< Genesis 21 >

1 Olúwa sì bẹ Sara wò bí ó ti wí, Olúwa sì ṣe fún Sara gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
L'Éternel visita Sara comme il l'avait dit, et l'Éternel fit à Sara ce qu'il avait dit.
2 Sara sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Abrahamu ní ọjọ́ ogbó rẹ̀, ní àkókò náà gan an tí Ọlọ́run ti ṣèlérí fún un.
Sara devint enceinte, et elle enfanta un fils à Abraham dans sa vieillesse, au temps fixé dont Dieu lui avait parlé.
3 Abrahamu sì sọ orúkọ ọmọ náà tí Sara bí fun un ní Isaaki.
Abraham appela Isaac le fils qui lui était né, et que Sara lui avait enfanté.
4 Nígbà tí Isaaki pé ọmọ ọjọ́ mẹ́jọ, Abrahamu sì kọ ọ́ ní ilà gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un.
Abraham circoncit son fils Isaac, à l'âge de huit jours, comme Dieu le lui avait ordonné.
5 Ẹni ọgọ́rùn-ún ọdún ni Abrahamu nígbà tí ó bí Isaaki.
Abraham était âgé de cent ans lorsque son fils Isaac lui est né.
6 Sara sì wí pé, “Ọlọ́run ti pa mí lẹ́rìn-ín. Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ pé mo bímọ yóò rẹ́rìn-ín pẹ̀lú mi.”
Sara dit: « Dieu m'a fait rire. Tous ceux qui l'entendent riront avec moi ».
7 Ó sì fi kún un pé, “Ta ni ó le sọ fún Abrahamu pé, Sara yóò di ọlọ́mọ? Síbẹ̀síbẹ̀, mo sì tún bí ọmọ fún Abrahamu ní ìgbà ogbó rẹ.”
Elle dit: « Qui aurait dit à Abraham que Sara allaiterait des enfants? Car je lui ai enfanté un fils dans sa vieillesse. »
8 Nígbà tí ọmọ náà dàgbà, ó sì gbà á lẹ́nu ọmú, ní ọjọ́ tí a gba Isaaki lẹ́nu ọmú, Abrahamu ṣe àsè ńlá.
L'enfant grandit et fut sevré. Abraham fit un grand festin le jour où Isaac fut sevré.
9 Ṣùgbọ́n Sara rí ọmọ Hagari ará Ejibiti tí ó bí fún Abrahamu tí ó fi ṣe ẹlẹ́yà,
Sara vit le fils d'Agar l'Égyptienne, qu'elle avait porté à Abraham, se moquer.
10 ó sì wí fún Abrahamu pé, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrú yìí kò ní bá ọmọ mi Isaaki pín ogún.”
Elle dit alors à Abraham: « Chasse cette servante et son fils! Car le fils de cette servante ne sera pas héritier de mon fils Isaac. »
11 Ọ̀rọ̀ náà sì ba Abrahamu lọ́kàn jẹ́ gidigidi nítorí ọmọ rẹ̀ náà sá à ni Iṣmaeli i ṣe.
La chose fut très pénible aux yeux d'Abraham, à cause de son fils.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fun Abrahamu pé, “Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí ọmọ náà àti ẹrúbìnrin rẹ. Gbọ́ ohun tí Sara wí fún ọ, nítorí nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.
Dieu dit à Abraham: « Que la chose ne soit pas pénible à tes yeux à cause de l'enfant et à cause de ta servante. Dans tout ce que Sarah te dira, écoute sa voix. Car ta descendance sera nommée par Isaac.
13 Èmi yóò sọ ọmọ ẹrúbìnrin náà di orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, nítorí ọmọ rẹ ni.”
Je ferai aussi une nation du fils de l'esclave, car il est ton enfant. »
14 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mú oúnjẹ àti ìgò omi kan, ó sì kó wọn fún Hagari, ó kó wọn lé e léjìká, ó sì lé e jáde pẹ̀lú ọmọ náà. Ó sì lọ lọ́nà rẹ, ó sì ń ṣe alárìnkiri ní ijù Beerṣeba.
Abraham se leva de bon matin, prit du pain et un récipient d'eau, et les donna à Agar, en les mettant sur son épaule; il lui donna l'enfant, et la renvoya. Elle partit, et erra dans le désert de Beer Schéba.
15 Nígbà tí omi inú ìgò náà tan, ó gbé ọmọ náà sí abẹ́ igbó.
L'eau du récipient fut épuisée, et elle mit l'enfant sous un des arbustes.
16 Ó sì lọ, ó sì jókòó nítòsí ibẹ̀, níwọ̀n bí ìtafà kan, nítorí, ó rò ó nínú ara rẹ̀ pé, “Èmi kò fẹ́ wo bí ọmọ náà yóò ṣe kú.” Bí ó sì ti jókòó sí tòsí ibẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
Elle alla s'asseoir en face de lui, à bonne distance, à environ un coup d'arc. Car elle disait: « Ne me laisse pas voir la mort de l'enfant. » Elle s'assit en face de lui, éleva la voix et pleura.
