< Genesis 21 >
1 Olúwa sì bẹ Sara wò bí ó ti wí, Olúwa sì ṣe fún Sara gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
Og Herren så til Sara som han hadde sagt, og Herren gjorde med Sara som han hadde lovt.
2 Sara sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Abrahamu ní ọjọ́ ogbó rẹ̀, ní àkókò náà gan an tí Ọlọ́run ti ṣèlérí fún un.
Sara blev fruktsommelig og fødte Abraham en sønn i hans alderdom på den fastsatte tid som Gud hadde talt til ham om.
3 Abrahamu sì sọ orúkọ ọmọ náà tí Sara bí fun un ní Isaaki.
Og Abraham kalte den sønn han hadde fått, den som Sara hadde født ham, Isak.
4 Nígbà tí Isaaki pé ọmọ ọjọ́ mẹ́jọ, Abrahamu sì kọ ọ́ ní ilà gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un.
Og Abraham omskar Isak, sin sønn, da han var åtte dager gammel, således som Gud hadde befalt ham.
5 Ẹni ọgọ́rùn-ún ọdún ni Abrahamu nígbà tí ó bí Isaaki.
Abraham var hundre år gammel da han fikk sin sønn Isak.
6 Sara sì wí pé, “Ọlọ́run ti pa mí lẹ́rìn-ín. Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ pé mo bímọ yóò rẹ́rìn-ín pẹ̀lú mi.”
Da sa Sara: Gud har gjort det så at jeg må le; alle som hører dette, vil le av mig.
7 Ó sì fi kún un pé, “Ta ni ó le sọ fún Abrahamu pé, Sara yóò di ọlọ́mọ? Síbẹ̀síbẹ̀, mo sì tún bí ọmọ fún Abrahamu ní ìgbà ogbó rẹ.”
Og hun sa: Hvem skulde vel ha sagt til Abraham at Sara gir barn å die? Og nu har jeg født ham en sønn i hans alderdom.
8 Nígbà tí ọmọ náà dàgbà, ó sì gbà á lẹ́nu ọmú, ní ọjọ́ tí a gba Isaaki lẹ́nu ọmú, Abrahamu ṣe àsè ńlá.
Og gutten vokste op og blev avvent; og Abraham gjorde et stort gjestebud den dag Isak blev avvent.
9 Ṣùgbọ́n Sara rí ọmọ Hagari ará Ejibiti tí ó bí fún Abrahamu tí ó fi ṣe ẹlẹ́yà,
Og Sara så at egypterkvinnen Hagars sønn, som hun hadde født Abraham, spottet,
10 ó sì wí fún Abrahamu pé, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrú yìí kò ní bá ọmọ mi Isaaki pín ogún.”
og hun sa til Abraham: Driv ut denne trælkvinne og hennes sønn! For denne trælkvinnes sønn skal ikke arve med min sønn, med Isak.
11 Ọ̀rọ̀ náà sì ba Abrahamu lọ́kàn jẹ́ gidigidi nítorí ọmọ rẹ̀ náà sá à ni Iṣmaeli i ṣe.
Dette gjorde Abraham meget ondt for hans sønns skyld.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fun Abrahamu pé, “Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí ọmọ náà àti ẹrúbìnrin rẹ. Gbọ́ ohun tí Sara wí fún ọ, nítorí nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.
Men Gud sa til Abraham: La det ikke gjøre dig ondt for guttens og for din trælkvinnes skyld! Lyd Sara i alt det hun sier til dig! For i Isak skal det nevnes dig en ætt.
13 Èmi yóò sọ ọmọ ẹrúbìnrin náà di orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, nítorí ọmọ rẹ ni.”
Men også trælkvinnens sønn vil jeg gjøre til et folk, fordi han er din sønn.
14 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mú oúnjẹ àti ìgò omi kan, ó sì kó wọn fún Hagari, ó kó wọn lé e léjìká, ó sì lé e jáde pẹ̀lú ọmọ náà. Ó sì lọ lọ́nà rẹ, ó sì ń ṣe alárìnkiri ní ijù Beerṣeba.
Da stod Abraham tidlig op om morgenen og tok brød og en skinnsekk med vann og gav Hagar og la det på hennes skulder; han gav henne også gutten med og lot henne fare. Og hun gikk avsted og for vill i Be'erseba-ørkenen.
15 Nígbà tí omi inú ìgò náà tan, ó gbé ọmọ náà sí abẹ́ igbó.
Da det var forbi med vannet i sekken, kastet hun gutten fra sig under en busk
16 Ó sì lọ, ó sì jókòó nítòsí ibẹ̀, níwọ̀n bí ìtafà kan, nítorí, ó rò ó nínú ara rẹ̀ pé, “Èmi kò fẹ́ wo bí ọmọ náà yóò ṣe kú.” Bí ó sì ti jókòó sí tòsí ibẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
og gikk bort og satte sig et stykke ifra, sa langt som et bueskudd; for hun tenkte: Jeg vil ikke se på at gutten dør. Så satt hun et stykke ifra og brast i gråt.
