< Genesis 21 >

1 Olúwa sì bẹ Sara wò bí ó ti wí, Olúwa sì ṣe fún Sara gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
Impangag ni Yahweh ni Sarah kas imbagana nga aramidenna, ket inaramid ni Yahweh para kenni Sara ti kas iti inkarina.
2 Sara sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Abrahamu ní ọjọ́ ogbó rẹ̀, ní àkókò náà gan an tí Ọlọ́run ti ṣèlérí fún un.
Nagsikog ni Sara ket inyanakna ti anakna a lalaki kenni Abraham iti kinalakayna, iti naikeddeng a tiempo kas imbaga ti Dios kenkuana.
3 Abrahamu sì sọ orúkọ ọmọ náà tí Sara bí fun un ní Isaaki.
Pinanaganan ni Abraham ti putotna kenni Sara, iti Isaac.
4 Nígbà tí Isaaki pé ọmọ ọjọ́ mẹ́jọ, Abrahamu sì kọ ọ́ ní ilà gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un.
Kinugit ni Abraham ni Isaac nga anakna idi walo nga aldawnan, kas imbilin ti Dios kenkuana.
5 Ẹni ọgọ́rùn-ún ọdún ni Abrahamu nígbà tí ó bí Isaaki.
Sangagasut ti tawen ni Abraham idi naiyanak ni Isaac kenkuana.
6 Sara sì wí pé, “Ọlọ́run ti pa mí lẹ́rìn-ín. Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ pé mo bímọ yóò rẹ́rìn-ín pẹ̀lú mi.”
Kinuna ni Sarah, “Pinagkatawanak ti Dios; tunggal maysa a makangngeg ket makipagkatawanto kaniak.''
7 Ó sì fi kún un pé, “Ta ni ó le sọ fún Abrahamu pé, Sara yóò di ọlọ́mọ? Síbẹ̀síbẹ̀, mo sì tún bí ọmọ fún Abrahamu ní ìgbà ogbó rẹ.”
Kinunana pay, ''Siasino ngay koma iti nakaibaga kenni Abraham nga agpasusonto ni Sarah kadagiti ubbing, nupay kasta inyanakko ti putotna iti kinalakayna!”
8 Nígbà tí ọmọ náà dàgbà, ó sì gbà á lẹ́nu ọmú, ní ọjọ́ tí a gba Isaaki lẹ́nu ọmú, Abrahamu ṣe àsè ńlá.
Dimmakkel ti ubing ket napusot, ket nagparambak ni Abraham iti dakkel a padaya iti aldaw a pannakapusot ni Isaac.
9 Ṣùgbọ́n Sara rí ọmọ Hagari ará Ejibiti tí ó bí fún Abrahamu tí ó fi ṣe ẹlẹ́yà,
Nakita ni Sara ti anak ni Hagar a taga-Egipto, nga anakna kenni Abraham, nga aguy- uyaw.
10 ó sì wí fún Abrahamu pé, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrú yìí kò ní bá ọmọ mi Isaaki pín ogún.”
Isu a kinunana kenni Abraham, “Papanawem daytoy a tagabu a babai ken ti anakna: Ta saanko a kayat a makipagtawid ti anakna iti anakko, a ni Isaac.”
11 Ọ̀rọ̀ náà sì ba Abrahamu lọ́kàn jẹ́ gidigidi nítorí ọmọ rẹ̀ náà sá à ni Iṣmaeli i ṣe.
Daytoy ket naladingit unay a banag kenni Abraham gapu iti anakna.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fun Abrahamu pé, “Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí ọmọ náà àti ẹrúbìnrin rẹ. Gbọ́ ohun tí Sara wí fún ọ, nítorí nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.
Ngem kinuna ti Dios kenni Abraham, saanka nga agladingit gapu iti ubing a lalaki, ken gapu iti tagabum a babai. Denggem dagiti amin nga ibagana maipanggep iti daytoy a banag, gapu ta babaen kenni Isaac a mapanagananto dagiti kaputotam.
