeire handũ harĩa Ngai aamwĩrĩte.
4 Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹta, Abrahamu gbé ojú sókè, ó sì rí ibi tí ó ń lọ ní òkèrè,
Mũthenya wa gatatũ, Iburahĩmu agĩtiira maitho na akĩona handũ hau harĩ o kũraya.
5 Abrahamu sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin, ẹ dúró níhìn-ín pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, èmi àti ọmọ yìí yóò lọ sí ohunkóhun láti sin Ọlọ́run, a ó sì tún padà wá bá a yín.”
Akĩĩra ndungata ciake atĩrĩ, “Ikaragai haha na ndigiri ĩno, na niĩ na kĩmwana gĩakwa tũthiĩ haarĩa tũkahooe Ngai, na tũcooke tũmũcookerere.”
6 Abrahamu sì gbé igi ẹbọ sísun náà ru Isaaki, òun fúnra rẹ̀ sì mú iná àti ọ̀bẹ. Bí àwọn méjèèjì ti ń lọ,
Iburahĩmu agĩkĩoya ngũ icio cia igongona rĩa njino, agĩciigĩrĩra mũriũ wake Isaaka, nake agĩkuua mwaki na kahiũ. Na rĩrĩa o eerĩ mathiiaga hamwe,
7 Isaaki sì sọ fún Abrahamu baba rẹ̀ wí pé, “Baba mi.” Abrahamu sì dalóhùn pé, “Èmi nìyí ọmọ mi.” Isaaki sì tún wí pé, “Wò ó iná àti igi nìyí, ṣùgbọ́n níbo ni ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà wà?”
Isaaka akĩaria, agĩĩta ithe Iburahĩmu atĩrĩ, “Baba!” Iburahĩmu akĩmũcookeria atĩrĩ, “Niĩ ũyũ, mũrũ wakwa.” Isaaka akiuga atĩrĩ, “Ndĩrona tũrĩ na mwaki na ngũ! No rĩrĩ, gatũrũme ka igongona rĩa njino karĩ ha?”
8 Abrahamu sì dáhùn pé, “Ọmọ mi, Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni yóò pèsè ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì jùmọ̀ ń lọ.
Iburahĩmu agĩcookia atĩrĩ, “Mũrũ wakwa, Ngai we mwene nĩekũheana gatũrũme ka igongona rĩa njino.” Nao eerĩ magĩthiĩ na mbere marĩ hamwe.
9 Nígbà tí wọn sì dé ibi tí Ọlọ́run sọ fún Abrahamu, ó mọ pẹpẹ kan, ó sì to igi lé e lórí, ó sì di Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì da dùbúlẹ̀ lórí pẹpẹ náà.
Maakinya handũ harĩa Ngai aamwĩrĩte-rĩ, Iburahĩmu agĩaka kĩgongona ho na akĩara ngũ igũrũ rĩakĩo. Agĩcooka akĩoha mũriũ wake Isaaka na akĩmũkomia kĩgongona-inĩ kĩu igũrũ rĩa ngũ.
10 Abrahamu sì nawọ́ mú ọ̀bẹ, láti dúńbú ọmọ rẹ̀.
Ningĩ akĩoya kahiũ, agĩtambũrũkia guoko gwake, oorage mũriũ.
11 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa ké sí i láti ọ̀run wá wí pé “Abrahamu! Abrahamu!” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
No mũraika wa Jehova akĩmwĩta kuuma igũrũ, akiuga atĩrĩ, “Iburahĩmu! Iburahĩmu!” Nake Iburahĩmu agĩcookia atĩrĩ, “Niĩ ũyũ haha.”
12 Angẹli Olúwa sì wí pé, “Má ṣe fọwọ́ kan ọmọ náà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣe é ni ohun kan. Nísinsin yìí ni mo mọ̀ pé o bẹ̀rù Ọlọ́run, nítorí pé ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí.”
Akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndũkahutie kĩmwana kĩu na guoko gwaku, na ndũgagĩĩke ũndũ o na ũrĩkũ. Rĩu nĩndamenya atĩ nĩwĩtigĩrĩte Ngai, tondũ ndũnarega kũruta mũrũguo, o we mũrũguo waku wa mũmwe, arĩ igongona.”
