< Genesis 16 >

1 Sarai, aya Abramu kò bímọ fún un, ṣùgbọ́n ó ní ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin ará Ejibiti kan tí ń jẹ́ Hagari.
Əmma Abramning ayali Saray uningƣa ⱨeq bala tuƣup bǝrmidi; lekin uning Ⱨǝjǝr isimlik misirliⱪ bir dediki bar idi;
2 Nítorí náà, Sarai wí fún Abramu pé, “Kíyèsi i Olúwa ti sé mi ní inú, èmi kò sì bímọ, wọlé tọ ọmọ ọ̀dọ̀ mi lọ, bóyá èmi yóò le ti ipasẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.” Abramu sì gba ohun tí Sarai sọ.
Saray Abramƣa: — Mana, Pǝrwǝrdigar meni tuƣuxtin tosti. Əmdi sǝn mening dedikimning ⱪexiƣa kirgin; bǝlkim u arⱪiliⱪ ana bolup tiklinixim mumkin, — dedi. Abram bolsa Sarayning sɵzini ⱪobul kɵrdi.
3 Lẹ́yìn ọdún mẹ́wàá tí Abramu ti ń gbé ni Kenaani ni Sarai mú ọmọbìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ Hagari, tí í ṣe ará Ejibiti fún Abramu ọkọ rẹ̀ láti fi ṣe aya.
Xuning bilǝn Abramning ayali Saray dediki misirliⱪ Ⱨǝjǝrni ɵz eri Abramƣa toⱪalliⱪⱪa apirip bǝrdi (u waⱪitta Abram Ⱪanaan zeminida on yil olturƣanidi).
4 Abramu sì bá Hagari lòpọ̀, ó sì lóyún. Nígbà tí ó sì ti mọ̀ pé òun lóyún, ó bẹ̀rẹ̀ sì ní kẹ́gàn ọ̀gá rẹ̀.
Abram Ⱨǝjǝrning ⱪexiƣa kirdi wǝ u ⱨamilidar boldi. Əmma u ɵzining ⱨamilidar bolƣinini bilginidǝ, u ayal hojayinini kɵzgǝ ilmas bolup ⱪaldi.
5 Nígbà náà ni Sarai wí fún Abramu pé, “Ìwọ ni ó jẹ́ kí ẹ̀gbin yìí máa jẹ mí, mo fa ọmọ ọ̀dọ̀ mi lé ọ lọ́wọ́, nígbà tí ó sì rí i pé òun lóyún, mo di ẹni ẹ̀gàn ní ojú rẹ̀. Kí Olúwa kí ó ṣe ìdájọ́ láàrín tèmi tìrẹ.”
Saray Abramƣa ⱪeyidap: — Manga qüxkǝn bu horluⱪ sening bexingƣa qüxsun! Mǝn ɵz dedikimni ⱪuqiⱪingƣa selip bǝrdim; ǝmdi u ɵzining ⱨamilidar bolƣinini kɵrgǝndǝ mǝn uning nǝziridǝ kɵzgǝ ilinmidim. Hǝyr, Pǝrwǝrdigar sǝn bilǝn mening otturimizda ⱨɵküm qiⱪarsun! — dedi.
6 Abramu dáhùn pé, “Ìwọ ló ni ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ, ṣe ohunkóhun tí ó bá tọ́ ní ojú rẹ sí i.” Nígbà náà ni Sarai fi ìyà jẹ Hagari, ó sì sálọ.
Abram Sarayƣa: — Mana, dediking ɵz ⱪolungdidur; sanga nemǝ layiⱪ kɵrünsǝ uningƣa xuni ⱪilƣin, — dedi. Buning bilǝn Saray uningƣa ⱪattiⱪliⱪ ⱪilixⱪa baxlidi; buning bilǝn u uning aldidin ⱪeqip kǝtti.
7 Angẹli Olúwa sì rí Hagari ní ẹ̀gbẹ́ ìsun omi ní ijù, ìsun omi tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà tí ó lọ sí Ṣuri.
