< Genesis 18 >

1 Olúwa sì farahan Abrahamu nítòsí àwọn igi ńlá Mamre, bí ó ti jókòó ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ rẹ̀, nígbà tí ọjọ́-kanrí tí oòrùn sì mú.
هنگامی که ابراهیم در بلوطستان ممری سکونت داشت، خداوند بار دیگر بر او ظاهر شد. شرح واقعه چنین است: ابراهیم در گرمای روز بر در خیمه خود نشسته بود.
2 Abrahamu gbójú sókè, ó sì rí àwọn ọkùnrin mẹ́ta tí wọn dúró nítòsí rẹ̀. Nígbà tí ó rí wọn, ó sáré láti lọ pàdé wọn, ó sì tẹríba bí ó ti ń kí wọn.
ناگهان متوجه شد که سه مرد به طرفش می‌آیند. پس از جا برخاست و به استقبال آنها شتافت. ابراهیم رو به زمین نهاده،
3 Ó wí pé, “Bí mo bá rí ojúrere yín Olúwa mi, ẹ má ṣe lọ láì yà sọ́dọ̀ ìránṣẹ́ yín.
گفت: «ای سَروَرم، تمنا می‌کنم اندکی توقف کرده،
4 Ẹ jẹ́ kí a bu omi díẹ̀ wá kí ẹ̀yin kí ó wẹ ẹsẹ̀ yín, kí ẹ sì sinmi lábẹ́ igi níhìn-ín.
در زیر سایه این درخت استراحت کنید. من می‌روم و برای شستن پاهای شما آب می‌آورم.
5 Ẹ jẹ́ kí n wá oúnjẹ wá fún un yín, kí ẹ̀yin kí ó lè jẹ, kí ara sì tù yín, kí ẹ si tẹ̀síwájú ní ọ̀nà yín, nígbà tí ẹ ti yà ní ọ̀dọ̀ ìránṣẹ́ yín.” Wọn sì wí pé “Ó dára.”
لقمه نانی نیز خواهم آورد تا بخورید و قوت بگیرید و بتوانید به سفر خود ادامه دهید. شما میهمان من هستید.» آنها گفتند: «آنچه گفتی بکن.»
6 Abrahamu sì yára tọ Sara aya rẹ̀ lọ nínú àgọ́, ó wí pé, “Tètè mú òsùwọ̀n ìyẹ̀fun dáradára mẹ́ta kí o sì pò ó pọ̀, kí o sì ṣe oúnjẹ.”
آنگاه ابراهیم با شتاب به خیمه برگشت و به سارا گفت: «عجله کن! چند نان از بهترین آردی که داری بپز.»
7 Abrahamu sì tún sáré lọ sí ibi agbo ẹran, ó sì mú ọmọ màlúù kan fún ìránṣẹ́ rẹ̀, ìránṣẹ́ náà sì tètè ṣè é.
سپس خودش به طرف گله دویده، یک گوسالهٔ خوب گرفت و به نوکر خود داد تا هر چه زودتر آن را آماده کند.
8 Ó sì mú wàrà àti mílíìkì àti màlúù tí ó ti pèsè, ó sì gbé síwájú wọn. Ó sì dúró nítòsí wọn lábẹ́ igi bí wọn ti ń jẹ ẹ́.
طولی نکشید که ابراهیم مقداری کره و شیر و کباب برای مهمانان خود آورد و جلوی آنها گذاشت و در حالی که آنها مشغول خوردن بودند، زیر درختی در کنار ایشان ایستاد.
9 Wọn béèrè pé, “Sara aya rẹ ń kọ́?” Ó dáhùn pé, “Ó wà nínú àgọ́.”
مهمانان از ابراهیم پرسیدند: «همسرت سارا کجاست؟» جواب داد: «او در خیمه است.»
10 Nígbà náà ni Olúwa wí fún un pé, “Èmi yóò sì tún padà tọ̀ ọ́ wá nítòótọ́ ní ìwòyí àmọ́dún; Sara aya rẹ yóò sì bí ọmọkùnrin kan.” Sara sì ń dẹtí gbọ́ láti ẹnu-ọ̀nà àgọ́ tí ó wà lẹ́yìn ọkùnrin náà.
آنگاه یکی از ایشان گفت: «سال بعد در چنین زمانی نزد تو خواهم آمد و سارا پسری خواهد زایید!» (سارا پشت درِ خیمه ایستاده بود و به سخنان آنها گوش می‌داد.)
11 Abrahamu àti Sara sì ti di arúgbó, Sara sì ti kọjá àsìkò ìbímọ.
در آن وقت ابراهیم و سارا هر دو بسیار پیر بودند و دیگر از سارا گذشته بود که صاحب فرزندی شود.
12 Nítorí náà, Sara rẹ́rìn-ín nínú ara rẹ̀ bí ó ti ń rò ó lọ́kàn rẹ̀ pé, “Lẹ́yìn ìgbà tí mo ti di arúgbó tán tí olúwa mi pẹ̀lú sì ti gbó jọ̀kújọ̀kú, èmi yóò ha tún lè bímọ?”
