< Genesis 19 >

1 Ní àṣálẹ́, àwọn angẹli méjì sì wá sí ìlú Sodomu, Lọti sì jókòó ní ẹnu ibodè ìlú. Bí ó sì ti rí wọn, ó sì dìde láti pàdé wọn, ó kí wọn, ó sì foríbalẹ̀ fún wọn.
Nao araika acio eerĩ magĩkinya Sodomu hwaĩ-inĩ, nake Loti aikarĩte kĩhingo-inĩ gĩa itũũra rĩu inene. Rĩrĩa aamoonire-rĩ, agĩũkĩra nĩguo amatũnge, na agĩturumithia ũthiũ wake thĩ.
2 Ó wí pé, “Ẹ̀yin olúwa mi, èmi bẹ̀ yín, ẹ yà sí ilé ìránṣẹ́ yín kí ẹ sì wẹ ẹsẹ̀ yín, kí n sì gbà yín lálejò, ẹ̀yin ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ láti máa bá ìrìnàjò yín lọ.” Wọ́n sì wí pé, “Rárá o, àwa yóò dúró ní ìgboro ní òru òní.”
Akĩmeera atĩrĩ, “Aathi akwa, ndamũthaitha ũkai mũtoonye nyũmba ya ndungata yanyu. No mwĩthambe magũrũ na mũraarĩrĩre, na rũciinĩ tene mũrooke gũthiĩ na mbere na rũgendo rwanyu.” No-o makĩmũcookeria atĩrĩ, “Aca, ithuĩ tũkũraara nja kĩhaaro-inĩ.”
3 Ṣùgbọ́n Lọti rọ̀ wọ́n gidigidi tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n gbà láti bá a lọ sì ilé. Ó sì ṣe àsè fún wọn, ó sì dín àkàrà aláìwú fún wọ́n, wọ́n sì jẹ.
Nowe Loti akĩmaringĩrĩria na hinya mũno mathiĩ gwake mũciĩ, nginya magĩtĩkĩra. Magĩthiĩ nake, magĩtoonya nyũmba gwake. Nake akĩmathondekera irio, akĩruga mĩgate ĩtaarĩ ndawa ya kũimbia, nao makĩrĩa.
4 Ṣùgbọ́n kí ó tó di pé wọ́n lọ sùn, àwọn ọkùnrin ìlú Sodomu tọmọdé tàgbà yí ilé náà ká.
Matanathiĩ gũkoma-rĩ, arũme othe a kuuma ituri ciothe cia itũũra rĩu rĩa Sodomu, arĩa ethĩ na arĩa akũrũ, makĩrigiicĩria nyũmba ya Loti.
5 Wọ́n pe Lọti pé, “Àwọn ọkùnrin tí ó wọ̀ sí ilé rẹ lálẹ́ yìí ń kọ́? Mú wọn jáde fún wa, kí a le ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú wọn.”
Nao magĩĩta Loti, makĩmũũria atĩrĩ, “Andũ arĩa mookire gwaku ũtukũ ũyũ-rĩ, marĩ-kũ? Marehe na gũkũ nja, tũkome nao.”
6 Lọti sì jáde láti pàdé wọn, ó sì ti ìlẹ̀kùn lẹ́yìn rẹ̀ bí ó ti jáde.
Loti akiuma na nja amatũnge, na akĩhinga mũrango,
7 Ó sì wí pé, “Rárá, ẹ̀yin ará mi, ẹ má ṣe ṣe ohun búburú yìí,
akĩmeera atĩrĩ, “Aca, arata akwa; mũtigeke ũndũ ũcio wa waganu.
8 kíyèsi i, mo ní ọmọbìnrin méjì tí kò mọ ọkùnrin rí, ẹ jẹ́ kí n mú wọn tọ̀ yín wá kí ẹ sì ṣe ohun tí ẹ fẹ́ pẹ̀lú wọn. Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣe àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ní ibi kan nítorí wọ́n wá wọ̀ lábẹ́ ààbò ní ilé mi.”