Əmma Pǝrwǝrdigarning Pǝrixtisi uni qɵldiki bir bulaⱪning yenida, yǝni Xur yolining boyidiki bulaⱪning yenidin tepip, uningƣa:
8 Ó sì wí pé, “Hagari, ìránṣẹ́ Sarai, níbo ni o ti ń bọ̀, níbo sì ni ìwọ ń lọ?” Ó sì dáhùn pé, “Mo ń sálọ kúrò lọ́dọ̀ ọ̀gá mi Sarai ni.”
Əy Sarayning dediki Ⱨǝjǝr, nǝdin kǝlding, nǝgǝ barisǝn? — dǝp soridi. U jawab berip: — Mǝn hojayinim Sarayning aldidin ⱪeqip qiⱪtim, — dedi.
9 Angẹli Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ kí o sì tẹríba fún un.”
Pǝrwǝrdigarning Pǝrixtisi uningƣa: — Ayal hojayiningning ⱪexiƣa ⱪaytip berip, uning ⱪol astida bol, — dedi.
10 Angẹli Olúwa náà sì fi kún fún un pé, “Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, ìran rẹ kì yóò sì lóǹkà.”
Pǝrwǝrdigarning Pǝrixtisi uningƣa yǝnǝ: — Sening nǝslingni xundaⱪ awutimǝnki, kɵplükidin uni sanap bolƣili bolmaydu, — dedi.
11 Angẹli Olúwa náà sì wí fún un pé, “Ìwọ ti lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan. Ìwọ yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Iṣmaeli, nítorí tí Olúwa ti rí ìpọ́njú rẹ.
Andin Pǝrwǝrdigarning Pǝrixtisi uningƣa: Mana, sǝn ⱨamilidarsǝn; sǝn bir oƣul tuƣup, uningƣa Ismail dǝp at ⱪoyƣin; qünki Pǝrwǝrdigar sening jǝbir-japayingni anglidi.
12 Òun yóò jẹ́ oníjàgídíjàgan ènìyàn ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára ènìyàn gbogbo, ọwọ́ ènìyàn gbogbo yóò sì wà lára rẹ̀, yóò sì máa gbé ní ìkanra pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀.”
U yawa exǝk kǝbi bir adǝm bolidu; uning ⱪoli ⱨǝr adǝmgǝ ⱪarxi uzitilidu, xuningdǝk ⱨǝr adǝmning ⱪoli uningƣa ⱪarxi uzitilidu; u ⱪerindaxlirining udulida ayrim turidu, dedi.
13 Ó sì pe orúkọ Olúwa tí o bá sọ̀rọ̀ ní, “Ìwọ ni Ọlọ́run tí ó rí mi,” nítorí tí ó wí pé, “Mo ti ri ẹni tí ó rí mi báyìí.”
Ⱨǝjǝr ɵz-ɵzigǝ: «Mǝn muxu yǝrdǝ meni Kɵrgüqini arⱪisidin kɵrdüm» dǝp, ɵzigǝ sɵz ⱪilƣan Pǝrwǝrdigarni: «Sǝn meni kɵrgüqi Tǝngridursǝn» dǝp atidi.
14 Nítorí náà ni a ṣe ń pe kànga náà ní Beeri-Lahai-Roi; kànga ẹni alààyè tí ó rí mi. Ó wà ní agbede-méjì Kadeṣi àti Beredi.
Xuning bilǝn u ⱪuduⱪ: «Bǝǝr-laⱨay-roy» dǝp ataldi. U Ⱪadǝx bilǝn Bǝrǝd xǝⱨirining ariliⱪididur.
15 Hagari sì bí ọmọkùnrin kan fún Abramu, Abramu sì pe orúkọ rẹ̀ ní Iṣmaeli.
Ⱨǝjǝr Abramƣa bir oƣul tuƣup bǝrdi. Abram Ⱨǝjǝr uningƣa tuƣup bǝrgǝn oƣliƣa Ismail dǝp at ⱪoydi.
16 Abramu jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínláàádọ́rùn-ún nígbà tí Hagari bí Iṣmaeli fún un.
Ⱨǝjǝr Abramƣa Ismailni tuƣup bǝrgǝndǝ Abram sǝksǝn altǝ yaxta idi.

< Genesis 16 >