< Genesis 19 >
1 Ní àṣálẹ́, àwọn angẹli méjì sì wá sí ìlú Sodomu, Lọti sì jókòó ní ẹnu ibodè ìlú. Bí ó sì ti rí wọn, ó sì dìde láti pàdé wọn, ó kí wọn, ó sì foríbalẹ̀ fún wọn.
Cependant les deux Anges vinrent à Sodome vers le soir, et Lot étant assis à la porte de la ville. Dès qu’il les eut vus, il se leva et alla au-devant d’eux, et se prosterna, incliné vers la terre.
2 Ó wí pé, “Ẹ̀yin olúwa mi, èmi bẹ̀ yín, ẹ yà sí ilé ìránṣẹ́ yín kí ẹ sì wẹ ẹsẹ̀ yín, kí n sì gbà yín lálejò, ẹ̀yin ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ láti máa bá ìrìnàjò yín lọ.” Wọ́n sì wí pé, “Rárá o, àwa yóò dúró ní ìgboro ní òru òní.”
Et il dit: Je vous conjure, seigneurs, venez dans la maison de votre serviteur, et demeurez-y; lavez vos pieds, et dès le matin vous continuerez votre route. Ils répondirent: Point du tout; mais c’est sur la place que nous demeurerons.
3 Ṣùgbọ́n Lọti rọ̀ wọ́n gidigidi tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n gbà láti bá a lọ sì ilé. Ó sì ṣe àsè fún wọn, ó sì dín àkàrà aláìwú fún wọ́n, wọ́n sì jẹ.
Mais il les força par ses instances de venir chez lui; et lorsqu’ils furent entrés dans sa maison, il leur prépara un repas, et il fit cuire des azymes; et ils mangèrent.
4 Ṣùgbọ́n kí ó tó di pé wọ́n lọ sùn, àwọn ọkùnrin ìlú Sodomu tọmọdé tàgbà yí ilé náà ká.
Mais avant qu’ils allassent se coucher, les hommes de la ville environnèrent la maison, depuis l’enfant jusqu’au vieillard, tout le peuple ensemble.
5 Wọ́n pe Lọti pé, “Àwọn ọkùnrin tí ó wọ̀ sí ilé rẹ lálẹ́ yìí ń kọ́? Mú wọn jáde fún wa, kí a le ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú wọn.”
Et ils appelèrent Lot et lui dirent: Où sont les hommes qui sont entrés chez toi cette nuit? Amène-les ici, afin que nous les connaissions.
6 Lọti sì jáde láti pàdé wọn, ó sì ti ìlẹ̀kùn lẹ́yìn rẹ̀ bí ó ti jáde.
Lot étant sorti vers eux, et ayant fermé derrière lui la porte, dit:
7 Ó sì wí pé, “Rárá, ẹ̀yin ará mi, ẹ má ṣe ṣe ohun búburú yìí,
Ne faites pas, je vous prie, mes frères, ne faites pas ce mal.
8 kíyèsi i, mo ní ọmọbìnrin méjì tí kò mọ ọkùnrin rí, ẹ jẹ́ kí n mú wọn tọ̀ yín wá kí ẹ sì ṣe ohun tí ẹ fẹ́ pẹ̀lú wọn. Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣe àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ní ibi kan nítorí wọ́n wá wọ̀ lábẹ́ ààbò ní ilé mi.”
J’ai deux filles qui n’ont pas encore connu d’hommes: je vous les amènerai, et vous ferez d’elles ce qui vous plaira, pourvu qu’à ces hommes vous ne fassiez aucun mal; car ils sont venus à l’ombre de mon toit.
9 Wọ́n sì wí fún pé, “Bì sẹ́yìn fún wa. Èyí yìí wá ṣe àtìpó láàrín wa, òun sì fẹ́ ṣe onídàájọ́! Aburú tí a ó fi ṣe ọ́ yóò pọ̀ ju tí wọn lọ.” Wọn rọ́ lu Lọti, wọ́n sì súnmọ́ ọn láti fọ́ ìlẹ̀kùn.
