< Genesis 20 >

1 Abrahamu sì kó kúrò níbẹ̀ lọ sí ìhà gúúsù ó sì ń gbé ní agbede-méjì Kadeṣi àti Ṣuri; ó sì gbé ní ìlú Gerari fún ìgbà díẹ̀.
Na ka turia atu e Aperahama i reira ki te whenua i te tonga, a ka noho ki waenganui o Karehe, o Huru, a ka noho ia ki Kerara, he noho manene.
2 Abrahamu sì sọ ní ti Sara aya rẹ̀ níbẹ̀ pé, “Arábìnrin mi ni.” Abimeleki ọba Gerari sì ránṣẹ́ mú Sara wá sí ààfin rẹ̀.
Na ko Hara, ko tana wahine, ka kiia e Aperahama, Ko toku tuahine ia: a ka tonoa mai e Apimereke kingi o Kerara, tangohia atu ana a Hara.
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tọ Abimeleki wá ní ojú àlá lọ́jọ́ kan, ó sì wí fún un pé, “Kíyèsi, kò sí ohun tí o fi sàn ju òkú lọ, nítorí obìnrin tí ìwọ mú sọ́dọ̀ n nì, aya ẹni kan ní íṣe.”
Na ka puta moemoea mai te Atua ki a Apimereke i te po, ka mea ki a ia, Nana, ka mate koe mo te wahine i tangohia nei i koe; he wahine hoki ia na te tane.
4 Ṣùgbọ́n Abimeleki kò tí ìbá obìnrin náà lòpọ̀, nítorí náà ó wí pé, “Olúwa ìwọ yóò run orílẹ̀-èdè aláìlẹ́bi bí?
Kahore ano ia a Apimereke kia tata noa ki a ia; a ka mea ia, E te Ariki, ka whakamate ano ranei koe i te iwi tika?
5 Ǹjẹ́ òun kò sọ fún mi pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ obìnrin náà pẹ̀lú sì sọ pé, ‘Arákùnrin mí ni’? Ní òtítọ́ pẹ̀lú ọkàn mímọ́ àti ọwọ́ mímọ́, ni mo ṣe èyí.”
Kahore ranei ia i mea mai ki ahau, Ko toku tuahine ia? me te wahine hoki, i mea mai ano ia, Ko toku tungane ia: he tapatahi toku ngakau, he harakore hoki oku ringa i mea ai ahau i tenei mea.
6 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un nínú àlá náà pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ pé pẹ̀lú òtítọ́ inú ni ìwọ ṣe èyí, èyí ni mo fi pa ọ́ mọ́ tí ń kò jẹ́ kí o ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyí tí n kò fi jẹ́ kí o ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin náà.
A ka korero moemoea mai te Atua ki a ia, Ae ra, i mohio tonu ahau he tapatahi tou ngakau i a koe i mea ai i tenei mea; i pupuri hoki ahau i a koe kei hara koe ki ahau; na reira koe te tukua ai e ahau kia pa ki a ia.
7 Nísinsin yìí, dá aya ọkùnrin náà padà, nítorí pé wòlíì ni, yóò sì gbàdúrà fún ọ, ìwọ yóò sì yè. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá dá a padà, mọ̀ dájú pé ìwọ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tìrẹ yóò kú.”
Na, whakahokia akuanei te wahine a tena tangata; no te mea hoki he poropiti ia, a mana e inoi mou, a ka ora koe: ki te kore e whakahokia e koe, kia mohio koe, ka tino mate koe, koutou ko nga mea katoa i a koe.
8 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, Abimeleki pe gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀. Nígbà tí ó sì sọ gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún wọn, ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi.
Na i te ata tu ka maranga a Apimereke, karangatia ana ana tangata katoa, a korerotia ana enei mea katoa ki o ratou taringa: a nui atu te wehi o aua tangata.
9 Nígbà náà ni Abimeleki pe Abrahamu ó sì wí fún un pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ́ tí ìwọ fi mú ìdálẹ́bi ńlá wá sí orí èmi àti ìjọba mi? Kò yẹ kí ìwọ hu irú ìwà yìí sí mi.”
