< Genesis 14 >
1 Ní àsìkò yìí ni Amrafeli ọba Ṣinari, Arioku ọba Ellasari, Kedorlaomeri ọba Elamu àti Tidali ọba Goyimu
Şi s-a întâmplat în zilele lui Amrafel, împărat al Şinarului, Arioc, împărat al Elasarului, Chedorlaomer, împărat al Elamului şi Tidal, împărat al naţiunilor,
2 jáde lọ láti bá Bera ọba Sodomu, Birṣa ọba Gomorra, Ṣenabu ọba Adma, Ṣemeberi ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari) jagun.
Că aceştia au făcut război cu Bera, împăratul Sodomei, şi cu Birşa, împăratul Gomorei, Şinab, împărat al Admei, şi Şemeber, împăratul Ţeboimului, şi cu împăratul din Bela, care este Ţoar.
3 Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí ni ó kó ogun wọn jọ pọ̀ sí àfonífojì Siddimu (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀).
Toţi aceştia s-au adunat în valea Sidim, care este marea sărată.
4 Fún ọdún méjìlá gbáko ni wọ́n ti ń sin Kedorlaomeri bí ẹrú. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di ọdún kẹtàlá wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i.
Doisprezece ani au servit lui Chedorlaomer, şi în al treisprezecelea an s-au răzvrătit.
5 Ní ọdún kẹrìnlá, ni Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí wọ́n ti jọ ni májẹ̀mú àṣepọ̀ wá, wọ́n ṣígun, wọ́n sì ṣẹ́gun ará Refaimu ní Aṣteroti-Karnaimu, àwọn ará Susimu ni Hamu, àwọn ará Emimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kiriataimu,
Şi în al paisprezecelea an a venit Chedorlaomer şi împăraţii care erau cu el şi au lovit pe refaimi în Aşterot Carnaim, şi pe zuzimi în Ham, şi pe emimi în Şave Chiriataim,
6 àti àwọn ará Hori ní orí òkè wọ̀n-ọn-nì Seiri, títí ó fi dé Eli-Parani ní etí ijù.
Şi pe horiţi în muntele lor Seir, spre Elparan, care este lângă pustie.
7 Wọ́n sì tún yípadà lọ sí En-Miṣpati (ti o túmọ̀ sí Kadeṣi), wọ́n sì ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ àwọn Amaleki, àti àwọn ará Amori tí ó tẹ̀dó sí Hasason Tamari pẹ̀lú.
Şi ei s-au întors şi au venit la Enmişpat, care este Cades, şi au lovit toată ţara amaleciţilor şi de asemenea pe amoriţi, care locuiesc în Haţeţon-Tamar.
8 Nígbà náà ni ọba Sodomu, ọba Gomorra, ọba Adma, ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari), kó àwọn ọmọ-ogun wọn, wọ́n sì pa ibùdó ogun wọn sí Àfonífojì Siddimu,
Şi au ieşit împăratul Sodomei şi împăratul Gomorei şi împăratul Admei şi împăratul Ţeboimului şi împăratul din Bela (care este Ţoar) şi au intrat în luptă cu ei în valea Sidim;
9 láti kojú ìjà sí Kedorlaomeri ọba Elamu, Tidali ọba Goyimu, Amrafeli ọba Ṣinari àti Arioku ọba Ellasari (ọba mẹ́rin kọjú ìjà sí ọba márùn-ún).
Cu Chedorlaomer, împăratul Elamului, şi cu Tidal împăratul naţiunilor, şi Amrafel, împăratul Şinarului, şi Arioc, împăratul Elasarului; patru împăraţi cu cinci.
10 Àfonífojì Siddimu sì kún fún kòtò ọ̀dà ilẹ̀, nígbà tí ọba Sodomu àti ọba Gomorra sì sá, díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin ogun náà ṣubú sínú àwọn kòtò náà, àwọn tókù sì sálọ sì orí òkè.
Şi valea Sidim era plină cu gropi de smoală; şi împăraţii Sodomei şi Gomorei au fugit şi au căzut acolo; şi cei ce au rămas au fugit la munte.
11 Àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà sì kó gbogbo ẹrù Sodomu àti Gomorra àti oúnjẹ wọn; wọ́n sì lọ.
Şi au luat toate bunurile Sodomei şi Gomorei şi toate merindele lor şi au plecat.
12 Wọ́n sì mú Lọti ọmọ arákùnrin Abramu tí ń gbé ní Sodomu àti gbogbo ohun ìní rẹ̀.
Şi au luat pe Lot, fiul fratelui lui Avram, care locuia în Sodoma, şi bunurile lui şi au plecat.
