< Genesis 18 >

1 Olúwa sì farahan Abrahamu nítòsí àwọn igi ńlá Mamre, bí ó ti jókòó ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ rẹ̀, nígbà tí ọjọ́-kanrí tí oòrùn sì mú.
Abraham te khothaih khobae vaengah Mamre thingnu rhoek kaepkah dap thohka ah ngol dae anih taengla BOEIPA a phoe pah.
2 Abrahamu gbójú sókè, ó sì rí àwọn ọkùnrin mẹ́ta tí wọn dúró nítòsí rẹ̀. Nígbà tí ó rí wọn, ó sáré láti lọ pàdé wọn, ó sì tẹríba bí ó ti ń kí wọn.
Te dongah a mik a huel tih a sawt hatah a taengah hlang pathum a pai te lawt a hmuh. Te dongah amih te doe ham dap thohka lamkah yong tih diklai la bakop.
3 Ó wí pé, “Bí mo bá rí ojúrere yín Olúwa mi, ẹ má ṣe lọ láì yà sọ́dọ̀ ìránṣẹ́ yín.
Te phoeiah, “Ka Boeipa na mikhmuh ah mikdaithen ni ka dang mai atah na sal taeng lamkah he khumpael mai boeh.
4 Ẹ jẹ́ kí a bu omi díẹ̀ wá kí ẹ̀yin kí ó wẹ ẹsẹ̀ yín, kí ẹ sì sinmi lábẹ́ igi níhìn-ín.
Tui bet han khuen mai saeh lamtah na kho silh uh mai. Te dongah thing hmuiah ana hangdang uh mai dae.
5 Ẹ jẹ́ kí n wá oúnjẹ wá fún un yín, kí ẹ̀yin kí ó lè jẹ, kí ara sì tù yín, kí ẹ si tẹ̀síwájú ní ọ̀nà yín, nígbà tí ẹ ti yà ní ọ̀dọ̀ ìránṣẹ́ yín.” Wọn sì wí pé “Ó dára.”
Tedae na sal taengah na pawk rhoi to vaengah buh kamat khaw ka loh dae vetih na lungbuei a duel phoeiah na cet rhoi mako,” a ti nah. Te vaengah, “Na thui bangla na saii pai,” a ti rhoi.
6 Abrahamu sì yára tọ Sara aya rẹ̀ lọ nínú àgọ́, ó wí pé, “Tètè mú òsùwọ̀n ìyẹ̀fun dáradára mẹ́ta kí o sì pò ó pọ̀, kí o sì ṣe oúnjẹ.”
Te dongah Abraham te Sarah taengah dap khuila koe kun tih, “Vaidam buh sum thum te a loe la nook lamtah buh thong laeh” a ti nah.
7 Abrahamu sì tún sáré lọ sí ibi agbo ẹran, ó sì mú ọmọ màlúù kan fún ìránṣẹ́ rẹ̀, ìránṣẹ́ náà sì tètè ṣè é.
Te phoeiah Abraham te saelhung taengla yong tih vaito ca a mongkawt neh a then te a loh. Te phoeiah cadong taengah a paek tih a loe la a saii sak.
8 Ó sì mú wàrà àti mílíìkì àti màlúù tí ó ti pèsè, ó sì gbé síwájú wọn. Ó sì dúró nítòsí wọn lábẹ́ igi bí wọn ti ń jẹ ẹ́.
Te phoeiah suknaeng neh suktui khaw, vaito ca a hmoel te khaw han khuen tih amih hmai ah a tawn pah. Tedae a caak uh vaengah amah te amih taengkah thing hmuiah pai.
9 Wọn béèrè pé, “Sara aya rẹ ń kọ́?” Ó dáhùn pé, “Ó wà nínú àgọ́.”
Te vaengah, “Na yuu Sarah ta?,” a ti na uh hatah, “Dap khuiah om ke,” a ti nah.
10 Nígbà náà ni Olúwa wí fún un pé, “Èmi yóò sì tún padà tọ̀ ọ́ wá nítòótọ́ ní ìwòyí àmọ́dún; Sara aya rẹ yóò sì bí ọmọkùnrin kan.” Sara sì ń dẹtí gbọ́ láti ẹnu-ọ̀nà àgọ́ tí ó wà lẹ́yìn ọkùnrin náà.
Te phoeiah, “Lomai tue ah nang taengla ka lo rhoe ka lo ni. Te vaengah na yuu Sarah te camoe om pawn ni te,” a ti nah. Te vaengah dap thohka kah anih hnukah aka om Sarah loh a hnatun van.
11 Abrahamu àti Sara sì ti di arúgbó, Sara sì ti kọjá àsìkò ìbímọ.
Tedae Abraham neh Sarah kah a kum patong la om rhoi coeng. Huta vanbangla Sarah taengkah khosing om ham khaw bawt coeng.
