< Genesis 20 >

1 Abrahamu sì kó kúrò níbẹ̀ lọ sí ìhà gúúsù ó sì ń gbé ní agbede-méjì Kadeṣi àti Ṣuri; ó sì gbé ní ìlú Gerari fún ìgbà díẹ̀.
Na rĩrĩ, Iburahĩmu nĩoimire kũu aarĩ, agĩthiĩ mwena wa Negevu, na agĩtũũra gatagatĩ ga Kadeshi na Shuri. Gwa kahinda nĩatũũrire Gerari
2 Abrahamu sì sọ ní ti Sara aya rẹ̀ níbẹ̀ pé, “Arábìnrin mi ni.” Abimeleki ọba Gerari sì ránṣẹ́ mú Sara wá sí ààfin rẹ̀.
na arĩ kũu Iburahĩmu oigaga atĩrĩ ha ũhoro wa mũtumia wake Sara, “Ũyũ nĩ mwarĩ wa baba.” Tondũ ũcio Abimeleku mũthamaki wa Gerari agĩtũmanĩra Sara na akĩmuoya.
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tọ Abimeleki wá ní ojú àlá lọ́jọ́ kan, ó sì wí fún un pé, “Kíyèsi, kò sí ohun tí o fi sàn ju òkú lọ, nítorí obìnrin tí ìwọ mú sọ́dọ̀ n nì, aya ẹni kan ní íṣe.”
No rĩrĩ, Ngai akiumĩrĩra Abimeleku ũtukũ na kĩroto, akĩmwĩra atĩrĩ, “Wee-rĩ, no ta ũkuĩte tondũ mũndũ-wa-nja ũcio woete nĩ mũtumia wene.”
4 Ṣùgbọ́n Abimeleki kò tí ìbá obìnrin náà lòpọ̀, nítorí náà ó wí pé, “Olúwa ìwọ yóò run orílẹ̀-èdè aláìlẹ́bi bí?
No Abimeleku ndaakoretwo akuhĩrĩirie Sara, nĩ ũndũ ũcio akĩũria atĩrĩ, “Mwathani, no wanange rũrĩrĩ rũtehĩtie?
5 Ǹjẹ́ òun kò sọ fún mi pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ obìnrin náà pẹ̀lú sì sọ pé, ‘Arákùnrin mí ni’? Ní òtítọ́ pẹ̀lú ọkàn mímọ́ àti ọwọ́ mímọ́, ni mo ṣe èyí.”
Githĩ ti we wanjĩĩrire, ‘Ũyũ nĩ mwarĩ wa baba?’ Na ningĩ o nake Sara githĩ ndoigire atĩrĩ, ‘Ũyũ nĩ mũrũ wa baba?’ Njĩkĩte ũndũ ũcio na ũrũngĩrĩru wa ngoro na moko matarĩ ũcuuke.”
6 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un nínú àlá náà pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ pé pẹ̀lú òtítọ́ inú ni ìwọ ṣe èyí, èyí ni mo fi pa ọ́ mọ́ tí ń kò jẹ́ kí o ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyí tí n kò fi jẹ́ kí o ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin náà.
Ningĩ Ngai akĩmwĩra atĩrĩ kĩroto-inĩ, “Ĩĩ, nĩnjũũĩ ũrekĩte ũguo na ũrũngĩrĩru wa ngoro, na nĩkĩo ndĩrakũgiririe ũnjĩhĩrie. Nĩkĩo itanareka ũmũhutie.
7 Nísinsin yìí, dá aya ọkùnrin náà padà, nítorí pé wòlíì ni, yóò sì gbàdúrà fún ọ, ìwọ yóò sì yè. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá dá a padà, mọ̀ dájú pé ìwọ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tìrẹ yóò kú.”
Rĩu-rĩ, cookeria mũndũ ũcio mũtumia wake, nĩgũkorwo nĩ mũnabii, nake nĩegũkũhooera, na nĩũgũtũũra muoyo. No waga kũmũcookia-rĩ, ũmenye ti-itherũ wee nĩũgũkua, na andũ aku othe nĩmegũkua.”
8 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, Abimeleki pe gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀. Nígbà tí ó sì sọ gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún wọn, ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi.
Mũthenya ũyũ ũngĩ rũciinĩ tene, Abimeleku agĩtũmanĩra anene ake othe, na aarĩkia kũmeera maũndũ marĩa mothe meekĩkĩte, andũ acio magĩĩtigĩra mũno.
9 Nígbà náà ni Abimeleki pe Abrahamu ó sì wí fún un pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ́ tí ìwọ fi mú ìdálẹ́bi ńlá wá sí orí èmi àti ìjọba mi? Kò yẹ kí ìwọ hu irú ìwà yìí sí mi.”