17 Ọlọ́run gbọ́ ohun ẹkún náà, Angẹli Ọlọ́run sì pe Hagari láti ọ̀run, ó sì wí fun un pé, “Hagari, kín ni ó ṣe ọ́? Má bẹ̀rù nítorí Ọlọ́run ti gbọ́ ẹkún ọmọ náà níbi tí o tẹ́ ẹ sí.
Men Gud hørte gutten ynke sig, og Guds engel ropte til Hagar fra himmelen og sa til henne: Hvad fattes dig, Hagar? Frykt ikke! For Gud har hørt gutten ynke sig der han ligger.
18 Dìde, gbé ọmọ náà sókè, kí o sì dìímú (tù ú nínú) nítorí èmi yóò sọ ọmọ náà di orílẹ̀-èdè ńlá.”
Reis dig, løft gutten op og hold ham ved hånden! For jeg vil gjøre ham til et stort folk.
19 Ọlọ́run sì ṣí ojú Hagari, ó sì rí kànga kan, ó lọ síbẹ̀, ó rọ omi kún inú ìgò náà, ó sì fún ọmọ náà mu.
Og Gud åpnet hennes øine, så hun så en brønn; da gikk hun dit og fylte sekken med vann og gav gutten å drikke.
20 Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú ọmọ náà bí ó ti ń dàgbà, ó ń gbé nínú ijù, ó sì di tafàtafà.
Og Gud var med gutten; han blev stor og bodde i ørkenen, og da han vokste til, blev han bueskytter.
21 Nígbà tí ó ń gbé ni aginjù ní Parani, ìyá rẹ̀ fẹ́ ìyàwó fún un láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
Han bosatte sig i ørkenen Paran, og hans mor tok en hustru til ham fra Egypten.
22 Ní àkókò yìí ni ọba Abimeleki àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀ wí fún Abrahamu pé, “Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo ohun tí ó ń ṣe.
Ved denne tid kom Abimelek og Pikol, hans hærfører, og sa til Abraham: Gud er med dig i alt det du gjør.
23 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, fi Ọlọ́run búra fún mi, ìwọ kì yóò tàn mí àti àwọn ọmọ mi àti àwọn ìran mi, ìwọ yóò fi inú rere hàn fún mi àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti ṣe àtìpó, bí mo ti fihàn fún ọ pẹ̀lú.”
Så tilsverg mig nu her ved Gud at du ikke vil fare med svik mot mig og mine barn og min ætt! Likesom jeg har vist godhet mot dig, så skal du gjøre det samme mot mig og mot det land du bor i som fremmed.
24 Abrahamu sì wí pé, “Èmí búra.”
Da sa Abraham: Ja, det skal jeg tilsverge dig.
25 Nígbà náà ni Abrahamu fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn fún Abimeleki nípa kànga tí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ gbà lọ́wọ́ rẹ̀.
Men Abraham gikk i rette med Abimelek for en brønn som Abimeleks tjenere hadde tatt med vold.
26 Ṣùgbọ́n Abimeleki dáhùn pé, “Èmi kò mọ ẹni tí ó ṣe nǹkan yìí. Ìwọ kò sì sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbọ́, bí kò ṣe lónìí.”
Da sa Abimelek: Jeg vet ikke hvem som har gjort dette; hverken har du sagt mig det, eller har jeg hørt det før idag.
27 Abrahamu sì mú àgùntàn àti màlúù wá, ó sì kó wọn fún Abimeleki. Àwọn méjèèjì sì dá májẹ̀mú.
Da tok Abraham småfe og storfe og gav Abimelek, og de gjorde en pakt med hverandre.
28 Abrahamu sì ya abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje nínú agbo àgùntàn rẹ̀ sọ́tọ̀.
Og Abraham stilte syv får av småfeet for sig selv.
29 Abimeleki sì béèrè lọ́wọ́ Abrahamu pé, “Kín ni ìtumọ̀ yíyà tí ìwọ ya àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí sọ́tọ̀ sí.”
Da sa Abimelek til Abraham Hvad skal disse syv får her som du har stilt for sig selv?
30 Ó dalóhùn pé, “Gba àwọn abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí lọ́wọ́ mi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”
Han svarte: Disse syv får skal du ta imot av mig; det skal være til et vidnesbyrd for mig at jeg har gravd denne brønn.
31 Nítorí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ náà ni Beerṣeba nítorí níbẹ̀ ni àwọn méjèèjì gbé búra.
Derfor kalte de dette sted Be'erseba; for der gjorde de begge sin ed.
32 Lẹ́yìn májẹ̀mú tí wọ́n dá ní Beerṣeba yìí, ni Abimeleki àti Fikoli olórí ogun rẹ̀ padà sí ilẹ̀ àwọn ará Filistini.
Så gjorde de da en pakt i Be'erseba; og Abimelek og Pikol, hans hærfører, brøt op og vendte tilbake til filistrenes land.
33 Abrahamu lọ́ igi tamariski kan sí Beerṣeba, níbẹ̀ ni ó sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run ayérayé.
Og Abraham plantet en tamarisk i Be'erseba, og der påkalte han Herrens, den evige Guds navn.
34 Abrahamu sì gbé ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọjọ́ pípẹ́.
Og Abraham bodde som fremmed i filistrenes land en lang tid.