< Genesis 2 >

1 Báyìí ni Ọlọ́run parí dídá àwọn ọ̀run àti ayé, àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.
Astfel au fost terminate cerurile şi pământul şi toată oştirea lor.
2 Ní ọjọ́ keje Ọlọ́run sì parí iṣẹ́ rẹ̀ tí ó ti ń ṣe; ó sì sinmi ní ọjọ́ keje kúrò nínú iṣẹ́ rẹ̀ gbogbo tí ó ti ń ṣe.
Şi în ziua a şaptea Dumnezeu şi-a terminat lucrarea pe care o făcuse; şi în ziua a şaptea s-a odihnit de toată lucrarea lui pe care o făcuse.
3 Ọlọ́run sì súre fún ọjọ́ keje, ó sì yà á sí mímọ́, nítorí pé ní ọjọ́ náà ni ó sinmi kúrò nínú iṣẹ́ dídá ayé tí ó ti ń ṣe.
Şi Dumnezeu a binecuvântat ziua a şaptea şi a sfinţit-o, pentru că în aceasta s-a odihnit de toată lucrarea sa, pe care Dumnezeu a creat-o şi a făcut-o.
4 Èyí ni ìtàn bí Ọlọ́run ṣe dá àwọn ọ̀run àti ayé nígbà tí ó dá wọn. Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run dá ayé àti àwọn ọ̀run.
Acestea sunt generaţiile cerurilor şi ale pământului când au fost create, în ziua în care DOMNUL Dumnezeu a făcut pământul şi cerurile,
5 Kò sí igi igbó kan ní orí ilẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ewéko igbó kan tí ó tí ì hù jáde ní ilẹ̀, nítorí Olúwa Ọlọ́run kò tí ì rọ̀jò sórí ilẹ̀, kò sì sí ènìyàn láti ro ilẹ̀.
Şi fiecare verdeaţă a câmpului, înainte ca aceasta să fi fost în pământ, şi fiecare verdeaţă a câmpului înainte de a fi încolţit, pentru că DOMNUL Dumnezeu nu făcuse să plouă peste pământ şi nu era om să are pământul.
6 Ṣùgbọ́n ìsun omi ń jáde láti ilẹ̀, ó sì ń bu omi rin gbogbo ilẹ̀.
Ci un abur se ridica din pământ şi uda toată suprafaţa pământului.
7 Olúwa Ọlọ́run sì fi erùpẹ̀ ilẹ̀ mọ ènìyàn, ó si mí èémí ìyè sí ihò imú rẹ̀, ènìyàn sì di alààyè ọkàn.
Şi DOMNUL Dumnezeu l-a format pe om din ţărâna pământului şi i-a suflat în nări suflarea vieţii şi omul a devenit un suflet viu.
8 Olúwa Ọlọ́run sì gbin ọgbà kan sí Edeni ní ìhà ìlà-oòrùn, níbẹ̀ ni ó fi ọkùnrin náà tí ó ti dá sí.
Şi DOMNUL Dumnezeu a sădit o grădină înspre est, în Eden, şi acolo a pus pe omul pe care l-a format.
9 Olúwa Ọlọ́run sì mú kí onírúurú igi hù jáde láti inú ilẹ̀, àwọn igi tí ó dùn ún wò lójú, tí ó sì dára fún oúnjẹ. Ní àárín ọgbà náà ni igi ìyè àti igi tí ń mú ènìyàn mọ rere àti búburú wà.
Şi din pământ DOMNUL Dumnezeu a făcut să încolţească fiecare pom care este plăcut la vedere şi bun pentru mâncare şi pomul vieţii, de asemenea, în mijlocul grădinii şi pomul cunoaşterii binelui şi răului.
10 Odò kan sì ń ti Edeni sàn wá láti bu omi rin ọgbà náà, láti ibẹ̀ ni odò náà gbé ya sí ipa mẹ́rin.
Şi un râu ieşea din Eden ca să ude grădina; şi de acolo se împărţea şi se făcea patru capete.
11 Orúkọ èkínní ni Pisoni, òun ni ó sàn yí gbogbo ilẹ̀ Hafila ká, níbi tí wúrà gbé wà.
Numele întâiului este Pison: acesta este cel ce înconjoară întreaga ţară Havila, unde este aur.
12 (Wúrà ilẹ̀ náà dára, òjìá àti òkúta óníkìsì oníyebíye wà níbẹ̀ pẹ̀lú).
Şi aurul acelei ţări este bun: acolo este bedelium şi piatra de onix.
13 Orúkọ odò kejì ni Gihoni, òun ni ó sàn yí gbogbo ilẹ̀ Kuṣi ká.
Şi numele celui de al doilea râu este Ghihon: acesta este cel ce înconjoară întreaga ţară a Etiopiei.