13 Èmi yóò sọ ọmọ ẹrúbìnrin náà di orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, nítorí ọmọ rẹ ni.”
Pagbalinekto met ti anak ti tagabum a babai a maysa a nasion, gapu ta isuna ket kaputotam.”
14 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mú oúnjẹ àti ìgò omi kan, ó sì kó wọn fún Hagari, ó kó wọn lé e léjìká, ó sì lé e jáde pẹ̀lú ọmọ náà. Ó sì lọ lọ́nà rẹ, ó sì ń ṣe alárìnkiri ní ijù Beerṣeba.
Bimmangon ni Abraham iti nasapa iti dayta a bigat, nangala iti tinapay ken danum a naikarga iti supot a lalat ket intedna kenni Hagar, inkabilna daytoy iti abagana. Intedna kenkuana ti ubing a lalaki ket imbagana a pumanaw isuna. Pimmanaw ket nagkalkallautang iti let-ang ti Beerseba.
15 Nígbà tí omi inú ìgò náà tan, ó gbé ọmọ náà sí abẹ́ igbó.
Idi naibusen ti danum iti supot a lalat, pinanawanna ti ubing iti sirok ti maysa a narukbos a kayo.
16 Ó sì lọ, ó sì jókòó nítòsí ibẹ̀, níwọ̀n bí ìtafà kan, nítorí, ó rò ó nínú ara rẹ̀ pé, “Èmi kò fẹ́ wo bí ọmọ náà yóò ṣe kú.” Bí ó sì ti jókòó sí tòsí ibẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
Ket pimmanaw isuna, ket nagtugaw iti saan unay nga adayo manipud iti ubing, ti kaadayona ket kas iti kaadayo ti naibiat a pana, ta kinunana, “Saanko kayat a buyaen ti pannakatay ti ubing.” Bayat iti panagtugtugawna iti saan unay nga adayo, nagpukkaw isuna ket nagsangit.
17 Ọlọ́run gbọ́ ohun ẹkún náà, Angẹli Ọlọ́run sì pe Hagari láti ọ̀run, ó sì wí fun un pé, “Hagari, kín ni ó ṣe ọ́? Má bẹ̀rù nítorí Ọlọ́run ti gbọ́ ẹkún ọmọ náà níbi tí o tẹ́ ẹ sí.
Nangngeg ti Dios ti timek ti ubing, ket inawagan ti anghel ti Apo ni Hagar, ket kinunana kenkuana, “Ania ti mangrirriribok kenka Hagar? Saanka nga agbuteng, ta nangeg ti Dios ti timek ti ubing iti ayanna.
18 Dìde, gbé ọmọ náà sókè, kí o sì dìímú (tù ú nínú) nítorí èmi yóò sọ ọmọ náà di orílẹ̀-èdè ńlá.”
Tumakderka, bangonem ti ubing ken pabilgem isuna; ta pagbalinekto isuna a maysa a naindaklan a nasion.”
19 Ọlọ́run sì ṣí ojú Hagari, ó sì rí kànga kan, ó lọ síbẹ̀, ó rọ omi kún inú ìgò náà, ó sì fún ọmọ náà mu.
Ket, linukatan ti Dios ti matana, ket nakitana ti maysa a bubon. Napan na insakdo ti supot a lalat iti danum, ket pinainomna ti ubing a lalaki.
20 Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú ọmọ náà bí ó ti ń dàgbà, ó ń gbé nínú ijù, ó sì di tafàtafà.
Ti Dios ket adda iti ubing, ket dimmakkel isuna. Nagnaed isuna idiay let-ang ket nagbalin isuna a pumapana.
21 Nígbà tí ó ń gbé ni aginjù ní Parani, ìyá rẹ̀ fẹ́ ìyàwó fún un láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
Nagnaed isuna idiay let-ang ti Paran, ket nangala ti inana iti asawaenna manipud iti daga ti Egipto.
22 Ní àkókò yìí ni ọba Abimeleki àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀ wí fún Abrahamu pé, “Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo ohun tí ó ń ṣe.
