< Genesis 15 >

1 Lẹ́yìn èyí, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Abramu wá lójú ìran pé, “Abramu má ṣe bẹ̀rù. Èmi ni ààbò rẹ, Èmi sì ni èrè ńlá rẹ.”
Muri iho i enei mea ka puta moemoea mai te kupu a Ihowa ki a Aperama, ka mea, Kaua e wehi, e Aperama: ko ahau tou whakangungu rakau, tou utu nui whakaharahara.
2 Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, kí ni ìwọ yóò fi fún mi níwọ̀n ìgbà tí èmi kò bímọ, Elieseri ará Damasku ni yóò sì jogún mi,”
Na ka mea a Aperama, E te Ariki, e Ihowa, ko te aha e homai e koe ki ahau, e haere urikore nei ahau, a ko te taunga o toku whare hei tenei Erietera o Ramahiku?
3 Abramu sì tún tẹ̀síwájú pé, “Ìwọ kò fún mi ní ọmọ, nítorí náà ẹrú nínú ilé mi sì ni yóò jẹ́ àrólé mi.”
I mea ano a Aperama, Titiro hoki, kahore nei i homai e koe he uri ki ahau: a akuanei, kei tetahi tamaiti i whanau ki toku whare te mahuetanga iho o oku taonga.
4 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ ọ́ wá pé, “Ọkùnrin yìí kọ́ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ bí kò ṣe ọmọ tí ìwọ bí fúnra rẹ̀ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ.”
Na, kua puta mai te kupu a Ihowa ki a ia, i mea ia, E kore e mahue iho ou taonga mo tena; engari ka mahue iho mo tetahi e puta mai i roto i ou whekau.
5 Olúwa sì mú Abramu jáde sí ìta ó sì wí fún un pé, “Gbé ojú sókè sí ọ̀run kí o sì ka àwọn ìràwọ̀ bí ó bá ṣe pé ìwọ le è kà wọ́n.” Ó sì wí fun un pé, “Nítorí náà, báyìí ni irú-ọmọ rẹ yóò rí.”
Na ka kawea ia e ia ki waho, a ka mea mai, Tena tirohia atu te rangi, taua hoki nga whetu, ki te taea ena e koe te tatau: a ka mea ia ki a ia, Ka pera tou uri.
6 Abramu gba Olúwa gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.
I whakapono hoki ia ki a Ihowa, a ka whakairia ki a ia hei tika.
7 Ó sì tún wí fún un pé, “Èmi ni Olúwa tí ó mú ọ jáde láti Uri ti Kaldea láti fún ọ ní ilẹ̀ yìí láti jogún.”
I mea ano ia ki a ia, Ko Ihowa ahau, nana nei koe i kawe mai i Uru o nga Karari, kia hoatu ai ki a koe tenei whenua hei kainga pumau.
8 Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, báwo ni mo ṣe lè mọ̀ pé ilẹ̀ náà yóò jẹ́ ohun ìní mi?”
Ano ra ko ia, E te Ariki, e Ihowa, ma te aha ka mohio ai ahau ka riro mai tenei i ahau?
9 Nítorí náà, Olúwa wí fún un pé, “Mú abo màlúù, ewúrẹ́ àti àgbò ọlọ́dún mẹ́ta mẹ́ta wá, àti àdàbà kan àti ọmọ ẹyẹlé kan.”
Na ka mea ia ki a ia, Tikina tetahi kau maku, hei te tau toru, me tetahi koati uha, hei te tau toru, me tetahi hipi toa, hei te tau toru, me tetahi kukupa, me tetahi pi kukupa.
10 Abramu sì mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí wá, ó sì là wọ́n sí méjì méjì, ó sì fi ẹ̀là èkínní kọjú sí èkejì, ṣùgbọ́n kò la àwọn ẹyẹ ní tiwọn.
Na tikina ana e ia aua mea katoa, a tapahia ana i waenganui, whakatakotoria ana nga wahi kia rite mai ki a raua whakawahi: ko nga manu ia kihai i tapahia e ia.
11 Àwọn ẹyẹ igún sì ń wá sórí òkú ẹran náà, Abramu sì ń lé wọn.
A ka rere iho nga manu ki nga tinana, ka aia atu e Aperama.
12 Bí oòrùn ti ń wọ̀, Abramu sùn lọ fọnfọn, òkùnkùn biribiri tí ó kún fún ẹ̀rù sì bò ó.
Na, i te rerenga o te ra, ka parangia a Aperama e te moe; na ko te whakawehi o te pouri kerekere e tau iho ana ki a ia.
13 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Abramu pé, “Mọ èyí dájú pé, irú-ọmọ rẹ yóò ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì, wọn ó sì sọ wọn di ẹrú, wọn ó sì pọ́n wọn lójú fún irinwó ọdún.
A ka mea ia ki a Aperama, Kia tino mohio koe, ka noho manene tou uri ki tetahi whenua ehara nei i a ratou, a ka mahi ki a ratou; a e wha rau nga tau e whakatupuria kinotia ai ratou;
14 Ṣùgbọ́n orílẹ̀-èdè náà tí wọn yóò máa sìn, ni èmi ó dá lẹ́jọ́, lẹ́yìn náà ni wọn ó sì jáde pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀.
Ka whakawakia ano e ahau te iwi e whakamahia ai ratou: a muri iho ka puta mai ratou me nga taonga maha.
15 Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tọ àwọn baba rẹ lọ ni àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò sì di arúgbó kí a tó gbé ọ sin.
Ko koe ia ka haere marie ki ou matua; ka pai tou koroheketanga, a tanumia noatia koe.
16 Ní ìran kẹrin àwọn ìran rẹ yóò padà wá sí ibi. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ará Amori kò ì tí ì kún òsùwọ̀n.”
Kei te wha ia a nga whakatupuranga ka hoki mai ratou ki konei no te mea kahore ano kia tutuki noa te hara o nga Amori.
17 Nígbà tí oòrùn wọ̀ tí ilẹ̀ sì ṣú, ìkòkò iná tí ń ṣèéfín àti ọwọ́ iná sì ń kọjá láàrín ẹ̀là ẹran náà.
Na i te tonga o te ra, no ka pouri, na, ko te oumu paowa, me te rama e ka ana, e tika ana i waenganui o aua porohanga.
18 Ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa dá májẹ̀mú pẹ̀lú Abramu, ó sì wí pé, “Àwọn ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún, láti odò Ejibiti dé odò ńlá Eufurate:
I taua rangi ano ka whakaritea e Ihowa he kawenata ki a Aperama, ka mea ia, Ka hoatu e ahau tenei whenua ki tou uri, mai ra ano o te awa o Ihipa, a tae noa ki te awa nui, ki te awa, ki Uparati:
19 ilẹ̀ àwọn ará Keni, àti ti ará Kenissiti, àti ará Kadmoni,
Nga Keni, nga Keniti, nga Karamoni,
20 àti ti ará Hiti, àti ti ará Peresi, àti ti ará Refaimu.
Nga Hiti, nga Perihi, nga Repaima,
21 Àti ti ará Amori, àti ti ará Kenaani, àti ti ará Girgaṣi àti ti ará Jebusi.”
Nga Amori, nga Kanaani, nga Kirikahi, me nga Iepuhi.

< Genesis 15 >