14 Orúkọ odò kẹta ni Tigirisi, òun ni ó sàn ní apá ìlà-oòrùn ilẹ̀ Asiria. Odò kẹrin ni Eufurate.
Şi numele celui de al treilea râu este Hidechel: acesta este cel ce merge spre estul Asiriei. Şi al patrulea râu este Eufratul.
15 Olúwa Ọlọ́run mú ọkùnrin náà sínú ọgbà Edeni láti máa ṣe iṣẹ́ níbẹ̀, kí ó sì máa ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
Şi DOMNUL Dumnezeu l-a luat pe om şi l-a pus în grădina Edenului, să o lucreze şi să o păzească.
16 Olúwa Ọlọ́run sì pàṣẹ fún ọkùnrin náà pé, “Ìwọ lè jẹ lára èyíkéyìí èso àwọn igi inú ọgbà;
Şi DOMNUL Dumnezeu i-a poruncit omului, spunând: Din orice pom din grădină poţi mânca în voie,
17 ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ nínú èso igi ìmọ̀ rere àti èso igi ìmọ̀ búburú, nítorí ní ọjọ́ tí ìwọ bá jẹ ẹ́ ni ìwọ yóò kùú.”
Dar din pomul cunoaşterii binelui şi răului să nu mănânci, căci în ziua în care vei mânca din el, vei muri negreşit.
18 Olúwa Ọlọ́run wí pé, “Kò dára kí ọkùnrin wà ní òun nìkan. Èmi yóò ṣe olùrànlọ́wọ́ tí ó rí bí i rẹ̀ fún un.”
Şi DOMNUL Dumnezeu a spus: Nu este bine ca omul să fie singur; îi voi face un ajutor potrivit pentru el.
19 Lẹ́yìn tí Olúwa Ọlọ́run ti dá àwọn ẹranko inú igbó àti gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run láti inú erùpẹ̀ ilẹ̀. Ó sì kó wọn tọ ọkùnrin náà wá láti wo orúkọ tí yóò sọ wọ́n; orúkọ tí ó sì sọ gbogbo ẹ̀dá alààyè náà ni wọ́n ń jẹ́.
Şi din pământ DOMNUL Dumnezeu a format fiecare fiară a câmpului şi fiecare pasăre a cerului şi le-a adus la Adam să vadă cum le va numi; şi oricum a numit Adam fiecare fiinţa vie, acela a fost numele ei.
20 Gbogbo ohun ọ̀sìn, ẹyẹ ojú ọ̀run àti gbogbo ẹranko igbó ni ọkùnrin náà sọ ní orúkọ. Ṣùgbọ́n fún Adamu ni a kò rí olùrànlọ́wọ́ tí ó rí bí i rẹ̀.
Şi Adam a dat nume tuturor vitelor şi tuturor păsărilor cerului şi fiecărei fiare a câmpului, dar pentru Adam nu s-a găsit un ajutor potrivit pentru el.
21 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run mú kí ọkùnrin náà sùn fọnfọn; nígbà tí ó sì ń sùn, Ọlọ́run yọ egungun ìhà rẹ̀ kan, ó sì fi ẹran-ara bò ó padà.
Şi DOMNUL Dumnezeu a făcut să cadă un somn adânc peste Adam; şi Adam a dormit; şi a luat una din coastele lui şi a închis carnea la loc;
22 Olúwa Ọlọ́run sì dá obìnrin láti inú egungun tí ó yọ ní ìhà ọkùnrin náà, Ó sì mu obìnrin náà tọ̀ ọ́ wá.
Şi din coasta pe care DOMNUL Dumnezeu a luat-o de la om, a făcut o femeie şi a adus-o la om.
23 Ọkùnrin náà sì wí pé, “Èyí ni egungun láti inú egungun mi àti ẹran-ara nínú ẹran-ara mi; ‘obìnrin’ ni a ó máa pè é, nítorí a mú un jáde láti ara ọkùnrin.”
Şi Adam a spus: Aceasta este acum os din oasele mele şi carne din carnea mea; ea se va chema femeie, pentru că a fost luată din bărbat.
24 Nítorí ìdí èyí, ọkùnrin yóò fi baba àti ìyá rẹ̀ sílẹ̀, yóò sì dàpọ̀ mọ́ aya rẹ̀, wọn yóò sì di ara kan.
De aceea va lăsa un bărbat pe tatăl său şi pe mama sa şi se va lipi de soţia sa şi cei doi vor fi un singur trup.
25 Ọkùnrin náà àti aya rẹ̀ sì wà ní ìhòhò, ojú kò sì tì wọ́n.
Şi ei erau amândoi goi, omul şi soţia sa, şi nu se ruşinau.

< Genesis 2 >