< Genesis 22 >

1 Nígbà tí ó ṣe, Ọlọ́run dán Abrahamu wò, ó pè é, ó sì wí pé, “Abrahamu.” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Když pakty věci pominuly, zkusil Bůh Abrahama, a řekl k němu: Abrahame! Kterýžto odpověděl: Teď jsem.
2 Ọlọ́run sì wí pé, “Mú ọmọ rẹ, àní Isaaki ọmọ rẹ kan ṣoṣo nì, tí ìwọ fẹ́ràn, lọ sí ilẹ̀ Moria, kí o sì fi rú ẹbọ sísun níbẹ̀ lórí ọ̀kan nínú àwọn òkè tí èmi yóò sọ fún ọ.”
I řekl: Vezmi nyní syna svého, toho jediného svého, kteréhož miluješ, Izáka, a jdi do země Moria; a obětuj ho tam v obět zápalnou na jedné hoře, o níž povím tobě.
3 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì mú méjì nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì ṣẹ́ igi fún ẹbọ sísun, ó sì gbéra lọ sí ibi tí Ọlọ́run ti sọ fún un.
Tedy vstav Abraham velmi ráno, osedlal osla svého a vzal dva služebníky své s sebou, a Izáka syna svého; a nasekav dříví k oběti zápalné, vstal a bral se k místu, o němž pověděl mu Bůh.
4 Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹta, Abrahamu gbé ojú sókè, ó sì rí ibi tí ó ń lọ ní òkèrè,
Třetího pak dne pozdvihl Abraham očí svých, a uzřel to místo zdaleka.
5 Abrahamu sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin, ẹ dúró níhìn-ín pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, èmi àti ọmọ yìí yóò lọ sí ohunkóhun láti sin Ọlọ́run, a ó sì tún padà wá bá a yín.”
A řekl Abraham služebníkům svým: Pozůstaňte vy tuto s oslem, já pak a dítě půjdeme tamto; a pomodlíce se, navrátíme se k vám.
6 Abrahamu sì gbé igi ẹbọ sísun náà ru Isaaki, òun fúnra rẹ̀ sì mú iná àti ọ̀bẹ. Bí àwọn méjèèjì ti ń lọ,
Tedy vzal Abraham dříví k zápalné oběti, a vložil je na Izáka syna svého; sám pak nesl v ruce své oheň a meč. I šli oba spolu.
7 Isaaki sì sọ fún Abrahamu baba rẹ̀ wí pé, “Baba mi.” Abrahamu sì dalóhùn pé, “Èmi nìyí ọmọ mi.” Isaaki sì tún wí pé, “Wò ó iná àti igi nìyí, ṣùgbọ́n níbo ni ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà wà?”
Mluvě pak Izák Abrahamovi otci svému, řekl: Otče můj! Kterýž odpověděl: Co chceš, synu můj? A řekl: Aj, teď oheň a dříví, a kdež hovádko k zápalné oběti?
8 Abrahamu sì dáhùn pé, “Ọmọ mi, Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni yóò pèsè ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì jùmọ̀ ń lọ.
Odpověděl Abraham: Bůh opatří sobě hovádko k oběti zápalné, synu můj. A šli předce oba spolu.
9 Nígbà tí wọn sì dé ibi tí Ọlọ́run sọ fún Abrahamu, ó mọ pẹpẹ kan, ó sì to igi lé e lórí, ó sì di Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì da dùbúlẹ̀ lórí pẹpẹ náà.
A když přišli k místu, o němž mu byl mluvil Bůh, udělal tu Abraham oltář, a srovnal dříví; a svázav syna svého, vložil ho na oltář na dříví.
10 Abrahamu sì nawọ́ mú ọ̀bẹ, láti dúńbú ọmọ rẹ̀.
I vztáhl Abraham ruku svou, a vzal meč, aby zabil syna svého.
11 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa ké sí i láti ọ̀run wá wí pé “Abrahamu! Abrahamu!” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Tedy zavolal na něho anděl Hospodinův s nebe a řekl: Abrahame, Abrahame! Kterýžto odpověděl: Aj, já.