Atĩrĩrĩ, ndĩ na airĩtu akwa eerĩ matarĩ maakoma na mũndũ mũrũme. Rekei ndĩmarehe na gũkũ nja, na inyuĩ mwĩke o ũrĩa mũkwenda nao. No mũtigeke ũndũ o na ũrĩkũ kũrĩ andũ aya, tondũ mokĩte gwakwa na no nginya ndĩmagitĩre.”
9 Wọ́n sì wí fún pé, “Bì sẹ́yìn fún wa. Èyí yìí wá ṣe àtìpó láàrín wa, òun sì fẹ́ ṣe onídàájọ́! Aburú tí a ó fi ṣe ọ́ yóò pọ̀ ju tí wọn lọ.” Wọn rọ́ lu Lọti, wọ́n sì súnmọ́ ọn láti fọ́ ìlẹ̀kùn.
Nao makĩmũcookeria atĩrĩ, “Ehera.” Na makiuga atĩrĩ, “Mũndũ ũyũ ookire gũkũ arĩ mũgeni, na rĩu arenda gũtũciirithia! Wee nĩwe tũgwĩka ũũru gũkĩra acio!” Magĩkĩrĩrĩria kũhatĩrĩria Loti, na magĩkuhĩrĩria nĩguo moinange mũrango.
10 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà nawọ́ fa Lọti wọlé, wọ́n sì ti ìlẹ̀kùn.
No ageni acio maarĩ thĩinĩ magĩtambũrũkia moko, makĩguucia Loti, makĩmũcookia nyũmba na makĩhinga mũrango.
11 Wọ́n sì bu ìfọ́jú lu àwọn ọkùnrin tí ó wà ní ẹnu-ọ̀nà ilé náà, àti èwe àti àgbà: wọ́n kò sì rí ẹnu-ọ̀nà mọ́.
Magĩcooka makĩhũũra andũ acio maarĩ nja ya mũrango wa nyũmba, ethĩ na akũrũ, na ũtumumu nĩgeetha mage kuona mũrango.
12 Àwọn ọkùnrin náà sì wí fún Lọti pé, “Ǹjẹ́ ó ní ẹlòmíràn ní ìlú yìí bí? Àna rẹ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ lọ́kùnrin àti lóbìnrin, tàbí ẹnikẹ́ni tí ìwọ ní ní ìlú yìí, kó wọn jáde kúrò ní ibí yìí,
Andũ acio eerĩ makĩũria Loti atĩrĩ, “Ũrĩ na andũ angĩ aku gũkũ, ta arĩa mahikĩtie airĩtu aku, aanake kana airĩtu aku, kana mũndũ ũngĩ waku o wothe ũrĩ itũũra-inĩ rĩĩrĩ inene? Moimagarie muume gũkũ,
13 nítorí a ó pa ìlú yìí run, nítorí igbe iṣẹ́ búburú wọn ń dí púpọ̀ níwájú Olúwa, Olúwa sì rán wa láti pa á run.”
tondũ nĩtũkwananga kũndũ gũkũ. Mũkayo ũrĩa ũkaĩirwo Jehova okĩrĩre andũ a gũkũ nĩ mũnene mũno, na nĩatũtũmĩte tũũke tũrĩanange.”
14 Nígbà náà ni Lọti jáde, ó sì wí fún àwọn àna rẹ̀ ọkùnrin tí ó ti bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fẹ́ àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ ṣe kánkán, kí ẹ jáde ní ìlú yìí, nítorí Olúwa fẹ́ pa ìlú yìí run!” Ṣùgbọ́n àwọn ọkọ ọmọ rẹ̀ wọ̀nyí rò pé àwàdà ló ń ṣe.
Nĩ ũndũ ũcio Loti akiumagara, agĩthiĩ akĩaria na athoni ake, arĩa maarĩ mahikie airĩtu ake. Akĩmeera atĩrĩ, “Mwĩhĩkei muume kũndũ gũkũ, nĩ ũndũ Jehova arĩ hakuhĩ kwananga itũũra rĩĩrĩ inene!” No athoni ake magĩĩciiria nĩ itherũ aamaringaga.
