< Genesis 18 >

1 Olúwa sì farahan Abrahamu nítòsí àwọn igi ńlá Mamre, bí ó ti jókòó ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ rẹ̀, nígbà tí ọjọ́-kanrí tí oòrùn sì mú.
Perwerdigar Mamrediki dubzarliqning yénida Ibrahimgha köründi; bu kün eng issighan waqit bolup, u öz chédirining ishikide olturatti.
2 Abrahamu gbójú sókè, ó sì rí àwọn ọkùnrin mẹ́ta tí wọn dúró nítòsí rẹ̀. Nígbà tí ó rí wọn, ó sáré láti lọ pàdé wọn, ó sì tẹríba bí ó ti ń kí wọn.
U béshini kötürüp nezer séliwidi, mana uning udulida üch kishi öre turatti. Ularni körüp u chédirining ishikidin qopup, ularning aldigha yügürüp bérip, yerge tegküdek tezim qilip:
3 Ó wí pé, “Bí mo bá rí ojúrere yín Olúwa mi, ẹ má ṣe lọ láì yà sọ́dọ̀ ìránṣẹ́ yín.
— i Rebbim, eger péqir nezerliride iltipat tapqan bolsam, ötünimenki, qullirining yénidin ötüp ketmigeyla;
4 Ẹ jẹ́ kí a bu omi díẹ̀ wá kí ẹ̀yin kí ó wẹ ẹsẹ̀ yín, kí ẹ sì sinmi lábẹ́ igi níhìn-ín.
azghina su keltürülsun, siler putliringlarni yuyup derexning tégide aram éliwélinglar.
5 Ẹ jẹ́ kí n wá oúnjẹ wá fún un yín, kí ẹ̀yin kí ó lè jẹ, kí ara sì tù yín, kí ẹ si tẹ̀síwájú ní ọ̀nà yín, nígbà tí ẹ ti yà ní ọ̀dọ̀ ìránṣẹ́ yín.” Wọn sì wí pé “Ó dára.”
Siler öz qulunglarning yénidin ötkenikensiler, men bir chishlem nan élip chiqay, siler harduqunglarni chiqirip, andin ötüp ketkeysiler, dédi. Ular jawab bérip: — Éytqiningdek qilghin, déwidi,
6 Abrahamu sì yára tọ Sara aya rẹ̀ lọ nínú àgọ́, ó wí pé, “Tètè mú òsùwọ̀n ìyẹ̀fun dáradára mẹ́ta kí o sì pò ó pọ̀, kí o sì ṣe oúnjẹ.”
Ibrahim chédirigha Sarahning qéshigha yügürüp kirip, uninggha: — Üch das ésil undin téz xémir yughurup toqach etkin, — dédi.
7 Abrahamu sì tún sáré lọ sí ibi agbo ẹran, ó sì mú ọmọ màlúù kan fún ìránṣẹ́ rẹ̀, ìránṣẹ́ náà sì tètè ṣè é.
Andin Ibrahim kala padisigha yügürüp bérip, yumran obdan bir mozayni tallap, chakirigha tapshurdi; u buni tézla teyyar qildi.
8 Ó sì mú wàrà àti mílíìkì àti màlúù tí ó ti pèsè, ó sì gbé síwájú wọn. Ó sì dúró nítòsí wọn lábẹ́ igi bí wọn ti ń jẹ ẹ́.
Andin Ibrahim sériq may, süt we teyyarlatqan mozayni élip kélip, ularning aldigha tutup, özi derexning tégide ularning aldida öre turdi; ular ulardin yédi. Ular uningdin: ayaling Sarah nede, dep soriwidi, u jawab bérip: — Mana, chédirda, dédi.
9 Wọn béèrè pé, “Sara aya rẹ ń kọ́?” Ó dáhùn pé, “Ó wà nínú àgọ́.”
10 Nígbà náà ni Olúwa wí fún un pé, “Èmi yóò sì tún padà tọ̀ ọ́ wá nítòótọ́ ní ìwòyí àmọ́dún; Sara aya rẹ yóò sì bí ọmọkùnrin kan.” Sara sì ń dẹtí gbọ́ láti ẹnu-ọ̀nà àgọ́ tí ó wà lẹ́yìn ọkùnrin náà.
Birsi: — Men kéler yili mushu waqitta qéshinggha jezmen qaytip kélimen, we mana u waqitta ayaling Sarahning bir oghli bolidu, — dédi. Sarah bolsa uning keynidiki chédirning ishikide turup, bularni anglawatatti.
11 Abrahamu àti Sara sì ti di arúgbó, Sara sì ti kọjá àsìkò ìbímọ.
Ibrahim bilen Sarah ikkisi yashinip, qérip qalghanidi; Sarahta ayal kishilerde bolidighan adet körüsh toxtap qalghanidi.
12 Nítorí náà, Sara rẹ́rìn-ín nínú ara rẹ̀ bí ó ti ń rò ó lọ́kàn rẹ̀ pé, “Lẹ́yìn ìgbà tí mo ti di arúgbó tán tí olúwa mi pẹ̀lú sì ti gbó jọ̀kújọ̀kú, èmi yóò ha tún lè bímọ?”
