< Genesis 21 >

1 Olúwa sì bẹ Sara wò bí ó ti wí, Olúwa sì ṣe fún Sara gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
Nake Jehova agĩtuga Sara o ta ũrĩa oigĩte, na Jehova akĩhingĩria Sara kĩrĩkanĩro kĩrĩa aamwĩrĩire.
2 Sara sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Abrahamu ní ọjọ́ ogbó rẹ̀, ní àkókò náà gan an tí Ọlọ́run ti ṣèlérí fún un.
Sara akĩgĩa nda, na agĩciarĩra Iburahĩmu kaana ga kahĩĩ ũkũrũ-inĩ wake, o ihinda rĩrĩa Jehova aamwĩrĩte.
3 Abrahamu sì sọ orúkọ ọmọ náà tí Sara bí fun un ní Isaaki.
Iburahĩmu agĩtua kaana kau ga kahĩĩ aaciarĩirwo nĩ Sara, Isaaka.
4 Nígbà tí Isaaki pé ọmọ ọjọ́ mẹ́jọ, Abrahamu sì kọ ọ́ ní ilà gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un.
Na rĩrĩa mũriũ ũcio wake Isaaka akinyirie thikũ inyanya-rĩ, Iburahĩmu akĩmũruithia, o ta ũrĩa Ngai aamwathĩte.
5 Ẹni ọgọ́rùn-ún ọdún ni Abrahamu nígbà tí ó bí Isaaki.
Iburahĩmu aarĩ na mĩaka igana rĩmwe rĩrĩa mũriũ wake Isaaka aaciarirwo.
6 Sara sì wí pé, “Ọlọ́run ti pa mí lẹ́rìn-ín. Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ pé mo bímọ yóò rẹ́rìn-ín pẹ̀lú mi.”
Sara akiuga atĩrĩ, “Ngai nĩatũmĩte theke, na mũndũ o wothe ũrĩiguaga ũhoro ũcio nĩarĩthekaga hamwe na niĩ.”
7 Ó sì fi kún un pé, “Ta ni ó le sọ fún Abrahamu pé, Sara yóò di ọlọ́mọ? Síbẹ̀síbẹ̀, mo sì tún bí ọmọ fún Abrahamu ní ìgbà ogbó rẹ.”
Agĩcooka akiuga atĩrĩ, “Nũũ ũngĩerire Iburahĩmu atĩ Sara nĩakongithia ciana? No rĩrĩ, nĩndĩmũciarĩire kaana ga kahĩĩ ũkũrũ-inĩ wake.”
8 Nígbà tí ọmọ náà dàgbà, ó sì gbà á lẹ́nu ọmú, ní ọjọ́ tí a gba Isaaki lẹ́nu ọmú, Abrahamu ṣe àsè ńlá.
Nako kaana kau gagĩkũra na gagĩtigithio kuonga; naguo mũthenya ũrĩa Isaaka aatigithirio kuonga-rĩ, Iburahĩmu akĩrugithia iruga inene.
9 Ṣùgbọ́n Sara rí ọmọ Hagari ará Ejibiti tí ó bí fún Abrahamu tí ó fi ṣe ẹlẹ́yà,
No Sara akĩona atĩ mũriũ wa Hagari ũrĩa Mũmisiri aaciarĩire Iburahĩmu aarĩ na kĩnyũrũri.
10 ó sì wí fún Abrahamu pé, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrú yìí kò ní bá ọmọ mi Isaaki pín ogún.”
Nake akĩĩra Iburahĩmu atĩrĩ, “Ingata ngombo ĩno ya mũndũ-wa-nja hamwe na mũriũ, tondũ mũriũ ũcio wa ngombo ĩyo ya mũndũ-wa-nja ndakagayana igai na mũriũ wakwa Isaaka.”
11 Ọ̀rọ̀ náà sì ba Abrahamu lọ́kàn jẹ́ gidigidi nítorí ọmọ rẹ̀ náà sá à ni Iṣmaeli i ṣe.
Naguo ũhoro ũcio ũgĩthĩĩnia Iburahĩmu mũno tondũ wakoniĩ mũriũ.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fun Abrahamu pé, “Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí ọmọ náà àti ẹrúbìnrin rẹ. Gbọ́ ohun tí Sara wí fún ọ, nítorí nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.
No Ngai akĩmwĩra atĩrĩ, “Tiga gũthĩĩnĩka mũno nĩ ũndũ wa kĩmwana kĩu, na ndungata ĩyo yaku ya mũndũ-wa-nja. Thikĩrĩria ũrĩa wothe Sara egũkwĩra, tondũ rũciaro rũrĩa rũgeetanio nawe rũkoima harĩ Isaaka.
