< Genesis 21 >

1 Olúwa sì bẹ Sara wò bí ó ti wí, Olúwa sì ṣe fún Sara gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
The lorde visyted Sara as he had sayde and dyd vnto her acordynge as he had spoken.
2 Sara sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Abrahamu ní ọjọ́ ogbó rẹ̀, ní àkókò náà gan an tí Ọlọ́run ti ṣèlérí fún un.
And Sara was with childe and bare Abraha a sonne in his olde age euen the same season which the LORde had appoynted.
3 Abrahamu sì sọ orúkọ ọmọ náà tí Sara bí fun un ní Isaaki.
And Abraham called his sonnes name that was borne vnto him which Sara bare him Isaac:
4 Nígbà tí Isaaki pé ọmọ ọjọ́ mẹ́jọ, Abrahamu sì kọ ọ́ ní ilà gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un.
and Abra circucysed Isaac his sone whe he was. viij. dayes olde as God commaunded him
5 Ẹni ọgọ́rùn-ún ọdún ni Abrahamu nígbà tí ó bí Isaaki.
And Abraha was an hundred yere olde when his sonne Isaac was borne vnto him.
6 Sara sì wí pé, “Ọlọ́run ti pa mí lẹ́rìn-ín. Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ pé mo bímọ yóò rẹ́rìn-ín pẹ̀lú mi.”
And Sara sayde: God hath made me a laughinge stocke: for all yt heare will laugh at me
7 Ó sì fi kún un pé, “Ta ni ó le sọ fún Abrahamu pé, Sara yóò di ọlọ́mọ? Síbẹ̀síbẹ̀, mo sì tún bí ọmọ fún Abrahamu ní ìgbà ogbó rẹ.”
She sayde also: who wolde haue sayde vnto Abraham that Sara shulde haue geuen childern sucke or yt I shulde haue borne him a sonne in his olde age:
8 Nígbà tí ọmọ náà dàgbà, ó sì gbà á lẹ́nu ọmú, ní ọjọ́ tí a gba Isaaki lẹ́nu ọmú, Abrahamu ṣe àsè ńlá.
The childe grewe and was wened and Abraham made a great feast the same daye that Isaac was wened.
9 Ṣùgbọ́n Sara rí ọmọ Hagari ará Ejibiti tí ó bí fún Abrahamu tí ó fi ṣe ẹlẹ́yà,
Sara sawe the sonne of Hagar the Egiptian which she had borne vnto Abraham a mockynge.
10 ó sì wí fún Abrahamu pé, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrú yìí kò ní bá ọmọ mi Isaaki pín ogún.”
Then she sayde vnto Abraham: put awaye this bondemayde and hyr sonne: for the sonne of this bondwoman shall not be heyre with my sonne Isaac:
11 Ọ̀rọ̀ náà sì ba Abrahamu lọ́kàn jẹ́ gidigidi nítorí ọmọ rẹ̀ náà sá à ni Iṣmaeli i ṣe.
But the wordes semed verey greavous in Abrahams syghte because of his sonne.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fun Abrahamu pé, “Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí ọmọ náà àti ẹrúbìnrin rẹ. Gbọ́ ohun tí Sara wí fún ọ, nítorí nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.
Than the LORde sayde vnto Abraham: let it not be greavous vnto the because of the ladd and of thy bondmayde: But in all that Sara hath saide vnto the heare hir voyce for in Isaac shall thy seed be called.
13 Èmi yóò sọ ọmọ ẹrúbìnrin náà di orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, nítorí ọmọ rẹ ni.”
Moreouer of the sonne of the Bondwoman will I make a nation because he is thy seed.
14 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mú oúnjẹ àti ìgò omi kan, ó sì kó wọn fún Hagari, ó kó wọn lé e léjìká, ó sì lé e jáde pẹ̀lú ọmọ náà. Ó sì lọ lọ́nà rẹ, ó sì ń ṣe alárìnkiri ní ijù Beerṣeba.
And Abraham rose vp early in the mornyng and toke brede and a bottell with water and gaue it vnto Hagar puttynge it on hir shulders wyth the lad also and sent her awaye. And she departed and wadred vpp and doune in the wyldernes of Berseba.
15 Nígbà tí omi inú ìgò náà tan, ó gbé ọmọ náà sí abẹ́ igbó.
When the water was spent that was in the botell she cast the lad vnder a bush
16 Ó sì lọ, ó sì jókòó nítòsí ibẹ̀, níwọ̀n bí ìtafà kan, nítorí, ó rò ó nínú ara rẹ̀ pé, “Èmi kò fẹ́ wo bí ọmọ náà yóò ṣe kú.” Bí ó sì ti jókòó sí tòsí ibẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
and went and satt her out of syghte a great waye as it were a bowshote off: For she sayde: I will not se the lad dye. And she satt doune out of syghte and lyfte vp hyr voyce and wepte.
