< Genesis 20 >
1 Abrahamu sì kó kúrò níbẹ̀ lọ sí ìhà gúúsù ó sì ń gbé ní agbede-méjì Kadeṣi àti Ṣuri; ó sì gbé ní ìlú Gerari fún ìgbà díẹ̀.
Niin Abraham vaelsi sieltä etelään päin, ja asui Kadeksen ja Surrin vaiheella: ja oli muukalainen Gerarissa.
2 Abrahamu sì sọ ní ti Sara aya rẹ̀ níbẹ̀ pé, “Arábìnrin mi ni.” Abimeleki ọba Gerari sì ránṣẹ́ mú Sara wá sí ààfin rẹ̀.
Ja Abraham sanoi emännästänsä Saarasta: hän on minun sisareni. Niin Abimelek Gerarin kuningas lähetti ja antoi noutaa Saaran tykönsä.
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tọ Abimeleki wá ní ojú àlá lọ́jọ́ kan, ó sì wí fún un pé, “Kíyèsi, kò sí ohun tí o fi sàn ju òkú lọ, nítorí obìnrin tí ìwọ mú sọ́dọ̀ n nì, aya ẹni kan ní íṣe.”
Mutta Jumala tuli Abimelekin tykö yöllä unessa: ja sanoi hänelle: katso, sinun pitää kuoleman sen vaimon tähden, jonkas ottanut olet; sillä hän on yhden miehen aviovaimo.
4 Ṣùgbọ́n Abimeleki kò tí ìbá obìnrin náà lòpọ̀, nítorí náà ó wí pé, “Olúwa ìwọ yóò run orílẹ̀-èdè aláìlẹ́bi bí?
Mutta Abimelek ei ollut ryhtynyt häneen, ja sanoi: Herra tahdotkos myös surmata hurskaan kansan?
5 Ǹjẹ́ òun kò sọ fún mi pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ obìnrin náà pẹ̀lú sì sọ pé, ‘Arákùnrin mí ni’? Ní òtítọ́ pẹ̀lú ọkàn mímọ́ àti ọwọ́ mímọ́, ni mo ṣe èyí.”
Eikö hän sanonut minulle: hän on minun sisareni, ja hän myös itse sanoi: hän on minun veljeni: yksivakaisella sydämellä ja viattomilla käsillä olen minä sen tehnyt.
6 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un nínú àlá náà pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ pé pẹ̀lú òtítọ́ inú ni ìwọ ṣe èyí, èyí ni mo fi pa ọ́ mọ́ tí ń kò jẹ́ kí o ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyí tí n kò fi jẹ́ kí o ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin náà.
Ja Jumala sanoi hänelle unessa: minä myös tiedän, ettäs sydämes yksivakaisuudessa sen tehnyt olet. Sentähden minä myös estin sinun, ettes rikkoisi minua vastaan; jonka tähden en minä sallinut sinua ryhtymään häneen.
7 Nísinsin yìí, dá aya ọkùnrin náà padà, nítorí pé wòlíì ni, yóò sì gbàdúrà fún ọ, ìwọ yóò sì yè. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá dá a padà, mọ̀ dájú pé ìwọ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tìrẹ yóò kú.”
Niin anna nyt miehelle hänen emäntänsä jälleen; sillä hän on propheta: ja hän on rukoileva sinun edestäs, ettäs saat elää. Mutta jos et sinä anna häntä jälleen, niin tiedä, ettäs totisesti kuolet, ja kaikki mitä sinulla on.
8 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, Abimeleki pe gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀. Nígbà tí ó sì sọ gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún wọn, ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi.
Niin Abimelek nousi varhain aamulla, ja kutsui kaikki palveliansa, ja puhui kaikki nämät sanat heidän kuultensa: ja miehet pelkäsivät suuresti.
9 Nígbà náà ni Abimeleki pe Abrahamu ó sì wí fún un pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ́ tí ìwọ fi mú ìdálẹ́bi ńlá wá sí orí èmi àti ìjọba mi? Kò yẹ kí ìwọ hu irú ìwà yìí sí mi.”