Shunga Sarah öz ichide külüp: — Men shunche qérip ketken tursam, rasttinla lezzet körelermenmu? Érimmu qérip ketken tursa? — dep xiyal qildi.
13 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Abrahamu pé, “Kín ló dé tí Sara fi rẹ́rìn-ín tí ó sì wí pé, ‘Èmi yóò ha bímọ nítòótọ́, nígbà tí mo di ẹni ogbó tán?’
Perwerdigar Ibrahimgha: — Sarahning: «Men qérip ketken tursam, rasttinla bala tugharmenmu?» dep külgini némisi?
14 Ǹjẹ́ ohunkóhun wà tí ó ṣòro jù fún Olúwa? Èmi ó padà tọ̀ ọ́ wá ní ìwòyí àmọ́dún, Sara yóò sì bí ọmọkùnrin.”
Perwerdigargha mumkin bolmaydighan tilsimat ish barmu? Békitken waqitta, yeni kéler yili del bu chaghda qaytip kélimen we u waqitta Sarahning bir oghli bolidu, — dédi.
15 Ẹ̀rù sì ba Sara, ó sì sẹ́ pé òun kò rẹ́rìn-ín. Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Dájúdájú ìwọ rẹ́rìn-ín.”
Emma Sarah qorqup kétip: — Külmidim, dep inkar qildi. Lékin U: — Yaq, sen küldüng, — dédi.
16 Nígbà tí àwọn ọkùnrin náà dìde láti máa lọ, wọn kọjú sí ọ̀nà Sodomu, Abrahamu sì sìn wọ́n dé ọ̀nà.
Andin bu zatlar u yerdin qopup, Sodom terepke nezirini aghdurdi. Ibrahimmu ularni uzitip, ular bilen bille mangdi.
17 Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Ǹjẹ́ èmi yóò ha pa ohun tí mo fẹ́ ṣe mọ́ fún Abrahamu bí?
Perwerdigar: — Men qilidighan ishimni Ibrahimdin yoshursam bolamdu?
18 Dájúdájú Abrahamu yóò sá à di orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára, àti gbogbo orílẹ̀-èdè ayé ni a ó bùkún fún nípasẹ̀ rẹ̀.
Chünki Ibrahimdin ulugh we küchlük bir el chiqidu we shuningdek yer yüzidiki barliq el-milletler u arqiliq bext-beriketke muyesser bolidighan tursa?
19 Nítorí tí èmi ti yàn án láti kọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ará ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, láti máa pa ọ̀nà Olúwa mọ nípa ṣíṣe olóòtítọ́ àti olódodo: kí Olúwa le è mú ìlérí rẹ̀ fún Abrahamu ṣẹ.”
Chünki Men uni bilip tallighanmen; u choqum öz balilirini we uning öyidikilerni özige egeshtürüp, ulargha Perwerdigarning yolini tutup, heqqaniyliqni we adaletni yürgüzüshni ögitidu. Buning bilen Menki Perwerdigar Ibrahim toghruluq qilghan wedemni emelge ashurimen, — dédi.
20 Olúwa sì wí pé, igbe Sodomu àti Gomorra pọ̀ púpọ̀ àti pé ẹ̀ṣẹ̀ wọn burú jọjọ.
Andin Perwerdigar mundaq dédi: — «Sodom we Gomorra toghruluq kötürülgen dad-peryad nahayiti küchlük, ularning gunahi intayin éghir bolghini üchün,
21 “Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ síbẹ̀ láti ṣe ìwádìí igbe tí ó dé sí etí ìgbọ́ mi nípa wọn, kí èmi sì mọ òtítọ́ tí ó wà níbẹ̀.”
Men hazirla chüshimen, qilmishliri rasttinla shu dad-peryadlardin Manga melum bolghandek shunche rezilmu, bilip baqay; unche rezil bolmighandimu, Men uni bilishim kérek».
22 Àwọn ọkùnrin náà yí padà, wọ́n sì ń lọ sí ìhà Sodomu. Ṣùgbọ́n Abrahamu dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa.
Shuning bilen bu kishiler u yerdin qozghilip, Sodom terepke yol aldi. Lékin Ibrahim yenila Perwerdigarning aldida öre turatti.
23 Nígbà náà ni Abrahamu súnmọ́ ọ̀dọ̀ Olúwa, ó sì wí pé, “Ìwọ yóò ha pa olódodo ènìyàn àti ènìyàn búburú run papọ̀ bí?”
Ibrahim yéqin bérip: — Sen rasttinla heqqaniylarni reziller bilen qoshup halak qilamsen?
24 “Bí ó bá ṣe pé ìwọ rí àádọ́ta olódodo nínú ìlú náà, ìwọ yóò ha run ún, ìwọ kì yóò ha dá ìlú náà sí nítorí àwọn àádọ́ta olódodo tí ó wà nínú rẹ̀ náà?