Na ka karanga a Apimereke ki a Aperahama, ka mea ki a ia, He mahi aha tenei au ki a matou? a he aha toku hara ki a koe, i takina mai ai e koe he hara nui ki ahau, ki toku kingitanga ano hoki? kua meinga e koe etahi mea ki ahau kahore nei i tika k ia mahia.
10 Abimeleki sì bi Abrahamu pé, “Kín ló dé tí ìwọ fi ṣe èyí?”
A ka mea ano a Apimereke ki a Aperahama, I kite koe i te aha i meatia ai tenei mea e koe?
11 Abrahamu sì dáhùn pé, “Mo ṣe èyí nítorí mo rò nínú ara mi pé, ẹ̀yin tí ẹ wà níhìn-ín, ẹ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, pé, ẹ sì le pa mí nítorí aya mi.
Na ka mea a Aperahama, I mahara hoki ahau, He pono, kahore te wehi o te Atua i tenei wahi; a ka patua ahau e ratou mo taku wahine.
12 Yàtọ̀ fún ìyẹn, òtítọ́ ni pé arábìnrin mi ni. Ọmọ baba kan ni wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, a kì í ṣe ọmọ ìyá kan. Mo sì fẹ́ ẹ ní aya.
He pono ano ia he tuahine ia noku, ko te tamahine a toku papa, otiia ehara i te tamahine na toku whaea; a ka noho hei wahine maku:
13 Nígbà tí Ọlọ́run sì mú mi rìn kiri kúrò ní ilé baba mi, mo wí fún un pé, ‘Èyí ni ọ̀nà tí ó lè gbà fihàn pé ó fẹ́ràn mi. Gbogbo ibi tí a bá dé máa sọ pé, “Arákùnrin rẹ ni mí.”’”
A, i ta te Atua meatanga i ahau kia kopiko haere ake i te whare o toku papa, ka mea ahau ki a ia, Ko tou aroha tenei, hei whakaputa mau ki ahau: hei nga wahi katoa e tae ai taua, korero moku, Ko toku tungane ia.
14 Nígbà náà ni Abimeleki mú àgùntàn àti màlúù wá, àti ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ó sì kó wọn fún Abrahamu, ó sì dá Sara aya rẹ̀ padà fún un.
Na ka tikina e Apimereke he hipi, he kau, he pononga tane, he pononga wahine, a hoatu ana e ia ki a Aperahama, a whakahokia ana e ia a Hara, tana wahine, ki a ia.
15 Abimeleki sì tún wí fún un pé, “Gbogbo ilẹ̀ mí nìyí níwájú rẹ, máa gbé ní ibikíbi tí o fẹ́ níbẹ̀.”
A ka mea a Apimereke, Nana, kei tou aroaro toku whenua: nohoia e koe te wahi e pai ana ki tau titiro.
16 Abimeleki sì wí fún Sara pé, “Mo fi ẹgbẹ̀rún owó ẹyọ fàdákà fún arákùnrin rẹ. Èyí ni owó ìtánràn ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ níwájú gbogbo ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ àti pé, a dá ọ láre pátápátá.”
A ki a Hara i mea ia, Nana, kua hoatu e ahua ki tou tungane kotahi mano nga hiriwa: na, hei uhi tena mo ou kanohi ki nga tangata katoa i a koe; hei tohu hoki mo tou tika i katoa.
17 Nígbà náà, Abrahamu gbàdúrà sí Ọlọ́run, Ọlọ́run sì wo Abimeleki àti aya rẹ̀ àti àwọn ẹrúbìnrin rẹ̀ sàn. Wọ́n sì tún ń bímọ,
Katahi ka inoi a Aperahama ki te Atua: na kua ora i te Atua a Apimereke, ratou ko tana wahine, ko ana pononga wahine; a ka whanau tamariki ratou.
18 nítorí Olúwa ti sé gbogbo ará ilé Abimeleki nínú nítorí Sara aya Abrahamu.
Kua tutakina rawatia hoki e Ihowa nga kopu katoa o te whare o Apimereke, mo Hara, mo te wahine a Aperahama.

< Genesis 20 >