< Genesis 20 >

1 Abrahamu sì kó kúrò níbẹ̀ lọ sí ìhà gúúsù ó sì ń gbé ní agbede-méjì Kadeṣi àti Ṣuri; ó sì gbé ní ìlú Gerari fún ìgbà díẹ̀.
U-Abhrahama wathutha kuleyondawo waya emangweni waseNegebi wayahlala phakathi kweKhadeshi leShuri. Okwesikhatshana wake wahlala eGerari,
2 Abrahamu sì sọ ní ti Sara aya rẹ̀ níbẹ̀ pé, “Arábìnrin mi ni.” Abimeleki ọba Gerari sì ránṣẹ́ mú Sara wá sí ààfin rẹ̀.
lapho u-Abhrahama athi khona ngomkakhe uSara, “Ngudadewethu.” Ngakho u-Abhimelekhi inkosi yaseGerari yathi uSara kalethwe, yazithathela.
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tọ Abimeleki wá ní ojú àlá lọ́jọ́ kan, ó sì wí fún un pé, “Kíyèsi, kò sí ohun tí o fi sàn ju òkú lọ, nítorí obìnrin tí ìwọ mú sọ́dọ̀ n nì, aya ẹni kan ní íṣe.”
Kodwa uNkulunkulu wafika ku-Abhimelekhi ephutsheni ebusuku wathi kuye, “Usufile wena ngenxa yomfazi omthetheyo; ngumfazi womnikazi.”
4 Ṣùgbọ́n Abimeleki kò tí ìbá obìnrin náà lòpọ̀, nítorí náà ó wí pé, “Olúwa ìwọ yóò run orílẹ̀-èdè aláìlẹ́bi bí?
Kodwa u-Abhimelekhi wayelokhu engakamthinti, ngakho wathi, “Thixo, uzasibhubhisa isizwe esimsulwa na?
5 Ǹjẹ́ òun kò sọ fún mi pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ obìnrin náà pẹ̀lú sì sọ pé, ‘Arákùnrin mí ni’? Ní òtítọ́ pẹ̀lú ọkàn mímọ́ àti ọwọ́ mímọ́, ni mo ṣe èyí.”
Katshongo kimi yini wathi, ‘Ngudadewethu,’ laye katshongo na wathi, ‘Ungumnewethu?’ Lokhu ngikwenze ngenhliziyo emsulwa langezandla ezimhlophe.”
6 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un nínú àlá náà pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ pé pẹ̀lú òtítọ́ inú ni ìwọ ṣe èyí, èyí ni mo fi pa ọ́ mọ́ tí ń kò jẹ́ kí o ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyí tí n kò fi jẹ́ kí o ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin náà.
Ngalokho uNkulunkulu wasesithi kuye ephutsheni, “Yebo, ngiyakwazi ukuthi lokhu ukwenze ngenhliziyo emsulwa, yikho ngikuthintile ukuthi ungenzi isono kimi. Yikho ngingakuyekelanga wamthinta.
7 Nísinsin yìí, dá aya ọkùnrin náà padà, nítorí pé wòlíì ni, yóò sì gbàdúrà fún ọ, ìwọ yóò sì yè. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá dá a padà, mọ̀ dájú pé ìwọ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tìrẹ yóò kú.”
Manje mbuyisele umfazi womuntu, ngoba umuntu lowo ungumphrofethi, uzakukhulekela ukuthi uphile. Kodwa nxa ungambuyiseli, yazi ukuthi wena lakho konke okungokwakho kuzakufa.”
8 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, Abimeleki pe gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀. Nígbà tí ó sì sọ gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún wọn, ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi.
Kusisa ngelanga elilandelayo ekuseni kakhulu, u-Abhimelekhi wabiza zonke izikhulu zakhe, kwathi esezitshelile konke okwenzakeleyo, zesaba kakhulu.
9 Nígbà náà ni Abimeleki pe Abrahamu ó sì wí fún un pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ́ tí ìwọ fi mú ìdálẹ́bi ńlá wá sí orí èmi àti ìjọba mi? Kò yẹ kí ìwọ hu irú ìwà yìí sí mi.”