12 Angẹli Olúwa sì wí pé, “Má ṣe fọwọ́ kan ọmọ náà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣe é ni ohun kan. Nísinsin yìí ni mo mọ̀ pé o bẹ̀rù Ọlọ́run, nítorí pé ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí.”
I řekl jemu: Nevztahuj ruky své na dítě, aniž mu co čiň; neboť jsem již poznal, že se Boha bojíš, když jsi neodpustil synu svému, jedinému svému pro mne.
13 Abrahamu sì gbójú sókè, ó sì rí àgbò kan tí ó fi ìwo há pàǹtírí, ó sì lọ mú un, ó sì fi rú ẹbọ sísun dípò ọmọ rẹ̀.
A pozdvih Abraham očí svých, viděl, a hle, skopec za ním vězel v trní za rohy své. I šel Abraham a vzal skopce toho, a obětoval jej v obět zápalnou místo syna svého.
14 Abrahamu sì pe orúkọ ibẹ̀ ni, Jehofah Jire. Bẹ́ẹ̀ ni a sì ń wí títí di òní olónìí pé, “Ní orí òkè Olúwa, ni a ó ti pèsè.”
A nazval Abraham jméno místa toho: Hospodin opatří. Odkudž říká se do dnes: Na hoře Hospodinově opatří se.
15 Angẹli Olúwa sì tún pe Abrahamu láti ọ̀run wá lẹ́ẹ̀kejì.
Zvolal pak anděl Hospodinův na Abrahama podruhé s nebe,
16 Ó sì wí pé, Olúwa wí pé, “Mo fi ara mi búra, níwọ̀n bí ìwọ ti ṣe èyí, tí ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí,
A řekl: Skrze sebe samého přisáhl jsem, praví Hospodin, poněvadž jsi učinil tu věc, že jsi neodpustil synu svému, jedinému svému:
17 nítòótọ́, ní bíbùkún èmi ó bùkún fún ọ, àti ní bíbísí èmi ó sì mú ọ bí sí i bí i ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti bí iyanrìn etí Òkun. Irú-ọmọ rẹ yóò sì gba ẹnu ibodè àwọn ọ̀tá wọn,
Požehnám velmi tobě, a velice rozmnožím símě tvé jako hvězdy nebeské, a jako písek, kterýž jest na břehu mořském; nadto dědičně vládnouti bude símě tvé branami nepřátel svých.
18 àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó ti bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nítorí tí ìwọ gbọ́rọ̀ sí mi lẹ́nu.”
Ano požehnáni budou v semeni tvém všickni národové země, proto že jsi uposlechl hlasu mého.
19 Nígbà náà ni Abrahamu padà tọ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ. Gbogbo wọn sì padà lọ sí Beerṣeba. Abrahamu sì jókòó ní Beerṣeba.
Tedy navrátil se Abraham k služebníkům svým; a vstavše, šli spolu do Bersabé; nebo bydlil Abraham v Bersabé.
20 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni a wí fún Abrahamu pé, “Milka aya Nahori bí àwọn ọmọkùnrin fún un.
A když se tyto věci staly, zvěstováno jest Abrahamovi v tato slova: Aj, porodila také Melcha syny Náchorovi, bratru tvému:
21 Usi àkọ́bí rẹ̀, Busi arákùnrin rẹ̀, Kemueli (baba Aramu).
Husa prvorozeného svého, a Buza bratra jeho, a Chamuele, otce Aramova;
22 Kesedi, Haso, Pildasi, Jidlafi, àti Betueli.”
A Kazeda a Azana, a Feldasa, a Jidlafa i Bathuele.
23 Betueli sì ni baba Rebeka. Milka sì bí àwọn ọmọ mẹ́jọ wọ̀nyí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
Bathuel pak zplodil Rebeku. Osm těchto porodila Melcha Náchorovi, bratru Abrahamovu.
24 Àlè rẹ̀ tí ń jẹ́ Reuma náà bí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí fun un: Teba, Gahamu, Tahasi àti Maaka.
Ale i ženina jeho, jejíž jméno bylo Réma, porodila také ona Tábe a Gahama, Thása a Máchu.

< Genesis 22 >