< Genesis 20 >

1 Abrahamu sì kó kúrò níbẹ̀ lọ sí ìhà gúúsù ó sì ń gbé ní agbede-méjì Kadeṣi àti Ṣuri; ó sì gbé ní ìlú Gerari fún ìgbà díẹ̀.
And Abraham brake up from thence, towards the land of the South, and fixed his dwelling between Kadesh and Shur, so he sojourned in Gerar.
2 Abrahamu sì sọ ní ti Sara aya rẹ̀ níbẹ̀ pé, “Arábìnrin mi ni.” Abimeleki ọba Gerari sì ránṣẹ́ mú Sara wá sí ààfin rẹ̀.
And Abraham said of Sarah his wife: My, sister, is she, —So Abimelech king of Gerar sent, and took Sarah.
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tọ Abimeleki wá ní ojú àlá lọ́jọ́ kan, ó sì wí fún un pé, “Kíyèsi, kò sí ohun tí o fi sàn ju òkú lọ, nítorí obìnrin tí ìwọ mú sọ́dọ̀ n nì, aya ẹni kan ní íṣe.”
Then God went in unto Abimelech, in a dream of the night, —and said to him, Behold thee dead! because of the woman whom thou hast taken, seeing that, she, is a married woman.
4 Ṣùgbọ́n Abimeleki kò tí ìbá obìnrin náà lòpọ̀, nítorí náà ó wí pé, “Olúwa ìwọ yóò run orílẹ̀-èdè aláìlẹ́bi bí?
Now, Abimelech, had not come near unto her, —so he said, O My Lord! a nation even a righteous one, wilt thou slay?
5 Ǹjẹ́ òun kò sọ fún mi pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ obìnrin náà pẹ̀lú sì sọ pé, ‘Arákùnrin mí ni’? Ní òtítọ́ pẹ̀lú ọkàn mímọ́ àti ọwọ́ mímọ́, ni mo ṣe èyí.”
Had not, he himself, said to me, My sister, is she? and even she herself, said, My brother, is he? In the integrity of my heart and in the pureness of my hand, have I done this!
6 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un nínú àlá náà pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ pé pẹ̀lú òtítọ́ inú ni ìwọ ṣe èyí, èyí ni mo fi pa ọ́ mọ́ tí ń kò jẹ́ kí o ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyí tí n kò fi jẹ́ kí o ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin náà.
And God said unto him in a dream, I, also, knew, that in the integrity of thy heart, thou didst this, so then, even I myself, withheld thee from sinning against me, for this reason, have I not suffered thee to touch her.
7 Nísinsin yìí, dá aya ọkùnrin náà padà, nítorí pé wòlíì ni, yóò sì gbàdúrà fún ọ, ìwọ yóò sì yè. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá dá a padà, mọ̀ dájú pé ìwọ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tìrẹ yóò kú.”
Now, therefore restore the man’s wife, for a prophet, is he, that he may pray for thee and live thou, —But if thou art not going to restore her, know, that thou shalt die, thou—and all that are thine.
8 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, Abimeleki pe gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀. Nígbà tí ó sì sọ gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún wọn, ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi.
So Abimelech rose early in the morning, and called all his servants, and spake all these words in their ears, and the men feared greatly.
9 Nígbà náà ni Abimeleki pe Abrahamu ó sì wí fún un pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ́ tí ìwọ fi mú ìdálẹ́bi ńlá wá sí orí èmi àti ìjọba mi? Kò yẹ kí ìwọ hu irú ìwà yìí sí mi.”
Then Abimelech called Abraham, and said to him, What hast thou done to us? and wherein had I sinned against thee, that thou shouldst have brought in over me and over my kingdom, a sin so great? Deeds, which should not be done, hast thou done with me.
10 Abimeleki sì bi Abrahamu pé, “Kín ló dé tí ìwọ fi ṣe èyí?”
And Abimelech said unto Abraham, —What hadst thou seen, that thou shouldst have done this thing?
11 Abrahamu sì dáhùn pé, “Mo ṣe èyí nítorí mo rò nínú ara mi pé, ẹ̀yin tí ẹ wà níhìn-ín, ẹ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, pé, ẹ sì le pa mí nítorí aya mi.
And Abraham said, Because I thought, Surely there is no fear of God, in this place, —therefore will they slay me for the sake of my wife.
12 Yàtọ̀ fún ìyẹn, òtítọ́ ni pé arábìnrin mi ni. Ọmọ baba kan ni wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, a kì í ṣe ọmọ ìyá kan. Mo sì fẹ́ ẹ ní aya.
Moreover also, in truth, my sister daughter of my father, she is, only not daughter of my mother, —so she became my wife.
13 Nígbà tí Ọlọ́run sì mú mi rìn kiri kúrò ní ilé baba mi, mo wí fún un pé, ‘Èyí ni ọ̀nà tí ó lè gbà fihàn pé ó fẹ́ràn mi. Gbogbo ibi tí a bá dé máa sọ pé, “Arákùnrin rẹ ni mí.”’”
And so it came to pass when the Gods caused me to wander from my father’s house, that I said to her, This, is thy lovingkindness, wherewith thou shalt deal with me, —Into whatsoever place we enter, say of me My brother, is he.
14 Nígbà náà ni Abimeleki mú àgùntàn àti màlúù wá, àti ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ó sì kó wọn fún Abrahamu, ó sì dá Sara aya rẹ̀ padà fún un.
Then took Abimelech sheep and oxen and men—servants and maid-servants, and gave to Abraham, —and restored to him Sarah his wife.
15 Abimeleki sì tún wí fún un pé, “Gbogbo ilẹ̀ mí nìyí níwájú rẹ, máa gbé ní ibikíbi tí o fẹ́ níbẹ̀.”
And Abimelech, said, Lo! my land is before thee, —wherever it may seem good in thine eyes, dwell.
16 Abimeleki sì wí fún Sara pé, “Mo fi ẹgbẹ̀rún owó ẹyọ fàdákà fún arákùnrin rẹ. Èyí ni owó ìtánràn ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ níwájú gbogbo ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ àti pé, a dá ọ láre pátápátá.”
And to Sarah, he said, Lo! I have given a thousand of silver unto thy brother: Lo! that is for thee as a covering of eyes, to all who are with thee, —And so in every way, hath right been done.
17 Nígbà náà, Abrahamu gbàdúrà sí Ọlọ́run, Ọlọ́run sì wo Abimeleki àti aya rẹ̀ àti àwọn ẹrúbìnrin rẹ̀ sàn. Wọ́n sì tún ń bímọ,
And Abraham prayed unto God, —and God healed Abimelech, and his wife, and his maid-servants, so that they bare children,
18 nítorí Olúwa ti sé gbogbo ará ilé Abimeleki nínú nítorí Sara aya Abrahamu.
For Yahweh, had restrained from bearing, every female of the house of Abimelech, —because of Sarah, wife of Abraham.

< Genesis 20 >