15 Ní àfẹ̀mọ́júmọ́, àwọn angẹli náà rọ Lọti pé, “Ṣe wéré, mú aya rẹ àti àwọn ọmọbìnrin rẹ méjèèjì tí ó wà níhìn-ín, àìṣe bẹ́ẹ̀, ìwọ yóò parun pẹ̀lú ìlú yìí nígbà tí wọ́n bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”
Rũciinĩ ruoro rũgĩtema-rĩ, araika acio makĩhĩkahĩka Loti, makĩmwĩra atĩrĩ, “Wĩhĩke! Oya mũtumia waku na airĩtu aku eerĩ arĩa marĩ gũkũ, kana mũniinanĩrio na itũũra rĩĩrĩ rĩkĩherithio.”
16 Nígbà tí ó ń jáfara, àwọn ọkùnrin náà nawọ́ mú un lọ́wọ́, wọ́n sì nawọ́ mú aya rẹ̀ náà lọ́wọ́ àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ méjèèjì, wọ́n sì mú wọn jáde sẹ́yìn odi ìlú, nítorí Olúwa ṣàánú fún wọn.
Rĩrĩa Loti aahindahindire-rĩ, andũ acio makĩmũnyiita guoko, na moko ma mũtumia wake na ma airĩtu ake eerĩ, na makĩmoimagaria o wega nginya nja ya itũũra rĩu inene, nĩgũkorwo Jehova nĩamaiguĩrĩire tha.
17 Ní kété tí wọ́n mú wọn jáde sẹ́yìn odi tán, ọ̀kan nínú wọn wí pé, “Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe wo ẹ̀yìn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ kí ó má ṣe dúró ní gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀! Sá àsálà lọ sí orí òkè, kí ìwọ ó má ba ṣègbé!”
Na maarĩkia kũmaruta nja ya itũũra, ũmwe wao akĩmeera atĩrĩ, “Mwĩtharei mũhonokie mĩoyo yanyu! Mũtikehũgũre, na mũtikarũgame handũ o na ha gũkũ kĩaragana-inĩ gĩkĩ! Ũrĩrai irĩma-inĩ, kana mũniinwo!”
18 Ṣùgbọ́n Lọti wí fún wọn pé, “Rárá, ẹ̀yin Olúwa mi, ẹ jọ̀wọ́!
No Loti akĩmeera atĩrĩ, “Aca, aathi akwa, ndamũthaitha!
19 Nígbà tí ìránṣẹ́ rẹ ti rí ojúrere rẹ, tí o sì ti fi àánú rẹ hàn nípa gbígba ẹ̀mí mi là, èmi kò le è sálọ sórí òkè, kí búburú yìí má ba à lé mi bá, kí n sì kú.
Tondũ ndungata yanyu nĩ ĩtĩkĩrĩkĩte maitho-inĩ manyu, na nĩmũnyonetie ũtugi mũnene wa kũhonokia muoyo wakwa, no ndingĩhota kũũrĩra irĩma-inĩ; mwanangĩko ũyũ nĩũkũngorerera, na nĩngũkua.
20 Wò ó, ìlú kékeré kan nìyí ní tòsí láti sá sí: jẹ́ kí n sálọ síbẹ̀, ìlú kékeré ha kọ́? Ẹ̀mí mi yóò sì yè.”
Ta rorai, haarĩa harĩ na itũũra rĩrĩ hakuhĩ ingĩũrĩra, na nĩ inini. Rekei njũrĩre kuo, nĩ itũũra inini mũno, githĩ tiguo? Naguo muoyo wakwa nĩũkũhonoka.”
21 Ó sì wí fún un pé, “Ó dára, mo gba ẹ̀bẹ̀ rẹ. Èmi kì yóò run ìlú náà tí ìwọ sọ̀rọ̀ rẹ̀.
