< Genesis 21 >

1 Olúwa sì bẹ Sara wò bí ó ti wí, Olúwa sì ṣe fún Sara gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
Ja Herra etsei Saaraa, niinkuin hän sanonut oli: ja Herra teki Saaralle niinkuin hän puhunut oli.
2 Sara sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Abrahamu ní ọjọ́ ogbó rẹ̀, ní àkókò náà gan an tí Ọlọ́run ti ṣèlérí fún un.
Ja Saara tuli raskaaksi, ja synnytti Abrahamille pojan hänen vanhuudessansa; sillä ajalla kuin Jumala hänelle sanonut oli.
3 Abrahamu sì sọ orúkọ ọmọ náà tí Sara bí fun un ní Isaaki.
Ja Abraham kutsui poikansa nimen, joka hänelle syntynyt oli, ja jonka Saara hänelle synnyttänyt oli, Isaak.
4 Nígbà tí Isaaki pé ọmọ ọjọ́ mẹ́jọ, Abrahamu sì kọ ọ́ ní ilà gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un.
Ja Abraham ympärileikkasi poikansa Isaakin kahdeksan päiväisenä: niinkuin Jumala hänen käskenyt oli.
5 Ẹni ọgọ́rùn-ún ọdún ni Abrahamu nígbà tí ó bí Isaaki.
Ja Abraham oli sadan ajastaikainen, koska Isaak hänen poikansa hänelle syntyi.
6 Sara sì wí pé, “Ọlọ́run ti pa mí lẹ́rìn-ín. Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ pé mo bímọ yóò rẹ́rìn-ín pẹ̀lú mi.”
Ja Saara sanoi: Jumala on tehnyt minulle nauron: kuka ikänä sen saa kuulla, hän nauraa minua.
7 Ó sì fi kún un pé, “Ta ni ó le sọ fún Abrahamu pé, Sara yóò di ọlọ́mọ? Síbẹ̀síbẹ̀, mo sì tún bí ọmọ fún Abrahamu ní ìgbà ogbó rẹ.”
Ja sanoi vielä: kuka olis taitanut sanoa Abrahamille: Saara on lapsia imettävä; sillä minä olen synnyttänyt pojan hänen vanhuudessansa.
8 Nígbà tí ọmọ náà dàgbà, ó sì gbà á lẹ́nu ọmú, ní ọjọ́ tí a gba Isaaki lẹ́nu ọmú, Abrahamu ṣe àsè ńlá.
Ja lapsi kasvoi ja vieroitettiin: ja Abraham teki suuren pidon sinä päivänä, jona Isaak vieroitettiin.
9 Ṣùgbọ́n Sara rí ọmọ Hagari ará Ejibiti tí ó bí fún Abrahamu tí ó fi ṣe ẹlẹ́yà,
Ja Saara näki Egyptiläisen Hagarin pojan, jonka se Abrahamille synnyttänyt oli, pilkkaajaksi.
10 ó sì wí fún Abrahamu pé, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrú yìí kò ní bá ọmọ mi Isaaki pín ogún.”
Ja sanoi Abrahamille: aja ulos tämä palkkavaimo poikinensa: sillä palkkavaimon pojan ei pidä perimän minun poikani Isaakin kanssa.
11 Ọ̀rọ̀ náà sì ba Abrahamu lọ́kàn jẹ́ gidigidi nítorí ọmọ rẹ̀ náà sá à ni Iṣmaeli i ṣe.
Ja tämä sana oli Abrahamin mielestä sangen karvas, hänen poikansa tähden.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fun Abrahamu pé, “Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí ọmọ náà àti ẹrúbìnrin rẹ. Gbọ́ ohun tí Sara wí fún ọ, nítorí nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.
Mutta Jumala sanoi Abrahamille: älä ota sitä pahakses pojasta ja palkkapiiastas: kaikki mitä Saara sinulle sanoo, niin kuule häntä: sillä Isaakissa pitää sinulle siemen kutsuttaman.
13 Èmi yóò sọ ọmọ ẹrúbìnrin náà di orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, nítorí ọmọ rẹ ni.”
Minä teen myös piikas pojan (suureksi) kansaksi; että hän sinun siemenes on.
14 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mú oúnjẹ àti ìgò omi kan, ó sì kó wọn fún Hagari, ó kó wọn lé e léjìká, ó sì lé e jáde pẹ̀lú ọmọ náà. Ó sì lọ lọ́nà rẹ, ó sì ń ṣe alárìnkiri ní ijù Beerṣeba.
Niin nousi Abraham aamulla varhain, ja otti leipiä ja vesileilin; ja antoi Hagarille, ja pani hänen selkäänsä, ja (antoi hänelle) pojan, ja laski hänen menemään. Ja hän meni matkaansa, ja eksyi BerSaban korvessa.
15 Nígbà tí omi inú ìgò náà tan, ó gbé ọmọ náà sí abẹ́ igbó.
Koska vesi oli loppunut leilistä, heitti hän pojan puun alle.
16 Ó sì lọ, ó sì jókòó nítòsí ibẹ̀, níwọ̀n bí ìtafà kan, nítorí, ó rò ó nínú ara rẹ̀ pé, “Èmi kò fẹ́ wo bí ọmọ náà yóò ṣe kú.” Bí ó sì ti jókòó sí tòsí ibẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
Ja meni pois, ja istui hänen kohdallensa taamma, liki joutsen kantamalle; sillä hän sanoi: en minä voi nähdä pojan kuolemaa. Ja hän istui hänen kohdallensa, korotti äänensä ja itki.