12 Nítorí náà, Sara rẹ́rìn-ín nínú ara rẹ̀ bí ó ti ń rò ó lọ́kàn rẹ̀ pé, “Lẹ́yìn ìgbà tí mo ti di arúgbó tán tí olúwa mi pẹ̀lú sì ti gbó jọ̀kújọ̀kú, èmi yóò ha tún lè bímọ?”
Te dongah Sarah loh amah ko khuiah, “Kai taengah omthennah a om ham ka hal tih ka boeipa khaw patong coeng,” a ti tih nuei.
13 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Abrahamu pé, “Kín ló dé tí Sara fi rẹ́rìn-ín tí ó sì wí pé, ‘Èmi yóò ha bímọ nítòótọ́, nígbà tí mo di ẹni ogbó tán?’
Tedae BOEIPA loh Abraham taengah, “Balae tih Sarah loh, 'Kai patong khaw ca ka cun tang venim,’ a ti tih, a nueih he.
14 Ǹjẹ́ ohunkóhun wà tí ó ṣòro jù fún Olúwa? Èmi ó padà tọ̀ ọ́ wá ní ìwòyí àmọ́dún, Sara yóò sì bí ọmọkùnrin.”
Hno pakhat he BOEIPA ham rhaisang a? Lomai tue kah khoning vaengah nang taengla ka mael ni. Te vaengah Sarah taengah capa om ni?” a ti nah.
15 Ẹ̀rù sì ba Sara, ó sì sẹ́ pé òun kò rẹ́rìn-ín. Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Dájúdájú ìwọ rẹ́rìn-ín.”
Tedae Sarah loh a rhih dongah, “Ka nuei pawh,” a ti tih a basa dae, “Pawh na nueih lalah,” a ti nah.
16 Nígbà tí àwọn ọkùnrin náà dìde láti máa lọ, wọn kọjú sí ọ̀nà Sodomu, Abrahamu sì sìn wọ́n dé ọ̀nà.
Te daengah hlang rhoek loh thoo uh tih Sodom ben la a dan uh hatah amih aka thak ham Abraham khaw amih taengah cet.
17 Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Ǹjẹ́ èmi yóò ha pa ohun tí mo fẹ́ ṣe mọ́ fún Abrahamu bí?
Tedae BOEIPA loh, “Kai loh ka saii te Abraham taengah ka phah a?,” a ti.
18 Dájúdájú Abrahamu yóò sá à di orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára, àti gbogbo orílẹ̀-èdè ayé ni a ó bùkún fún nípasẹ̀ rẹ̀.
Abraham khaw namtu len neh pilnu la om rhoe om ni. Anih lamloh diklai namtom boeih a yoethen ni.
19 Nítorí tí èmi ti yàn án láti kọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ará ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, láti máa pa ọ̀nà Olúwa mọ nípa ṣíṣe olóòtítọ́ àti olódodo: kí Olúwa le è mú ìlérí rẹ̀ fún Abrahamu ṣẹ.”
Anih ka ming daengah ni anih phoeikah a ca rhoek neh a imkhui te a uen vetih duengnah neh tiktamnah saii ham BOEIPA kah longpuei a ngaithuen uh eh. Te daengah ni BOEIPA loh Abraham ham a taengah a thui pah te a thoeng eh.
20 Olúwa sì wí pé, igbe Sodomu àti Gomorra pọ̀ púpọ̀ àti pé ẹ̀ṣẹ̀ wọn burú jọjọ.
Tedae BOEIPA loh Sodom neh Gomorrah a doek vaengah amih kah tholhnah khaw pungtai tih bahoeng nah coeng.
21 “Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ síbẹ̀ láti ṣe ìwádìí igbe tí ó dé sí etí ìgbọ́ mi nípa wọn, kí èmi sì mọ òtítọ́ tí ó wà níbẹ̀.”
Ka suntla laeh vetih a pangngawlnah te ka hmuh mako. Kai taengla aka pawk te boeih a saii uh neh a saii uh pawt khaw ka ming mako,” a ti.
22 Àwọn ọkùnrin náà yí padà, wọ́n sì ń lọ sí ìhà Sodomu. Ṣùgbọ́n Abrahamu dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa.
Te dongah hlang rhoek loh te lamkah hooi uh tih Sodom la a caeh uh vaengah Abraham tah BOEIPA hmai kah pai pueng.
23 Nígbà náà ni Abrahamu súnmọ́ ọ̀dọ̀ Olúwa, ó sì wí pé, “Ìwọ yóò ha pa olódodo ènìyàn àti ènìyàn búburú run papọ̀ bí?”
Te phoeiah Abraham te thoeih tih, “Hlang dueng neh halang te na khoengvoep sak tang aya?
24 “Bí ó bá ṣe pé ìwọ rí àádọ́ta olódodo nínú ìlú náà, ìwọ yóò ha run ún, ìwọ kì yóò ha dá ìlú náà sí nítorí àwọn àádọ́ta olódodo tí ó wà nínú rẹ̀ náà?
