< Genesis 17 >

1 Ní ìgbà tí Abramu di ẹni ọ̀kàndínlọ́gọ́rùn-ún ọdún, Olúwa farahàn án, ó sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run alágbára, máa rìn níwájú mi, kí o sì jẹ́ aláìlábùkù.
Midőn Ávrom kilencvenkilenc éves volt, megjelent az Örökkévaló Ávromnak és mondta neki: Én vagyok Isten, a Mindenható, járj előttem és légy tökéletes.
2 Èmi yóò sì fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò sì sọ ọ́ di púpọ̀ gidigidi.”
És én teszem szövetségemet közém és közéd és megsokasítlak igen nagyon.
3 Abramu sì dojúbolẹ̀, Ọlọ́run sì wí fún un pé.
És Ávrom leborult arcára; Isten pedig beszélt vele, mondván:
4 “Ní ti èmi, májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ nìyí. Ìwọ yóò di baba orílẹ̀-èdè púpọ̀.
Az én szövetségem íme veled van és te leszel a népek tömegének atyjává.
5 A kì yóò pe orúkọ rẹ̀ ní Abramu mọ́, bí kò ṣe Abrahamu, nítorí, mo ti sọ ọ́ di baba orílẹ̀-èdè púpọ̀.
Azért ne neveztessék a te neved Ávromnak, hanem legyen a te neved Ábrahám, mert népek tömegének atyjává teszlek én téged.
6 Èmi yóò mú ọ bí si lọ́pọ̀lọ́pọ̀, ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè ni èmi yóò sì mú ti ara rẹ jáde wá, àwọn ọba pẹ̀lú yóò sì ti inú rẹ jáde.
És megszaporítlak téged igen nagyon és népekké teszlek, és királyok származnak majd tőled.
7 Èmi yóò sì gbé májẹ̀mú mi kalẹ̀ láàrín tèmi tìrẹ, ní májẹ̀mú ayérayé àti láàrín irú-ọmọ rẹ ní ìran-ìran wọn, láti máa ṣe Ọlọ́run rẹ àti ti irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ.
És én fönntartom, szövetségemet közöttem és közötted, meg magzatod között utánad, az ő nemzedékeiken át, örök szövetség gyanánt, hogy legyek teneked Istened és magzatodnak utánad.
8 Gbogbo ilẹ̀ Kenaani níbi tí ìwọ ti ṣe àjèjì ni èmi yóò fi fún ọ àti fún irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ láéláé. Èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.”
Neked adom és a te magzatodnak utánad tartózkodásod országát: Kánaán egész országát, örök birtokul; és én leszek nekik Istenük.
9 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Abrahamu pé, “Ìwọ máa pa májẹ̀mú mi mọ́, ìwọ àti irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ àti àwọn ìran tí ó ń bọ̀.
És mondta Isten Ábrahámnak: Te pedig az én szövetségemet őrizd meg, te és a te magzatod utánad, az ő nemzedékeiken át.
10 Èyí ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ àti ìran rẹ lẹ́yìn rẹ, májẹ̀mú tí ẹ̀yin yóò máa pamọ́. Gbogbo ọkùnrin yín ni a gbọdọ̀ kọ ní ilà.
Ez az én szövetségem, amelyet megőrizzetek közöttem és köztetek és magzatod között utánad: Metéltessék körül nálatok minden férfiszemély!
11 Ẹ̀yin yóò kọ ara yín ní ilà, èyí ni yóò jẹ́ àmì májẹ̀mú láàrín tèmi tiyín.
Metéljétek körül fitymátok húsát és legyen ez szövetségjelül köztem és köztetek:
12 Ní gbogbo ìran tí ń bọ̀ lẹ́yìn, gbogbo ọkùnrin ni a gbọdọ̀ kọ ni ilà ní ọjọ́ kẹjọ tí a bí wọn, àti àwọn tí a bí ní ilé rẹ, tàbí tí a fi owó rà lọ́wọ́ àwọn àjèjì, àwọn tí kì í ṣe ọmọ rẹ̀. Èyí yóò sì jẹ́ májẹ̀mú láéláé tí yóò wà láàrín Èmi àti irú-ọmọ rẹ.
És pedig nyolc napos korában metéltessék körül nálatok minden férfiszemély, nemzedékeiteken át; a házban született vagy a pénzen vett bármely idegen közül, aki nem a te magzatodból való.
13 Ìbá à ṣe ẹni tí a bí nínú ilé rẹ, tàbí ẹni tí o fi owó rà, a gbọdọ̀ kọ wọ́n ní ilà; májẹ̀mú mí lára yín yóò jẹ́ májẹ̀mú ayérayé.
Körülmetéltessék a házadban született és a pénzeden vett és legyen szövetségem a testeteken örök szövetségül!
14 Gbogbo ọmọkùnrin tí kò bá kọ ilà, tí a kò kọ ní ilà abẹ́, ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀, nítorí pé ó da májẹ̀mú mi.”