Mais ils répondirent: Retire-toi d’ici. Et de nouveau: Tu es venu ici, dirent-ils, comme étranger; est-ce pour t’ériger en juge. C’est donc toi-même que nous maltraiterons plus qu’eux. Et ils faisaient à Lot la plus grande violence; et déjà ils étaient près d’enfoncer la porte.
10 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà nawọ́ fa Lọti wọlé, wọ́n sì ti ìlẹ̀kùn.
Mais voilà que les hommes avancèrent la main, firent rentrer Lot auprès d’eux et fermèrent la porte;
11 Wọ́n sì bu ìfọ́jú lu àwọn ọkùnrin tí ó wà ní ẹnu-ọ̀nà ilé náà, àti èwe àti àgbà: wọ́n kò sì rí ẹnu-ọ̀nà mọ́.
Et ceux qui étaient dehors, ils les frappèrent d’aveuglement, depuis le plus petit Jusqu’au plus grand, en sorte qu’ils ne pouvaient retrouver la porte.
12 Àwọn ọkùnrin náà sì wí fún Lọti pé, “Ǹjẹ́ ó ní ẹlòmíràn ní ìlú yìí bí? Àna rẹ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ lọ́kùnrin àti lóbìnrin, tàbí ẹnikẹ́ni tí ìwọ ní ní ìlú yìí, kó wọn jáde kúrò ní ibí yìí,
Alors ils dirent à Lot: As-tu ici quelqu’un des tiens, un gendre, ou des fils, ou des filles? tous ceux qui sont à toi, fais-les sortir de cette ville;
13 nítorí a ó pa ìlú yìí run, nítorí igbe iṣẹ́ búburú wọn ń dí púpọ̀ níwájú Olúwa, Olúwa sì rán wa láti pa á run.”
Car nous détruirons ce lieu, parce que leur clameur s’est élevée de plus en plus devant le Seigneur qui nous a envoyés pour les perdre.
14 Nígbà náà ni Lọti jáde, ó sì wí fún àwọn àna rẹ̀ ọkùnrin tí ó ti bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fẹ́ àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ ṣe kánkán, kí ẹ jáde ní ìlú yìí, nítorí Olúwa fẹ́ pa ìlú yìí run!” Ṣùgbọ́n àwọn ọkọ ọmọ rẹ̀ wọ̀nyí rò pé àwàdà ló ń ṣe.
Lot étant donc sorti, parla à ses gendres, qui devaient épouser ses filles, et dit: Levez-vous, sortez de ce lieu; parce que le Seigneur détruira cette ville. Et il leur sembla parler comme en se jouant.
15 Ní àfẹ̀mọ́júmọ́, àwọn angẹli náà rọ Lọti pé, “Ṣe wéré, mú aya rẹ àti àwọn ọmọbìnrin rẹ méjèèjì tí ó wà níhìn-ín, àìṣe bẹ́ẹ̀, ìwọ yóò parun pẹ̀lú ìlú yìí nígbà tí wọ́n bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”
Mais lorsqu’il fut matin, les Anges le pressaient, disant: Lève-toi, prends ta femme, et les deux filles que tu as, afin que tu ne périsses pas, toi aussi, dans le châtiment de la ville.
16 Nígbà tí ó ń jáfara, àwọn ọkùnrin náà nawọ́ mú un lọ́wọ́, wọ́n sì nawọ́ mú aya rẹ̀ náà lọ́wọ́ àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ méjèèjì, wọ́n sì mú wọn jáde sẹ́yìn odi ìlú, nítorí Olúwa ṣàánú fún wọn.
Mais lui différant, ils prirent sa main et la main de sa femme et de ses deux filles, parce que le Seigneur lui faisait grâce.
17 Ní kété tí wọ́n mú wọn jáde sẹ́yìn odi tán, ọ̀kan nínú wọn wí pé, “Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe wo ẹ̀yìn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ kí ó má ṣe dúró ní gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀! Sá àsálà lọ sí orí òkè, kí ìwọ ó má ba ṣègbé!”
