< Genesis 22 >
1 Nígbà tí ó ṣe, Ọlọ́run dán Abrahamu wò, ó pè é, ó sì wí pé, “Abrahamu.” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Eso enoga, Gode da A: ibalaha: me ea hou adoba: ma: ne, ema amane sia: i, “A: ibalaha: me!” A: ibalaha: me da bu adole i, “Na wea!”
2 Ọlọ́run sì wí pé, “Mú ọmọ rẹ, àní Isaaki ọmọ rẹ kan ṣoṣo nì, tí ìwọ fẹ́ràn, lọ sí ilẹ̀ Moria, kí o sì fi rú ẹbọ sísun níbẹ̀ lórí ọ̀kan nínú àwọn òkè tí èmi yóò sọ fún ọ.”
Gode da ema amane sia: i, “Defea! Di da mano afadafa fawane gala. Amo dia dogolegei mano Aisage lale, oule asili, Molaia sogega doaga: ma. Goe sogega Na da goumi dima olelemu. Amo heda: le, dia mano gobele salasu hou hamoma: ne, medole legele, laluga gobele salima.”
3 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì mú méjì nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì ṣẹ́ igi fún ẹbọ sísun, ó sì gbéra lọ sí ibi tí Ọlọ́run ti sọ fún un.
Golale hahabe, A:ibalaha: me da nedigili, liligi ea dougi da: iya ligisili, gobele salasu hou hamomusa: lalu ifa habele, ea mano amola hawa: hamosu ayeligi aduna, Molaia sogega doaga: musa: oule asi.
4 Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹta, Abrahamu gbé ojú sókè, ó sì rí ibi tí ó ń lọ ní òkèrè,
Eso udiana ahoanu, A:ibalaha: me da amo sogebi sedagawane dialebe ba: i.
5 Abrahamu sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin, ẹ dúró níhìn-ín pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, èmi àti ọmọ yìí yóò lọ sí ohunkóhun láti sin Ọlọ́run, a ó sì tún padà wá bá a yín.”
Amalalu, A:ibalaha: me da ea hawa: hamosu dunu elama amane sia: i, “Ali gui esaloma! Dougi ouligima! Na amola nagofe da amo sogega Godema nodone sia: ne gadolalu, bu misunu.”
6 Abrahamu sì gbé igi ẹbọ sísun náà ru Isaaki, òun fúnra rẹ̀ sì mú iná àti ọ̀bẹ. Bí àwọn méjèèjì ti ń lọ,
Amalalu, A:ibalaha: me da lalu ifa habei amo Aisagema gisa masa: ne i. A: ibalaha: me da lalu dasu amola gobihei gisa asili, ela da goumiba: le heda: i. Ela da gilisili ahoana,
7 Isaaki sì sọ fún Abrahamu baba rẹ̀ wí pé, “Baba mi.” Abrahamu sì dalóhùn pé, “Èmi nìyí ọmọ mi.” Isaaki sì tún wí pé, “Wò ó iná àti igi nìyí, ṣùgbọ́n níbo ni ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà wà?”
Aisage da edama amane sia: i, “Ada!” A: ibalaha: me da bu adole i, “Nagofe! Adi laha?” Aisage da amane sia: i, “Laludai amola lalu habei diala. Be sibi mano, gobele salasu hou hamoma: ne amo da habila: ?”
8 Abrahamu sì dáhùn pé, “Ọmọ mi, Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni yóò pèsè ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì jùmọ̀ ń lọ.
A: ibalaha: me da bu adole i, “Nagofe! Gode Hi da ani gobele salimusa: , sibi mano imunu!” Amalalu, ela da gilisili bu ahoanu.
9 Nígbà tí wọn sì dé ibi tí Ọlọ́run sọ fún Abrahamu, ó mọ pẹpẹ kan, ó sì to igi lé e lórí, ó sì di Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì da dùbúlẹ̀ lórí pẹpẹ náà.
Elea da Gode Ea musa: adoi sogebiga doaga: loba, A:ibalaha: me da gelega oloda hamone, lalu habei oloda da: iya ligisili, ea mano ea emo amola lobo la: gili, amo da: iya ligisi.
10 Abrahamu sì nawọ́ mú ọ̀bẹ, láti dúńbú ọmọ rẹ̀.
Amalalu, A:ibalaha: me da ea mano medole legemusa: , gobihei gaguia gadoi.
11 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa ké sí i láti ọ̀run wá wí pé “Abrahamu! Abrahamu!” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Be muagado, Hina Gode Ea a: igele dunu da gagabole ha: giwane wele sia: i, “A: ibalaha: me! A: ibalaha: me!” E bu adole i, “Na wea!”