A körülmetéletlen férfiszemély pedig, aki nem metéli körül fitymájának húsát, irtassék ki az a lélek népe köréből, szövetségemet szegte meg.
15 Ọlọ́run wí fún Abrahamu pé, “Ní ti Sarai, aya rẹ̀, ìwọ kì yóò pè é ní Sarai mọ́, bí kò ṣe Sara.
És mondta Isten Ábrahámnak: Szórájt, a te feleségedet ne nevezd Szórájnak, hanem Sára legyen a neve.
16 Èmi yóò bùkún fún un, èmi yóò sì fun ọ ní ọmọkùnrin kan nípasẹ̀ rẹ̀. Èmi yóò bùkún un, yóò sì di ìyá àwọn orílẹ̀-èdè, àwọn ọba àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì ti ara rẹ̀ jáde wá.”
Én pedig megáldom őt és adok is őtőle neked fiat; megáldom őt, hogy nemzetekké legyen és népek királyai származzanak tőle.
17 Abrahamu sì dojúbolẹ̀, ó rẹ́rìn-ín, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, “A ó ha bí ọmọ fún ẹni ọgọ́rùn-ún ọdún? Sara tí í ṣe ẹni àádọ́rùn-ún ọdún yóò ha bímọ bí?”
És leborult Ábrahám arcára és nevetett; mondta pedig szívében: Vajon a száz évesnek szülessék-e, vagy Sára, a kilencven éves szüljön?
18 Abrahamu sì wí fún Ọlọ́run pé, “Sá à jẹ́ kí Iṣmaeli kí ó wà láààyè lábẹ́ ìbùkún rẹ.”
És mondta Ábrahám Istennek: Vajha Ismáel élne a te színed előtt!
19 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí pé, “Mo gbọ́, ṣùgbọ́n Sara aya rẹ̀ yóò bí ọmọkùnrin kan fún ọ, ìwọ yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Isaaki, èmi yóò fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀ ní májẹ̀mú ayérayé àti àwọn irú-ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.
És mondta Isten: Bizony, Sára, a te feleséged szül neked fiút és nevezd őt Jicchoknak (Izsák); és fönntartom szövetségemet vele örök szövetségül az ő magzata számára, utána.
20 Ṣùgbọ́n ní ti Iṣmaeli, mo gbọ́ ohun tí ìwọ wí, èmi yóò bùkún fún un nítòótọ́, èmi ó sì mú un bí sí i, yóò sì pọ̀ sí i, òun yóò sì jẹ́ baba fún àwọn ọmọ ọba méjìlá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá.
Ismáelre nézve pedig meghallgattalak; íme, megáldom őt, megszaporítom őt és megsokasítom őt igen nagyon, tizenkét fejedelmet fog nemzeni és nagy néppé teszem őt.
21 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú Isaaki, ẹni tí Sara yóò bí fún ọ ni ìwòyí àmọ́dún.”
De szövetségemet Izsákkal tartom fönn, akit Sára fog neked szülni ezen időben, a jövő évben.
22 Nígbà tí ó ti bá Abrahamu sọ̀rọ̀ tán, Ọlọ́run sì gòkè lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
Midőn végzett azzal, hogy beszéljen vele, fölszállt Isten Ábrahámtól.
23 Ní ọjọ́ náà gan an ni Abrahamu mú Iṣmaeli ọmọ rẹ̀ àti àwọn ẹrú tí a bí ní ilé rẹ̀ àti àwọn tí ó fi owó rà, ó sì kọ wọ́n ní ilà. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì kọ gbogbo ọkùnrin tí ń bẹ ní ilé rẹ̀ ní ilà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Ọlọ́run.
És vette Ábrahám Ismáelt, az ő fiát és házának minden szülöttét, és minden pénzen vettet, minden férfiszemélyt Ábrahám háza népe közül és körülmetélte fitymájának húsát ugyanazon a napon, melyen beszélt vele Isten.
24 Abrahamu jẹ́ ẹni ọ̀kàndínlọ́gọ́rùn-ún ọdún nígbà tí a kọ ọ́ ní ilà.
Ábrahám pedig kilencvenkilenc éves volt, midőn körülmetélte fitymájának húsát.
25 Iṣmaeli ọmọ rẹ̀ jẹ́ ẹni ọdún mẹ́tàlá.
És Ismáel, az ő fia, tizenhárom éves volt, midőn körülmetéltetett fitymájának húsa.
26 Ní ọjọ́ náà gan an ni a kọ Abrahamu ní ilà pẹ̀lú Iṣmaeli ọmọ rẹ̀ ọkùnrin.
Ugyanazon a napon metéltetett körül Ábrahám és Ismáel, az ő fia;
27 Àti gbogbo ọkùnrin tí ó wà ní ilé Abrahamu, ìbá à ṣe èyí tí a bí ní ilé rẹ̀ tàbí èyí tí a fi owó rà lọ́wọ́ àlejò ni a kọ ní ilà pẹ̀lú rẹ̀.
meg házának minden férfi, házában született vagy pénzen vett az idegen közül, vele együtt metéltettek körül.

< Genesis 17 >