< Genesis 20 >
1 Abrahamu sì kó kúrò níbẹ̀ lọ sí ìhà gúúsù ó sì ń gbé ní agbede-méjì Kadeṣi àti Ṣuri; ó sì gbé ní ìlú Gerari fún ìgbà díẹ̀.
És elköltözék onnan Ábrahám a déli tartományba, és letelepedék Kádes és Súr között, és tartózkodék Gérárban.
2 Abrahamu sì sọ ní ti Sara aya rẹ̀ níbẹ̀ pé, “Arábìnrin mi ni.” Abimeleki ọba Gerari sì ránṣẹ́ mú Sara wá sí ààfin rẹ̀.
És monda Ábrahám Sáráról az ő feleségéről: Én húgom ő. Elkülde azért Abimélek Gérárnak királya, és elviteté Sárát.
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tọ Abimeleki wá ní ojú àlá lọ́jọ́ kan, ó sì wí fún un pé, “Kíyèsi, kò sí ohun tí o fi sàn ju òkú lọ, nítorí obìnrin tí ìwọ mú sọ́dọ̀ n nì, aya ẹni kan ní íṣe.”
De Isten Abimélekhez jöve éjjeli álomban, és monda néki: Ímé meghalsz az asszonyért, a kit elvettél, holott férjnél van.
4 Ṣùgbọ́n Abimeleki kò tí ìbá obìnrin náà lòpọ̀, nítorí náà ó wí pé, “Olúwa ìwọ yóò run orílẹ̀-èdè aláìlẹ́bi bí?
Abimélek pedig nem illette vala őt, és monda: Uram, az ártatlan népet is megölöd-é?
5 Ǹjẹ́ òun kò sọ fún mi pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ obìnrin náà pẹ̀lú sì sọ pé, ‘Arákùnrin mí ni’? Ní òtítọ́ pẹ̀lú ọkàn mímọ́ àti ọwọ́ mímọ́, ni mo ṣe èyí.”
Avagy nem ő mondotta-é nékem: én húgom ő; s ez is azt mondotta: én bátyám ő. Szívem ártatlanságában, és kezeim tisztaságában cselekedtem ezt.
6 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un nínú àlá náà pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ pé pẹ̀lú òtítọ́ inú ni ìwọ ṣe èyí, èyí ni mo fi pa ọ́ mọ́ tí ń kò jẹ́ kí o ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyí tí n kò fi jẹ́ kí o ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin náà.
És monda az Isten néki álomban: Én is tudom, hogy szívednek ártatlanságában mívelted ezt, azért tartóztattalak én is, hogy ne vétkezzél ellenem, azért nem engedtem, hogy illessed azt.
7 Nísinsin yìí, dá aya ọkùnrin náà padà, nítorí pé wòlíì ni, yóò sì gbàdúrà fún ọ, ìwọ yóò sì yè. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá dá a padà, mọ̀ dájú pé ìwọ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tìrẹ yóò kú.”
Mostan azért add vissza az embernek az ő feleségét, mert Próféta ő: és imádkozik te éretted, és élsz; hogyha pedig vissza nem adod: tudd meg, hogy halállal halsz meg te, és minden hozzád tartozó.
8 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, Abimeleki pe gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀. Nígbà tí ó sì sọ gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún wọn, ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi.
Felkele azért Abimélek reggel, és előhívatá minden szolgáját, s fülök hallatára mindezeket elbeszélé és az emberek igen megfélemlének.
9 Nígbà náà ni Abimeleki pe Abrahamu ó sì wí fún un pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ́ tí ìwọ fi mú ìdálẹ́bi ńlá wá sí orí èmi àti ìjọba mi? Kò yẹ kí ìwọ hu irú ìwà yìí sí mi.”
És hívatá Abimélek Ábrahámot, és monda néki: Mit cselekedtél mi velünk? És mit vétettem te ellened, hogy én reám és az én országomra ilyen nagy bűnt hoztál? A miket cselekedni nem szabad, olyan dolgokat cselekedtél ellenem.
10 Abimeleki sì bi Abrahamu pé, “Kín ló dé tí ìwọ fi ṣe èyí?”
És monda Abimélek Ábrahámnak: Mit láttál, hogy ezt a dolgot cselekedted?
11 Abrahamu sì dáhùn pé, “Mo ṣe èyí nítorí mo rò nínú ara mi pé, ẹ̀yin tí ẹ wà níhìn-ín, ẹ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, pé, ẹ sì le pa mí nítorí aya mi.
Felele Ábrahám: Bizony azt gondoltam: nincsen istenfélelem e helyen, és megölnek engem az én feleségemért.
12 Yàtọ̀ fún ìyẹn, òtítọ́ ni pé arábìnrin mi ni. Ọmọ baba kan ni wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, a kì í ṣe ọmọ ìyá kan. Mo sì fẹ́ ẹ ní aya.
De valósággal húgom is, az én atyámnak leánya ő, csakhogy nem az én anyámnak leánya; és így lőn feleségemmé.
13 Nígbà tí Ọlọ́run sì mú mi rìn kiri kúrò ní ilé baba mi, mo wí fún un pé, ‘Èyí ni ọ̀nà tí ó lè gbà fihàn pé ó fẹ́ràn mi. Gbogbo ibi tí a bá dé máa sọ pé, “Arákùnrin rẹ ni mí.”’”
És lőn hogy a mikor kibujdostata engem az Isten az én atyámnak házából, azt mondám néki: Ilyen kegyességet cselekedjél én velem, mindenütt valahová megyünk, azt mondjad én felőlem: én bátyám ez.
14 Nígbà náà ni Abimeleki mú àgùntàn àti màlúù wá, àti ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ó sì kó wọn fún Abrahamu, ó sì dá Sara aya rẹ̀ padà fún un.
Akkor Abimélek vett juhokat, ökröket, szolgákat és szolgálókat, és adá Ábrahámnak, és vissza adá néki Sárát is az ő feleségét.
15 Abimeleki sì tún wí fún un pé, “Gbogbo ilẹ̀ mí nìyí níwájú rẹ, máa gbé ní ibikíbi tí o fẹ́ níbẹ̀.”
És monda Abimélek: Ímé előtted van az én országom, a hol tenéked jónak tetszik, ott lakjál.
16 Abimeleki sì wí fún Sara pé, “Mo fi ẹgbẹ̀rún owó ẹyọ fàdákà fún arákùnrin rẹ. Èyí ni owó ìtánràn ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ níwájú gbogbo ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ àti pé, a dá ọ láre pátápátá.”
Sárának pedig monda: Ímé ezer ezüst pénzt adtam a te bátyádnak, ímé az neked a szemek befedezője mindazok előtt, a kik veled vannak; és így mindenképen igazolva vagy.
17 Nígbà náà, Abrahamu gbàdúrà sí Ọlọ́run, Ọlọ́run sì wo Abimeleki àti aya rẹ̀ àti àwọn ẹrúbìnrin rẹ̀ sàn. Wọ́n sì tún ń bímọ,
Könyörge azért Ábrahám az Istennek, és meggyógyítá Isten Abiméleket, és az ő feleségét, és az ő szolgálóit, és szűlének.
18 nítorí Olúwa ti sé gbogbo ará ilé Abimeleki nínú nítorí Sara aya Abrahamu.
Mert az Úr erősen bezárta vala az Abimélek háza népének méhét, Sáráért az Ábrahám feleségéért.