< Genesis 2 >

1 Báyìí ni Ọlọ́run parí dídá àwọn ọ̀run àti ayé, àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.
És elvégeztetett az ég és a föld és minden seregük.
2 Ní ọjọ́ keje Ọlọ́run sì parí iṣẹ́ rẹ̀ tí ó ti ń ṣe; ó sì sinmi ní ọjọ́ keje kúrò nínú iṣẹ́ rẹ̀ gbogbo tí ó ti ń ṣe.
Elvégezte Isten a hetedik napon művét, melyet alkotott és megnyugodott a hetedik napon minden művétől, melyet alkotott.
3 Ọlọ́run sì súre fún ọjọ́ keje, ó sì yà á sí mímọ́, nítorí pé ní ọjọ́ náà ni ó sinmi kúrò nínú iṣẹ́ dídá ayé tí ó ti ń ṣe.
És megáldotta Isten a hetedik napot és megszentelte azt, mert azon nyugodott meg minden művétől, melyet teremtett Isten és alkotott.
4 Èyí ni ìtàn bí Ọlọ́run ṣe dá àwọn ọ̀run àti ayé nígbà tí ó dá wọn. Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run dá ayé àti àwọn ọ̀run.
Ez a keletkezése az égnek és a földnek, amidőn teremtettek, amely napon alkotta az Örökkévaló Isten a földet és az eget.
5 Kò sí igi igbó kan ní orí ilẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ewéko igbó kan tí ó tí ì hù jáde ní ilẹ̀, nítorí Olúwa Ọlọ́run kò tí ì rọ̀jò sórí ilẹ̀, kò sì sí ènìyàn láti ro ilẹ̀.
De semmi mezei növény sem volt a földön és semmi mezei fű sem sarjadt még, mert nem bocsátott esőt az Örökkévaló Isten a földre és ember sem volt, hogy megmunkálja a földek.
6 Ṣùgbọ́n ìsun omi ń jáde láti ilẹ̀, ó sì ń bu omi rin gbogbo ilẹ̀.
De köd szállt föl a földről és megáztatta a föld egész színét.
7 Olúwa Ọlọ́run sì fi erùpẹ̀ ilẹ̀ mọ ènìyàn, ó si mí èémí ìyè sí ihò imú rẹ̀, ènìyàn sì di alààyè ọkàn.
Akkor megalkotta az Örökkévaló Isten az embert a föld porából és lehelt az orrába éltető lelket, és az ember lett élőlénnyé.
8 Olúwa Ọlọ́run sì gbin ọgbà kan sí Edeni ní ìhà ìlà-oòrùn, níbẹ̀ ni ó fi ọkùnrin náà tí ó ti dá sí.
És ültetett az Örökkévaló Isten kertet Édenbe, kelet felől és odahelyezte az embert, akit alkotott.
9 Olúwa Ọlọ́run sì mú kí onírúurú igi hù jáde láti inú ilẹ̀, àwọn igi tí ó dùn ún wò lójú, tí ó sì dára fún oúnjẹ. Ní àárín ọgbà náà ni igi ìyè àti igi tí ń mú ènìyàn mọ rere àti búburú wà.
És növesztett az Örökkévaló Isten a földből mindenféle fát, kívánatosát a tekintetre és jót az eledelre; az élet fája pedig a kert közepén volt, meg a jó és rossz tudásának fája.
10 Odò kan sì ń ti Edeni sàn wá láti bu omi rin ọgbà náà, láti ibẹ̀ ni odò náà gbé ya sí ipa mẹ́rin.
És egy folyam jött ki Édenből; hogy áztassa a kertet; onnan pedig elágazott és lett négy főfolyóvá.
11 Orúkọ èkínní ni Pisoni, òun ni ó sàn yí gbogbo ilẹ̀ Hafila ká, níbi tí wúrà gbé wà.
Az egyiknek neve Pisón, az, mely megkerüli Cháviló egész országát, ahol az arany van.
12 (Wúrà ilẹ̀ náà dára, òjìá àti òkúta óníkìsì oníyebíye wà níbẹ̀ pẹ̀lú).
És ezen országnak aranya jó; ott van a bedólách és a sóhámkő.
13 Orúkọ odò kejì ni Gihoni, òun ni ó sàn yí gbogbo ilẹ̀ Kuṣi ká.
A második folyó neve Gichón; az, mely megkerüli Kúsnak egész országát.
