< Genesis 21 >
1 Olúwa sì bẹ Sara wò bí ó ti wí, Olúwa sì ṣe fún Sara gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
Och Herren sökte Sara, såsom han sagt hade, och Herren gjorde med henne såsom han talat hade.
2 Sara sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Abrahamu ní ọjọ́ ogbó rẹ̀, ní àkókò náà gan an tí Ọlọ́run ti ṣèlérí fún un.
Och Sara vardt hafvande, och födde Abraham en son i sinom ålderdom, vid den tiden, som Gud honom föresagt hade.
3 Abrahamu sì sọ orúkọ ọmọ náà tí Sara bí fun un ní Isaaki.
Och Abraham nämnde sin son, som honom född var, Isaac, den honom Sara födt hade.
4 Nígbà tí Isaaki pé ọmọ ọjọ́ mẹ́jọ, Abrahamu sì kọ ọ́ ní ilà gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un.
Och omskar honom på åttonde dagen, som Gud honom budit hade.
5 Ẹni ọgọ́rùn-ún ọdún ni Abrahamu nígbà tí ó bí Isaaki.
Hundrade år gammal var Abraham, då honom hans son Isaac födder var.
6 Sara sì wí pé, “Ọlọ́run ti pa mí lẹ́rìn-ín. Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ pé mo bímọ yóò rẹ́rìn-ín pẹ̀lú mi.”
Och Sara sade: Gud hafver gjort mig ett löje; ty hvilken det får höra, han får le åt mig.
7 Ó sì fi kún un pé, “Ta ni ó le sọ fún Abrahamu pé, Sara yóò di ọlọ́mọ? Síbẹ̀síbẹ̀, mo sì tún bí ọmọ fún Abrahamu ní ìgbà ogbó rẹ.”
Och sade ytterligare: Ho torde ock säga Abraham sjelfvom, att Sara däggde barn, och hade födt honom en son i sinom ålderdom?
8 Nígbà tí ọmọ náà dàgbà, ó sì gbà á lẹ́nu ọmú, ní ọjọ́ tí a gba Isaaki lẹ́nu ọmú, Abrahamu ṣe àsè ńlá.
Och barnet växte, och vardt afvandt. Och Abraham gjorde ett stort gästabud den dagen, då Isaac afvandes.
9 Ṣùgbọ́n Sara rí ọmọ Hagari ará Ejibiti tí ó bí fún Abrahamu tí ó fi ṣe ẹlẹ́yà,
Och Sara fick se den Egyptiska qvinnones Hagars son, den hon Abraham födt hade, att han var en bespottare.
10 ó sì wí fún Abrahamu pé, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrú yìí kò ní bá ọmọ mi Isaaki pín ogún.”
Och sade till Abraham: Drif denna tjensteqvinnona ut med hennes son; ty denne tjensteqvinnones son skall icke ärfva med min son Isaac.
11 Ọ̀rọ̀ náà sì ba Abrahamu lọ́kàn jẹ́ gidigidi nítorí ọmọ rẹ̀ náà sá à ni Iṣmaeli i ṣe.
Detta ordet behagade Abraham ganska illa för sin sons skull.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fun Abrahamu pé, “Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí ọmọ náà àti ẹrúbìnrin rẹ. Gbọ́ ohun tí Sara wí fún ọ, nítorí nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.
Men Gud sade till honom: Låt dig icke tycka hårdt vara om pilten och tjensteqvinnone; allt det Sara dig sagt hafver, så lyd henne; förty i Isaac skall säden dig nämnd varda.
13 Èmi yóò sọ ọmọ ẹrúbìnrin náà di orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, nítorí ọmọ rẹ ni.”
Jag skall ock göra tjensteqvinnones son till folk, derföre att han din säd är.
14 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mú oúnjẹ àti ìgò omi kan, ó sì kó wọn fún Hagari, ó kó wọn lé e léjìká, ó sì lé e jáde pẹ̀lú ọmọ náà. Ó sì lọ lọ́nà rẹ, ó sì ń ṣe alárìnkiri ní ijù Beerṣeba.
Då stod Abraham bittida upp om morgonen, och tog bröd och en flaska med vatten, och lade på Hagars rygg, och pilten med, och lät gå henne. Hon gick sin väg, och for vill i öknene, vid BerSaba.
15 Nígbà tí omi inú ìgò náà tan, ó gbé ọmọ náà sí abẹ́ igbó.
Då nu vattnet i flaskone var förtärdt, kastade hon pilten under en buska.
16 Ó sì lọ, ó sì jókòó nítòsí ibẹ̀, níwọ̀n bí ìtafà kan, nítorí, ó rò ó nínú ara rẹ̀ pé, “Èmi kò fẹ́ wo bí ọmọ náà yóò ṣe kú.” Bí ó sì ti jókòó sí tòsí ibẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
Och gick bort och satte sig tvärs öfver långt ifrå, vid ett armborst skott; ty hon sade: Jag gitter icke se uppå att pilten dör. Och vid hon satt tvärs öfver, hof hon upp sina röst, och gret.