17 Ọlọ́run gbọ́ ohun ẹkún náà, Angẹli Ọlọ́run sì pe Hagari láti ọ̀run, ó sì wí fun un pé, “Hagari, kín ni ó ṣe ọ́? Má bẹ̀rù nítorí Ọlọ́run ti gbọ́ ẹkún ọmọ náà níbi tí o tẹ́ ẹ sí.
And God herde the voyce of the childe. And the angell of God called Hagar out of heaven and sayde vnto her: What ayleth the Hagar? Feare not for God hath herde the voyce of the childe where he lyeth.
18 Dìde, gbé ọmọ náà sókè, kí o sì dìímú (tù ú nínú) nítorí èmi yóò sọ ọmọ náà di orílẹ̀-èdè ńlá.”
Aryse and lyfte vp the lad and take hym in thy hande for I will make off him a greate people.
19 Ọlọ́run sì ṣí ojú Hagari, ó sì rí kànga kan, ó lọ síbẹ̀, ó rọ omi kún inú ìgò náà, ó sì fún ọmọ náà mu.
And God opened hir eyes and she sawe a well of water. And she went and fylled the bottell with water and gaue the boye drynke.
20 Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú ọmọ náà bí ó ti ń dàgbà, ó ń gbé nínú ijù, ó sì di tafàtafà.
And God was wyth the lad and he grewe and dweld in the wildernesse and became an archer.
21 Nígbà tí ó ń gbé ni aginjù ní Parani, ìyá rẹ̀ fẹ́ ìyàwó fún un láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
And he dweld in the wyldernesse of Pharan. And hys mother gott him a wyfe out of the land of Egypte.
22 Ní àkókò yìí ni ọba Abimeleki àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀ wí fún Abrahamu pé, “Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo ohun tí ó ń ṣe.
And it chaunced the same season that Abimelech and Phicoll his chefe captayne spake vnto Abraham saynge: God is wyth the in all that thou doist.
23 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, fi Ọlọ́run búra fún mi, ìwọ kì yóò tàn mí àti àwọn ọmọ mi àti àwọn ìran mi, ìwọ yóò fi inú rere hàn fún mi àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti ṣe àtìpó, bí mo ti fihàn fún ọ pẹ̀lú.”
Now therfore swere vnto me even here by God that thou wylt not hurt me nor my childern nor my childerns childern. But that thou shalt deale with me and the contre where thou art a straunger acordynge vnto the kyndnesse that I haue shewed the.
24 Abrahamu sì wí pé, “Èmí búra.”
Then sayde Abraham: I wyll swere.
25 Nígbà náà ni Abrahamu fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn fún Abimeleki nípa kànga tí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ gbà lọ́wọ́ rẹ̀.
And Abraham rebuked Abimelech for a well of water which Abimelech servauntes had taken awaye.
26 Ṣùgbọ́n Abimeleki dáhùn pé, “Èmi kò mọ ẹni tí ó ṣe nǹkan yìí. Ìwọ kò sì sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbọ́, bí kò ṣe lónìí.”
And Abimelech answered I wyst not who dyd it: Also thou toldest me not nether herde I of it but this daye.
27 Abrahamu sì mú àgùntàn àti màlúù wá, ó sì kó wọn fún Abimeleki. Àwọn méjèèjì sì dá májẹ̀mú.
And Abraham toke shepe and oxen and gaue them vnto Abimelech. And they made both of them a bonde together.
28 Abrahamu sì ya abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje nínú agbo àgùntàn rẹ̀ sọ́tọ̀.
And Abraham sett vij. lambes by them selues.
29 Abimeleki sì béèrè lọ́wọ́ Abrahamu pé, “Kín ni ìtumọ̀ yíyà tí ìwọ ya àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí sọ́tọ̀ sí.”
And Abimelech sayde vnto Abraham: what meane these. vij. lamdes which thou hast sett by them selues.
30 Ó dalóhùn pé, “Gba àwọn abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí lọ́wọ́ mi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”
And he answered: vij. lambes shalt thou take of my hande that it maye be a wytnesse vnto me that I haue dygged this well:
31 Nítorí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ náà ni Beerṣeba nítorí níbẹ̀ ni àwọn méjèèjì gbé búra.
Wherfore the place is called Berseba because they sware both of them.
32 Lẹ́yìn májẹ̀mú tí wọ́n dá ní Beerṣeba yìí, ni Abimeleki àti Fikoli olórí ogun rẹ̀ padà sí ilẹ̀ àwọn ará Filistini.
Thus made they a bonde to gether at Berseba. Than Abimelech and Phicoll his chefe captayne rose vp and turned agayne vnto the lande of the Philistines.
33 Abrahamu lọ́ igi tamariski kan sí Beerṣeba, níbẹ̀ ni ó sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run ayérayé.
And Abraham planted a wodd in Berseba and called there on the name of the LORde the everlastynge God:
34 Abrahamu sì gbé ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọjọ́ pípẹ́.
and dwelt in the Phelistinlade alonge season

< Genesis 21 >