Abimeleku agĩcooka agĩĩta Iburahĩmu na akĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ atĩa ũguo ũtwĩkĩte? Nĩ atĩa ngwĩhĩirie, nĩguo ũndeherere niĩ na ũthamaki wakwa ũũru mũnene ũguo? Ũnjĩkĩte maũndũ mataagĩrĩire gwĩkwo.”
10 Abimeleki sì bi Abrahamu pé, “Kín ló dé tí ìwọ fi ṣe èyí?”
Ningĩ Abimeleku akĩũria Iburahĩmu atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩatũmire wĩke ũguo?”
11 Abrahamu sì dáhùn pé, “Mo ṣe èyí nítorí mo rò nínú ara mi pé, ẹ̀yin tí ẹ wà níhìn-ín, ẹ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, pé, ẹ sì le pa mí nítorí aya mi.
Iburahĩmu akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ndeĩrire atĩrĩ, ‘Kũndũ gũkũ andũ matiĩtigĩrĩte Ngai, na nĩmekũnjũraga nĩ ũndũ wa mũtumia wakwa.’
12 Yàtọ̀ fún ìyẹn, òtítọ́ ni pé arábìnrin mi ni. Ọmọ baba kan ni wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, a kì í ṣe ọmọ ìyá kan. Mo sì fẹ́ ẹ ní aya.
O na kũrĩ ũguo, ti-itherũ nĩ mwarĩ wa-baba, mũirĩtu wa baba; no tũtirĩ a nyina ũmwe, nĩkĩo aatuĩkire mũtumia wakwa.
13 Nígbà tí Ọlọ́run sì mú mi rìn kiri kúrò ní ilé baba mi, mo wí fún un pé, ‘Èyí ni ọ̀nà tí ó lè gbà fihàn pé ó fẹ́ràn mi. Gbogbo ibi tí a bá dé máa sọ pé, “Arákùnrin rẹ ni mí.”’”
Na rĩrĩa Ngai aandutire kuuma nyũmba-inĩ ya baba thiĩ ngorũũrage, ndeerire mũtumia wakwa atĩrĩ, ‘Ũũ nĩguo ũrĩnyonagia wendo waku: Kũrĩa guothe tũrĩthiiaga, uugage atĩrĩ ũhoro-inĩ ũnjĩgiĩ, “Ũyũ nĩ mũrũ wa baba.”’”
14 Nígbà náà ni Abimeleki mú àgùntàn àti màlúù wá, àti ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ó sì kó wọn fún Abrahamu, ó sì dá Sara aya rẹ̀ padà fún un.
Iburahĩmu aarĩkia kwaria, Abimeleku akĩruta ngʼondu na ngʼombe, na ngombo cia arũme na cia andũ-a-nja, na agĩcihe Iburahĩmu, na akĩmũcookeria Sara mũtumia wake.
15 Abimeleki sì tún wí fún un pé, “Gbogbo ilẹ̀ mí nìyí níwájú rẹ, máa gbé ní ibikíbi tí o fẹ́ níbẹ̀.”
Ningĩ Abimeleku akĩmwĩra atĩrĩ, “Bũrũri wakwa ũrĩ mbere yaku; tũũra harĩa hothe ũngĩenda.”
16 Abimeleki sì wí fún Sara pé, “Mo fi ẹgbẹ̀rún owó ẹyọ fàdákà fún arákùnrin rẹ. Èyí ni owó ìtánràn ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ níwájú gbogbo ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ àti pé, a dá ọ láre pátápátá.”
Nake Abimeleku akĩĩra Sara atĩrĩ, “Nĩngũhe mũrũ-wa-thoguo cekeri 1,000 cia betha ituĩke cia kũrĩhĩria ihĩtia rĩrĩa ũhĩtĩirio mbere ya andũ aya othe mũrĩ nao; we ndũrĩ ũũru wĩkĩte.”
17 Nígbà náà, Abrahamu gbàdúrà sí Ọlọ́run, Ọlọ́run sì wo Abimeleki àti aya rẹ̀ àti àwọn ẹrúbìnrin rẹ̀ sàn. Wọ́n sì tún ń bímọ,
Nake Iburahĩmu akĩhooya Ngai, nake Ngai akĩhonia Abimeleku, na mũtumia wake, na ngombo ciake cia airĩtu nĩguo mahote gũciara ciana rĩngĩ,
18 nítorí Olúwa ti sé gbogbo ará ilé Abimeleki nínú nítorí Sara aya Abrahamu.
nĩgũkorwo Jehova nĩahingĩte nda cia andũ-a-nja othe a nyũmba ya Abimeleku, makaaga kũgĩa ciana, nĩ ũndũ wa Abimeleku kuoya Sara mũtumia wa Iburahĩmu.

< Genesis 20 >