< Genesis 21 >

1 Olúwa sì bẹ Sara wò bí ó ti wí, Olúwa sì ṣe fún Sara gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
خداوند به وعده‌ای که به سارا داده بود، وفا کرد.
2 Sara sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Abrahamu ní ọjọ́ ogbó rẹ̀, ní àkókò náà gan an tí Ọlọ́run ti ṣèlérí fún un.
سارا در زمانی که خداوند مقرر فرموده بود، حامله شد و برای ابراهیم در سن پیری پسری زایید.
3 Abrahamu sì sọ orúkọ ọmọ náà tí Sara bí fun un ní Isaaki.
ابراهیم پسرش را که سارا برای او به دنیا آورده بود، اِسحاق (یعنی «خنده») نام نهاد؛
4 Nígbà tí Isaaki pé ọmọ ọjọ́ mẹ́jọ, Abrahamu sì kọ ọ́ ní ilà gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un.
و ابراهیم طبق فرمان خدا اسحاق را هشت روز بعد از تولدش ختنه کرد.
5 Ẹni ọgọ́rùn-ún ọdún ni Abrahamu nígbà tí ó bí Isaaki.
هنگام تولدِ اسحاق، ابراهیم صد ساله بود.
6 Sara sì wí pé, “Ọlọ́run ti pa mí lẹ́rìn-ín. Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ pé mo bímọ yóò rẹ́rìn-ín pẹ̀lú mi.”
سارا گفت: «خدا برایم خنده و شادی آورده است. هر کس خبر تولد پسرم را بشنود با من خواهد خندید.
7 Ó sì fi kún un pé, “Ta ni ó le sọ fún Abrahamu pé, Sara yóò di ọlọ́mọ? Síbẹ̀síbẹ̀, mo sì tún bí ọmọ fún Abrahamu ní ìgbà ogbó rẹ.”
چه کسی باور می‌کرد که روزی من بچهٔ ابراهیم را شیر بدهم؟ ولی اکنون برای ابراهیم در سن پیری او پسری زاییده‌ام!»
8 Nígbà tí ọmọ náà dàgbà, ó sì gbà á lẹ́nu ọmú, ní ọjọ́ tí a gba Isaaki lẹ́nu ọmú, Abrahamu ṣe àsè ńlá.
اسحاق بزرگ شده، از شیر گرفته شد و ابراهیم به این مناسبت جشن بزرگی بر پا کرد.
9 Ṣùgbọ́n Sara rí ọmọ Hagari ará Ejibiti tí ó bí fún Abrahamu tí ó fi ṣe ẹlẹ́yà,
یک روز سارا متوجه شد که اسماعیل، پسر هاجر مصری، اسحاق را اذیت می‌کند.
10 ó sì wí fún Abrahamu pé, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrú yìí kò ní bá ọmọ mi Isaaki pín ogún.”
پس به ابراهیم گفت: «این کنیز و پسرش را از خانه بیرون کن، زیرا اسماعیل با پسر من اسحاق وارث تو نخواهد بود.»
11 Ọ̀rọ̀ náà sì ba Abrahamu lọ́kàn jẹ́ gidigidi nítorí ọmọ rẹ̀ náà sá à ni Iṣmaeli i ṣe.
این موضوع ابراهیم را بسیار رنجاند، چون اسماعیل نیز پسر او بود.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fun Abrahamu pé, “Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí ọmọ náà àti ẹrúbìnrin rẹ. Gbọ́ ohun tí Sara wí fún ọ, nítorí nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.
اما خدا به ابراهیم فرمود: «دربارهٔ پسر و کنیزت آزرده‌خاطر نشو. آنچه سارا گفته است انجام بده، زیرا توسط اسحاق است که تو صاحب نسلی می‌شوی که وعده‌اش را به تو داده‌ام.
13 Èmi yóò sọ ọmọ ẹrúbìnrin náà di orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, nítorí ọmọ rẹ ni.”
از پسر آن کنیز هم قومی به وجود خواهم آورد، چون او نیز پسر توست.»
14 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mú oúnjẹ àti ìgò omi kan, ó sì kó wọn fún Hagari, ó kó wọn lé e léjìká, ó sì lé e jáde pẹ̀lú ọmọ náà. Ó sì lọ lọ́nà rẹ, ó sì ń ṣe alárìnkiri ní ijù Beerṣeba.
پس ابراهیم صبح زود برخاست و نان و مشکی پُر از آب برداشت و بر دوش هاجر گذاشت، و او را با پسر روانه ساخت. هاجر به بیابان بئرشِبَع رفت و در آنجا سرگردان شد.
15 Nígbà tí omi inú ìgò náà tan, ó gbé ọmọ náà sí abẹ́ igbó.
وقتی آب مشک تمام شد، هاجر پسرش را زیر بوته‌ها گذاشت
16 Ó sì lọ, ó sì jókòó nítòsí ibẹ̀, níwọ̀n bí ìtafà kan, nítorí, ó rò ó nínú ara rẹ̀ pé, “Èmi kò fẹ́ wo bí ọmọ náà yóò ṣe kú.” Bí ó sì ti jókòó sí tòsí ibẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
و خود حدود صد متر دورتر از او نشست و با خود گفت: «نمی‌خواهم ناظر مرگ فرزندم باشم.» و زارزار بگریست.
17 Ọlọ́run gbọ́ ohun ẹkún náà, Angẹli Ọlọ́run sì pe Hagari láti ọ̀run, ó sì wí fun un pé, “Hagari, kín ni ó ṣe ọ́? Má bẹ̀rù nítorí Ọlọ́run ti gbọ́ ẹkún ọmọ náà níbi tí o tẹ́ ẹ sí.
