< Genesis 15 >

1 Lẹ́yìn èyí, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Abramu wá lójú ìran pé, “Abramu má ṣe bẹ̀rù. Èmi ni ààbò rẹ, Èmi sì ni èrè ńlá rẹ.”
Ezen dolgok után volt az Örökkévaló igéje Ávromhoz látomásban, mondván: Ne félj Ávrom, én pajzsod vagyok neked, a te jutalmad igen sok.
2 Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, kí ni ìwọ yóò fi fún mi níwọ̀n ìgbà tí èmi kò bímọ, Elieseri ará Damasku ni yóò sì jogún mi,”
És mondta Ávrom: Uram, Isten! mit adsz én nekem? hisz én járok magtalanul és házam birtokosa a damaszkusi Eliezer.
3 Abramu sì tún tẹ̀síwájú pé, “Ìwọ kò fún mi ní ọmọ, nítorí náà ẹrú nínú ilé mi sì ni yóò jẹ́ àrólé mi.”
És mondta Ávrom: Íme, nekem nem adtál magzatot és íme, az én házam szolgaszülöttje örököl utánam.
4 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ ọ́ wá pé, “Ọkùnrin yìí kọ́ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ bí kò ṣe ọmọ tí ìwọ bí fúnra rẹ̀ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ.”
És íme az Örökkévaló igéje hozzá, mondván: Nem örököl ez te utánad, hanem az, aki származni fog ágyékodból, az örököl majd utánad.
5 Olúwa sì mú Abramu jáde sí ìta ó sì wí fún un pé, “Gbé ojú sókè sí ọ̀run kí o sì ka àwọn ìràwọ̀ bí ó bá ṣe pé ìwọ le è kà wọ́n.” Ó sì wí fun un pé, “Nítorí náà, báyìí ni irú-ọmọ rẹ yóò rí.”
És kivezette őt a szabadba és mondta: Tekints csak fel az égre és számláld meg a csillagokat, ha meg bírod azokat számlálni. És mondta neki: Így lesz a te magzatod!
6 Abramu gba Olúwa gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.
És ő hitt az Örökkévalóban és (Isten) betudta azt neki igazságul.
7 Ó sì tún wí fún un pé, “Èmi ni Olúwa tí ó mú ọ jáde láti Uri ti Kaldea láti fún ọ ní ilẹ̀ yìí láti jogún.”
És mondta neki: Én vagyok az Örökkévaló, aki kihoztalak téged Ur-Kászdimból, hogy neked adjam ezt az országot, hogy bírjad azt.
8 Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, báwo ni mo ṣe lè mọ̀ pé ilẹ̀ náà yóò jẹ́ ohun ìní mi?”
És ő mondta: Uram, Isten! mi által tudom meg, hogy én fogom azt bírni?
9 Nítorí náà, Olúwa wí fún un pé, “Mú abo màlúù, ewúrẹ́ àti àgbò ọlọ́dún mẹ́ta mẹ́ta wá, àti àdàbà kan àti ọmọ ẹyẹlé kan.”
És mondta neki: Vegyél nekem egy három éves üszőt, egy hároméves kecskét és egy három éves kost, egy gerlicét és egy galambfiát.
10 Abramu sì mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí wá, ó sì là wọ́n sí méjì méjì, ó sì fi ẹ̀là èkínní kọjú sí èkejì, ṣùgbọ́n kò la àwọn ẹyẹ ní tiwọn.
És ő vette Neki mindezt és szétvágta azokat középen és tette mindegyiknek a részét a másikkal szembe; a madarat azonban nem vágta ketté.
11 Àwọn ẹyẹ igún sì ń wá sórí òkú ẹran náà, Abramu sì ń lé wọn.
És leszállottak a ragadozó madarak a hullákra, de Ávrom elkergette azokat.
12 Bí oòrùn ti ń wọ̀, Abramu sùn lọ fọnfọn, òkùnkùn biribiri tí ó kún fún ẹ̀rù sì bò ó.
És midőn a nap lemenőben volt, mély álom borult Ávromra és íme, félelem, nagy sötétség borul rá.
13 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Abramu pé, “Mọ èyí dájú pé, irú-ọmọ rẹ yóò ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì, wọn ó sì sọ wọn di ẹrú, wọn ó sì pọ́n wọn lójú fún irinwó ọdún.
És mondta (Isten) Ávromnak: Tudd meg, hogy idegen lesz a te magzatod egy országban, mely nem az övék és szolgálatra szorítják őket és sanyargatják őket négyszáz évig.
14 Ṣùgbọ́n orílẹ̀-èdè náà tí wọn yóò máa sìn, ni èmi ó dá lẹ́jọ́, lẹ́yìn náà ni wọn ó sì jáde pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀.
De ama nép fölött is, melyet szolgálni fognak, ítéletet tartok én és azután ki fognak vonulni nagy vagyonnal.
15 Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tọ àwọn baba rẹ lọ ni àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò sì di arúgbó kí a tó gbé ọ sin.
Te pedig elmégy atyáidhoz békében, el fogsz temettetni jó vénségben.
16 Ní ìran kẹrin àwọn ìran rẹ yóò padà wá sí ibi. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ará Amori kò ì tí ì kún òsùwọ̀n.”
És a negyedik nemzedék tér majd vissza ide, mert nem telik be az Emóri vétke addig.
17 Nígbà tí oòrùn wọ̀ tí ilẹ̀ sì ṣú, ìkòkò iná tí ń ṣèéfín àti ọwọ́ iná sì ń kọjá láàrín ẹ̀là ẹran náà.
És volt, midőn a nap lement és sötétség lett, íme, egy kemence: füst és tűzláng, mely átvonult ama darabok között.
18 Ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa dá májẹ̀mú pẹ̀lú Abramu, ó sì wí pé, “Àwọn ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún, láti odò Ejibiti dé odò ńlá Eufurate:
Azon a napon kötött az Örökkévaló szövetséget Ávrommal, mondván: A te magzatodnak adom ezt a földet, az egyiptomi folyamtól a nagy folyamig, a Perosz folyamig:
19 ilẹ̀ àwọn ará Keni, àti ti ará Kenissiti, àti ará Kadmoni,
A Kénit, a Kenizzit és a Kádmónit,
20 àti ti ará Hiti, àti ti ará Peresi, àti ti ará Refaimu.
a Chittit, a Perizzit és a Refóimot,
21 Àti ti ará Amori, àti ti ará Kenaani, àti ti ará Girgaṣi àti ti ará Jebusi.”
az Emórit, a Kánaánit, a Girgósit és a Jevúszit.

< Genesis 15 >