13 Ẹnìkan tí ó sá àsálà sì wá ròyìn fún Abramu, ará Heberu ni. Abramu sá ti tẹ̀dó sí ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre ará Amori, arákùnrin Eṣkolu àti Aneri: àwọn ẹni tí ó ń bá Abramu ní àṣepọ̀.
Şi a venit unul care scăpase şi a spus lui Avram, evreul, căci locuia în câmpia lui Mamre amoritul, fratele lui Eşcol şi fratele lui Aner; şi aceştia erau aliaţi cu Avram.
14 Nígbà tí Abramu gbọ́ wí pé, a di Lọti ní ìgbèkùn, ó kó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí a bí sí ilẹ̀ rẹ̀ tí ó sì ti kọ́ ni ogun jíjà jáde, wọ́n jẹ́ okòó lé lọ́ọ̀dúnrún ó dín méjì ènìyàn, ó sì lépa wọn títí dé Dani.
Şi când a auzit Avram că fratele său a fost luat captiv, a înarmat pe servitorii lui instruiţi, născuţi în casa lui, trei sute şi optsprezece, şi i-a urmărit până la Dan.
15 Ní ọ̀gànjọ́ òru, Abramu pín àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sí méjì, ó sì kọlù wọ́n, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì lé wọn títí dé Hoba tí ó wà ní apá òsì Damasku.
Şi s-a împărţit împotriva lor, el şi servitorii lui, noaptea, şi i-a lovit şi i-a urmărit până la Hoba, care este la stânga Damascului.
16 Gbogbo ìkógun ni ó rí gbà padà àti ọmọ arákùnrin rẹ̀, Lọti pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, àti àwọn obìnrin pẹ̀lú àwọn ènìyàn tókù.
Şi a adus înapoi toate bunurile şi de asemenea a adus înapoi pe fratele său, Lot, şi bunurile lui şi pe femei de asemenea şi pe oameni.
17 Nígbà tí Abramu ti ṣẹ́gun Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí ó pẹ̀lú rẹ̀, ọba Sodomu lọ pàdé rẹ̀ ní àfonífojì Ṣafe (èyí ni àfonífojì Ọba).
Şi împăratul Sodomei a ieşit să îl întâmpine după întoarcerea lui de la măcelul lui Chedorlaomer şi a împăraţilor care erau cu el, la valea Şave, care este valea împăratului.
18 Melkisedeki ọba Salẹmu sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo.
Şi Melchisedec, împăratul Salemului, a adus pâine şi vin; şi el era preotul Dumnezeului cel preaînalt.
19 Ó sì súre fún Abramu, wí pé, “Ìbùkún ni fún Abramu ti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Şi l-a binecuvântat şi a spus: Binecuvântat fie Avram de Dumnezeul cel preaînalt, stăpânul cerului şi al pământului;
20 Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ, tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.” Abramu sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.
Şi binecuvântat fie Dumnezeul cel preaînalt care a dat pe duşmanii tăi în mâna ta. Şi Avram i-a dat zeciuieli din toate.
21 Ọba Sodomu sì wí fún Abramu pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”
Şi împăratul Sodomei i-a spus lui Avram: Dă-mi oamenii şi ia bunurile pentru tine.
22 Ṣùgbọ́n Abramu dá ọba Sodomu lóhùn pé, “Mo ti búra fún Olúwa, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ó dá ọ̀run àti ayé, mo sì ti gbọ́wọ́ sókè,
Şi Avram a spus împăratului Sodomei: Mi-am înălţat mâna spre DOMNUL, Dumnezeul cel preaînalt, stăpânul cerului şi pământului,
23 pé, èmi kì yóò mú láti fọ́nrán òwú títí dé okùn bàtà, àti pé, èmi kí yóò mú ohun kan tí ṣe tìrẹ, kí ìwọ kí ó má ba à wí pé, ‘Mo sọ Abramu di ọlọ́rọ̀.’
Că nu voi lua de la o aţă chiar până la o curea de sandală şi că nu voi lua nimic din ceea ce este al tău, ca nu cumva să spui: Eu l-am făcut pe Avram bogat;
24 Èmi kì yóò gba ohunkóhun yàtọ̀ sí ohun tí àwọn ọkùnrin mi ti jẹ́, ṣùgbọ́n fi ìpín fún àwọn ọkùnrin tí ó bá mi lọ, Aneri, Eṣkolu àti Mamre. Jẹ́ kí wọn kí ó gba ìpín wọn.”
În afară de ceea ce tinerii au mâncat şi partea oamenilor care au fost cu mine, Aner, Eşcol şi Mamre, lasă-i să îşi ia partea lor.