Kho khui ah aka dueng sawmnga om khaming, na khoengvoep kuekluek aya? Amih khui kah hlang dueng sawmnga ham hmuen te na hlun mahpawt a?
25 Kò jẹ́ rí bẹ́ẹ̀! Dájúdájú ìwọ kì yóò ṣe ohun tí ó jọ bẹ́ẹ̀, láti pa olódodo pẹ̀lú àwọn ènìyàn rere àti àwọn ènìyàn búburú. Dájúdájú, ìwọ kì yóò ṣe èyí tí ó tọ́ bi?”
Halang taengah aka dueng duek sak ham hno he saii ham tah nang lamloh savisava. A dueng la, halang la a om khaw, nang lamloh savisava saeh. Diklai pum lai aka tloek loh tiktamnah saii mahpawt nim?,” a ti nah.
26 Olúwa wí pé, “Bí mo bá rí àádọ́ta olódodo ní ìlú Sodomu, èmi yóò dá ìlú náà sí nítorí tiwọn.”
Tedae BOEIPA loh, “Sodom ah sawmnga ka hmuh tih khopuei khui ah hlang dueng om koinih amih kong ah hmuen takuem la ka khuen ni,” a ti nah.
27 Abrahamu sì tún tẹ̀síwájú pé, “Wò ó nísinsin yìí, níwọ̀n bí èmi ti ní ìgboyà láti bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa, èmi ẹni tí í ṣe erùpẹ̀ àti eérú,
Tedae Abraham loh a doo tih, “Kai he laipi neh hmaiphu la ka om dae Boeipa taengah cal ham ka mulmet coeng he.
28 bí ó bá ṣe pe olódodo márùndínláàádọ́ta ni ó wà nínú ìlú, ìwọ yóò ha pa ìlú náà run nítorí ènìyàn márùn-ún bí?” Olúwa dáhùn pé, “Èmi kì yóò pa ìlú náà run bí mo bá rí olódodo márùndínláàádọ́ta nínú rẹ̀.”
Aka dueng sawmnga te panga loh a vaitah khaming, panga kongah khopuei pum te na phae aya?” a ti nah hatah, “Sawmli panga te ka hmuh koinih ka phae mahpawh,” a ti nah.
29 Òun sì tún wí lẹ́ẹ̀kan si pé, “Bí ó bá ṣe pé ogójì ni ń kọ́?” Olúwa sì tún wí pé, “Èmi kì yóò pa ìlú náà run bí mo bá rí olódodo ogójì nínú rẹ̀.”
Tedae anih te voek hamla koep a koei tih, “Likip te a hmuh uh khaming,” a ti nah vaengah, “Likip kong ah ka saii mahpawh,” a ti nah.
30 Abrahamu sì tún bẹ Olúwa pé, “Kí Olúwa má ṣe bínú, ṣùgbọ́n èmi yóò sọ̀rọ̀. Bí ó bá ṣe pé ọgbọ̀n ni a rí níbẹ̀ ń kọ́?” Olúwa dáhùn pé, “Bí mó bá rí ọgbọ̀n, èmi kì yóò pa ìlú run.”
Te phoeiah, “Boeipa, saii boel mai lamtah ka thui mai eh. Sawmthum khaw a hmuh uh khaming,” a ti nah. Tedae, “Sawmthum te ka hmu koinih ka saii mahpawh,” a ti nah.
31 Abrahamu wí pé, “Níwọ́n bí mo ti ní ìgboyà láti bá Olúwa sọ̀rọ̀ báyìí, jẹ́ kí n tẹ̀síwájú. Bí o bá ṣe pé olódodo ogún péré ni ó wà nínú ìlú náà ń kọ́?” Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi kì yóò pa á run nítorí ogún ènìyàn náà.”
Tedae Abaraham loh, “Boeipa taengah cal ham ka mulmet coeng he. Teah te pakul khaw a hmuh uh khaming,” a ti nah vaengah pakul kong ah ka phae mahpawh,” a ti nah.
32 Abrahamu sì wí pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú Olúwa. Jẹ́ kí ń béèrè lẹ́ẹ̀kan si. Bí ó bá ṣe pé ènìyàn mẹ́wàá ni ó jẹ́ olódodo ń kọ́?” Olúwa wí pé, “Nítorí ènìyàn mẹ́wàá náà, èmi kì yóò pa á run.”
Te phoeiah khaw, “Sai boel mai dae Boeipa vai bueng mah ka thui mai eh. Hlang rha khaw a hmu uh khaming,” a ti nah vaengah, “Hlang rha kong ah ka phae mahpawh,” a ti nah.
33 Olúwa sì bá tirẹ̀ lọ, nígbà tí ó bá Abrahamu sọ̀rọ̀ tán, Abrahamu sì padà sílé.
BOEIPA loh Abraham neh cal ham te a khah van neh vik nong tih Abraham khaw amah hmuen la bal.

< Genesis 18 >