< Genesis 15 >
1 Lẹ́yìn èyí, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Abramu wá lójú ìran pé, “Abramu má ṣe bẹ̀rù. Èmi ni ààbò rẹ, Èmi sì ni èrè ńlá rẹ.”
Bu ishlardin kéyin Perwerdigarning söz-kalami Abramgha alamet körünüshte kélip: «Ey Abram, qorqmighin; Men Özüm qalqining we zor in’amingdurmen» — dédi.
2 Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, kí ni ìwọ yóò fi fún mi níwọ̀n ìgbà tí èmi kò bímọ, Elieseri ará Damasku ni yóò sì jogún mi,”
Lékin Abram: — Ey Reb Perwerdigar, manga néme bérisen? Mana, men balisiz tursam, öy-bisatlirimgha warisliq qilghuchi mushu Demeshqlik Eliézerla bardur, — dédi.
3 Abramu sì tún tẹ̀síwájú pé, “Ìwọ kò fún mi ní ọmọ, nítorí náà ẹrú nínú ilé mi sì ni yóò jẹ́ àrólé mi.”
Abram yene: Mana, Sen manga héch nesil bermiding, mana öyümde turuwatqanlardin biri manga waris bolidu, dédi.
4 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ ọ́ wá pé, “Ọkùnrin yìí kọ́ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ bí kò ṣe ọmọ tí ìwọ bí fúnra rẹ̀ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ.”
Shu haman Perwerdigarning söz-kalami uninggha kélip: «Bu kishi sanga waris bolmaydu, belki öz pushtungdin bolidighan kishi sanga waris bolidu», — dédi.
5 Olúwa sì mú Abramu jáde sí ìta ó sì wí fún un pé, “Gbé ojú sókè sí ọ̀run kí o sì ka àwọn ìràwọ̀ bí ó bá ṣe pé ìwọ le è kà wọ́n.” Ó sì wí fun un pé, “Nítorí náà, báyìí ni irú-ọmọ rẹ yóò rí.”
Shuning bilen Perwerdigar uni tashqirigha élip chiqip: — Emdi asman’gha qarap yultuzlarni sana — Qéni, ularni saniyalamsenkin?! — dédi. Andin uninggha: — Séning neslingmu shundaq bolidu, — dédi.
6 Abramu gba Olúwa gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.
Abram Perwerdigargha ishendi; Perwerdigar uningdiki bu [ishenchni] uning heqqaniyliqi dep hésablidi.
7 Ó sì tún wí fún un pé, “Èmi ni Olúwa tí ó mú ọ jáde láti Uri ti Kaldea láti fún ọ ní ilẹ̀ yìí láti jogún.”
Yene uninggha: Men bu zémin’gha ige qilishqa séni Kaldiyediki Ur shehiridin élip chiqqan Perwerdigardurmen, — dédi.
8 Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, báwo ni mo ṣe lè mọ̀ pé ilẹ̀ náà yóò jẹ́ ohun ìní mi?”
Lékin [Abram]: — I Reb Perwerdigar, men uninggha jezmen ige bolidighinimni qandaq bilimen? — dep soridi.
9 Nítorí náà, Olúwa wí fún un pé, “Mú abo màlúù, ewúrẹ́ àti àgbò ọlọ́dún mẹ́ta mẹ́ta wá, àti àdàbà kan àti ọmọ ẹyẹlé kan.”
[Perwerdigar] uninggha: — Men üchün üch yashliq bir inek, üch yashliq bir chishi öchke, üch yashliq bir qochqar bilen bir kepter we bir bajka élip kelgin, — dédi.
10 Abramu sì mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí wá, ó sì là wọ́n sí méjì méjì, ó sì fi ẹ̀là èkínní kọjú sí èkejì, ṣùgbọ́n kò la àwọn ẹyẹ ní tiwọn.
Shunga u bularning hemmisini élip, ularning herbirsini yérimdin ikki parche qilip, yérimini yene bir yérimigha udulmu’udul qilip qoyup qoydi; emma qushlarni parchilimidi.
11 Àwọn ẹyẹ igún sì ń wá sórí òkú ẹran náà, Abramu sì ń lé wọn.
Qagha-quzghunlar taplarning üstige chüshkende, Abram ularni ürkütüp heydiwetti.
12 Bí oòrùn ti ń wọ̀, Abramu sùn lọ fọnfọn, òkùnkùn biribiri tí ó kún fún ẹ̀rù sì bò ó.
Lékin kün patay dégende, Abramni éghir bir uyqu basti we mana, uning üstige dehshetlik bir wehime, tom qarangghuluq chüshti.
13 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Abramu pé, “Mọ èyí dájú pé, irú-ọmọ rẹ yóò ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì, wọn ó sì sọ wọn di ẹrú, wọn ó sì pọ́n wọn lójú fún irinwó ọdún.
Andin Perwerdigar Abramgha: — Jezmen bilishing kérekki, séning nesling özlirining bolmighan bir zéminda musapir bolup, shu yerdiki xelqning qulluqida bolidu we shundaqla, bu xelq ulargha töt yüz yilghiche jebir-zulum salidu.
14 Ṣùgbọ́n orílẹ̀-èdè náà tí wọn yóò máa sìn, ni èmi ó dá lẹ́jọ́, lẹ́yìn náà ni wọn ó sì jáde pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀.
Lékin Men ularni qulluqqa salghuchi shu taipining üstidin höküm chiqirimen. Kéyin ular nurghun bayliqlarni élip shu yerdin chiqidu.
15 Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tọ àwọn baba rẹ lọ ni àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò sì di arúgbó kí a tó gbé ọ sin.
Emma sen bolsang, aman-xatirjemlik ichide ata-bowiliringgha qoshulisen; uzun ömür körüp andin depne qilinisen.
16 Ní ìran kẹrin àwọn ìran rẹ yóò padà wá sí ibi. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ará Amori kò ì tí ì kún òsùwọ̀n.”
Lékin shu yerde töt ewlad ötüp, [nesling] bu yerge yénip kélidu; chünki Amoriylarning qebihlikining zixi téxi toshmidi, dédi.
17 Nígbà tí oòrùn wọ̀ tí ilẹ̀ sì ṣú, ìkòkò iná tí ń ṣèéfín àti ọwọ́ iná sì ń kọjá láàrín ẹ̀là ẹran náà.
Shundaq boldiki, kün pétip qarangghu bolghanda, mana, göshlerning otturisidin ötüp kétiwatqan, is-tütek chiqip turghan bir otdan bilen yalqunluq bir mesh’el köründi.
18 Ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa dá májẹ̀mú pẹ̀lú Abramu, ó sì wí pé, “Àwọn ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún, láti odò Ejibiti dé odò ńlá Eufurate:
Del shu küni Perwerdigar Abram bilen ehde tüzüp uninggha: — «Men séning neslingge bu zéminni Misirning éqinidin tartip Ulugh derya, yeni Efrat deryasighiche bérimen; yeni Kéniyler, Kenizziylar, Kadmoniylar,
19 ilẹ̀ àwọn ará Keni, àti ti ará Kenissiti, àti ará Kadmoni,
20 àti ti ará Hiti, àti ti ará Peresi, àti ti ará Refaimu.
Hittiylar, Perizziyler, Refayiylar,
21 Àti ti ará Amori, àti ti ará Kenaani, àti ti ará Girgaṣi àti ti ará Jebusi.”
Amoriylar, Qanaaniylar, Girgashiylar we Yebusiylarning yurtini ularningki qilimen» dédi.