< Genesis 16 >

1 Sarai, aya Abramu kò bímọ fún un, ṣùgbọ́n ó ní ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin ará Ejibiti kan tí ń jẹ́ Hagari.
Abram zu, Sarai loe caa kaak; toe anih loe Izip tanuh, Hagar tiah ahmin kaom tamna maeto tawnh.
2 Nítorí náà, Sarai wí fún Abramu pé, “Kíyèsi i Olúwa ti sé mi ní inú, èmi kò sì bímọ, wọlé tọ ọmọ ọ̀dọ̀ mi lọ, bóyá èmi yóò le ti ipasẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.” Abramu sì gba ohun tí Sarai sọ.
To pongah Sarai mah Abram khaeah, Angraeng mah caa ang kaaksak boeh; caeh ah loe ka tamna nongpata khaeah iip ah, anih mah caa na sah pae khoe doeh om tih, tiah a naa. Abram mah Sarai ih lok to tahngaih pae.
3 Lẹ́yìn ọdún mẹ́wàá tí Abramu ti ń gbé ni Kenaani ni Sarai mú ọmọbìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ Hagari, tí í ṣe ará Ejibiti fún Abramu ọkọ rẹ̀ láti fi ṣe aya.
Abram loe Kanaan prae ah saning hato oh pacoengah, Sarai mah a tamna nongpata, Izip tanuh Hagar to lak moe, zu haih hanah sava khaeah paek.
4 Abramu sì bá Hagari lòpọ̀, ó sì lóyún. Nígbà tí ó sì ti mọ̀ pé òun lóyún, ó bẹ̀rẹ̀ sì ní kẹ́gàn ọ̀gá rẹ̀.
Abram mah Hagar to iih haih, to naah nongpata to zokpomh; zokpom boeh, tiah Hagar mah panoek naah angmah angraeng ih zupui to hnap.
5 Nígbà náà ni Sarai wí fún Abramu pé, “Ìwọ ni ó jẹ́ kí ẹ̀gbin yìí máa jẹ mí, mo fa ọmọ ọ̀dọ̀ mi lé ọ lọ́wọ́, nígbà tí ó sì rí i pé òun lóyún, mo di ẹni ẹ̀gàn ní ojú rẹ̀. Kí Olúwa kí ó ṣe ìdájọ́ láàrín tèmi tìrẹ.”
To naah Sarai mah Abram khaeah, Ka sakpazae ih hmuen loe na lu nuiah om nasoe; ka tamna nongpata to na saoek nuiah kang paek; anih mah zokpom boeh, tiah panoek naah, kai hae ang patoek; nang hoi kai salakah Angraeng mah lokcaek halat nasoe, tiah a naa.
6 Abramu dáhùn pé, “Ìwọ ló ni ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ, ṣe ohunkóhun tí ó bá tọ́ ní ojú rẹ sí i.” Nígbà náà ni Sarai fi ìyà jẹ Hagari, ó sì sálọ.
Toe Abram mah Sarai khaeah, Na tamna nongpata loe na ban ah ni oh; na koeh baktiah a nuiah sah khae, tiah a naa. Sarai mah Hagar to pacaekthlaek, to pongah Hagar loe anih khae hoi cawnh ving.
7 Angẹli Olúwa sì rí Hagari ní ẹ̀gbẹ́ ìsun omi ní ijù, ìsun omi tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà tí ó lọ sí Ṣuri.
Angraeng ih van kami mah Hagar to praezaek tuipuek taeng, Shur vangpui caehhaih loklam taengah hnuk.
8 Ó sì wí pé, “Hagari, ìránṣẹ́ Sarai, níbo ni o ti ń bọ̀, níbo sì ni ìwọ ń lọ?” Ó sì dáhùn pé, “Mo ń sálọ kúrò lọ́dọ̀ ọ̀gá mi Sarai ni.”
Anih mah, Sarai ih tamna nongpata, Hagar, naa hoiah maw nang zoh? Naa ah maw na caeh han? tiah a naa. Anih mah, Ka angraeng zupui Sarai khae hoiah ka cawnh ving, tiah a naa.
9 Angẹli Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ kí o sì tẹríba fún un.”
To naah Angraeng ih van kami mah anih khaeah, Na angraeng zupui khaeah amlaem let loe, anih tlim ah khosah ah, tiah a naa.
10 Angẹli Olúwa náà sì fi kún fún un pé, “Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, ìran rẹ kì yóò sì lóǹkà.”
Van kami mah anih khaeah, Kroek laek ai khoek to na caanawk kang pungsak han, tiah a naa.
11 Angẹli Olúwa náà sì wí fún un pé, “Ìwọ ti lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan. Ìwọ yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Iṣmaeli, nítorí tí Olúwa ti rí ìpọ́njú rẹ.
Angraeng ih van kami mah anih khaeah, Khenah, nang loe zokpomh boeh, caa nongpa to na sah tih; na patanghaih Angraeng mah thaih pae boeh pongah, anih ih ahmin to Ishmael, tiah sah ah, tiah a naa.
12 Òun yóò jẹ́ oníjàgídíjàgan ènìyàn ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára ènìyàn gbogbo, ọwọ́ ènìyàn gbogbo yóò sì wà lára rẹ̀, yóò sì máa gbé ní ìkanra pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀.”
Anih loe poek ham kami ah om ueloe, kami boih hoi angtuh tih, kami boih mah anih to tuh tih; anih loe angmah ih nawkamyanawk taengah khosah tih, tiah a naa.
13 Ó sì pe orúkọ Olúwa tí o bá sọ̀rọ̀ ní, “Ìwọ ni Ọlọ́run tí ó rí mi,” nítorí tí ó wí pé, “Mo ti ri ẹni tí ó rí mi báyìí.”
To naah Hagar mah, angmah khaeah lokthuikung Angraeng to, Nang loe kai hnukung Sithaw, tiah ahmin paek; anih mah, Vaihi kai Hnukung to ka hnuk boeh, tiah thuih.
14 Nítorí náà ni a ṣe ń pe kànga náà ní Beeri-Lahai-Roi; kànga ẹni alààyè tí ó rí mi. Ó wà ní agbede-méjì Kadeṣi àti Beredi.
To pongah to ih tuipuek to, Beer Lahai Roi, tiah ahmin sak; khenah, to tuipuek loe Kadesh hoi Bered salakah oh.
15 Hagari sì bí ọmọkùnrin kan fún Abramu, Abramu sì pe orúkọ rẹ̀ ní Iṣmaeli.
Hagar mah Abram hanah capa maeto sak pae; Hagar mah sak pae ih capa to Abram mah Ishmael, tiah ahmin phui.
16 Abramu jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínláàádọ́rùn-ún nígbà tí Hagari bí Iṣmaeli fún un.
Hagar mah Abram han Ishmael sak pae naah, Abram loe saning qui tazet, tarukto oh boeh.

< Genesis 16 >