< Genesis 21 >

1 Olúwa sì bẹ Sara wò bí ó ti wí, Olúwa sì ṣe fún Sara gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
А Господь згадав Сарру, як сказав був, і вчинив Господь Саррі, як Він говорив.
2 Sara sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Abrahamu ní ọjọ́ ogbó rẹ̀, ní àkókò náà gan an tí Ọlọ́run ti ṣèlérí fún un.
І Сарра зачала́, і породила сина Авраамові в старості його на означений час, що про нього сказав йому Бог.
3 Abrahamu sì sọ orúkọ ọmọ náà tí Sara bí fun un ní Isaaki.
І назвав Авраам ім'я́ синові своєму, що вродився йому, що Сарра йому породила: Ісак.
4 Nígbà tí Isaaki pé ọmọ ọjọ́ mẹ́jọ, Abrahamu sì kọ ọ́ ní ilà gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un.
І обрізав Авраам Ісака, сина свого, коли мав він вісім день, як Бог наказав був йому.
5 Ẹni ọgọ́rùn-ún ọdún ni Abrahamu nígbà tí ó bí Isaaki.
А Авраам був віку ста літ, як уродився йому Ісак, син його.
6 Sara sì wí pé, “Ọlọ́run ti pa mí lẹ́rìn-ín. Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ pé mo bímọ yóò rẹ́rìn-ín pẹ̀lú mi.”
І промовила Сарра: „Сміх учинив мені Бог, — кожен, хто почує, буде сміятися з мене“.
7 Ó sì fi kún un pé, “Ta ni ó le sọ fún Abrahamu pé, Sara yóò di ọlọ́mọ? Síbẹ̀síbẹ̀, mo sì tún bí ọmọ fún Abrahamu ní ìgbà ogbó rẹ.”
І промовила: „Хто б сказав Авраамові: Сарра годує синів? Бо вродила я сина в старості його“.
8 Nígbà tí ọmọ náà dàgbà, ó sì gbà á lẹ́nu ọmú, ní ọjọ́ tí a gba Isaaki lẹ́nu ọmú, Abrahamu ṣe àsè ńlá.
І дитина росла, і була відлучена. І справив Авраам велику гостину в день відлучення Ісака.
9 Ṣùgbọ́n Sara rí ọmọ Hagari ará Ejibiti tí ó bí fún Abrahamu tí ó fi ṣe ẹlẹ́yà,
І побачила Сарра сина Аґари єги́птянки, що вродила була Авраамові, що він насміхається.
10 ó sì wí fún Abrahamu pé, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrú yìí kò ní bá ọmọ mi Isaaki pín ogún.”
I сказала вона Авраамові: „Прожени ту невільницю та сина її, бо не буде наслідувати син тієї невільниці разом із сином моїм, із Ісаком“.
11 Ọ̀rọ̀ náà sì ba Abrahamu lọ́kàn jẹ́ gidigidi nítorí ọmọ rẹ̀ náà sá à ni Iṣmaeli i ṣe.
Але ця справа була дуже не до вподоби Авраамові через сина його.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fun Abrahamu pé, “Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí ọmọ náà àti ẹrúbìnrin rẹ. Gbọ́ ohun tí Sara wí fún ọ, nítorí nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.
І промовив Господь Авраамові: „Нехай не буде не до вподоби тобі це через хлопця та через невільницю твою. Усе, що скаже тобі Сарра, послухай голосу її, бо Ісаком буде покликане тобі потомство.
13 Èmi yóò sọ ọmọ ẹrúbìnrin náà di orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, nítorí ọmọ rẹ ni.”
І також сина невільниці тієї — учиню його наро́дом, бо він — твоє насіння“.
14 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mú oúnjẹ àti ìgò omi kan, ó sì kó wọn fún Hagari, ó kó wọn lé e léjìká, ó sì lé e jáde pẹ̀lú ọmọ náà. Ó sì lọ lọ́nà rẹ, ó sì ń ṣe alárìnkiri ní ijù Beerṣeba.
І встав рано Авраам, і взяв хліба й бурдюка́ води, і дав до Аґари на плече її, також дитину, та й послав її. І пішла вона, та й заблудила в пустині Беер-Шева.
15 Nígbà tí omi inú ìgò náà tan, ó gbé ọmọ náà sí abẹ́ igbó.
І скінчилась вода в бурдюці, і покинула вона дитину під одним із кущів.
16 Ó sì lọ, ó sì jókòó nítòsí ibẹ̀, níwọ̀n bí ìtafà kan, nítorí, ó rò ó nínú ara rẹ̀ pé, “Èmi kò fẹ́ wo bí ọmọ náà yóò ṣe kú.” Bí ó sì ti jókòó sí tòsí ibẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
І пішла вона, і сіла собі навпроти, на віддалі — як стрілити луком, бо сказала: „Нехай я не бачу смерти цієї дитини!“І сіла навпроти, і піднесла свій голос та й заплакала.