17 Ọlọ́run gbọ́ ohun ẹkún náà, Angẹli Ọlọ́run sì pe Hagari láti ọ̀run, ó sì wí fun un pé, “Hagari, kín ni ó ṣe ọ́? Má bẹ̀rù nítorí Ọlọ́run ti gbọ́ ẹkún ọmọ náà níbi tí o tẹ́ ẹ sí.
Dieu entendit la voix de l'enfant. L'ange de Dieu appela Hagar du ciel et lui dit: « Qu'est-ce qui te trouble, Hagar? N'aie pas peur. Car Dieu a entendu la voix de l'enfant là où il est.
18 Dìde, gbé ọmọ náà sókè, kí o sì dìímú (tù ú nínú) nítorí èmi yóò sọ ọmọ náà di orílẹ̀-èdè ńlá.”
Lève-toi, soulève l'enfant, et tiens-le avec ta main. Car je ferai de lui une grande nation. »
19 Ọlọ́run sì ṣí ojú Hagari, ó sì rí kànga kan, ó lọ síbẹ̀, ó rọ omi kún inú ìgò náà, ó sì fún ọmọ náà mu.
Dieu lui ouvrit les yeux, et elle vit un puits d'eau. Elle y alla, remplit le récipient d'eau et donna à boire au garçon.
20 Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú ọmọ náà bí ó ti ń dàgbà, ó ń gbé nínú ijù, ó sì di tafàtafà.
Dieu était avec le garçon, et il grandit. Il vécut dans le désert, et, en grandissant, il devint archer.
21 Nígbà tí ó ń gbé ni aginjù ní Parani, ìyá rẹ̀ fẹ́ ìyàwó fún un láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
Il habita dans le désert de Paran. Sa mère lui trouva une femme du pays d'Égypte.
22 Ní àkókò yìí ni ọba Abimeleki àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀ wí fún Abrahamu pé, “Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo ohun tí ó ń ṣe.
En ce temps-là, Abimélec et Phicol, le chef de son armée, parlèrent à Abraham en disant: « Dieu est avec toi dans tout ce que tu fais.
23 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, fi Ọlọ́run búra fún mi, ìwọ kì yóò tàn mí àti àwọn ọmọ mi àti àwọn ìran mi, ìwọ yóò fi inú rere hàn fún mi àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti ṣe àtìpó, bí mo ti fihàn fún ọ pẹ̀lú.”
Maintenant, jure-moi ici par Dieu que tu ne me tromperas pas, ni mon fils, ni le fils de mon fils. Mais selon la bonté que j'ai eue pour toi, tu me feras la même chose qu'au pays dans lequel tu as vécu comme étranger. »
24 Abrahamu sì wí pé, “Èmí búra.”
Abraham répondit: « Je le jurerai. »
25 Nígbà náà ni Abrahamu fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn fún Abimeleki nípa kànga tí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ gbà lọ́wọ́ rẹ̀.
Abraham se plaignit à Abimélec à cause d'un puits d'eau que les serviteurs d'Abimélec avaient violemment enlevé.
26 Ṣùgbọ́n Abimeleki dáhùn pé, “Èmi kò mọ ẹni tí ó ṣe nǹkan yìí. Ìwọ kò sì sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbọ́, bí kò ṣe lónìí.”
Abimélec répondit: « Je ne sais pas qui a fait cela. Tu ne me l'as pas dit, et je n'en ai entendu parler qu'aujourd'hui. »
27 Abrahamu sì mú àgùntàn àti màlúù wá, ó sì kó wọn fún Abimeleki. Àwọn méjèèjì sì dá májẹ̀mú.
Abraham prit des moutons et du bétail, et les donna à Abimélec. Ces deux-là firent une alliance.
28 Abrahamu sì ya abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje nínú agbo àgùntàn rẹ̀ sọ́tọ̀.
Abraham mit à part sept agnelles du troupeau.
29 Abimeleki sì béèrè lọ́wọ́ Abrahamu pé, “Kín ni ìtumọ̀ yíyà tí ìwọ ya àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí sọ́tọ̀ sí.”
Abimélec dit à Abraham: « Que signifient ces sept agnelles que tu as mises à part? »
30 Ó dalóhùn pé, “Gba àwọn abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí lọ́wọ́ mi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”
Il dit: « Tu prendras ces sept agnelles de ma main, afin que cela me serve de témoignage que j'ai creusé ce puits. »
31 Nítorí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ náà ni Beerṣeba nítorí níbẹ̀ ni àwọn méjèèjì gbé búra.
Il appela ce lieu Beersheba, car ils y firent tous deux un serment.
32 Lẹ́yìn májẹ̀mú tí wọ́n dá ní Beerṣeba yìí, ni Abimeleki àti Fikoli olórí ogun rẹ̀ padà sí ilẹ̀ àwọn ará Filistini.
Ils firent donc alliance à Beersheba. Abimélec se leva avec Phicol, le chef de son armée, et ils retournèrent au pays des Philistins.
33 Abrahamu lọ́ igi tamariski kan sí Beerṣeba, níbẹ̀ ni ó sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run ayérayé.
Abraham planta un tamaris à Beersheba, et là, il invoqua le nom de Yahvé, le Dieu de l'éternité.
34 Abrahamu sì gbé ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọjọ́ pípẹ́.
Abraham vécut longtemps comme un étranger dans le pays des Philistins.

< Genesis 21 >