< Genesis 14 >
1 Ní àsìkò yìí ni Amrafeli ọba Ṣinari, Arioku ọba Ellasari, Kedorlaomeri ọba Elamu àti Tidali ọba Goyimu
Un notikās Amrafela, Sineāras ķēniņa, Arioka, Elasaras ķēniņa, Ķedorlaomera, Elama ķēniņa, un Tideāla, Gojimu ķēniņa, laikā -
2 jáde lọ láti bá Bera ọba Sodomu, Birṣa ọba Gomorra, Ṣenabu ọba Adma, Ṣemeberi ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari) jagun.
Tie karoja pret Beru, Sodomas ķēniņu, un pret Biršu, Gomoras ķēniņu, Sineabu, Adamas ķēniņu, un Semeberu, Ceboīma ķēniņu, un Belas, tas ir Coāras ķēniņu.
3 Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí ni ó kó ogun wọn jọ pọ̀ sí àfonífojì Siddimu (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀).
Šie visi sapulcējās Sidim ielejā, tā ir tā Sāls jūra.
4 Fún ọdún méjìlá gbáko ni wọ́n ti ń sin Kedorlaomeri bí ẹrú. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di ọdún kẹtàlá wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i.
Divpadsmit gadus tie bija kalpojuši Ķedorlaomeram, un trīspadsmitā gadā tie atkrita.
5 Ní ọdún kẹrìnlá, ni Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí wọ́n ti jọ ni májẹ̀mú àṣepọ̀ wá, wọ́n ṣígun, wọ́n sì ṣẹ́gun ará Refaimu ní Aṣteroti-Karnaimu, àwọn ará Susimu ni Hamu, àwọn ará Emimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kiriataimu,
Un četrpadsmitā gadā Ķedorlaomers nāca un tie ķēniņi, kas līdz ar viņu bija, un sakāva tos Refaīm iekš Astarot-Karnaīm un tos Hauzim Amā, un tos Emim Kiriataīm ielejā,
6 àti àwọn ará Hori ní orí òkè wọ̀n-ọn-nì Seiri, títí ó fi dé Eli-Parani ní etí ijù.
Un tos Horiešus uz viņu Seīra kalniem līdz Ēl-Param, kas pie tuksneša.
7 Wọ́n sì tún yípadà lọ sí En-Miṣpati (ti o túmọ̀ sí Kadeṣi), wọ́n sì ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ àwọn Amaleki, àti àwọn ará Amori tí ó tẹ̀dó sí Hasason Tamari pẹ̀lú.
Un tie griezās atpakaļ un nāca pie Mišpata avota, tas ir Kādeša, un sakāva visu Amalekiešu apgabalu un arī Amoriešus, kas dzīvoja Acecon-Tamarā.
8 Nígbà náà ni ọba Sodomu, ọba Gomorra, ọba Adma, ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari), kó àwọn ọmọ-ogun wọn, wọ́n sì pa ibùdó ogun wọn sí Àfonífojì Siddimu,
Tad izgāja Sodomas ķēniņš un Gomoras ķēniņš un Adamas ķēniņš un Ceboīma ķēniņš un Belas, tas ir Coāras, ķēniņš, un taisījās pret tiem kauties Sidim ielejā,
9 láti kojú ìjà sí Kedorlaomeri ọba Elamu, Tidali ọba Goyimu, Amrafeli ọba Ṣinari àti Arioku ọba Ellasari (ọba mẹ́rin kọjú ìjà sí ọba márùn-ún).
Pret Ķedorlaomeru, Elama ķēniņu, un Tideālu, Gojimu ķēniņu, un Amrafeli, Sineāras ķēniņu, un Arioku, Elasaras ķēniņu: - četri ķēniņi pret pieciem.
10 Àfonífojì Siddimu sì kún fún kòtò ọ̀dà ilẹ̀, nígbà tí ọba Sodomu àti ọba Gomorra sì sá, díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin ogun náà ṣubú sínú àwọn kòtò náà, àwọn tókù sì sálọ sì orí òkè.
Un Sidim ielejā bija daudz zemes piķa bedres; tad Sodomas un Gomoras ķēniņi bēga un tur iekrita, un tie atlikušie aizbēga kalnos.
11 Àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà sì kó gbogbo ẹrù Sodomu àti Gomorra àti oúnjẹ wọn; wọ́n sì lọ.
Un tie paņēma visu Sodomas un Gomoras mantu un visu viņu barību un aizgāja projām;
12 Wọ́n sì mú Lọti ọmọ arákùnrin Abramu tí ń gbé ní Sodomu àti gbogbo ohun ìní rẹ̀.
Un paņēma arī Latu, Ābrama brālēnu, un viņa mantu, jo tas dzīvoja Sodomā, - un aizgāja projām.
