< Genesis 22 >

1 Nígbà tí ó ṣe, Ọlọ́run dán Abrahamu wò, ó pè é, ó sì wí pé, “Abrahamu.” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
And aftir that these thingis weren don, God assaiede Abraham, and seide to hym, Abraham! Abraham! He answerde, Y am present.
2 Ọlọ́run sì wí pé, “Mú ọmọ rẹ, àní Isaaki ọmọ rẹ kan ṣoṣo nì, tí ìwọ fẹ́ràn, lọ sí ilẹ̀ Moria, kí o sì fi rú ẹbọ sísun níbẹ̀ lórí ọ̀kan nínú àwọn òkè tí èmi yóò sọ fún ọ.”
God seide to him, Take thi `sone oon gendrid, whom thou louest, Ysaac; and go into the lond of visioun, and offre thou hym there in to brent sacrifice, on oon of the hillis whiche Y schal schewe to thee.
3 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì mú méjì nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì ṣẹ́ igi fún ẹbọ sísun, ó sì gbéra lọ sí ibi tí Ọlọ́run ti sọ fún un.
Therfor Abraham roos bi niyt, and sadlide his asse, and ledde with hym twey yonge men, and Ysaac his sone; and whanne he hadde hewe trees in to brent sacrifice, he yede to the place which God hadde comaundid to him.
4 Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹta, Abrahamu gbé ojú sókè, ó sì rí ibi tí ó ń lọ ní òkèrè,
Forsothe in the thridde dai he reiside hise iyen, and seiy a place afer;
5 Abrahamu sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin, ẹ dúró níhìn-ín pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, èmi àti ọmọ yìí yóò lọ sí ohunkóhun láti sin Ọlọ́run, a ó sì tún padà wá bá a yín.”
and he seide to hise children, Abide ye here with the asse, Y and the child schulen go thidur; and aftir that we han worschipid, we schulen turne ayen to you.
6 Abrahamu sì gbé igi ẹbọ sísun náà ru Isaaki, òun fúnra rẹ̀ sì mú iná àti ọ̀bẹ. Bí àwọn méjèèjì ti ń lọ,
And he took the trees of brent sacrifice, and puttide on Ysaac his sone; forsothe he bar fier, and a swerd in hise hondis. And whanne thei tweyne yeden togidere, Isaac seide to his fadir, My fadir!
7 Isaaki sì sọ fún Abrahamu baba rẹ̀ wí pé, “Baba mi.” Abrahamu sì dalóhùn pé, “Èmi nìyí ọmọ mi.” Isaaki sì tún wí pé, “Wò ó iná àti igi nìyí, ṣùgbọ́n níbo ni ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà wà?”
And he answerde, What wolt thou, sone? He seide, Lo! fier and trees, where is the beeste of brent sacrifice?
8 Abrahamu sì dáhùn pé, “Ọmọ mi, Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni yóò pèsè ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì jùmọ̀ ń lọ.
Abraham seide, My sone, God schal puruey to hym the beeste of brent sacrifice.
9 Nígbà tí wọn sì dé ibi tí Ọlọ́run sọ fún Abrahamu, ó mọ pẹpẹ kan, ó sì to igi lé e lórí, ó sì di Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì da dùbúlẹ̀ lórí pẹpẹ náà.
Therfor thei yeden to gidere, and camen to the place whiche God hadde schewid to hym, in which place Abraham bildide an auter, and dresside trees a boue; and whanne he hadde bounde to gidere Ysaac, his sone, he puttide Ysaac in the auter, on the heep of trees.
10 Abrahamu sì nawọ́ mú ọ̀bẹ, láti dúńbú ọmọ rẹ̀.
And he helde forth his hond, and took the swerd to sacrifice his sone.
11 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa ké sí i láti ọ̀run wá wí pé “Abrahamu! Abrahamu!” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
And lo! an aungel of the Lord criede fro heuene, and seide, Abraham! Abraham!
