< Genesis 17 >

1 Ní ìgbà tí Abramu di ẹni ọ̀kàndínlọ́gọ́rùn-ún ọdún, Olúwa farahàn án, ó sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run alágbára, máa rìn níwájú mi, kí o sì jẹ́ aláìlábùkù.
Alors qu'Abram était âgé de quatre-vingt-dix-neuf ans, Yahvé apparut à Abram et lui dit: « Je suis le Dieu tout-puissant. Marche devant moi et sois irréprochable.
2 Èmi yóò sì fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò sì sọ ọ́ di púpọ̀ gidigidi.”
Je conclurai mon alliance entre moi et toi, et je te multiplierai à l'infini. »
3 Abramu sì dojúbolẹ̀, Ọlọ́run sì wí fún un pé.
Abram tomba sur sa face. Dieu lui parla, en disant:
4 “Ní ti èmi, májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ nìyí. Ìwọ yóò di baba orílẹ̀-èdè púpọ̀.
« Quant à moi, voici que mon alliance est avec toi. Tu seras le père d'une multitude de nations.
5 A kì yóò pe orúkọ rẹ̀ ní Abramu mọ́, bí kò ṣe Abrahamu, nítorí, mo ti sọ ọ́ di baba orílẹ̀-èdè púpọ̀.
Ton nom ne sera plus Abram, mais ton nom sera Abraham, car je t'ai établi père d'une multitude de nations.
6 Èmi yóò mú ọ bí si lọ́pọ̀lọ́pọ̀, ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè ni èmi yóò sì mú ti ara rẹ jáde wá, àwọn ọba pẹ̀lú yóò sì ti inú rẹ jáde.
Je te rendrai extrêmement fécond, et je ferai de toi des nations. Des rois sortiront de toi.
7 Èmi yóò sì gbé májẹ̀mú mi kalẹ̀ láàrín tèmi tìrẹ, ní májẹ̀mú ayérayé àti láàrín irú-ọmọ rẹ ní ìran-ìran wọn, láti máa ṣe Ọlọ́run rẹ àti ti irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ.
J'établirai mon alliance entre moi et toi, et tes descendants après toi, de génération en génération, comme une alliance éternelle, pour être un Dieu pour toi et pour tes descendants après toi.
8 Gbogbo ilẹ̀ Kenaani níbi tí ìwọ ti ṣe àjèjì ni èmi yóò fi fún ọ àti fún irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ láéláé. Èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.”
Je vous donnerai, à vous et à votre postérité après vous, le pays où vous voyagez, tout le pays de Canaan, comme une possession éternelle. Je serai leur Dieu. »
9 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Abrahamu pé, “Ìwọ máa pa májẹ̀mú mi mọ́, ìwọ àti irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ àti àwọn ìran tí ó ń bọ̀.
Dieu dit à Abraham: « Pour toi, tu garderas mon alliance, toi et ta postérité après toi, de génération en génération.
10 Èyí ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ àti ìran rẹ lẹ́yìn rẹ, májẹ̀mú tí ẹ̀yin yóò máa pamọ́. Gbogbo ọkùnrin yín ni a gbọdọ̀ kọ ní ilà.
Voici mon alliance, que tu garderas, entre moi et toi, et ta postérité après toi. Tout mâle parmi vous sera circoncis.
11 Ẹ̀yin yóò kọ ara yín ní ilà, èyí ni yóò jẹ́ àmì májẹ̀mú láàrín tèmi tiyín.
Vous serez circoncis dans la chair de votre prépuce. Ce sera un signe de l'alliance entre moi et vous.
12 Ní gbogbo ìran tí ń bọ̀ lẹ́yìn, gbogbo ọkùnrin ni a gbọdọ̀ kọ ni ilà ní ọjọ́ kẹjọ tí a bí wọn, àti àwọn tí a bí ní ilé rẹ, tàbí tí a fi owó rà lọ́wọ́ àwọn àjèjì, àwọn tí kì í ṣe ọmọ rẹ̀. Èyí yóò sì jẹ́ májẹ̀mú láéláé tí yóò wà láàrín Èmi àti irú-ọmọ rẹ.
Celui qui aura huit jours sera circoncis parmi vous, tout mâle, de génération en génération, qu'il soit né dans la maison ou acheté à prix d'argent à un étranger qui n'est pas de votre race.
13 Ìbá à ṣe ẹni tí a bí nínú ilé rẹ, tàbí ẹni tí o fi owó rà, a gbọdọ̀ kọ wọ́n ní ilà; májẹ̀mú mí lára yín yóò jẹ́ májẹ̀mú ayérayé.
Celui qui est né dans ta maison, et celui qui a été acheté avec ton argent, doit être circoncis. Mon alliance sera dans ta chair pour une alliance éternelle.
14 Gbogbo ọmọkùnrin tí kò bá kọ ilà, tí a kò kọ ní ilà abẹ́, ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀, nítorí pé ó da májẹ̀mú mi.”