Nake mũraika akĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩ wega mũno, nĩngũkũiguĩra ihooya rĩu o narĩo; Ndikũharagania itũũra rĩu waria ũhoro warĩo.
22 Tètè! Sálọ síbẹ̀, nítorí èmi kò le ṣe ohun kan àyàfi tí ó bá dé ibẹ̀.” (ìdí nìyí tí a fi ń pe ìlú náà ní Soari).
No rĩrĩ, ũrĩra kuo na ihenya, nĩ ũndũ gũtirĩ ũndũ ingĩĩka nginya ũkinye kuo.” (Nĩkĩo itũũra rĩu rĩĩtagwo Zoari.)
23 Nígbà tí Lọti yóò fi dé ìlú Soari, oòrùn ti yọ.
Loti agĩkinya Zoari-rĩ, riũa nĩrĩarĩkĩtie kũratha.
24 Nígbà náà ni Olúwa rọ̀jò iná àti sulfuru sórí Sodomu àti Gomorra láti ọ̀run lọ́dọ̀ Olúwa wá.
Nake Jehova akiurĩria Sodomu na Gomora mwaki wa ũbiriti uumĩte igũrũ kũrĩ Jehova.
25 Báyìí ni ó run àwọn ìlú náà àti gbogbo ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó wà ní ìlú ńlá ńlá wọ̀n-ọn-nì àti ohun gbogbo tí ó hù jáde nílẹ̀.
Nake akĩharagania matũũra macio manene, na kĩaragana kĩu gĩothe, o hamwe na arĩa othe maatũire matũũra-inĩ macio manene, o na mĩmera yothe ya bũrũri ũcio.
26 Ṣùgbọ́n aya Lọti bojú wo ẹ̀yìn, ó sì di ọ̀wọ́n iyọ̀.
No mũtumia wa Loti nĩehũgũrire na thuutha, nake agĩtuĩka gĩtugĩ gĩa cumbĩ.
27 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Abrahamu sì dìde ó sì padà lọ sí ibi tí ó gbé dúró níwájú Olúwa.
Mũthenya ũyũ ũngĩ rũciinĩ tene-rĩ, Iburahĩmu agĩũkĩra na agĩcooka handũ harĩa aarũgamĩte mbere ya Jehova.
28 Ó sì wo ìhà Sodomu àti Gomorra àti àwọn ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, ó sì rí èéfín tí ń ti ibẹ̀ jáde bí èéfín iná ìléru.
Agĩcũthĩrĩria mwena wa Sodomu na Gomora, bũrũri wothe wa kĩaragana kĩu, nake akĩona ndogo ndumanu yambatĩte na igũrũ kuuma bũrũri-inĩ ũcio, ĩhaana ta ndogo yumĩte icua-inĩ.
29 Ọlọ́run sì rántí Abrahamu, nígbà tí ó run ìlú pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀n-ọn-nì tan, ó sì mú Lọti jáde kúrò láàrín ìparun náà, tí ó kọlu ìlú tí Lọti ti gbé.
Nĩ ũndũ ũcio, rĩrĩa Jehova aanangire matũũra macio manene ma kĩaragana kĩu, nĩaririkanire Iburahĩmu, na akĩruta Loti mwanangĩko-inĩ ũcio waharaganirie matũũra macio manene kũrĩa Loti atũire.
30 Lọti àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin méjèèjì sì kúrò ní Soari, wọ́n sì ń lọ gbé ní orí òkè ní inú ihò àpáta, nítorí ó bẹ̀rù láti gbé ní ìlú Soari.
Thuutha ũcio Loti akiuma Zoari, agĩthiĩ gũtũũra kĩrĩma-inĩ arĩ hamwe na airĩtu ake eerĩ, tondũ nĩetigĩrire gũikara Zoari. We na airĩtu ake eerĩ magĩtũũra ngurunga-inĩ.
31 Ní ọjọ́ kan, èyí ẹ̀gbọ́n sọ fún àbúrò rẹ̀ pé, “Baba wa ti dàgbà, kò sì sí ọkùnrin kankan ní agbègbè yìí tí ìbá bá wa lòpọ̀, bí ìṣe gbogbo ayé.