Sheherde ellik heqqaniy kishi bar bolushi mumkin; Sen rasttinla shu jayni halak qilamsen, ellik heqqaniy kishi üchün u jayni kechürüm qilmamsen?
25 Kò jẹ́ rí bẹ́ẹ̀! Dájúdájú ìwọ kì yóò ṣe ohun tí ó jọ bẹ́ẹ̀, láti pa olódodo pẹ̀lú àwọn ènìyàn rere àti àwọn ènìyàn búburú. Dájúdájú, ìwọ kì yóò ṣe èyí tí ó tọ́ bi?”
Yaq, yaq. Bu ish Sendin néri bolghay! Heqqaniylarni rezillerge qoshup öltürüp, heqqaniylargha rezillerge oxshash muamile qilish Sendin néri bolghay! Pütkül jahanning soraqchisi adalet yürgüzmemdu? — dédi.
26 Olúwa wí pé, “Bí mo bá rí àádọ́ta olódodo ní ìlú Sodomu, èmi yóò dá ìlú náà sí nítorí tiwọn.”
Perwerdigar jawab bérip: — Eger Men Sodom shehiride ellik heqqaniyni tapsam, ular üchün pütkül jayni ayap qalimen, — dédi.
27 Abrahamu sì tún tẹ̀síwájú pé, “Wò ó nísinsin yìí, níwọ̀n bí èmi ti ní ìgboyà láti bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa, èmi ẹni tí í ṣe erùpẹ̀ àti eérú,
Andin Ibrahim jawab bérip: — Mana men peqet topa bilen küldin ibaret bolsammu, men Igem bilen sözleshkili yene pétinalidim.
28 bí ó bá ṣe pe olódodo márùndínláàádọ́ta ni ó wà nínú ìlú, ìwọ yóò ha pa ìlú náà run nítorí ènìyàn márùn-ún bí?” Olúwa dáhùn pé, “Èmi kì yóò pa ìlú náà run bí mo bá rí olódodo márùndínláàádọ́ta nínú rẹ̀.”
Mubada shu ellik heqqaniydin besh kishi kem bolsa, Sen bu besh kishining kem bolghini üchün pütkül sheherni yoqitamsen? — dédi. U: — Eger Men shu yerde qiriq beshni tapsammu, uni yoqatmaymen, dédi.
29 Òun sì tún wí lẹ́ẹ̀kan si pé, “Bí ó bá ṣe pé ogójì ni ń kọ́?” Olúwa sì tún wí pé, “Èmi kì yóò pa ìlú náà run bí mo bá rí olódodo ogójì nínú rẹ̀.”
Ibrahim Uninggha sözini dawam qilip: — Shu yerde qiriq kishila tépilishi mumkin, déwidi, [Perwerdigar]: — Bu qiriqi üchün uni yoqatmaymen, — dédi.
30 Abrahamu sì tún bẹ Olúwa pé, “Kí Olúwa má ṣe bínú, ṣùgbọ́n èmi yóò sọ̀rọ̀. Bí ó bá ṣe pé ọgbọ̀n ni a rí níbẹ̀ ń kọ́?” Olúwa dáhùn pé, “Bí mó bá rí ọgbọ̀n, èmi kì yóò pa ìlú run.”
U yene söz qilip: I Igem, xapa bolmighaysen, men yene söz qilay. Shu yerde ottuzi tépilishi mumkin? — dédi. U: — Eger Men u yerde ottuzni tapsammu, yoqatmaymen, — dédi.
31 Abrahamu wí pé, “Níwọ́n bí mo ti ní ìgboyà láti bá Olúwa sọ̀rọ̀ báyìí, jẹ́ kí n tẹ̀síwájú. Bí o bá ṣe pé olódodo ogún péré ni ó wà nínú ìlú náà ń kọ́?” Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi kì yóò pa á run nítorí ogún ènìyàn náà.”
U yene söz qilip: — Mana emdi men Igem bilen sözleshkili jür’et qildim; shu yerde yigirmisi tépilishi mumkin, — dédi. Perwerdigar söz qilip: bu yigirmisi üchün u yerni yoqatmaymen, — dédi.
32 Abrahamu sì wí pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú Olúwa. Jẹ́ kí ń béèrè lẹ́ẹ̀kan si. Bí ó bá ṣe pé ènìyàn mẹ́wàá ni ó jẹ́ olódodo ń kọ́?” Olúwa wí pé, “Nítorí ènìyàn mẹ́wàá náà, èmi kì yóò pa á run.”
U sözlep: — I Igem, xapa bolmighay, men peqet mushu bir qétimla söz qilay! Shu yerde oni tépilishi mumkin, déwidi, u jawab bérip: — Men oni üchün uni yoqatmaymen, — dédi.
33 Olúwa sì bá tirẹ̀ lọ, nígbà tí ó bá Abrahamu sọ̀rọ̀ tán, Abrahamu sì padà sílé.
Perwerdigar Ibrahim bilen sözliship bolghandin kéyin ketti; Ibrahimmu öz jayigha qaytip ketti.

< Genesis 18 >