< Genesis 14 >

1 Ní àsìkò yìí ni Amrafeli ọba Ṣinari, Arioku ọba Ellasari, Kedorlaomeri ọba Elamu àti Tidali ọba Goyimu
På den tid då Amrafel var konung i Sinear, Arjok konung i Ellasar, Kedorlaomer konung i Elam och Tideal konung över Goim, hände sig
2 jáde lọ láti bá Bera ọba Sodomu, Birṣa ọba Gomorra, Ṣenabu ọba Adma, Ṣemeberi ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari) jagun.
att dessa begynte krig mot Bera, konungen i Sodom, Birsa, konungen i Gomorra, Sinab, konungen i Adma, Semeber, konungen i Seboim, och mot konungen i Bela, det är Soar.
3 Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí ni ó kó ogun wọn jọ pọ̀ sí àfonífojì Siddimu (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀).
De förenade sig alla och tågade till Siddimsdalen, där Salthavet nu är.
4 Fún ọdún méjìlá gbáko ni wọ́n ti ń sin Kedorlaomeri bí ẹrú. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di ọdún kẹtàlá wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i.
I tolv år hade de varit under Kedorlaomer, men i det trettonde året hade de avfallit.
5 Ní ọdún kẹrìnlá, ni Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí wọ́n ti jọ ni májẹ̀mú àṣepọ̀ wá, wọ́n ṣígun, wọ́n sì ṣẹ́gun ará Refaimu ní Aṣteroti-Karnaimu, àwọn ará Susimu ni Hamu, àwọn ará Emimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kiriataimu,
Så kom nu i det fjortonde året Kedorlaomer med de konungar som voro på hans sida; och de slogo rafaéerna i Asterot-Karnaim, suséerna i Ham, eméerna i Save-Kirjataim
6 àti àwọn ará Hori ní orí òkè wọ̀n-ọn-nì Seiri, títí ó fi dé Eli-Parani ní etí ijù.
och horéerna på deras berg Seir och drevo dem ända till El-Paran vid öknen.
7 Wọ́n sì tún yípadà lọ sí En-Miṣpati (ti o túmọ̀ sí Kadeṣi), wọ́n sì ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ àwọn Amaleki, àti àwọn ará Amori tí ó tẹ̀dó sí Hasason Tamari pẹ̀lú.
Sedan vände de om och kommo till En-Mispat, det är Kades, och härjade amalekiternas hela land; de slogo ock amoréerna som bodde i Hasason-Tamar.
8 Nígbà náà ni ọba Sodomu, ọba Gomorra, ọba Adma, ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari), kó àwọn ọmọ-ogun wọn, wọ́n sì pa ibùdó ogun wọn sí Àfonífojì Siddimu,
Då drogo konungen i Sodom, konungen i Gomorra, konungen i Adma, konungen i Seboim och konungen i Bela, det är Soar, ut och ställde upp sig i Siddimsdalen till strid mot dem --
9 láti kojú ìjà sí Kedorlaomeri ọba Elamu, Tidali ọba Goyimu, Amrafeli ọba Ṣinari àti Arioku ọba Ellasari (ọba mẹ́rin kọjú ìjà sí ọba márùn-ún).
mot Kedorlaomer, konungen i Elam, Tideal, konungen över Goim, Amrafel, konungen i Sinear, och Arjok, konungen i Ellasar, fyra konungar mot de fem.
10 Àfonífojì Siddimu sì kún fún kòtò ọ̀dà ilẹ̀, nígbà tí ọba Sodomu àti ọba Gomorra sì sá, díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin ogun náà ṣubú sínú àwọn kòtò náà, àwọn tókù sì sálọ sì orí òkè.
Men Siddimsdalen var full av jordbecksgropar. Och konungarna i Sodom och Gomorra måste fly och föllo då i dessa, och de som kommo undan flydde till bergsbygden.
11 Àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà sì kó gbogbo ẹrù Sodomu àti Gomorra àti oúnjẹ wọn; wọ́n sì lọ.
Så togo de allt gods som fanns i Sodom och Gomorra, och alla livsmedel där, och tågade bort;
12 Wọ́n sì mú Lọti ọmọ arákùnrin Abramu tí ń gbé ní Sodomu àti gbogbo ohun ìní rẹ̀.
de togo ock med sig Lot, Abrams brorson, och hans ägodelar, när de tågade bort; ty denne bodde i Sodom.