آنگاه خدا به ناله‌های پسر توجه نمود و فرشتهٔ خدا از آسمان هاجر را ندا داده، گفت: «ای هاجر، چه شده است؟ نترس! زیرا خدا ناله‌های پسرت را شنیده است.
18 Dìde, gbé ọmọ náà sókè, kí o sì dìímú (tù ú nínú) nítorí èmi yóò sọ ọmọ náà di orílẹ̀-èdè ńlá.”
برو و او را بردار و در آغوش بگیر. من قوم بزرگی از او به وجود خواهم آورد.»
19 Ọlọ́run sì ṣí ojú Hagari, ó sì rí kànga kan, ó lọ síbẹ̀, ó rọ omi kún inú ìgò náà, ó sì fún ọmọ náà mu.
سپس خدا چشمان هاجر را گشود و او چاه آبی در مقابل خود دید. پس به طرف چاه رفته، مشک را پر از آب کرد و به پسرش نوشانید.
20 Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú ọmọ náà bí ó ti ń dàgbà, ó ń gbé nínú ijù, ó sì di tafàtafà.
و خدا با اسماعیل بود و او در صحرا بزرگ شده، در تیراندازی ماهر گشت.
21 Nígbà tí ó ń gbé ni aginjù ní Parani, ìyá rẹ̀ fẹ́ ìyàwó fún un láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
او در صحرای فاران زندگی می‌کرد و مادرش دختری از مصر برای او گرفت.
22 Ní àkókò yìí ni ọba Abimeleki àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀ wí fún Abrahamu pé, “Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo ohun tí ó ń ṣe.
در آن زمان ابیملکِ پادشاه، با فرماندهٔ سپاهش فیکول نزد ابراهیم آمده، گفت: «خدا در آنچه می‌کنی با توست!
23 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, fi Ọlọ́run búra fún mi, ìwọ kì yóò tàn mí àti àwọn ọmọ mi àti àwọn ìran mi, ìwọ yóò fi inú rere hàn fún mi àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti ṣe àtìpó, bí mo ti fihàn fún ọ pẹ̀lú.”
اکنون به نام خدا سوگند یاد کن که به من و فرزندان و نواده‌های من خیانت نخواهی کرد و همان‌طوری که من با تو به خوبی رفتار کرده‌ام، تو نیز با من و مملکتم که در آن ساکنی، به خوبی رفتار خواهی نمود.»
24 Abrahamu sì wí pé, “Èmí búra.”
ابراهیم پاسخ داد: «سوگند می‌خورم چنانکه گفتید رفتار کنم.»
25 Nígbà náà ni Abrahamu fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn fún Abimeleki nípa kànga tí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ gbà lọ́wọ́ rẹ̀.
سپس ابراهیم دربارهٔ چاهِ آبی که خدمتگزاران ابیملک به زور از او گرفته بودند، نزد وی شکایت کرد.
26 Ṣùgbọ́n Abimeleki dáhùn pé, “Èmi kò mọ ẹni tí ó ṣe nǹkan yìí. Ìwọ kò sì sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbọ́, bí kò ṣe lónìí.”
ابیملکِ پادشاه گفت: «این اولین باری است که راجع به این موضوع می‌شنوم و نمی‌دانم کدام یک از خدمتگزارانم در این کار مقصر است. چرا پیش از این به من خبر ندادی؟»
27 Abrahamu sì mú àgùntàn àti màlúù wá, ó sì kó wọn fún Abimeleki. Àwọn méjèèjì sì dá májẹ̀mú.
آنگاه ابراهیم، گوسفندان و گاوانی به ابیملک داد و با یکدیگر عهد بستند.
28 Abrahamu sì ya abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje nínú agbo àgùntàn rẹ̀ sọ́tọ̀.
سپس ابراهیم هفت بره از گله جدا ساخت.
29 Abimeleki sì béèrè lọ́wọ́ Abrahamu pé, “Kín ni ìtumọ̀ yíyà tí ìwọ ya àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí sọ́tọ̀ sí.”
پادشاه پرسید: «چرا این کار را می‌کنی؟»
30 Ó dalóhùn pé, “Gba àwọn abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí lọ́wọ́ mi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”
ابراهیم پاسخ داد: «اینها هدایایی هستند که من به تو می‌دهم تا همه بدانند که این چاه از آنِ من است.»
31 Nítorí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ náà ni Beerṣeba nítorí níbẹ̀ ni àwọn méjèèjì gbé búra.
از آن پس این چاه، بئرشبع (یعنی «چاه سوگند») نامیده شد، زیرا آنها در آنجا با هم عهد بسته بودند.
32 Lẹ́yìn májẹ̀mú tí wọ́n dá ní Beerṣeba yìí, ni Abimeleki àti Fikoli olórí ogun rẹ̀ padà sí ilẹ̀ àwọn ará Filistini.
آنگاه ابیملک و فیکول فرماندهٔ سپاهش به سرزمین خود فلسطین بازگشتند.
33 Abrahamu lọ́ igi tamariski kan sí Beerṣeba, níbẹ̀ ni ó sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run ayérayé.
ابراهیم در کنار آن چاه درخت گزی کاشت و خداوند، خدای ابدی را عبادت نمود.
34 Abrahamu sì gbé ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọjọ́ pípẹ́.
ابراهیم مدت زیادی در سرزمین فلسطین در غربت زندگی کرد.

< Genesis 21 >