14 Orúkọ odò kẹta ni Tigirisi, òun ni ó sàn ní apá ìlà-oòrùn ilẹ̀ Asiria. Odò kẹrin ni Eufurate.
És a harmadik folyó neve Chiddekel, az, mely Ássúr keleti oldalán folyik; és a negyedik folyó a Perosz.
15 Olúwa Ọlọ́run mú ọkùnrin náà sínú ọgbà Edeni láti máa ṣe iṣẹ́ níbẹ̀, kí ó sì máa ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
És vette az Örökkévaló Isten az embert és belehelyezte Éden kertjébe, hogy megmunkálja és őrizze azt.
16 Olúwa Ọlọ́run sì pàṣẹ fún ọkùnrin náà pé, “Ìwọ lè jẹ lára èyíkéyìí èso àwọn igi inú ọgbà;
És megparancsolta az Örökkévaló Isten az embernek, mondván: A kertnek minden fájáról ehetsz;
17 ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ nínú èso igi ìmọ̀ rere àti èso igi ìmọ̀ búburú, nítorí ní ọjọ́ tí ìwọ bá jẹ ẹ́ ni ìwọ yóò kùú.”
de a jó és rossz tudásának fájáról ne egyél arról, mert amely napon eszel arról, meg kell halnod.
18 Olúwa Ọlọ́run wí pé, “Kò dára kí ọkùnrin wà ní òun nìkan. Èmi yóò ṣe olùrànlọ́wọ́ tí ó rí bí i rẹ̀ fún un.”
És mondta az Örökkévaló Isten: Nem jó, hogy az ember egyedül van, alkotok számára segítőt, neki megfelelőt.
19 Lẹ́yìn tí Olúwa Ọlọ́run ti dá àwọn ẹranko inú igbó àti gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run láti inú erùpẹ̀ ilẹ̀. Ó sì kó wọn tọ ọkùnrin náà wá láti wo orúkọ tí yóò sọ wọ́n; orúkọ tí ó sì sọ gbogbo ẹ̀dá alààyè náà ni wọ́n ń jẹ́.
Mert alkotta az Örökkévaló Isten a földből a mező minden vadját és az ég minden madarát, elvitte az emberhez, hogy lássa, minek nevezi azt el, és bárminek nevezi el az ember az élőlényt, az legyen a neve.
20 Gbogbo ohun ọ̀sìn, ẹyẹ ojú ọ̀run àti gbogbo ẹranko igbó ni ọkùnrin náà sọ ní orúkọ. Ṣùgbọ́n fún Adamu ni a kò rí olùrànlọ́wọ́ tí ó rí bí i rẹ̀.
És adott az ember neveket minden baromnak, az ég madarának és a mező minden vadjának; de az ember számára nem talált segítőt, neki megfelelőt.
21 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run mú kí ọkùnrin náà sùn fọnfọn; nígbà tí ó sì ń sùn, Ọlọ́run yọ egungun ìhà rẹ̀ kan, ó sì fi ẹran-ara bò ó padà.
Akkor bocsátott az Örökkévaló Isten mély álmot az emberre, hogy elaludt; ekkor kivett egyet annak bordáiból és húst zárt helyébe.
22 Olúwa Ọlọ́run sì dá obìnrin láti inú egungun tí ó yọ ní ìhà ọkùnrin náà, Ó sì mu obìnrin náà tọ̀ ọ́ wá.
És alakította az Örökkévaló Isten a bordát; melyet kivett az emberből, asszonnyá és elvitte azt az emberhez.
23 Ọkùnrin náà sì wí pé, “Èyí ni egungun láti inú egungun mi àti ẹran-ara nínú ẹran-ara mi; ‘obìnrin’ ni a ó máa pè é, nítorí a mú un jáde láti ara ọkùnrin.”
Akkor mondta az ember: Ez immár csontomból való csont és húsomból való hús; azért neveztessék némbernek, mert az emberből vétetett az.
24 Nítorí ìdí èyí, ọkùnrin yóò fi baba àti ìyá rẹ̀ sílẹ̀, yóò sì dàpọ̀ mọ́ aya rẹ̀, wọn yóò sì di ara kan.
Azért hagyja el a férfi az ő atyját és anyját és ragaszkodjék feleségéhez, hogy legyenek egy testté.
25 Ọkùnrin náà àti aya rẹ̀ sì wà ní ìhòhò, ojú kò sì tì wọ́n.
És mindketten meztelenek voltak, az ember és az ő felesége, de nem szégyenlették magukat.

< Genesis 2 >