Mũthenya ũmwe-rĩ, mũirĩtu ũrĩa warĩ mũkũrũ akĩĩra ũrĩa warĩ mũnini atĩrĩ, “Ithe witũ nĩ mũkũrũ, na gũtirĩ mũndũ mũrũme ũrĩ hakuhĩ wa gũkoma na ithuĩ, ta ũrĩa arĩ mũtugo kũndũ guothe gũkũ thĩ.
32 Wá, jẹ́ kí a mú baba wa mu ọtí yó, kí ó ba à le bá wa lòpọ̀, kí àwa kí ó lè bí ọmọ, kí ìran wa má ba à parẹ́.”
Reke tũhe ithe witũ ndibei anyue nĩgeetha tũkome nake, na tũtũũrie rũciaro rwitũ na ũndũ wa ithe witũ.”
33 Ní òru ọjọ́ náà, wọ́n rọ baba wọn ní ọtí yó. Èyí ẹ̀gbọ́n sì wọlé tọ̀ ọ́, ó sì bá a lòpọ̀, baba wọn kò mọ̀ ìgbà tí ó sùn ti òun àti ìgbà tí ó dìde.
Ũtukũ ũcio magĩtũma ithe wao anyue ndibei, na mũirĩtu ũrĩa mũkũrũ agĩtoonya na agĩkoma nake. Nowe Loti ndaamenyire rĩrĩa mũirĩtu aakomire kana rĩrĩa ookĩrire.
34 Ní ọjọ́ kejì èyí ẹ̀gbọ́n wí fún àbúrò rẹ̀ pé, “Ní àná mo sùn ti baba mi. Jẹ́ kí a tún wọlé tọ̀ ọ́, kí a lè ní irú-ọmọ láti ọ̀dọ̀ baba wa.”
Mũthenya ũyũ ũngĩ, mũirĩtu ũrĩa mũkũrũ akĩĩra ũrĩa mũnini atĩrĩ, “Hwaĩ ũtukũ nĩ niĩ ndĩrakomire na ithe witũ. Reke tũmũhe ndibei rĩngĩ anyue ũtukũ wa ũmũthĩ, nawe ũthiĩ ũkome nake, nĩgeetha tũtũũrie rũciaro rwitũ na ũndũ wa ithe witũ.”
35 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tún fún baba wọn ní ọtí mu yó ni alẹ́ ọjọ́ náà, èyí àbúrò náà sì wọlé tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bá a lòpọ̀, kò sì tún mọ ìgbà tí ó wọlé sùn ti òun tàbí ìgbà tí ó dìde.
Nĩ ũndũ ũcio magĩtũma ithe wao anyue ndibei ũtukũ ũcio o naguo, nake mũirĩtu ũrĩa warĩ mũnini agĩtoonya agĩkoma nake. O rĩngĩ Loti ndaamenyire rĩrĩa mũirĩtu aakomire kana rĩrĩa ookĩrire.
36 Àwọn ọmọbìnrin Lọti méjèèjì sì lóyún fún baba wọn.
Nĩ ũndũ ũcio airĩtu acio eerĩ a Loti makĩgĩa nda na ithe wao.
37 Èyí ẹ̀gbọ́n sì bí ọmọkùnrin, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Moabu. Òun ni baba ńlá àwọn ará Moabu lónìí.
Mũirĩtu ũrĩa mũkũrũ agĩciara kahĩĩ na agĩgatua Moabi, na nĩwe ithe wa andũ a Moabi gwata ũmũthĩ.
38 Èyí àbúrò náà sì bí ọmọkùnrin, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Bene-Ami. Òun ni baba ńlá àwọn ará Ammoni lónìí.
Mũirĩtu ũrĩa mũnini o nake agĩciara kahĩĩ, nake agĩgatua Beni-Ami, na nĩwe ithe wa Aamoni arĩa marĩ kuo nginya ũmũthĩ.

< Genesis 19 >