< Genesis 20 >

1 Abrahamu sì kó kúrò níbẹ̀ lọ sí ìhà gúúsù ó sì ń gbé ní agbede-méjì Kadeṣi àti Ṣuri; ó sì gbé ní ìlú Gerari fún ìgbà díẹ̀.
Abraham left Mamre and moved southwest to the Negev desert and lived in a place named Gerar, between Kadesh and Shur.
2 Abrahamu sì sọ ní ti Sara aya rẹ̀ níbẹ̀ pé, “Arábìnrin mi ni.” Abimeleki ọba Gerari sì ránṣẹ́ mú Sara wá sí ààfin rẹ̀.
While he was there, he told people that Sarah was his sister, not his wife. Then King Abimelech of Gerar sent some of his men to Sarah, and they brought her to him to be his wife.
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tọ Abimeleki wá ní ojú àlá lọ́jọ́ kan, ó sì wí fún un pé, “Kíyèsi, kò sí ohun tí o fi sàn ju òkú lọ, nítorí obìnrin tí ìwọ mú sọ́dọ̀ n nì, aya ẹni kan ní íṣe.”
But God appeared to Abimelech in a dream during the night and said to him, “Listen to me! You are going to die because the woman you took is another man’s wife.”
4 Ṣùgbọ́n Abimeleki kò tí ìbá obìnrin náà lòpọ̀, nítorí náà ó wí pé, “Olúwa ìwọ yóò run orílẹ̀-èdè aláìlẹ́bi bí?
But Abimelech had not had sex [EUP] with her, so he said, “God, since the people of my nation and I am innocent; will you kill me?
5 Ǹjẹ́ òun kò sọ fún mi pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ obìnrin náà pẹ̀lú sì sọ pé, ‘Arákùnrin mí ni’? Ní òtítọ́ pẹ̀lú ọkàn mímọ́ àti ọwọ́ mímọ́, ni mo ṣe èyí.”
He told me, ‘She is my sister,’ and she also said, ‘He is my brother.’ I did this with pure motives and I [SYN] have not done anything wrong yet.”
6 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un nínú àlá náà pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ pé pẹ̀lú òtítọ́ inú ni ìwọ ṣe èyí, èyí ni mo fi pa ọ́ mọ́ tí ń kò jẹ́ kí o ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyí tí n kò fi jẹ́ kí o ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin náà.
God said to him in another dream, “Yes, I know that your motives were pure. That is why I truly prevented you from sinning against me. I did not allow you to have sex [EUP] with her.
7 Nísinsin yìí, dá aya ọkùnrin náà padà, nítorí pé wòlíì ni, yóò sì gbàdúrà fún ọ, ìwọ yóò sì yè. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá dá a padà, mọ̀ dájú pé ìwọ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tìrẹ yóò kú.”
Now, return this man’s wife to her husband, because he is (a prophet/a man who receives messages from me). He will pray for you, and you will (remain alive/not die). But if you do not return her to him, you will certainly die, and all the members of your household will also certainly die.”
8 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, Abimeleki pe gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀. Nígbà tí ó sì sọ gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún wọn, ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi.
Early the next morning, Abimelech summoned all his officials, and told them everything that had happened. When they heard that [MTY], his men were very afraid [that God would punish them].
9 Nígbà náà ni Abimeleki pe Abrahamu ó sì wí fún un pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ́ tí ìwọ fi mú ìdálẹ́bi ńlá wá sí orí èmi àti ìjọba mi? Kò yẹ kí ìwọ hu irú ìwà yìí sí mi.”
Abimelech then summoned Abraham, and said to him, “You should not have done that to us [RHQ]! Did I do something wrong to you, with the result that you are causing me and the people in [MTY] my kingdom to be guilty of committing a great sin [RHQ]? You have done things to me that (should not be done/you should not have done)!”
10 Abimeleki sì bi Abrahamu pé, “Kín ló dé tí ìwọ fi ṣe èyí?”
Abimelech asked Abraham, “What was your reason for doing this?”
11 Abrahamu sì dáhùn pé, “Mo ṣe èyí nítorí mo rò nínú ara mi pé, ẹ̀yin tí ẹ wà níhìn-ín, ẹ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, pé, ẹ sì le pa mí nítorí aya mi.
Abraham replied, “I said that because I thought, ‘They certainly do not respect God in this place. If they don’t respect God, they will not respect relationships with others. [If I say she is my sister, they will try to pay me a bride price] to get her. But if I say she is my wife, they will kill me to get her.’
12 Yàtọ̀ fún ìyẹn, òtítọ́ ni pé arábìnrin mi ni. Ọmọ baba kan ni wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, a kì í ṣe ọmọ ìyá kan. Mo sì fẹ́ ẹ ní aya.
Besides, she really [can be considered] my sister, because she is the daughter of my father, although she is not the daughter of my mother. She is the daughter of another woman, and I married her.
13 Nígbà tí Ọlọ́run sì mú mi rìn kiri kúrò ní ilé baba mi, mo wí fún un pé, ‘Èyí ni ọ̀nà tí ó lè gbà fihàn pé ó fẹ́ràn mi. Gbogbo ibi tí a bá dé máa sọ pé, “Arákùnrin rẹ ni mí.”’”
Later, when God told me to move away from my father’s household, I said to her, ‘This is the way you can show that you love me: Everywhere we go, say about me, “This is my brother.”’”
14 Nígbà náà ni Abimeleki mú àgùntàn àti màlúù wá, àti ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ó sì kó wọn fún Abrahamu, ó sì dá Sara aya rẹ̀ padà fún un.
So Abimelech brought some sheep and cattle and male and female slaves and gave them to Abraham. And he returned his wife Sarah to him.
15 Abimeleki sì tún wí fún un pé, “Gbogbo ilẹ̀ mí nìyí níwájú rẹ, máa gbé ní ibikíbi tí o fẹ́ níbẹ̀.”
And Abimelech said to him, “Look! All my land is here in front of you. Live in whatever place you like!”
16 Abimeleki sì wí fún Sara pé, “Mo fi ẹgbẹ̀rún owó ẹyọ fàdákà fún arákùnrin rẹ. Èyí ni owó ìtánràn ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ níwájú gbogbo ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ àti pé, a dá ọ láre pátápátá.”
And he said to Sarah, “Look here, I am giving 1,000 pieces of silver to your brother. This is to insure that no one will [bring up this matter again and] say that I have done something wrong. [EUP, IDM]”
17 Nígbà náà, Abrahamu gbàdúrà sí Ọlọ́run, Ọlọ́run sì wo Abimeleki àti aya rẹ̀ àti àwọn ẹrúbìnrin rẹ̀ sàn. Wọ́n sì tún ń bímọ,
Then Abraham prayed to God, and God healed Abimelech’s wife and his slave girls so that they could become pregnant.
18 nítorí Olúwa ti sé gbogbo ará ilé Abimeleki nínú nítorí Sara aya Abrahamu.
This was because Yahweh had caused it to be impossible for any of the women in Abimelech’s household to bear children, because Abimelech had taken Abraham’s wife Sarah.

< Genesis 20 >