13 Abrahamu sì gbójú sókè, ó sì rí àgbò kan tí ó fi ìwo há pàǹtírí, ó sì lọ mú un, ó sì fi rú ẹbọ sísun dípò ọmọ rẹ̀.
Nake Iburahĩmu agĩtiira maitho, na hau kĩhinga-inĩ akĩona ndũrũme ĩnyiitĩtwo hĩa nĩ mĩrita. Agĩthiĩ ho, akĩoya ndũrũme ĩyo na akĩmĩruta ĩrĩ igongona rĩa njino handũ ha mũriũ.
14 Abrahamu sì pe orúkọ ibẹ̀ ni, Jehofah Jire. Bẹ́ẹ̀ ni a sì ń wí títí di òní olónìí pé, “Ní orí òkè Olúwa, ni a ó ti pèsè.”
Nĩ ũndũ ũcio Iburahĩmu agĩĩta handũ hau Jehova-Nĩarĩheanaga. Na nginya ũmũthĩ kuugagwo atĩrĩ, “Kĩrĩma-inĩ kĩa Jehova-rĩ, nĩarĩtũheaga.”
15 Angẹli Olúwa sì tún pe Abrahamu láti ọ̀run wá lẹ́ẹ̀kejì.
Nake mũraika wa Jehova arĩ igũrũ, agĩĩta Iburahĩmu hĩndĩ ya keerĩ,
16 Ó sì wí pé, Olúwa wí pé, “Mo fi ara mi búra, níwọ̀n bí ìwọ ti ṣe èyí, tí ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí,
akĩmwĩra atĩrĩ, “Jehova ekuuga ũũ: Nĩndĩhĩtĩte na niĩ mwene, atĩ tondũ nĩwĩkĩte ũndũ ũyũ na ndũnarega kũndutĩra mũrũguo, o mũrũguo waku wa mũmwe-rĩ,
17 nítòótọ́, ní bíbùkún èmi ó bùkún fún ọ, àti ní bíbísí èmi ó sì mú ọ bí sí i bí i ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti bí iyanrìn etí Òkun. Irú-ọmọ rẹ yóò sì gba ẹnu ibodè àwọn ọ̀tá wọn,
ti-itherũ nĩngakũrathima na ndũme njiaro ciaku cingĩhe ta njata cia matu-inĩ na ta mũthanga ũrĩa ũrĩ hũgũrũrũ-inĩ cia iria. Njiaro ciaku nĩ ikegwatĩra matũũra marĩa manene ma thũ ciacio,
18 àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó ti bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nítorí tí ìwọ gbọ́rọ̀ sí mi lẹ́nu.”
na nĩ ũndũ wa rũciaro rwaku, ndũrĩrĩ ciothe cia thĩ nĩikarathimwo, tondũ wee nĩũnjathĩkĩire.”
19 Nígbà náà ni Abrahamu padà tọ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ. Gbogbo wọn sì padà lọ sí Beerṣeba. Abrahamu sì jókòó ní Beerṣeba.
Nake Iburahĩmu agĩcookerera ndungata ciake, magĩthiĩ hamwe marorete Birishiba. Nake Iburahĩmu agĩtũũra kũu Birishiba.
20 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni a wí fún Abrahamu pé, “Milka aya Nahori bí àwọn ọmọkùnrin fún un.
Thuutha wa maũndũ macio Iburahĩmu agĩkinyĩrwo nĩ ũhoro, akĩĩrwo atĩrĩ, “Milika o nake nĩagĩĩte na ciana; nĩaciarĩire mũrũ-wa-nyũkwa Nahoru ciana:
21 Usi àkọ́bí rẹ̀, Busi arákùnrin rẹ̀, Kemueli (baba Aramu).
Uzu nĩwe wa irigithathi, na mũrũ wa nyina nĩ Buzu, na Kemueli (ithe wa Aramu),
22 Kesedi, Haso, Pildasi, Jidlafi, àti Betueli.”
na Kesedu, na Hazo, na Pilidashu, na Jidilafu, na Bethueli.”
23 Betueli sì ni baba Rebeka. Milka sì bí àwọn ọmọ mẹ́jọ wọ̀nyí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
Bethueli nĩwe watuĩkire ithe wa Rebeka. Acio nĩo ariũ arĩa anana Milika aaciarĩire Nahoru, mũrũ wa nyina na Iburahĩmu.
24 Àlè rẹ̀ tí ń jẹ́ Reuma náà bí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí fun un: Teba, Gahamu, Tahasi àti Maaka.
Thuriya yake, ĩrĩa yetagwo Reuma, o nayo yarĩ na ariũ ake, nĩo Teba, na Gahamu, na Tahashu na Maaka.