13 Èmi yóò sọ ọmọ ẹrúbìnrin náà di orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, nítorí ọmọ rẹ ni.”
O na ningĩ nĩngatũma mũriũ wa ndungata ĩyo ya mũndũ-wa-nja atuĩke rũrĩrĩ rũnene, tondũ nĩ rũciaro rwaku.”
14 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mú oúnjẹ àti ìgò omi kan, ó sì kó wọn fún Hagari, ó kó wọn lé e léjìká, ó sì lé e jáde pẹ̀lú ọmọ náà. Ó sì lọ lọ́nà rẹ, ó sì ń ṣe alárìnkiri ní ijù Beerṣeba.
Mũthenya ũyũ ũngĩ rũciinĩ tene Iburahĩmu akĩoya irio na mondo ya rũũa ĩrĩ na maaĩ, na agĩcinengera Hagari. Akĩmũigĩrĩra ciande-inĩ ciake, agĩcooka akĩmumagaria hamwe na kĩmwana kĩu. Nake Hagari agĩĩthiĩra, na agĩturĩrwo nĩ njĩra arĩ kũu werũ-inĩ wa Birishiba.
15 Nígbà tí omi inú ìgò náà tan, ó gbé ọmọ náà sí abẹ́ igbó.
Na rĩrĩa maaĩ marĩa maarĩ rũũa-inĩ maathirire-rĩ, Hagari akĩiga kĩmwana kĩu rungu rwa kĩhinga kĩmwe.
16 Ó sì lọ, ó sì jókòó nítòsí ibẹ̀, níwọ̀n bí ìtafà kan, nítorí, ó rò ó nínú ara rẹ̀ pé, “Èmi kò fẹ́ wo bí ọmọ náà yóò ṣe kú.” Bí ó sì ti jókòó sí tòsí ibẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
Nake agĩthiiathiia, agĩikara thĩ handũ hataarĩ haraihu, ta ha rĩikia rĩa mũguĩ, tondũ eeciiririe atĩrĩ, “Ndingĩĩrorera kĩmwana gĩakwa gĩgĩkua.” Na aikarĩte hau hakuhĩ, akĩambĩrĩria kũgirĩka.
17 Ọlọ́run gbọ́ ohun ẹkún náà, Angẹli Ọlọ́run sì pe Hagari láti ọ̀run, ó sì wí fun un pé, “Hagari, kín ni ó ṣe ọ́? Má bẹ̀rù nítorí Ọlọ́run ti gbọ́ ẹkún ọmọ náà níbi tí o tẹ́ ẹ sí.
Nake Ngai akĩigua kĩmwana kĩu gĩkĩrĩra, nake mũraika wa Ngai agĩĩta Hagari arĩ kũu igũrũ akĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ kĩragũthĩĩnia Hagari? Tiga gwĩtigĩra; Ngai nĩaiguĩte kĩrĩro gĩa kĩmwana kĩu kĩrĩ o hau kĩrĩ.
18 Dìde, gbé ọmọ náà sókè, kí o sì dìímú (tù ú nínú) nítorí èmi yóò sọ ọmọ náà di orílẹ̀-èdè ńlá.”
Tiira kĩmwana kĩu na igũrũ, na ũkĩnyiitĩrĩre na guoko, nĩgũkorwo nĩngagĩtua rũrĩrĩ rũnene.”
19 Ọlọ́run sì ṣí ojú Hagari, ó sì rí kànga kan, ó lọ síbẹ̀, ó rọ omi kún inú ìgò náà, ó sì fún ọmọ náà mu.
Hĩndĩ ĩyo Ngai akĩmũhingũra maitho, nake akĩona gĩthima kĩa maaĩ. Agĩthiĩ ho, akĩiyũria rũũa maaĩ, na akĩhe kĩmwana kĩu kĩnyue.
20 Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú ọmọ náà bí ó ti ń dàgbà, ó ń gbé nínú ijù, ó sì di tafàtafà.
Ngai nĩakorirwo hamwe na kĩmwana kĩu o ũrĩa gĩakũraga. Gĩatũũrire werũ-inĩ, na gĩgĩtuĩka mũrathi na ũta.
21 Nígbà tí ó ń gbé ni aginjù ní Parani, ìyá rẹ̀ fẹ́ ìyàwó fún un láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
Hĩndĩ ĩyo aatũũraga Werũ-inĩ wa Parani-rĩ, nyina akĩmwethera mũtumia kuuma Misiri.
22 Ní àkókò yìí ni ọba Abimeleki àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀ wí fún Abrahamu pé, “Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo ohun tí ó ń ṣe.