پس سارا در دل خود خندید و گفت: «آیا زنی به سن و سال من با چنین شوهر پیری می‌تواند بچه‌دار شود؟»
13 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Abrahamu pé, “Kín ló dé tí Sara fi rẹ́rìn-ín tí ó sì wí pé, ‘Èmi yóò ha bímọ nítòótọ́, nígbà tí mo di ẹni ogbó tán?’
خداوند به ابراهیم گفت: «چرا سارا خندید و گفت:”آیا زنی به سن و سال من می‌تواند بچه‌دار شود؟“
14 Ǹjẹ́ ohunkóhun wà tí ó ṣòro jù fún Olúwa? Èmi ó padà tọ̀ ọ́ wá ní ìwòyí àmọ́dún, Sara yóò sì bí ọmọkùnrin.”
مگر کاری هست که برای خداوند مشکل باشد؟ همان‌طوری که به تو گفتم سال بعد، در چنین زمانی نزد تو خواهم آمد و سارا پسری خواهد زایید.»
15 Ẹ̀rù sì ba Sara, ó sì sẹ́ pé òun kò rẹ́rìn-ín. Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Dájúdájú ìwọ rẹ́rìn-ín.”
اما سارا چون ترسیده بود، انکار نموده، گفت: «من نخندیدم!» گفت: «چرا خندیدی!»
16 Nígbà tí àwọn ọkùnrin náà dìde láti máa lọ, wọn kọjú sí ọ̀nà Sodomu, Abrahamu sì sìn wọ́n dé ọ̀nà.
آنگاه آن سه مرد برخاستند تا به شهر سدوم بروند و ابراهیم نیز برخاست تا ایشان را بدرقه کند.
17 Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Ǹjẹ́ èmi yóò ha pa ohun tí mo fẹ́ ṣe mọ́ fún Abrahamu bí?
اما خداوند گفت: «آیا نقشهٔ خود را از ابراهیم پنهان کنم؟
18 Dájúdájú Abrahamu yóò sá à di orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára, àti gbogbo orílẹ̀-èdè ayé ni a ó bùkún fún nípasẹ̀ rẹ̀.
حال آنکه از وی قومی بزرگ و قوی پدید خواهد آمد و همهٔ قومهای جهان از او برکت خواهند یافت.
19 Nítorí tí èmi ti yàn án láti kọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ará ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, láti máa pa ọ̀nà Olúwa mọ nípa ṣíṣe olóòtítọ́ àti olódodo: kí Olúwa le è mú ìlérí rẹ̀ fún Abrahamu ṣẹ.”
من او را برگزیده‌ام تا فرزندان و اهل خانهٔ خود را تعلیم دهد که مرا اطاعت نموده، آنچه را که راست و درست است به جا آورند. اگر چنین کنند من نیز آنچه را که به او وعده داده‌ام، انجام خواهم داد.»
20 Olúwa sì wí pé, igbe Sodomu àti Gomorra pọ̀ púpọ̀ àti pé ẹ̀ṣẹ̀ wọn burú jọjọ.
پس خداوند به ابراهیم فرمود: «فریاد علیه ظلمِ مردم سدوم و عموره بلند شده است و گناهان ایشان بسیار زیاد گشته است.
21 “Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ síbẹ̀ láti ṣe ìwádìí igbe tí ó dé sí etí ìgbọ́ mi nípa wọn, kí èmi sì mọ òtítọ́ tí ó wà níbẹ̀.”
پس به پایین می‌روم تا به فریادی که به گوش من رسیده است، رسیدگی کنم.»
22 Àwọn ọkùnrin náà yí padà, wọ́n sì ń lọ sí ìhà Sodomu. Ṣùgbọ́n Abrahamu dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa.
آنگاه آن دو نفر به جانب شهر سدوم روانه شدند، ولی خداوند نزد ابراهیم ماند.
23 Nígbà náà ni Abrahamu súnmọ́ ọ̀dọ̀ Olúwa, ó sì wí pé, “Ìwọ yóò ha pa olódodo ènìyàn àti ènìyàn búburú run papọ̀ bí?”
ابراهیم به او نزدیک شده، گفت: «خداوندا، آیا عادلان را با بدکاران با هم هلاک می‌کنی؟
24 “Bí ó bá ṣe pé ìwọ rí àádọ́ta olódodo nínú ìlú náà, ìwọ yóò ha run ún, ìwọ kì yóò ha dá ìlú náà sí nítorí àwọn àádọ́ta olódodo tí ó wà nínú rẹ̀ náà?
