< Genesis 20 >

1 Abrahamu sì kó kúrò níbẹ̀ lọ sí ìhà gúúsù ó sì ń gbé ní agbede-méjì Kadeṣi àti Ṣuri; ó sì gbé ní ìlú Gerari fún ìgbà díẹ̀.
Potem Abraham wyruszył stamtąd do ziemi południowej i zamieszkał między Kadesz a Szur, i był przybyszem w Gerarze.
2 Abrahamu sì sọ ní ti Sara aya rẹ̀ níbẹ̀ pé, “Arábìnrin mi ni.” Abimeleki ọba Gerari sì ránṣẹ́ mú Sara wá sí ààfin rẹ̀.
Tam Abraham powiedział o swej żonie Sarze: Ona jest moją siostrą. Dlatego Abimelek, król Geraru, posłał po Sarę i wziął ją.
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tọ Abimeleki wá ní ojú àlá lọ́jọ́ kan, ó sì wí fún un pé, “Kíyèsi, kò sí ohun tí o fi sàn ju òkú lọ, nítorí obìnrin tí ìwọ mú sọ́dọ̀ n nì, aya ẹni kan ní íṣe.”
Lecz Bóg przyszedł do Abimeleka we śnie w nocy i powiedział mu: Umrzesz z powodu tej kobiety, którą wziąłeś, bo ona ma męża.
4 Ṣùgbọ́n Abimeleki kò tí ìbá obìnrin náà lòpọ̀, nítorí náà ó wí pé, “Olúwa ìwọ yóò run orílẹ̀-èdè aláìlẹ́bi bí?
Ale Abimelek jeszcze nie zbliżył się do niej i powiedział: Panie, czy zabijesz też lud sprawiedliwy?
5 Ǹjẹ́ òun kò sọ fún mi pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ obìnrin náà pẹ̀lú sì sọ pé, ‘Arákùnrin mí ni’? Ní òtítọ́ pẹ̀lú ọkàn mímọ́ àti ọwọ́ mímọ́, ni mo ṣe èyí.”
Czy on sam nie mówił mi: Ona jest moją siostrą? I czy ona również nie mówiła: On jest moim bratem? Uczyniłem to w prostocie mego serca i z czystymi rękami.
6 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un nínú àlá náà pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ pé pẹ̀lú òtítọ́ inú ni ìwọ ṣe èyí, èyí ni mo fi pa ọ́ mọ́ tí ń kò jẹ́ kí o ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyí tí n kò fi jẹ́ kí o ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin náà.
Wtedy Bóg powiedział mu we śnie: Wiem, że uczyniłeś to w prostocie swego serca. Dlatego powstrzymałem cię, abyś nie zgrzeszył przeciwko mnie, i nie dopuściłem, abyś jej dotknął.
7 Nísinsin yìí, dá aya ọkùnrin náà padà, nítorí pé wòlíì ni, yóò sì gbàdúrà fún ọ, ìwọ yóò sì yè. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá dá a padà, mọ̀ dájú pé ìwọ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tìrẹ yóò kú.”
Teraz więc zwróć żonę mężowi, bo on jest prorokiem i będzie się modlił za ciebie, a będziesz żył. Jeśli jej nie zwrócisz, wiedz, że na pewno umrzesz, ty i wszystko, co jest twoje.
8 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, Abimeleki pe gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀. Nígbà tí ó sì sọ gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún wọn, ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi.
Abimelek wstał zatem wcześnie rano, zwołał wszystkie swoje sługi i do ich uszu opowiedział wszystko. Gdy ci mężczyźni to usłyszeli, bardzo się przestraszyli.
9 Nígbà náà ni Abimeleki pe Abrahamu ó sì wí fún un pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ́ tí ìwọ fi mú ìdálẹ́bi ńlá wá sí orí èmi àti ìjọba mi? Kò yẹ kí ìwọ hu irú ìwà yìí sí mi.”
Potem Abimelek wezwał Abrahama i powiedział mu: Co nam uczyniłeś? W czym zgrzeszyłem przeciwko tobie, że sprowadziłeś na mnie i na moje królestwo tak wielki grzech? Postąpiłeś ze mną tak, jak nie należy postępować.
10 Abimeleki sì bi Abrahamu pé, “Kín ló dé tí ìwọ fi ṣe èyí?”
Abimelek zapytał [jeszcze] Abrahama: Co widziałeś, że tak postąpiłeś?
11 Abrahamu sì dáhùn pé, “Mo ṣe èyí nítorí mo rò nínú ara mi pé, ẹ̀yin tí ẹ wà níhìn-ín, ẹ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, pé, ẹ sì le pa mí nítorí aya mi.
Abraham odpowiedział: Bo myślałem – na pewno nie ma w tym miejscu bojaźni Bożej i zabiją mnie z powodu mojej żony.
12 Yàtọ̀ fún ìyẹn, òtítọ́ ni pé arábìnrin mi ni. Ọmọ baba kan ni wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, a kì í ṣe ọmọ ìyá kan. Mo sì fẹ́ ẹ ní aya.
Zresztą ona naprawdę [jest] moją siostrą, córką mego ojca, choć nie córką mojej matki. I została moją żoną.
13 Nígbà tí Ọlọ́run sì mú mi rìn kiri kúrò ní ilé baba mi, mo wí fún un pé, ‘Èyí ni ọ̀nà tí ó lè gbà fihàn pé ó fẹ́ràn mi. Gbogbo ibi tí a bá dé máa sọ pé, “Arákùnrin rẹ ni mí.”’”
Gdy więc Bóg wyprawił mnie na wędrówkę z domu mego ojca, powiedziałem do niej: Oto przysługa, jaką mi wyświadczysz – w każdym miejscu, do którego przyjdziemy, mów o mnie: [To] jest mój brat.
14 Nígbà náà ni Abimeleki mú àgùntàn àti màlúù wá, àti ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ó sì kó wọn fún Abrahamu, ó sì dá Sara aya rẹ̀ padà fún un.
Wtedy Abimelek wziął owce i woły oraz służących i służące i dał Abrahamowi, i zwrócił mu jego żonę Sarę.
15 Abimeleki sì tún wí fún un pé, “Gbogbo ilẹ̀ mí nìyí níwájú rẹ, máa gbé ní ibikíbi tí o fẹ́ níbẹ̀.”
I Abimelek powiedział: Oto moja ziemia jest przed tobą. Zamieszkaj, gdzie ci się podoba.
16 Abimeleki sì wí fún Sara pé, “Mo fi ẹgbẹ̀rún owó ẹyọ fàdákà fún arákùnrin rẹ. Èyí ni owó ìtánràn ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ níwájú gbogbo ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ àti pé, a dá ọ láre pátápátá.”
A do Sary powiedział: Dałem twemu bratu tysiąc srebrników. Oto on [jest] zasłoną twoich oczu u wszystkich, którzy [są] z tobą, i u wszystkich innych. O tym [Sara] została pouczona.
17 Nígbà náà, Abrahamu gbàdúrà sí Ọlọ́run, Ọlọ́run sì wo Abimeleki àti aya rẹ̀ àti àwọn ẹrúbìnrin rẹ̀ sàn. Wọ́n sì tún ń bímọ,
Wtedy Abraham modlił się do Boga i Bóg uzdrowił Abimeleka, a także jego żonę i jego służące, i one rodziły.
18 nítorí Olúwa ti sé gbogbo ará ilé Abimeleki nínú nítorí Sara aya Abrahamu.
PAN bowiem zamknął wszystkie łona domu Abimeleka z powodu Sary, żony Abrahama.

< Genesis 20 >