Ihinda-inĩ-rĩu Abimeleku na Fikolu mũnene wa mbũtũ ciake cia ita makĩĩra Iburahĩmu atĩrĩ, “Ngai arĩ hamwe nawe maũndũ-inĩ mothe marĩa wĩkaga.
23 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, fi Ọlọ́run búra fún mi, ìwọ kì yóò tàn mí àti àwọn ọmọ mi àti àwọn ìran mi, ìwọ yóò fi inú rere hàn fún mi àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti ṣe àtìpó, bí mo ti fihàn fún ọ pẹ̀lú.”
Rĩu-rĩ, wĩhĩte ũrĩ mbere ya Ngai atĩ ndũkanjuukanĩrĩra, kana ũcuukanĩre ciana ciakwa, o na kana njiaro ciakwa. Nyonagia ũtugi niĩ na bũrũri ũyũ we ũtũũraga ũrĩ mũgeni o ta ũrĩa niĩ nguonetie ũtugi.”
24 Abrahamu sì wí pé, “Èmí búra.”
Iburahĩmu agĩcookia atĩrĩ, “Nĩndehĩta.”
25 Nígbà náà ni Abrahamu fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn fún Abimeleki nípa kànga tí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ gbà lọ́wọ́ rẹ̀.
Ningĩ Iburahĩmu agĩtetia Abimeleku nĩ ũndũ wa gĩthima kĩa maaĩ kĩrĩa ndungata cia Abimeleku ciamũtunyĩte.
26 Ṣùgbọ́n Abimeleki dáhùn pé, “Èmi kò mọ ẹni tí ó ṣe nǹkan yìí. Ìwọ kò sì sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbọ́, bí kò ṣe lónìí.”
No Abimeleku akiuga atĩrĩ, “Ndiũĩ nũũ wĩkĩte ũndũ ũcio. Wee ndwanjĩĩrire, na ndaigua ũhoro ũcio ũmũthĩ.”
27 Abrahamu sì mú àgùntàn àti màlúù wá, ó sì kó wọn fún Abimeleki. Àwọn méjèèjì sì dá májẹ̀mú.
Nĩ ũndũ ũcio Iburahĩmu akĩrehe ngʼondu na ngʼombe akĩhe Abimeleku, nao andũ acio eerĩ makĩgĩa na kĩrĩkanĩro.
28 Abrahamu sì ya abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje nínú agbo àgùntàn rẹ̀ sọ́tọ̀.
Iburahĩmu akĩamũra mĩatĩ mũgwanja kuuma rũũru-inĩ rwake.
29 Abimeleki sì béèrè lọ́wọ́ Abrahamu pé, “Kín ni ìtumọ̀ yíyà tí ìwọ ya àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí sọ́tọ̀ sí.”
Nake Abimeleku akĩũria Iburahĩmu atĩrĩ, “Mĩatĩ ĩno mũgwanja-rĩ, wamĩamũra kuuma rũũru-inĩ nĩkĩ?”
30 Ó dalóhùn pé, “Gba àwọn abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí lọ́wọ́ mi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”
Iburahĩmu akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ĩtĩkĩra kuoya mĩatĩ ĩno mũgwanja kuuma kũrĩ niĩ, ĩtuĩke ũira atĩ nĩ niĩ ndenjire gĩthima gĩkĩ.”
31 Nítorí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ náà ni Beerṣeba nítorí níbẹ̀ ni àwọn méjèèjì gbé búra.
Tondũ ũcio handũ hau hagĩĩtwo Birishiba tondũ hau nĩ ho andũ acio eerĩ mehĩtĩire mwĩhĩtwa.
32 Lẹ́yìn májẹ̀mú tí wọ́n dá ní Beerṣeba yìí, ni Abimeleki àti Fikoli olórí ogun rẹ̀ padà sí ilẹ̀ àwọn ará Filistini.
Thuutha wa kũrĩkanĩra kĩrĩĩko kĩu kũu Birishiba, Abimeleku na Fikolu mũnene wa mbũtũ ciake cia ita, magĩcooka bũrũri wa Afilisti.
33 Abrahamu lọ́ igi tamariski kan sí Beerṣeba, níbẹ̀ ni ó sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run ayérayé.
Nake Iburahĩmu akĩhaanda mũtĩ wa mũbinde kũu Birishiba, na agĩkaĩra rĩĩtwa rĩa Jehova, o we Mũrungu Ũrĩa-Ũtũũraga-Tene-na-Tene, arĩ handũ hau.
34 Abrahamu sì gbé ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọjọ́ pípẹ́.
Nake Iburahĩmu agĩikara bũrũri-inĩ ũcio wa Afilisti ihinda iraaya ma.

< Genesis 21 >