17 Ọlọ́run gbọ́ ohun ẹkún náà, Angẹli Ọlọ́run sì pe Hagari láti ọ̀run, ó sì wí fun un pé, “Hagari, kín ni ó ṣe ọ́? Má bẹ̀rù nítorí Ọlọ́run ti gbọ́ ẹkún ọmọ náà níbi tí o tẹ́ ẹ sí.
Ja Jumala kuuli pojan äänen, ja Jumalan enkeli huusi Hagaria taivaasta, ja sanoi hänelle: mikä sinun on, Hagar? älä pelkää; sillä Jumala on kuullut pojan äänen, kussa hän makaa.
18 Dìde, gbé ọmọ náà sókè, kí o sì dìímú (tù ú nínú) nítorí èmi yóò sọ ọmọ náà di orílẹ̀-èdè ńlá.”
Nouse, ota poika, ja tue häntä kädelläs: sillä minä teen hänen suureksi kansaksi.
19 Ọlọ́run sì ṣí ojú Hagari, ó sì rí kànga kan, ó lọ síbẹ̀, ó rọ omi kún inú ìgò náà, ó sì fún ọmọ náà mu.
Ja Jumala avasi hänen silmänsä, että hän näki vesikaivon; niin hän meni ja täytti leilin vedellä, ja antoi pojan juoda.
20 Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú ọmọ náà bí ó ti ń dàgbà, ó ń gbé nínú ijù, ó sì di tafàtafà.
Ja Jumala oli pojan kanssa, ja hän kasvoi; ja asui korvessa, ja tuli tarkaksi joutsimieheksi.
21 Nígbà tí ó ń gbé ni aginjù ní Parani, ìyá rẹ̀ fẹ́ ìyàwó fún un láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
Ja asui Paranin korvessa; ja hänen äitinsä otti hänelle emännän Egyptin maalta.
22 Ní àkókò yìí ni ọba Abimeleki àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀ wí fún Abrahamu pé, “Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo ohun tí ó ń ṣe.
Sillä ajalla puhui Abimelek ja hänen sotapäämiehensä Phikol Abrahamille, sanoen: Jumala on sinun kanssas kaikissa mitä sinä teet.
23 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, fi Ọlọ́run búra fún mi, ìwọ kì yóò tàn mí àti àwọn ọmọ mi àti àwọn ìran mi, ìwọ yóò fi inú rere hàn fún mi àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti ṣe àtìpó, bí mo ti fihàn fún ọ pẹ̀lú.”
Niin vanno nyt minulle tässä Jumalan kautta, ettes ole minulle, ja minun pojalleni, ja poikanipojalle petollinen; vaan sen laupiuden jälkeen, jonka minä tein sinun kanssas, tee sinä myös minun kanssani, ja sen maan kanssa, jossa sinä olet muukalainen.
24 Abrahamu sì wí pé, “Èmí búra.”
Niin sanoi Abraham: minä vannon.
25 Nígbà náà ni Abrahamu fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn fún Abimeleki nípa kànga tí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ gbà lọ́wọ́ rẹ̀.
Ja Abraham nuhteli Abimelekiä, sen vesikaivon tähden, kun Abimelekin palveliat olivat väkivallalla ottaneet.
26 Ṣùgbọ́n Abimeleki dáhùn pé, “Èmi kò mọ ẹni tí ó ṣe nǹkan yìí. Ìwọ kò sì sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbọ́, bí kò ṣe lónìí.”
Ja Abimelek sanoi: en ole minä tietänyt kuka sen teki; etkä sinä ilmoittanut minulle; enkä minä sitä ole ennen kuullut, kuin tänä päivänä.
27 Abrahamu sì mú àgùntàn àti màlúù wá, ó sì kó wọn fún Abimeleki. Àwọn méjèèjì sì dá májẹ̀mú.
Niin otti Abraham lampaita ja karjaa, ja antoi Abimelekille; ja he tekivät molemmat liiton keskenänsä.
28 Abrahamu sì ya abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje nínú agbo àgùntàn rẹ̀ sọ́tọ̀.
Ja Abraham asetti seitsemän karitsaa laumasta erinänsä.
29 Abimeleki sì béèrè lọ́wọ́ Abrahamu pé, “Kín ni ìtumọ̀ yíyà tí ìwọ ya àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí sọ́tọ̀ sí.”
Ja Abimelek sanoi Abrahamille: mihinkä ne seitsemän karitsaa, jotkas olet asettanut erinänsä?
30 Ó dalóhùn pé, “Gba àwọn abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí lọ́wọ́ mi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”
Hän vastasi: nämät seitsemän karitsaa pitää sinun ottaman minun kädestäni, todistukseksi minulle, että minä olen tämän kaivon kaivanut.
31 Nítorí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ náà ni Beerṣeba nítorí níbẹ̀ ni àwọn méjèèjì gbé búra.
Sentähden kutsui hän sen sian BerSaba: sillä siinä he molemmat vannoivat keskenänsä.
32 Lẹ́yìn májẹ̀mú tí wọ́n dá ní Beerṣeba yìí, ni Abimeleki àti Fikoli olórí ogun rẹ̀ padà sí ilẹ̀ àwọn ará Filistini.
Ja niin he tekivät liiton BerSabassa. Ja Abimelek nousi ja Phikol hänen sotapäämiehensä, ja palasivat Philistealaisten maalle.
33 Abrahamu lọ́ igi tamariski kan sí Beerṣeba, níbẹ̀ ni ó sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run ayérayé.
Ja Abraham istutti puita BerSabassa; ja saarnasi siinä Herran ijankaikkisen Jumalan nimestä.
34 Abrahamu sì gbé ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọjọ́ pípẹ́.
Ja oli muukalainen Philistealaisten maalla kauvan aikaa.

< Genesis 21 >