شاید پنجاه عادل در آن شهر باشند. آیا به خاطر آنها، از نابود کردن آنجا صرفنظر نخواهی کرد؟
25 Kò jẹ́ rí bẹ́ẹ̀! Dájúdájú ìwọ kì yóò ṣe ohun tí ó jọ bẹ́ẹ̀, láti pa olódodo pẹ̀lú àwọn ènìyàn rere àti àwọn ènìyàn búburú. Dájúdájú, ìwọ kì yóò ṣe èyí tí ó tọ́ bi?”
یقین دارم که تو عادلان را با بدکاران هلاک نخواهی نمود. چطور ممکن است با عادلان و بدکاران یکسان رفتار کنی؟ آیا داور تمام جهان از روی عدل و انصاف داوری نخواهد کرد؟»
26 Olúwa wí pé, “Bí mo bá rí àádọ́ta olódodo ní ìlú Sodomu, èmi yóò dá ìlú náà sí nítorí tiwọn.”
خداوند در پاسخ ابراهیم فرمود: «اگر پنجاه عادل در شهر سدوم پیدا کنم، به خاطر آنها از نابود کردن آنجا صرفنظر خواهم کرد.»
27 Abrahamu sì tún tẹ̀síwájú pé, “Wò ó nísinsin yìí, níwọ̀n bí èmi ti ní ìgboyà láti bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa, èmi ẹni tí í ṣe erùpẹ̀ àti eérú,
ابراهیم باز عرض کرد: «به منِ ناچیز و خاکی اجازه بده جسارت کرده، بگویم که
28 bí ó bá ṣe pe olódodo márùndínláàádọ́ta ni ó wà nínú ìlú, ìwọ yóò ha pa ìlú náà run nítorí ènìyàn márùn-ún bí?” Olúwa dáhùn pé, “Èmi kì yóò pa ìlú náà run bí mo bá rí olódodo márùndínláàádọ́ta nínú rẹ̀.”
اگر در شهر سدوم فقط چهل و پنج عادل باشند، آیا برای پنج نفر کمتر، شهر را نابود خواهی کرد؟» خداوند فرمود: «اگر چهل و پنج نفر آدم درستکار در آنجا باشند، آن را از بین نخواهم برد.»
29 Òun sì tún wí lẹ́ẹ̀kan si pé, “Bí ó bá ṣe pé ogójì ni ń kọ́?” Olúwa sì tún wí pé, “Èmi kì yóò pa ìlú náà run bí mo bá rí olódodo ogójì nínú rẹ̀.”
ابراهیم باز به سخنان خود ادامه داد و گفت: «شاید چهل نفر باشند!» خداوند فرمود: «اگر چهل نفر هم باشند آنجا را از بین نخواهم برد.»
30 Abrahamu sì tún bẹ Olúwa pé, “Kí Olúwa má ṣe bínú, ṣùgbọ́n èmi yóò sọ̀rọ̀. Bí ó bá ṣe pé ọgbọ̀n ni a rí níbẹ̀ ń kọ́?” Olúwa dáhùn pé, “Bí mó bá rí ọgbọ̀n, èmi kì yóò pa ìlú run.”
ابراهیم عرض کرد: «تمنا اینکه غضبناک نشوی و اجازه دهی سخن گویم. شاید در آنجا سی نفر پیدا کنی!» خداوند فرمود: «اگر سی نفر یافت شوند، من آنجا را از بین نخواهم برد.»
31 Abrahamu wí pé, “Níwọ́n bí mo ti ní ìgboyà láti bá Olúwa sọ̀rọ̀ báyìí, jẹ́ kí n tẹ̀síwájú. Bí o bá ṣe pé olódodo ogún péré ni ó wà nínú ìlú náà ń kọ́?” Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi kì yóò pa á run nítorí ogún ènìyàn náà.”
ابراهیم عرض کرد: «جسارت مرا ببخش و اجازه بده بپرسم اگر بیست عادل در آنجا یافت شوند، آیا باز هم آنجا را نابود خواهی کرد؟» خداوند فرمود: «اگر بیست نفر هم باشند شهر را نابود نخواهم کرد.»
32 Abrahamu sì wí pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú Olúwa. Jẹ́ kí ń béèrè lẹ́ẹ̀kan si. Bí ó bá ṣe pé ènìyàn mẹ́wàá ni ó jẹ́ olódodo ń kọ́?” Olúwa wí pé, “Nítorí ènìyàn mẹ́wàá náà, èmi kì yóò pa á run.”
ابراهیم بار دیگر عرض کرد: «خداوندا، غضبت افروخته نشود! این آخرین سؤال من است. شاید ده نفر عادل در آن شهر یافت شوند!» خداوند فرمود: «اگر چنانچه ده عادل نیز باشند، شهر را نابود نخواهم کرد.»
33 Olúwa sì bá tirẹ̀ lọ, nígbà tí ó bá Abrahamu sọ̀rọ̀ tán, Abrahamu sì padà sílé.
خداوند پس از پایان گفتگو با ابراهیم، از آنجا رفت و ابراهیم به خیمه‌اش بازگشت.

< Genesis 18 >