Le mâle incirconcis qui n'est pas circoncis dans la chair de son prépuce, cette âme sera retranchée de son peuple. Il a rompu mon alliance. »
15 Ọlọ́run wí fún Abrahamu pé, “Ní ti Sarai, aya rẹ̀, ìwọ kì yóò pè é ní Sarai mọ́, bí kò ṣe Sara.
Dieu dit à Abraham: « Pour ce qui est de Saraï, ta femme, tu ne l'appelleras pas Saraï, mais son nom sera Sara.
16 Èmi yóò bùkún fún un, èmi yóò sì fun ọ ní ọmọkùnrin kan nípasẹ̀ rẹ̀. Èmi yóò bùkún un, yóò sì di ìyá àwọn orílẹ̀-èdè, àwọn ọba àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì ti ara rẹ̀ jáde wá.”
Je la bénirai, et en plus je te donnerai un fils par elle. Oui, je la bénirai, et elle sera une mère de nations. Les rois des peuples viendront d'elle. »
17 Abrahamu sì dojúbolẹ̀, ó rẹ́rìn-ín, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, “A ó ha bí ọmọ fún ẹni ọgọ́rùn-ún ọdún? Sara tí í ṣe ẹni àádọ́rùn-ún ọdún yóò ha bímọ bí?”
Alors Abraham tomba sur sa face et se mit à rire, et il dit en son cœur: « Naîtra-t-il un enfant à celui qui est âgé de cent ans? Sara, qui a quatre-vingt-dix ans, accouchera-t-elle? »
18 Abrahamu sì wí fún Ọlọ́run pé, “Sá à jẹ́ kí Iṣmaeli kí ó wà láààyè lábẹ́ ìbùkún rẹ.”
Abraham dit à Dieu: « Oh, si Ismaël pouvait vivre devant toi! »
19 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí pé, “Mo gbọ́, ṣùgbọ́n Sara aya rẹ̀ yóò bí ọmọkùnrin kan fún ọ, ìwọ yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Isaaki, èmi yóò fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀ ní májẹ̀mú ayérayé àti àwọn irú-ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.
Dieu dit: « Non, mais Sara, ta femme, t'enfantera un fils. Tu lui donneras le nom d'Isaac. J'établirai mon alliance avec lui comme une alliance éternelle pour sa descendance après lui.
20 Ṣùgbọ́n ní ti Iṣmaeli, mo gbọ́ ohun tí ìwọ wí, èmi yóò bùkún fún un nítòótọ́, èmi ó sì mú un bí sí i, yóò sì pọ̀ sí i, òun yóò sì jẹ́ baba fún àwọn ọmọ ọba méjìlá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá.
Quant à Ismaël, je t'ai entendu. Voici, je l'ai béni, je le rendrai fécond et je le multiplierai à l'infini. Il sera le père de douze princes, et je ferai de lui une grande nation.
21 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú Isaaki, ẹni tí Sara yóò bí fún ọ ni ìwòyí àmọ́dún.”
Mais j'établirai mon alliance avec Isaac, que Sarah t'enfantera l'année prochaine à cette époque précise. »
22 Nígbà tí ó ti bá Abrahamu sọ̀rọ̀ tán, Ọlọ́run sì gòkè lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
Quand il eut fini de parler avec lui, Dieu s'éloigna d'Abraham.
23 Ní ọjọ́ náà gan an ni Abrahamu mú Iṣmaeli ọmọ rẹ̀ àti àwọn ẹrú tí a bí ní ilé rẹ̀ àti àwọn tí ó fi owó rà, ó sì kọ wọ́n ní ilà. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì kọ gbogbo ọkùnrin tí ń bẹ ní ilé rẹ̀ ní ilà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Ọlọ́run.
Abraham prit son fils Ismaël, tous ceux qui étaient nés dans sa maison et tous ceux qu'il avait achetés avec son argent, tous les mâles parmi les hommes de la maison d'Abraham, et il circoncit la chair de leur prépuce le même jour, comme Dieu le lui avait dit.
24 Abrahamu jẹ́ ẹni ọ̀kàndínlọ́gọ́rùn-ún ọdún nígbà tí a kọ ọ́ ní ilà.
Abraham était âgé de quatre-vingt-dix-neuf ans lorsqu'il fut circoncis dans la chair de son prépuce.
25 Iṣmaeli ọmọ rẹ̀ jẹ́ ẹni ọdún mẹ́tàlá.
Ismaël, son fils, avait treize ans lorsqu'il fut circoncis dans la chair de son prépuce.
26 Ní ọjọ́ náà gan an ni a kọ Abrahamu ní ilà pẹ̀lú Iṣmaeli ọmọ rẹ̀ ọkùnrin.
Le même jour, Abraham et Ismaël, son fils, furent circoncis.
27 Àti gbogbo ọkùnrin tí ó wà ní ilé Abrahamu, ìbá à ṣe èyí tí a bí ní ilé rẹ̀ tàbí èyí tí a fi owó rà lọ́wọ́ àlejò ni a kọ ní ilà pẹ̀lú rẹ̀.
Tous les hommes de sa maison, ceux qui étaient nés dans la maison et ceux qui avaient été achetés à prix d'argent à un étranger, furent circoncis avec lui.

< Genesis 17 >