17 Ọlọ́run gbọ́ ohun ẹkún náà, Angẹli Ọlọ́run sì pe Hagari láti ọ̀run, ó sì wí fun un pé, “Hagari, kín ni ó ṣe ọ́? Má bẹ̀rù nítorí Ọlọ́run ti gbọ́ ẹkún ọmọ náà níbi tí o tẹ́ ẹ sí.
Då hörde Gud piltens röst, och Guds Ängel kallade Hagar af himmelen, sägandes: Hvad skadar dig, Hagar? Frukta dig intet; förty Gud hafver hört piltens röst, der han ligger.
18 Dìde, gbé ọmọ náà sókè, kí o sì dìímú (tù ú nínú) nítorí èmi yóò sọ ọmọ náà di orílẹ̀-èdè ńlá.”
Statt upp, tag pilten, och håll honom med dina händer; ty jag skall göra honom till stort folk.
19 Ọlọ́run sì ṣí ojú Hagari, ó sì rí kànga kan, ó lọ síbẹ̀, ó rọ omi kún inú ìgò náà, ó sì fún ọmọ náà mu.
Och Gud öppnade hennes ögon, att hon fick se en vattubrunn. Då gick hon till och fyllde sina flasko med vatten, och gaf piltenom dricka.
20 Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú ọmọ náà bí ó ti ń dàgbà, ó ń gbé nínú ijù, ó sì di tafàtafà.
Och Gud var med piltenom; han växte, och bodde i öknene, och vardt en god skytte.
21 Nígbà tí ó ń gbé ni aginjù ní Parani, ìyá rẹ̀ fẹ́ ìyàwó fún un láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
Och bodde i den öknene Pharan: Och hans moder tog honom hustru utur Egypti land.
22 Ní àkókò yìí ni ọba Abimeleki àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀ wí fún Abrahamu pé, “Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo ohun tí ó ń ṣe.
På samma tiden talade Abimelech och Phicol, hans härhöfvitsman, med Abraham, och sade: Gud är med dig uti allt det du gör.
23 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, fi Ọlọ́run búra fún mi, ìwọ kì yóò tàn mí àti àwọn ọmọ mi àti àwọn ìran mi, ìwọ yóò fi inú rere hàn fún mi àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti ṣe àtìpó, bí mo ti fihàn fún ọ pẹ̀lú.”
Så svär mig nu vid Gud, att du är mig icke arg, eller minom barnom, eller minom barnabarnom: Utan den barmhertighet, som jag hafver gjort med dig, den gör ock med mig, och landena, der du en främling uti äst.
24 Abrahamu sì wí pé, “Èmí búra.”
Då sade Abraham: Jag vill svärja.
25 Nígbà náà ni Abrahamu fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn fún Abimeleki nípa kànga tí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ gbà lọ́wọ́ rẹ̀.
Och Abraham straffade Abimelech för den vattubrunnens skull, som Abimelechs tjenare hade tagit med våld.
26 Ṣùgbọ́n Abimeleki dáhùn pé, “Èmi kò mọ ẹni tí ó ṣe nǹkan yìí. Ìwọ kò sì sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbọ́, bí kò ṣe lónìí.”
Då svarade Abimelech: Jag hafver icke vist, ho det gjorde; ej heller sade du mig det; dertill hafver jag icke hört det förra än i dag.
27 Abrahamu sì mú àgùntàn àti màlúù wá, ó sì kó wọn fún Abimeleki. Àwọn méjèèjì sì dá májẹ̀mú.
Då tog Abraham får och fä, och gaf Abimelech: Och gjorde båda ett förbund med hvarannan.
28 Abrahamu sì ya abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje nínú agbo àgùntàn rẹ̀ sọ́tọ̀.
Och Abraham ställde sju lamb afsides.
29 Abimeleki sì béèrè lọ́wọ́ Abrahamu pé, “Kín ni ìtumọ̀ yíyà tí ìwọ ya àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí sọ́tọ̀ sí.”
Sade Abimelech till Abraham: Hvad skola de sju lamb, som du hafver ställt der afsides?
30 Ó dalóhùn pé, “Gba àwọn abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí lọ́wọ́ mi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”
Han svarade: Sju lamb skall du taga af mine hand, att de skola vara mig till ett vittnesbörd, att jag denna brunn grafvit hafver.
31 Nítorí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ náà ni Beerṣeba nítorí níbẹ̀ ni àwọn méjèèjì gbé búra.
Deraf heter det rummet BerSaba, att de båda med hvarannan der så svoro.
32 Lẹ́yìn májẹ̀mú tí wọ́n dá ní Beerṣeba yìí, ni Abimeleki àti Fikoli olórí ogun rẹ̀ padà sí ilẹ̀ àwọn ará Filistini.
Och alltså gjorde de det förbund i BerSaba. Då stodo Abimelech och hans härhöfvitsman Phicol upp, och drogo in i de Philisteers land igen.
33 Abrahamu lọ́ igi tamariski kan sí Beerṣeba, níbẹ̀ ni ó sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run ayérayé.
Och Abraham plantade trä i BerSaba; och predikade der om Herrans eviga Guds namn;
34 Abrahamu sì gbé ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọjọ́ pípẹ́.
Och var en främling uti de Philisteers land i långan tid.