13 Ẹnìkan tí ó sá àsálà sì wá ròyìn fún Abramu, ará Heberu ni. Abramu sá ti tẹ̀dó sí ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre ará Amori, arákùnrin Eṣkolu àti Aneri: àwọn ẹni tí ó ń bá Abramu ní àṣepọ̀.
Men en av de räddade kom och berättade detta för Abram, hebréen; denne bodde vid den terebintlund som tillhörde amoréen Mamre, Eskols och Aners broder, och dessa voro i förbund med Abram.
14 Nígbà tí Abramu gbọ́ wí pé, a di Lọti ní ìgbèkùn, ó kó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí a bí sí ilẹ̀ rẹ̀ tí ó sì ti kọ́ ni ogun jíjà jáde, wọ́n jẹ́ okòó lé lọ́ọ̀dúnrún ó dín méjì ènìyàn, ó sì lépa wọn títí dé Dani.
Då nu Abram hörde att hans frände var fången, lät han sina mest beprövade tjänare, sådana som voro födda i hans hus, tre hundra aderton män, rycka ut, och förföljde fienderna ända till Dan
15 Ní ọ̀gànjọ́ òru, Abramu pín àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sí méjì, ó sì kọlù wọ́n, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì lé wọn títí dé Hoba tí ó wà ní apá òsì Damasku.
Och han delade sitt folk och överföll dem så om natten med sina tjänare och slog dem, och förföljde dem sedan ända till Hoba, norr om Damaskus,
16 Gbogbo ìkógun ni ó rí gbà padà àti ọmọ arákùnrin rẹ̀, Lọti pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, àti àwọn obìnrin pẹ̀lú àwọn ènìyàn tókù.
och tog tillbaka allt godset; sin frände Lot och hans ägodelar tog han ock tillbaka, ävensom kvinnorna och det övriga folket.
17 Nígbà tí Abramu ti ṣẹ́gun Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí ó pẹ̀lú rẹ̀, ọba Sodomu lọ pàdé rẹ̀ ní àfonífojì Ṣafe (èyí ni àfonífojì Ọba).
Då han nu var på återvägen, sedan han hade slagit Kedorlaomer och de konungar som voro på hans sida, gick konungen i Sodom honom till mötes i Savedalen, det är Konungsdalen.
18 Melkisedeki ọba Salẹmu sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo.
Och Melki-Sedek, konungen i Salem, lät bära ut bröd och vin; denne var präst åt Gud den Högste.
19 Ó sì súre fún Abramu, wí pé, “Ìbùkún ni fún Abramu ti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Och han välsignade honom och sade: »Välsignad vare Abram av Gud den Högste, himmelens och jordens skapare!
20 Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ, tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.” Abramu sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.
Och välsignad vare Gud den Högste, som har givit dina ovänner i din hand!» Och Abram gav honom tionde av allt.
21 Ọba Sodomu sì wí fún Abramu pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”
Och konungen i Sodom sade till Abram: »Giv mig folket; godset må du behålla för dig själv.»
22 Ṣùgbọ́n Abramu dá ọba Sodomu lóhùn pé, “Mo ti búra fún Olúwa, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ó dá ọ̀run àti ayé, mo sì ti gbọ́wọ́ sókè,
Men Abram svarade konungen i Sodom: »Jag lyfter min hand upp till HERREN, till Gud den Högste, himmelens och jordens skapare, och betygar
23 pé, èmi kì yóò mú láti fọ́nrán òwú títí dé okùn bàtà, àti pé, èmi kí yóò mú ohun kan tí ṣe tìrẹ, kí ìwọ kí ó má ba à wí pé, ‘Mo sọ Abramu di ọlọ́rọ̀.’
att jag icke vill taga ens en tråd eller en skorem, än mindre något annat som tillhör dig. Du skall icke kunna säga: 'Jag har riktat Abram.'
24 Èmi kì yóò gba ohunkóhun yàtọ̀ sí ohun tí àwọn ọkùnrin mi ti jẹ́, ṣùgbọ́n fi ìpín fún àwọn ọkùnrin tí ó bá mi lọ, Aneri, Eṣkolu àti Mamre. Jẹ́ kí wọn kí ó gba ìpín wọn.”
Jag vill intet hava; det är nog med vad mina män hava förtärt och den del som tillkommer mina följeslagare. Aner, Eskol och Mamre, de må få sin del.»

< Genesis 14 >