Napasamak iti dayta a tiempo a ni Abimelek kenni Pikol a kapitan ti armadana ket nakiao kenni Abraham, a kinunana, “Ti Dios ket adda kenka iti amin nga ar-aramidem.
23 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, fi Ọlọ́run búra fún mi, ìwọ kì yóò tàn mí àti àwọn ọmọ mi àti àwọn ìran mi, ìwọ yóò fi inú rere hàn fún mi àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti ṣe àtìpó, bí mo ti fihàn fún ọ pẹ̀lú.”
Ita ngarud agsapataka kaniak ditoy babaen iti Dios a saannakto nga allilawen, uray dagiti annakko, wenno kadagiti kaputotak. Ipakitam kaniak ken iti daga a pagnanaedam ti kinapudnom a kas iti kinapudno nga impakitak kenka.”
24 Abrahamu sì wí pé, “Èmí búra.”
Kinuna ni Abraham, “Isapatak.”
25 Nígbà náà ni Abrahamu fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn fún Abimeleki nípa kànga tí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ gbà lọ́wọ́ rẹ̀.
Nagriri met ni Abraham kenni Abimelek maipanggep iti bubon ti danum nga inagaw dagiti adipen ni Abimelech manipud kenkuana.
26 Ṣùgbọ́n Abimeleki dáhùn pé, “Èmi kò mọ ẹni tí ó ṣe nǹkan yìí. Ìwọ kò sì sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbọ́, bí kò ṣe lónìí.”
Kinuna ni Abimelek, “Saanko nga ammo no siasino ti nangaramid iti daytoy a banag. Saanmo nga imbagbaga idi kaniak sakbay ita; Saanko pay a nangnangegan ti maipanggep iti daytoy agingga ita nga aldaw.”
27 Abrahamu sì mú àgùntàn àti màlúù wá, ó sì kó wọn fún Abimeleki. Àwọn méjèèjì sì dá májẹ̀mú.
Isu a nangala ni Abraham iti karnero ken baka ket intedna kenni Abimelek, ket nagtulag dagiti dua a lallaki.
28 Abrahamu sì ya abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje nínú agbo àgùntàn rẹ̀ sọ́tọ̀.
Ket nangilasin ni Abraham iti pito a kaba-ian a karnero manipud iti arban.
29 Abimeleki sì béèrè lọ́wọ́ Abrahamu pé, “Kín ni ìtumọ̀ yíyà tí ìwọ ya àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí sọ́tọ̀ sí.”
Kinuna ni Abimelec kenni Abraham, “Ania ti kayat a sawen dagitoy pito a babbai a karnero nga inlasinmo?
30 Ó dalóhùn pé, “Gba àwọn abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí lọ́wọ́ mi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”
Simmungbat isuna, “Dagitoy pito a babai a karnero ket awatem manipud iti imak, tapno agbalin a saksi para kaniak, a kinalik daytoy a bubon.
31 Nítorí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ náà ni Beerṣeba nítorí níbẹ̀ ni àwọn méjèèjì gbé búra.
Isu nga inawaganna dayta a lugar iti Beerseba, gaputa ta nagkinnarida a dua.
32 Lẹ́yìn májẹ̀mú tí wọ́n dá ní Beerṣeba yìí, ni Abimeleki àti Fikoli olórí ogun rẹ̀ padà sí ilẹ̀ àwọn ará Filistini.
Nagtulagda idiay Beerseba, ket kalpasanna, nagsubli ni Abimelec ken ni Picol a kapitan ti armadana iti daga dagiti Filisteo.
33 Abrahamu lọ́ igi tamariski kan sí Beerṣeba, níbẹ̀ ni ó sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run ayérayé.
Nagmula ni Abraham iti kayo a tamarisko idiay Beerseba. Sadiay, nagdayaw isuna kenni Yahweh, ti agnanayon a Dios.
34 Abrahamu sì gbé ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọjọ́ pípẹ́.
Nagtalinaed a gangannaet ni Abraham iti daga dagiti Filisteo iti adu nga al-aldaw.

< Genesis 21 >