< Genesis 16 >

1 Sarai, aya Abramu kò bímọ fún un, ṣùgbọ́n ó ní ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin ará Ejibiti kan tí ń jẹ́ Hagari.
Acum Sarai, soţia lui Avram, nu îi năştea copii; şi ea avea o roabă, o egipteancă, al cărei nume era Hagar.
2 Nítorí náà, Sarai wí fún Abramu pé, “Kíyèsi i Olúwa ti sé mi ní inú, èmi kò sì bímọ, wọlé tọ ọmọ ọ̀dọ̀ mi lọ, bóyá èmi yóò le ti ipasẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.” Abramu sì gba ohun tí Sarai sọ.
Şi Sarai i-a spus lui Avram: Iată acum, DOMNUL m-a oprit de la a naşte; te rog, intră la servitoarea mea, poate că voi obţine copii prin ea. Şi Avram a dat ascultare vocii lui Sarai.
3 Lẹ́yìn ọdún mẹ́wàá tí Abramu ti ń gbé ni Kenaani ni Sarai mú ọmọbìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ Hagari, tí í ṣe ará Ejibiti fún Abramu ọkọ rẹ̀ láti fi ṣe aya.
Şi Sarai, soţia lui Avram, a luat pe Hagar, servitoarea ei, egipteanca, după ce Avram a locuit zece ani în ţara lui Canaan, şi a dat-o soţului ei, Avram, să fie soţia lui.
4 Abramu sì bá Hagari lòpọ̀, ó sì lóyún. Nígbà tí ó sì ti mọ̀ pé òun lóyún, ó bẹ̀rẹ̀ sì ní kẹ́gàn ọ̀gá rẹ̀.
Şi a intrat la Hagar şi ea a rămas însărcinată; şi când a văzut că a rămas însărcinată, stăpâna ei a fost dispreţuită în ochii ei.
5 Nígbà náà ni Sarai wí fún Abramu pé, “Ìwọ ni ó jẹ́ kí ẹ̀gbin yìí máa jẹ mí, mo fa ọmọ ọ̀dọ̀ mi lé ọ lọ́wọ́, nígbà tí ó sì rí i pé òun lóyún, mo di ẹni ẹ̀gàn ní ojú rẹ̀. Kí Olúwa kí ó ṣe ìdájọ́ láàrín tèmi tìrẹ.”
Şi Sarai i-a spus lui Avram: Răul făcut mie fie asupra ta; eu am dat pe servitoarea mea la sânul tău, şi când a văzut ea că a rămas însărcinată, am fost dispreţuită în ochii ei; DOMNUL să judece între mine şi tine.
6 Abramu dáhùn pé, “Ìwọ ló ni ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ, ṣe ohunkóhun tí ó bá tọ́ ní ojú rẹ sí i.” Nígbà náà ni Sarai fi ìyà jẹ Hagari, ó sì sálọ.
Dar Avram i-a spus lui Sarai: Iată, servitoarea ta este în mâna ta, fă-i cum îţi place. Şi când Sarai s-a purtat aspru cu ea, ea a fugit de la faţa ei.
7 Angẹli Olúwa sì rí Hagari ní ẹ̀gbẹ́ ìsun omi ní ijù, ìsun omi tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà tí ó lọ sí Ṣuri.
Şi îngerul DOMNULUI a găsit-o lângă o fântână de apă în pustie, lângă fântâna pe calea spre Şur.
8 Ó sì wí pé, “Hagari, ìránṣẹ́ Sarai, níbo ni o ti ń bọ̀, níbo sì ni ìwọ ń lọ?” Ó sì dáhùn pé, “Mo ń sálọ kúrò lọ́dọ̀ ọ̀gá mi Sarai ni.”
Şi a spus: Hagar, servitoarea lui Sarai, de unde vii? Şi unde mergi? Iar ea a spus: Fug de la faţa stăpânei mele Sarai.
9 Angẹli Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ kí o sì tẹríba fún un.”
Şi îngerul DOMNULUI i-a spus: Întoarce-te la stăpâna ta şi supune-te sub mâinile ei.
10 Angẹli Olúwa náà sì fi kún fún un pé, “Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, ìran rẹ kì yóò sì lóǹkà.”
Şi îngerul DOMNULUI i-a spus: Voi înmulţi sămânţa ta peste măsură, încât nu va putea fi numărată din cauza mulţimii ei.
11 Angẹli Olúwa náà sì wí fún un pé, “Ìwọ ti lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan. Ìwọ yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Iṣmaeli, nítorí tí Olúwa ti rí ìpọ́njú rẹ.
Şi îngerul DOMNULUI i-a spus: Iată, eşti însărcinată şi vei naşte un fiu şi îi vei pune numele Ismael, pentru că DOMNUL a auzit necazul tău.
12 Òun yóò jẹ́ oníjàgídíjàgan ènìyàn ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára ènìyàn gbogbo, ọwọ́ ènìyàn gbogbo yóò sì wà lára rẹ̀, yóò sì máa gbé ní ìkanra pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀.”
Şi el va fi un om sălbatic, mâna lui va fi împotriva fiecărui om şi mâna fiecărui om împotriva lui şi va locui în faţa tuturor fraţilor săi.
13 Ó sì pe orúkọ Olúwa tí o bá sọ̀rọ̀ ní, “Ìwọ ni Ọlọ́run tí ó rí mi,” nítorí tí ó wí pé, “Mo ti ri ẹni tí ó rí mi báyìí.”
Şi ea a chemat numele DOMNULUI care i-a vorbit: Tu, Dumnezeu, mă vezi, pentru că ea a spus: Nu am privit de asemenea aici spatele celui care mă vede?
14 Nítorí náà ni a ṣe ń pe kànga náà ní Beeri-Lahai-Roi; kànga ẹni alààyè tí ó rí mi. Ó wà ní agbede-méjì Kadeṣi àti Beredi.
De aceea fântâna a fost numită Beerlahairoi; iată, este între Cades şi Bered.
15 Hagari sì bí ọmọkùnrin kan fún Abramu, Abramu sì pe orúkọ rẹ̀ ní Iṣmaeli.
Şi Hagar a născut lui Avram un fiu şi Avram a pus fiului său, pe care Hagar l-a născut, numele Ismael.
16 Abramu jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínláàádọ́rùn-ún nígbà tí Hagari bí Iṣmaeli fún un.
Şi Avram era în vârstă de optzeci şi şase de ani când Hagar a născut pe Ismael lui Avram.

< Genesis 16 >