Ja Abimelek kutsui Abrahamin, ja sanoi hänelle: mitäs meille teit? ja mitä minä olen rikkonut sinua vastaan, ettäs saattaisit minulle ja minun valtakunnalleni niin suuren rikoksen? sinä olet tehnyt minua vastaan niitä töitä joita ei sovi tehdä.
10 Abimeleki sì bi Abrahamu pé, “Kín ló dé tí ìwọ fi ṣe èyí?”
Ja Abimelek sanoi vielä Abrahamille: mitäs näit, ettäs tämän teit?
11 Abrahamu sì dáhùn pé, “Mo ṣe èyí nítorí mo rò nínú ara mi pé, ẹ̀yin tí ẹ wà níhìn-ín, ẹ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, pé, ẹ sì le pa mí nítorí aya mi.
Abraham sanoi: minä ajattelin: kukaties ei tässä paikassa ole yhtään Jumalan pelkoa: ja he surmaavat minun, emäntäni tähden.
12 Yàtọ̀ fún ìyẹn, òtítọ́ ni pé arábìnrin mi ni. Ọmọ baba kan ni wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, a kì í ṣe ọmọ ìyá kan. Mo sì fẹ́ ẹ ní aya.
Ja hän on tosin minun sisareni: sillä hän on minun isäni tytär, vaan ei äitini tytär: ja minä otin hänen emännäkseni.
13 Nígbà tí Ọlọ́run sì mú mi rìn kiri kúrò ní ilé baba mi, mo wí fún un pé, ‘Èyí ni ọ̀nà tí ó lè gbà fihàn pé ó fẹ́ràn mi. Gbogbo ibi tí a bá dé máa sọ pé, “Arákùnrin rẹ ni mí.”’”
Koska Jumala laski minun kulkemaan isäni huoneesta, sanoin minä hänelle: tämä on sinun lempes, jonka sinun minua kohtaan pitää tekemän: kuhunka paikkaan ikänänsä me tulemme, sano minusta: hän on minun veljeni.
14 Nígbà náà ni Abimeleki mú àgùntàn àti màlúù wá, àti ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ó sì kó wọn fún Abrahamu, ó sì dá Sara aya rẹ̀ padà fún un.
Niin Abimelek otti lampaita, ja karjaa, ja palvelioita, ja piikoja, ja antoi Abrahamille: ja antoi hänelle jälleen Saaran hänen emäntänsä.
15 Abimeleki sì tún wí fún un pé, “Gbogbo ilẹ̀ mí nìyí níwájú rẹ, máa gbé ní ibikíbi tí o fẹ́ níbẹ̀.”
Ja Abimelek sanoi: katso, minun maani on altis sinun edessäs: asu kussa sinulle parhain kelpaa.
16 Abimeleki sì wí fún Sara pé, “Mo fi ẹgbẹ̀rún owó ẹyọ fàdákà fún arákùnrin rẹ. Èyí ni owó ìtánràn ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ níwájú gbogbo ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ àti pé, a dá ọ láre pátápátá.”
Ja sanoi Saaralle: katso, minä olen antanut veljelles tuhannen hopiapenninkiä, katso, ne pitää oleman sinulle silmäin peitteeksi, kaikkein edessä, jotka sinun kanssas ovat, ja kaikkein muiden edessä. Ja niin vahvistettiin (hänen nuhteettomuutensa).
17 Nígbà náà, Abrahamu gbàdúrà sí Ọlọ́run, Ọlọ́run sì wo Abimeleki àti aya rẹ̀ àti àwọn ẹrúbìnrin rẹ̀ sàn. Wọ́n sì tún ń bímọ,
Ja Abraham rukoili Jumalaa: ja Jumala paransi Abimelekin, ja hänen emäntänsä, ja hänen piikansa, ja ne siittivät.
18 nítorí Olúwa ti sé gbogbo ará ilé Abimeleki nínú nítorí Sara aya Abrahamu.
Sillä Herra oli peräti sulkenut kaikki kohdut Abimelekin huoneessa, Saaran Abrahamin emännän tähden.