Et ils l’emmenèrent, le mirent hors de la ville: et là, ils lui parlèrent, disant: Sauve ton âme; ne regarde point derrière toi, et ne t’arrête dans aucune contrée d’alentour; mais sauve-toi sur la montagne, de peur que tu ne périsses toi aussi avec les autres.
18 Ṣùgbọ́n Lọti wí fún wọn pé, “Rárá, ẹ̀yin Olúwa mi, ẹ jọ̀wọ́!
Et Lot leur répondit: Je vous prie, mon Seigneur,
19 Nígbà tí ìránṣẹ́ rẹ ti rí ojúrere rẹ, tí o sì ti fi àánú rẹ hàn nípa gbígba ẹ̀mí mi là, èmi kò le è sálọ sórí òkè, kí búburú yìí má ba à lé mi bá, kí n sì kú.
Puisque votre serviteur a trouvé grâce devant vous et que vous avez signalé la miséricorde que vous m’avez faite, pour sauver mon âme, non, je ne puis être sauvé sur la montagne; il est à craindre que le mal ne m’atteigne, et que je ne meure.
20 Wò ó, ìlú kékeré kan nìyí ní tòsí láti sá sí: jẹ́ kí n sálọ síbẹ̀, ìlú kékeré ha kọ́? Ẹ̀mí mi yóò sì yè.”
Cette ville ici près, où je puis m’enfuir, est petite et j’y serai sauvé; n’est-elle pas de peu d’étendue? et mon âme n’y vivra-t-elle pas?
21 Ó sì wí fún un pé, “Ó dára, mo gba ẹ̀bẹ̀ rẹ. Èmi kì yóò run ìlú náà tí ìwọ sọ̀rọ̀ rẹ̀.
Et il lui répondit: Voici que même en cela, j’ai accueilli ta prière, de ne pas détruire la ville pour laquelle tu m’as parlé.
22 Tètè! Sálọ síbẹ̀, nítorí èmi kò le ṣe ohun kan àyàfi tí ó bá dé ibẹ̀.” (ìdí nìyí tí a fi ń pe ìlú náà ní Soari).
Hâte-toi, et tu y seras sauvé; car je ne pourrai rien faire jusqu’à ce que tu y sois entré. C’est pourquoi cette ville fut appelée du nom de Ségor.
23 Nígbà tí Lọti yóò fi dé ìlú Soari, oòrùn ti yọ.
Le soleil se leva sur la terre, et Lot entra dans Ségor.
24 Nígbà náà ni Olúwa rọ̀jò iná àti sulfuru sórí Sodomu àti Gomorra láti ọ̀run lọ́dọ̀ Olúwa wá.
Le Seigneur donc fit pleuvoir sur Sodome et Gomorrhe du soufre et du feu venus du ciel d’auprès du Seigneur;
25 Báyìí ni ó run àwọn ìlú náà àti gbogbo ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó wà ní ìlú ńlá ńlá wọ̀n-ọn-nì àti ohun gbogbo tí ó hù jáde nílẹ̀.
Et il détruisit ces villes, et toute la contrée d’alentour, et tous les habitants des villes, et toutes les plantes de la terre.
26 Ṣùgbọ́n aya Lọti bojú wo ẹ̀yìn, ó sì di ọ̀wọ́n iyọ̀.
Et la femme de Lot, regardant derrière elle, fut changée en une statue de sel.
27 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Abrahamu sì dìde ó sì padà lọ sí ibi tí ó gbé dúró níwájú Olúwa.
Or Abraham se levant le matin, et venant où il avait été auparavant avec le Seigneur,
28 Ó sì wo ìhà Sodomu àti Gomorra àti àwọn ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, ó sì rí èéfín tí ń ti ibẹ̀ jáde bí èéfín iná ìléru.
Regarda Sodome et Gomorrhe, et toute la terre de cette contrée, et il vit une fumée qui montait de la terre, comme la fumée d’une fournaise.