U-Abhimelekhi wasebiza u-Abhrahama wathi, “Ukwenzeleni lokhu kithi na? Ngikone ngani uze ulethe ukona okunje phezu kwami lombuso wami na? Wenze kimi izinto okungafanelanga zenziwe.”
10 Abimeleki sì bi Abrahamu pé, “Kín ló dé tí ìwọ fi ṣe èyí?”
U-Abhimelekhi wabuza u-Abhrahama wathi, “Besiyini isizatho sakho sokwenza lokhu na?”
11 Abrahamu sì dáhùn pé, “Mo ṣe èyí nítorí mo rò nínú ara mi pé, ẹ̀yin tí ẹ wà níhìn-ín, ẹ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, pé, ẹ sì le pa mí nítorí aya mi.
U-Abhrahama waphendula wathi, “Ngazitshela ngathi, ‘Ngempela kakukho ukumesaba uNkulunkulu kule indawo njalo bazangibulala ngenxa yomkami.’
12 Yàtọ̀ fún ìyẹn, òtítọ́ ni pé arábìnrin mi ni. Ọmọ baba kan ni wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, a kì í ṣe ọmọ ìyá kan. Mo sì fẹ́ ẹ ní aya.
Ngaphandle kwalokho, uvele ungudadewethu, indodakazi kababa kodwa engasuye kamama; waba ngumkami.
13 Nígbà tí Ọlọ́run sì mú mi rìn kiri kúrò ní ilé baba mi, mo wí fún un pé, ‘Èyí ni ọ̀nà tí ó lè gbà fihàn pé ó fẹ́ràn mi. Gbogbo ibi tí a bá dé máa sọ pé, “Arákùnrin rẹ ni mí.”’”
Kwathi uNkulunkulu esengisusile emzini kababa ngathi kuSara, ‘Nansi indlela ongatshengisa ngayo uthando lwakho kimi: Noma ngaphi lapho esiya khona, ubokuthi ngami, “Ungumnewethu.”’”
14 Nígbà náà ni Abimeleki mú àgùntàn àti màlúù wá, àti ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ó sì kó wọn fún Abrahamu, ó sì dá Sara aya rẹ̀ padà fún un.
U-Abhimelekhi waseletha izimvu lenkomo, lezisebenzi zesilisa lezesifazane wazipha u-Abhrahama, wabuyisela uSara umkakhe kuye.
15 Abimeleki sì tún wí fún un pé, “Gbogbo ilẹ̀ mí nìyí níwájú rẹ, máa gbé ní ibikíbi tí o fẹ́ níbẹ̀.”
Njalo u-Abhimelekhi wathi, “Nanti ilizwe lami uyalibona; ungahlala lapho othanda khona.”
16 Abimeleki sì wí fún Sara pé, “Mo fi ẹgbẹ̀rún owó ẹyọ fàdákà fún arákùnrin rẹ. Èyí ni owó ìtánràn ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ níwájú gbogbo ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ àti pé, a dá ọ láre pátápátá.”
Wathi kuSara, “Umnewenu ngimupha amashekeli esiliva ayinkulungwane. Le iyinhlawulo yehlazo elenziwe kuwe phambi kwabantu bonke bakini; usugeziwe.”
17 Nígbà náà, Abrahamu gbàdúrà sí Ọlọ́run, Ọlọ́run sì wo Abimeleki àti aya rẹ̀ àti àwọn ẹrúbìnrin rẹ̀ sàn. Wọ́n sì tún ń bímọ,
U-Abhrahama wasekhuleka kuNkulunkulu, uNkulunkulu wamsilisa u-Abhimelekhi, lomkakhe lezigqili zakhe zesifazane ukuthi babelabantwana njalo,
18 nítorí Olúwa ti sé gbogbo ará ilé Abimeleki nínú nítorí Sara aya Abrahamu.
ngoba uThixo wayevale bonke abesifazane bendlu ka-Abhimelekhi inzalo ngenxa yomka-Abhrahama, uSara.

< Genesis 20 >