12 Angẹli Olúwa sì wí pé, “Má ṣe fọwọ́ kan ọmọ náà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣe é ni ohun kan. Nísinsin yìí ni mo mọ̀ pé o bẹ̀rù Ọlọ́run, nítorí pé ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí.”
A: igele da amane sia: i, “Dia mano mae medoma! E se nabima: ne mae fama! Di da dia mano Nama imunu hame hihi galu. Amaiba: le, di da Godema beda: i amola nabasu hou dawa: , amo Na da ba: i dagoi.”
13 Abrahamu sì gbójú sókè, ó sì rí àgbò kan tí ó fi ìwo há pàǹtírí, ó sì lọ mú un, ó sì fi rú ẹbọ sísun dípò ọmọ rẹ̀.
Amalalu, A:ibalaha: me da ea si ba: le ga: le, sibi gawali amo ea hono da ifa amoga lala: gi lelebe ba: i. Amaiba: le, e da ea mano mae medole, amo sibi lale, medole legele, gobele salasu hamoi.
14 Abrahamu sì pe orúkọ ibẹ̀ ni, Jehofah Jire. Bẹ́ẹ̀ ni a sì ń wí títí di òní olónìí pé, “Ní orí òkè Olúwa, ni a ó ti pèsè.”
A: ibalaha: me da amo sogebi ‘Yehoufayaila’ dio asuli. Goe dio dawaloma: ne da, “Hina Gode Hi da hahawane imunu!” Wali eso amola, dunu da amane sia: sa, “Hina Gode da Hi goumi da: iya hahawane imunu.”
15 Angẹli Olúwa sì tún pe Abrahamu láti ọ̀run wá lẹ́ẹ̀kejì.
Amalalu, Gode Ea a: igele dunu da Hebeneganini A: ibalaha: mema bu sia: i,
16 Ó sì wí pé, Olúwa wí pé, “Mo fi ara mi búra, níwọ̀n bí ìwọ ti ṣe èyí, tí ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí,
“Di da Na sia: nabawane hamobeba: le, amola dia dogolegei mano Nama imunusa: hame hihiba: le, Na da Na Dioba: le agoane ilegele sia: sa. Na da dima bagadewane hahawane dogolegele ilegemu.
17 nítòótọ́, ní bíbùkún èmi ó bùkún fún ọ, àti ní bíbísí èmi ó sì mú ọ bí sí i bí i ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti bí iyanrìn etí Òkun. Irú-ọmọ rẹ yóò sì gba ẹnu ibodè àwọn ọ̀tá wọn,
Na da digaga fi mano ilia da gasumuni ilia idi defele, amola sa: iboso idi defei defele hamomu. Dia fi da ilia ha lai dunu amo hasalasimu.
18 àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó ti bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nítorí tí ìwọ gbọ́rọ̀ sí mi lẹ́nu.”
Di da Na hamoma: ne sia: nababeba: le, osobo bagade fifi asi gala huluane, da Nama Na da di hahawane dogolegele ilegei defele, ilima hahawane dogolegele ilegesu ima: ne adole ba: mu.”
19 Nígbà náà ni Abrahamu padà tọ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ. Gbogbo wọn sì padà lọ sí Beerṣeba. Abrahamu sì jókòó ní Beerṣeba.
Amalalu, A:ibalaha: me da ea hawa: hamosu dunu elama buhagili, ilia gilisili Biasiba moilaiga asi. Amola A: ibalaha: me da Biasiba amo ganodini esalu.
20 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni a wí fún Abrahamu pé, “Milka aya Nahori bí àwọn ọmọkùnrin fún un.
Fa: no, dunu eno da A: ibalaha: mema amane sia: i, “Miliga da mano lai. E da dia eya Na: iho ema dunu mano godoane lai.
21 Usi àkọ́bí rẹ̀, Busi arákùnrin rẹ̀, Kemueli (baba Aramu).
Magobo dunu mano da Use. Ea eyalali da Buse, Gemuele (ea mano da Alame),
22 Kesedi, Haso, Pildasi, Jidlafi, àti Betueli.”
Gisede, Ha: iso, Bilada: se, Yidala: fe amola Bediuele.
23 Betueli sì ni baba Rebeka. Milka sì bí àwọn ọmọ mẹ́jọ wọ̀nyí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
Bediuele da uda mano lai, amo Lebega. Amo dunu mano godoane ilia ame da Miliga, amola ilia eda da A: ibalaha: me eya amo Na: iho.
24 Àlè rẹ̀ tí ń jẹ́ Reuma náà bí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí fun un: Teba, Gahamu, Tahasi àti Maaka.
Na: iho ea gidisedagi uda amo ea dio amo Liuma, da dunu manolali lai. Ilia dio da Diba, Ga: iha: me, Da: iha: se amola Ma: iaga.