29 Ọlọ́run sì rántí Abrahamu, nígbà tí ó run ìlú pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀n-ọn-nì tan, ó sì mú Lọti jáde kúrò láàrín ìparun náà, tí ó kọlu ìlú tí Lọti ti gbé.
Mais, lorsque le Seigneur détruisait les villes de cette contrée, s’étant souvenu d’Abraham, il sauva Lot de la ruine de ces villes dans lesquelles il avait habité.
30 Lọti àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin méjèèjì sì kúrò ní Soari, wọ́n sì ń lọ gbé ní orí òkè ní inú ihò àpáta, nítorí ó bẹ̀rù láti gbé ní ìlú Soari.
Et Lot sortit de Ségor; il se retira sur la montagne, et ses deux filles avec lui (car il craignait de demeurer dans Ségor), et il demeura dans la caverne, lui et ses deux filles avec lui.
31 Ní ọjọ́ kan, èyí ẹ̀gbọ́n sọ fún àbúrò rẹ̀ pé, “Baba wa ti dàgbà, kò sì sí ọkùnrin kankan ní agbègbè yìí tí ìbá bá wa lòpọ̀, bí ìṣe gbogbo ayé.
Or l’aînée dit à la plus jeune: Notre père est vieux, et il n’est resté sur la terre aucun homme qui puisse nous épouser selon la coutume de toute la terre.
32 Wá, jẹ́ kí a mú baba wa mu ọtí yó, kí ó ba à le bá wa lòpọ̀, kí àwa kí ó lè bí ọmọ, kí ìran wa má ba à parẹ́.”
Viens, et enivrons-le de vin, et dormons avec lui, afin que nous puissions par notre père conserver une postérité.
33 Ní òru ọjọ́ náà, wọ́n rọ baba wọn ní ọtí yó. Èyí ẹ̀gbọ́n sì wọlé tọ̀ ọ́, ó sì bá a lòpọ̀, baba wọn kò mọ̀ ìgbà tí ó sùn ti òun àti ìgbà tí ó dìde.
Elles donnèrent donc à leur père du vin à boire cette nuit-là; et l’aînée vint et dormit avec son père; mais celui-ci ne s’aperçut, ni quand sa fille se coucha, ni quand elle se leva.
34 Ní ọjọ́ kejì èyí ẹ̀gbọ́n wí fún àbúrò rẹ̀ pé, “Ní àná mo sùn ti baba mi. Jẹ́ kí a tún wọlé tọ̀ ọ́, kí a lè ní irú-ọmọ láti ọ̀dọ̀ baba wa.”
Et le lendemain, l’aînée dit à la plus jeune: Voilà que j’ai dormi hier avec mon père; donnons-lui à boire du vin encore cette nuit, et tu dormiras avec lui, afin que nous conservions une postérité de notre père.
35 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tún fún baba wọn ní ọtí mu yó ni alẹ́ ọjọ́ náà, èyí àbúrò náà sì wọlé tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bá a lòpọ̀, kò sì tún mọ ìgbà tí ó wọlé sùn ti òun tàbí ìgbà tí ó dìde.
Et elles donnèrent encore cette nuit-là à leur père du vin à boire; et la plus jeune fille dormit avec lui; et encore cette fois, il ne s’aperçut pas quand elle se coucha, ou quand elle se leva.
36 Àwọn ọmọbìnrin Lọti méjèèjì sì lóyún fún baba wọn.
Ainsi les deux filles de Lot conçurent de leur père.
37 Èyí ẹ̀gbọ́n sì bí ọmọkùnrin, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Moabu. Òun ni baba ńlá àwọn ará Moabu lónìí.
L’aînée enfanta un fils, et l’appela du nom de Moab; c’est le père des Moabites, jusqu’au présent jour.
38 Èyí àbúrò náà sì bí ọmọkùnrin, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Bene-Ami. Òun ni baba ńlá àwọn ará Ammoni lónìí.
La plus jeune aussi enfanta un fils, et l’appela du nom d’Ammon, c’est-à-dire le fils de mon peuple; c’est le père des Ammonites, jusqu’aujourd’hui.