< Genesis 16 >

1 Sarai, aya Abramu kò bímọ fún un, ṣùgbọ́n ó ní ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin ará Ejibiti kan tí ń jẹ́ Hagari.
Sarai Abrams wyfe bare him no childerne. But she had an hand mayde an Egiptian whose name was Hagar.
2 Nítorí náà, Sarai wí fún Abramu pé, “Kíyèsi i Olúwa ti sé mi ní inú, èmi kò sì bímọ, wọlé tọ ọmọ ọ̀dọ̀ mi lọ, bóyá èmi yóò le ti ipasẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.” Abramu sì gba ohun tí Sarai sọ.
Wherfore the sayde vnto Abram. Beholde the LORde hath closed me that I can not bere. I praye the goo in vnto my mayde peradueture I shall be multiplyed by meanes of her And Abram herde the voyce of Sarai. Than Sarai
3 Lẹ́yìn ọdún mẹ́wàá tí Abramu ti ń gbé ni Kenaani ni Sarai mú ọmọbìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ Hagari, tí í ṣe ará Ejibiti fún Abramu ọkọ rẹ̀ láti fi ṣe aya.
Abrams wife toke Hagar hyr mayde the Egitian (after Abram had dwelled. x. yere in the lande of Canaan) and gaue her to hyr husbonde Abram to be his wyfe.
4 Abramu sì bá Hagari lòpọ̀, ó sì lóyún. Nígbà tí ó sì ti mọ̀ pé òun lóyún, ó bẹ̀rẹ̀ sì ní kẹ́gàn ọ̀gá rẹ̀.
And he wente in vnto Hagar and she conceaved. And when she sawe that she had conceyved hyr mastresse was despised in hyr syghte.
5 Nígbà náà ni Sarai wí fún Abramu pé, “Ìwọ ni ó jẹ́ kí ẹ̀gbin yìí máa jẹ mí, mo fa ọmọ ọ̀dọ̀ mi lé ọ lọ́wọ́, nígbà tí ó sì rí i pé òun lóyún, mo di ẹni ẹ̀gàn ní ojú rẹ̀. Kí Olúwa kí ó ṣe ìdájọ́ láàrín tèmi tìrẹ.”
Than sayd Sarai vnto Abram: Thou dost me vnrighte for I haue geuen my mayde in to thy bosome: and now because she seyth that she hath coceaved I am despysed in hyr syghte: the LORde iudge betwene the and me.
6 Abramu dáhùn pé, “Ìwọ ló ni ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ, ṣe ohunkóhun tí ó bá tọ́ ní ojú rẹ sí i.” Nígbà náà ni Sarai fi ìyà jẹ Hagari, ó sì sálọ.
Than sayde Abra to Sarai: beholde thy mayde is in thy hande do with hyr as it pleaseth the. And because Sarai fared foule with her she fled from her.
7 Angẹli Olúwa sì rí Hagari ní ẹ̀gbẹ́ ìsun omi ní ijù, ìsun omi tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà tí ó lọ sí Ṣuri.
And the angell of the LORde founde her besyde a fountayne of water in the wyldernes: euen by a well in the way to Sur.
8 Ó sì wí pé, “Hagari, ìránṣẹ́ Sarai, níbo ni o ti ń bọ̀, níbo sì ni ìwọ ń lọ?” Ó sì dáhùn pé, “Mo ń sálọ kúrò lọ́dọ̀ ọ̀gá mi Sarai ni.”
And he sayde: Hagar Sarais mayde whence comest thou and whether wylt thou goo? And she answered: I flee from my mastresse Sarai.
9 Angẹli Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ kí o sì tẹríba fún un.”
And the angell of the LORde sayde vnto her: returne to thy mastresse agayne and submytte thy selfe vnder her handes.
10 Angẹli Olúwa náà sì fi kún fún un pé, “Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, ìran rẹ kì yóò sì lóǹkà.”
And the angell of ye LORde sayde vnto her: I will so encrease thy seed that it shall not be numbred for multitude.
11 Angẹli Olúwa náà sì wí fún un pé, “Ìwọ ti lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan. Ìwọ yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Iṣmaeli, nítorí tí Olúwa ti rí ìpọ́njú rẹ.
And the LORdes angell sayd further vnto her: se thou art wyth childe and shalt bere a sonne and shalt call his name Ismael: because the LORDE hath herde thy tribulation.
12 Òun yóò jẹ́ oníjàgídíjàgan ènìyàn ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára ènìyàn gbogbo, ọwọ́ ènìyàn gbogbo yóò sì wà lára rẹ̀, yóò sì máa gbé ní ìkanra pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀.”
He will be a wylde man and his hande will be agenst every man and euery mans hande agenst him. And yet shall he dwell faste by all his brothren.
13 Ó sì pe orúkọ Olúwa tí o bá sọ̀rọ̀ ní, “Ìwọ ni Ọlọ́run tí ó rí mi,” nítorí tí ó wí pé, “Mo ti ri ẹni tí ó rí mi báyìí.”
And she called the name of the LORde that spake vnto her: thou art the God that lokest on me for she sayde: I haue of a suertie sene here the backe parties of him that seith me.
14 Nítorí náà ni a ṣe ń pe kànga náà ní Beeri-Lahai-Roi; kànga ẹni alààyè tí ó rí mi. Ó wà ní agbede-méjì Kadeṣi àti Beredi.
Wherfore she called the well the well of the lyuynge that seith me which well is betwene Cades and Bared.
15 Hagari sì bí ọmọkùnrin kan fún Abramu, Abramu sì pe orúkọ rẹ̀ ní Iṣmaeli.
And Hagar bare Abram a sonne and Abram called his sons name which Hagar bare Ismaell.
16 Abramu jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínláàádọ́rùn-ún nígbà tí Hagari bí Iṣmaeli fún un.
And Abram was. lxxxvi. yere olde when Hagar bare him Ismael.

< Genesis 16 >