17 Ọlọ́run gbọ́ ohun ẹkún náà, Angẹli Ọlọ́run sì pe Hagari láti ọ̀run, ó sì wí fun un pé, “Hagari, kín ni ó ṣe ọ́? Má bẹ̀rù nítorí Ọlọ́run ti gbọ́ ẹkún ọmọ náà níbi tí o tẹ́ ẹ sí.
І почув Бог голос того хлопця. І кликнув до Аґари Божий Ангол із неба, і сказав їй: „Що тобі, Аґаро? Не бійся, бо почув Бог голос хлопця, де він там.
18 Dìde, gbé ọmọ náà sókè, kí o sì dìímú (tù ú nínú) nítorí èmi yóò sọ ọmọ náà di orílẹ̀-èdè ńlá.”
Устань, підійми хлопця, і рукою своєю держи його, бо великим наро́дом зроблю Я його“.
19 Ọlọ́run sì ṣí ojú Hagari, ó sì rí kànga kan, ó lọ síbẹ̀, ó rọ omi kún inú ìgò náà, ó sì fún ọmọ náà mu.
І відкрив Бог очі її, і вона побачила криницю води. І пішла вона, і наповнила бурдюка водою, та й напоїла хлопця.
20 Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú ọmọ náà bí ó ti ń dàgbà, ó ń gbé nínú ijù, ó sì di tafàtafà.
І з хлопцем був Бог, — і він виріс. І осів у пустині, і став він стрілець-лучник.
21 Nígbà tí ó ń gbé ni aginjù ní Parani, ìyá rẹ̀ fẹ́ ìyàwó fún un láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
І осів він у пустині Паран, а мати його взяла йому жінку з єгипетського кра́ю.
22 Ní àkókò yìí ni ọba Abimeleki àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀ wí fún Abrahamu pé, “Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo ohun tí ó ń ṣe.
І сталося ча́су того, і сказав Авімеле́х і Піхол, головний провідник його війська, до Авраама, говорячи: „Бог із тобою в усьому, що́ ти робиш!
23 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, fi Ọlọ́run búra fún mi, ìwọ kì yóò tàn mí àti àwọn ọmọ mi àti àwọn ìran mi, ìwọ yóò fi inú rere hàn fún mi àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti ṣe àtìpó, bí mo ti fihàn fún ọ pẹ̀lú.”
А тепер присягни ж мені Богом отут, що ти не обманиш мене, і нащадка мого, і онука мого. І яка була ласка, яку я до тебе чинив, ти вчиниш зо мною та з краєм, що ти в нім чужинцем пробува́єш“.
24 Abrahamu sì wí pé, “Èmí búra.”
І сказав Авраам: „Я присягаю!“
25 Nígbà náà ni Abrahamu fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn fún Abimeleki nípa kànga tí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ gbà lọ́wọ́ rẹ̀.
І Авраам дорікав Авімелехові за криницю води, що її відняли були Авімелехові раби.
26 Ṣùgbọ́n Abimeleki dáhùn pé, “Èmi kò mọ ẹni tí ó ṣe nǹkan yìí. Ìwọ kò sì sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbọ́, bí kò ṣe lónìí.”
І сказав Авімелех: „Я не знаю, хто вчинив оту річ, — ані ти не розповів мені, й ані я не чув, хібащо сьогодні“.
27 Abrahamu sì mú àgùntàn àti màlúù wá, ó sì kó wọn fún Abimeleki. Àwọn méjèèjì sì dá májẹ̀mú.
І взяв Авраам дрібну та велику худобу, та й дав Авімелехові, і оби́два вони склали умову.
28 Abrahamu sì ya abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje nínú agbo àgùntàn rẹ̀ sọ́tọ̀.
І поставив Авраам сім овечок з дрібного товару осібно.
29 Abimeleki sì béèrè lọ́wọ́ Abrahamu pé, “Kín ni ìtumọ̀ yíyà tí ìwọ ya àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí sọ́tọ̀ sí.”
І сказав Авімелех до Авраама: „Що́ вони, сім овечок отих, що ти їх поставив осібно?“
30 Ó dalóhùn pé, “Gba àwọn abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí lọ́wọ́ mi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”
А той відказав: „Бо з моєї руки сім овечок ти візьмеш, щоб для мене були на свідоцтво, що я́ викопав цю криницю“.
31 Nítorí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ náà ni Beerṣeba nítorí níbẹ̀ ni àwọn méjèèjì gbé búra.
Тому то назвав він це місце Беер-Шева, бо там поклялися вони.
32 Lẹ́yìn májẹ̀mú tí wọ́n dá ní Beerṣeba yìí, ni Abimeleki àti Fikoli olórí ogun rẹ̀ padà sí ilẹ̀ àwọn ará Filistini.
І склали умову вони в Беер-Шеві. І встав Авімелех та Піхол, головний провідник його війська, і вернулись вони до краю филистимського.
33 Abrahamu lọ́ igi tamariski kan sí Beerṣeba, níbẹ̀ ni ó sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run ayérayé.
А Авраам посадив тамариска в Беер-Шеві, і кликав там Ім'я́ Господа, Бога Вічного.
34 Abrahamu sì gbé ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọjọ́ pípẹ́.
І Авраам пробув́ав у филистимській землі багато днів.

< Genesis 21 >