< Genesis 20 >

1 Abrahamu sì kó kúrò níbẹ̀ lọ sí ìhà gúúsù ó sì ń gbé ní agbede-méjì Kadeṣi àti Ṣuri; ó sì gbé ní ìlú Gerari fún ìgbà díẹ̀.
Abraham partit de là pour se rendre dans le pays du Sud, et il habita entre Kadès et Shur. Il habita comme étranger à Guérar.
2 Abrahamu sì sọ ní ti Sara aya rẹ̀ níbẹ̀ pé, “Arábìnrin mi ni.” Abimeleki ọba Gerari sì ránṣẹ́ mú Sara wá sí ààfin rẹ̀.
Abraham dit de Sara, sa femme: « C'est ma sœur. » Abimélec, roi de Guérar, l'envoya chercher et prit Sara.
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tọ Abimeleki wá ní ojú àlá lọ́jọ́ kan, ó sì wí fún un pé, “Kíyèsi, kò sí ohun tí o fi sàn ju òkú lọ, nítorí obìnrin tí ìwọ mú sọ́dọ̀ n nì, aya ẹni kan ní íṣe.”
Mais Dieu apparut à Abimélec en songe pendant la nuit, et lui dit: « Voici, tu es un homme mort, à cause de la femme que tu as prise, car c'est la femme d'un homme. »
4 Ṣùgbọ́n Abimeleki kò tí ìbá obìnrin náà lòpọ̀, nítorí náà ó wí pé, “Olúwa ìwọ yóò run orílẹ̀-èdè aláìlẹ́bi bí?
Or Abimélec ne s'était pas approché d'elle. Il dit: « Seigneur, vas-tu tuer même une nation juste?
5 Ǹjẹ́ òun kò sọ fún mi pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ obìnrin náà pẹ̀lú sì sọ pé, ‘Arákùnrin mí ni’? Ní òtítọ́ pẹ̀lú ọkàn mímọ́ àti ọwọ́ mímọ́, ni mo ṣe èyí.”
Ne m'a-t-il pas dit: C'est ma sœur? Elle-même a dit: « C'est mon frère ». J'ai fait cela dans l'intégrité de mon cœur et l'innocence de mes mains. »
6 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un nínú àlá náà pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ pé pẹ̀lú òtítọ́ inú ni ìwọ ṣe èyí, èyí ni mo fi pa ọ́ mọ́ tí ń kò jẹ́ kí o ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyí tí n kò fi jẹ́ kí o ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin náà.
Dieu lui dit en songe: « Oui, je sais que tu as fait cela dans l'intégrité de ton cœur, et je t'ai aussi empêché de pécher contre moi. C'est pourquoi je ne t'ai pas permis de la toucher.
7 Nísinsin yìí, dá aya ọkùnrin náà padà, nítorí pé wòlíì ni, yóò sì gbàdúrà fún ọ, ìwọ yóò sì yè. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá dá a padà, mọ̀ dájú pé ìwọ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tìrẹ yóò kú.”
Maintenant, rends la femme de cet homme. Car il est prophète, il priera pour toi, et tu vivras. Si tu ne la rends pas, sache que tu mourras, toi et tous ceux qui sont à toi. »
8 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, Abimeleki pe gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀. Nígbà tí ó sì sọ gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún wọn, ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi.
Abimélec se leva tôt le matin, appela tous ses serviteurs et leur raconta toutes ces choses à l'oreille. Les hommes eurent très peur.
9 Nígbà náà ni Abimeleki pe Abrahamu ó sì wí fún un pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ́ tí ìwọ fi mú ìdálẹ́bi ńlá wá sí orí èmi àti ìjọba mi? Kò yẹ kí ìwọ hu irú ìwà yìí sí mi.”
Alors Abimélec appela Abraham et lui dit: « Que nous as-tu fait? Comment ai-je péché contre toi, pour que tu aies attiré sur moi et sur mon royaume un grand péché? Tu m'as fait des choses qui ne doivent pas être faites! ».
10 Abimeleki sì bi Abrahamu pé, “Kín ló dé tí ìwọ fi ṣe èyí?”
Abimélec dit à Abraham: « Qu'as-tu vu, pour que tu aies fait cette chose? ».
11 Abrahamu sì dáhùn pé, “Mo ṣe èyí nítorí mo rò nínú ara mi pé, ẹ̀yin tí ẹ wà níhìn-ín, ẹ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, pé, ẹ sì le pa mí nítorí aya mi.
Abraham dit: « Parce que j'ai pensé: « La crainte de Dieu n'est pas dans ce lieu. Ils me tueront à cause de ma femme.
12 Yàtọ̀ fún ìyẹn, òtítọ́ ni pé arábìnrin mi ni. Ọmọ baba kan ni wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, a kì í ṣe ọmọ ìyá kan. Mo sì fẹ́ ẹ ní aya.
D'ailleurs, elle est bien ma sœur, la fille de mon père, mais pas la fille de ma mère, et elle est devenue ma femme.
13 Nígbà tí Ọlọ́run sì mú mi rìn kiri kúrò ní ilé baba mi, mo wí fún un pé, ‘Èyí ni ọ̀nà tí ó lè gbà fihàn pé ó fẹ́ràn mi. Gbogbo ibi tí a bá dé máa sọ pé, “Arákùnrin rẹ ni mí.”’”
Lorsque Dieu m'a fait errer loin de la maison de mon père, je lui ai dit: « Voici la bonté que tu me témoigneras. Partout où nous irons, tu diras de moi: « C'est mon frère ».
14 Nígbà náà ni Abimeleki mú àgùntàn àti màlúù wá, àti ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ó sì kó wọn fún Abrahamu, ó sì dá Sara aya rẹ̀ padà fún un.
Abimélec prit des brebis et des bœufs, des serviteurs et des servantes, et les donna à Abraham, et il lui rendit Sara, sa femme.
15 Abimeleki sì tún wí fún un pé, “Gbogbo ilẹ̀ mí nìyí níwájú rẹ, máa gbé ní ibikíbi tí o fẹ́ níbẹ̀.”
Abimélec dit: « Voici, mon pays est devant toi. Habite où il te plaira. »
16 Abimeleki sì wí fún Sara pé, “Mo fi ẹgbẹ̀rún owó ẹyọ fàdákà fún arákùnrin rẹ. Èyí ni owó ìtánràn ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ níwájú gbogbo ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ àti pé, a dá ọ láre pátápátá.”
Il dit à Sara: « Voici, j'ai donné à ton frère mille pièces d'argent. Voici, c'est pour toi une couverture des yeux pour tous ceux qui sont avec toi. Devant tous, tu es justifiée. »
17 Nígbà náà, Abrahamu gbàdúrà sí Ọlọ́run, Ọlọ́run sì wo Abimeleki àti aya rẹ̀ àti àwọn ẹrúbìnrin rẹ̀ sàn. Wọ́n sì tún ń bímọ,
Abraham pria Dieu. Dieu guérit Abimélek, sa femme et ses servantes, et elles eurent des enfants.
18 nítorí Olúwa ti sé gbogbo ará ilé Abimeleki nínú nítorí Sara aya Abrahamu.
Car l'Éternel avait fermé hermétiquement tous les utérus de la maison d'Abimélec, à cause de Sara, la femme d'Abraham.

< Genesis 20 >