12 Angẹli Olúwa sì wí pé, “Má ṣe fọwọ́ kan ọmọ náà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣe é ni ohun kan. Nísinsin yìí ni mo mọ̀ pé o bẹ̀rù Ọlọ́run, nítorí pé ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí.”
Which answerde, I am present. And the aungel seide to hym, Holde thou not forth thin honde on the child, nether do thou ony thing to him; now Y haue knowe that thou dredist God, and sparidist not thin oon gendrid sone for me.
13 Abrahamu sì gbójú sókè, ó sì rí àgbò kan tí ó fi ìwo há pàǹtírí, ó sì lọ mú un, ó sì fi rú ẹbọ sísun dípò ọmọ rẹ̀.
Abraham reiside hise iyen, and he seiy `bihynde his bak a ram cleuynge bi hornes among breris, which he took, and offride brent sacrifice for the sone.
14 Abrahamu sì pe orúkọ ibẹ̀ ni, Jehofah Jire. Bẹ́ẹ̀ ni a sì ń wí títí di òní olónìí pé, “Ní orí òkè Olúwa, ni a ó ti pèsè.”
And he clepide the name of that place, The Lord seeth; wherfore it is seyd, til to dai, The Lord schal see in the hil.
15 Angẹli Olúwa sì tún pe Abrahamu láti ọ̀run wá lẹ́ẹ̀kejì.
Forsothe the aungel of the Lord clepide Abraham the secounde tyme fro heuene,
16 Ó sì wí pé, Olúwa wí pé, “Mo fi ara mi búra, níwọ̀n bí ìwọ ti ṣe èyí, tí ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí,
and seide, The Lord seith, Y haue swore bi my silf, for thou hast do this thing, and hast not sparid thin oon gendrid for me,
17 nítòótọ́, ní bíbùkún èmi ó bùkún fún ọ, àti ní bíbísí èmi ó sì mú ọ bí sí i bí i ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti bí iyanrìn etí Òkun. Irú-ọmọ rẹ yóò sì gba ẹnu ibodè àwọn ọ̀tá wọn,
Y schal blesse thee, and Y schal multiplie thi seed as the sterris of heuene, and as grauel which is in the brynk of the see; thi seed schal gete the yatis of hise enemyes;
18 àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó ti bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nítorí tí ìwọ gbọ́rọ̀ sí mi lẹ́nu.”
and alle the folkis of erthe schulen be blessid in thi seed, for thou obeiedist to my vois.
19 Nígbà náà ni Abrahamu padà tọ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ. Gbogbo wọn sì padà lọ sí Beerṣeba. Abrahamu sì jókòó ní Beerṣeba.
Abraham turnede ayen to hise children, and thei yeden to Bersabee to gidere, and he dwellide there.
20 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni a wí fún Abrahamu pé, “Milka aya Nahori bí àwọn ọmọkùnrin fún un.
And so whanne these thingis weren don, it was teld to Abraham that also Melcha hadde bore sones to Nachor his brother;
21 Usi àkọ́bí rẹ̀, Busi arákùnrin rẹ̀, Kemueli (baba Aramu).
Hus the firste gendrid, and Buz his brothir, and Chamuhel the fadir of Sireis,
22 Kesedi, Haso, Pildasi, Jidlafi, àti Betueli.”
and Cased, and Asan, and Feldas,
23 Betueli sì ni baba Rebeka. Milka sì bí àwọn ọmọ mẹ́jọ wọ̀nyí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
and Jedlaf, and Batuhel, of whom Rebecca was borun; Melcha childide these eiyte to Nachor brother of Abraham.
24 Àlè rẹ̀ tí ń jẹ́ Reuma náà bí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí fun un: Teba, Gahamu, Tahasi àti Maaka.
Forsothe his concubyn, Roma bi name, childide Thabee, and Gaon, and Thaas, and Maacha.

< Genesis 22 >