13 Ẹnìkan tí ó sá àsálà sì wá ròyìn fún Abramu, ará Heberu ni. Abramu sá ti tẹ̀dó sí ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre ará Amori, arákùnrin Eṣkolu àti Aneri: àwọn ẹni tí ó ń bá Abramu ní àṣepọ̀.
Tad nāca viens, kas bija izmucis, un pasacīja to Ābramam, tam Ebrejam; tas dzīvoja starp tiem ozoliem, kas piederēja tam Amorietim Mamre, Eškola un Anera brālim; šie bija Ābrama derības biedri.
14 Nígbà tí Abramu gbọ́ wí pé, a di Lọti ní ìgbèkùn, ó kó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí a bí sí ilẹ̀ rẹ̀ tí ó sì ti kọ́ ni ogun jíjà jáde, wọ́n jẹ́ okòó lé lọ́ọ̀dúnrún ó dín méjì ènìyàn, ó sì lépa wọn títí dé Dani.
Un Ābrams dzirdējis, savu brāli esam aizvestu cietumā, apbruņojās ar saviem kalpiem, kas viņa namā bija dzimuši, trīssimt un astoņpadsmit, un dzinās tiem pakaļ līdz Danam.
15 Ní ọ̀gànjọ́ òru, Abramu pín àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sí méjì, ó sì kọlù wọ́n, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì lé wọn títí dé Hoba tí ó wà ní apá òsì Damasku.
Un viņš dalījās un uzbruka tiem naktī, viņš un viņa kalpi, un tos sakāva un dzinās tiem pakaļ līdz Hobai, kas Damaskum pa kreiso roku,
16 Gbogbo ìkógun ni ó rí gbà padà àti ọmọ arákùnrin rẹ̀, Lọti pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, àti àwọn obìnrin pẹ̀lú àwọn ènìyàn tókù.
Un atveda atpakaļ visu mantu, un arī Latu, savu brāli, un viņa mantu viņš atveda atpakaļ, ir tās sievas un tos ļaudis.
17 Nígbà tí Abramu ti ṣẹ́gun Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí ó pẹ̀lú rẹ̀, ọba Sodomu lọ pàdé rẹ̀ ní àfonífojì Ṣafe (èyí ni àfonífojì Ọba).
Un kad viņš atpakaļ nāca no kaušanās ar Kedorlaomeru un ar tiem ķēniņiem, kas pie tā bija, tad Sodomas ķēniņš izgāja viņam pretī līdz Šaves ielejai, - tā ir tā ķēniņa ieleja.
18 Melkisedeki ọba Salẹmu sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo.
Un Melhizedeks, Salemes ķēniņš, iznesa maizi un vīnu, un tas bija priesteris Dievam tam visu augstajam.
19 Ó sì súre fún Abramu, wí pé, “Ìbùkún ni fún Abramu ti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Un tas viņu svētīja un sacīja: svētīts lai ir Ābrams no tā visu augstā Dieva, kam pieder zeme un debess.
20 Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ, tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.” Abramu sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.
Un svētīts lai ir tas visu augstais Dievs, kas tavus ienaidniekus nodevis tavā rokā. Un Ābrams tam deva desmito tiesu no visām lietām.
21 Ọba Sodomu sì wí fún Abramu pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”
Un Sodomas ķēniņš sacīja uz Ābramu: dod man tos ļaudis, un to mantu ņem sev.
22 Ṣùgbọ́n Abramu dá ọba Sodomu lóhùn pé, “Mo ti búra fún Olúwa, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ó dá ọ̀run àti ayé, mo sì ti gbọ́wọ́ sókè,
Un Ābrams sacīja uz Sodomas ķēniņu: es savu roku paceļu uz To Kungu, to visaugsto Dievu, kam debess un zeme pieder, -
23 pé, èmi kì yóò mú láti fọ́nrán òwú títí dé okùn bàtà, àti pé, èmi kí yóò mú ohun kan tí ṣe tìrẹ, kí ìwọ kí ó má ba à wí pé, ‘Mo sọ Abramu di ọlọ́rọ̀.’
Nevienu pavedienu, nedz kurpes siksnu, nedz citu ko es neņemšu no visa tā, kas tev pieder, lai tu nesaki: es Ābramu esmu darījis bagātu.
24 Èmi kì yóò gba ohunkóhun yàtọ̀ sí ohun tí àwọn ọkùnrin mi ti jẹ́, ṣùgbọ́n fi ìpín fún àwọn ọkùnrin tí ó bá mi lọ, Aneri, Eṣkolu àti Mamre. Jẹ́ kí wọn kí ó gba ìpín wọn.”
Tik vien to, ko tie jaunekļi apēduši, un to vīru daļu, kas man gājuši līdz, Aners, Eškols un Mamre, tie lai ņem savu daļu.